Heberu 1 – YCB & JCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Heberu 1:1-14

Ọmọ tí o ṣe pàtàkì fún àwọn Angẹli

1Ní ìgbà àtijọ́, Ọlọ́run bá àwọn baba ńlá wa sọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì ní ọ̀pọ̀ ìgbà àti ní onírúurú ọ̀nà, 2ṣùgbọ́n ní ìgbà ìkẹyìn yìí Ọlọ́run ń bá wa sọ̀rọ̀ nípasẹ̀ Ọmọ rẹ̀ Jesu Kristi, ẹni tí ó fi ṣe ajogún ohun gbogbo, nípasẹ̀ ẹni tí ó dá gbogbo ayé yìí àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀: 3Ọmọ tí í ṣe ìtànṣán ògo Ọlọ́run àti àwòrán òun tìkára rẹ̀, tí ó sì ń fi ọ̀rọ̀ agbára rẹ̀ mú ohun gbogbo dúró: Lẹ́yìn tí ó ti ṣe ìwẹ̀nù ẹ̀ṣẹ̀ wa tan, ó wá jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún Ọláńlá ní òkè. 4Nítorí náà, ó sì ti fi bẹ́ẹ̀ di ẹni tí ó ga ní ipò ju angẹli lọ, bí ó ti jogún orúkọ èyí tí ó tayọ̀ tiwọn.

51.5: Sm 2.7; 2Sa 7.14.Nítorí kò sí ọ̀kan nínú àwọn angẹli tí Ọlọ́run fi ìgbà kan sọ fún pé:

“Ìwọ ni ọmọ mi;

lónìí ni mo bí ọ”?

Àti pẹ̀lú pé;

“Èmi yóò jẹ́ baba fún un,

Òun yóò sì jẹ́ ọmọ mi”?

61.6: De 32.43; Sm 97.7.Àti pẹ̀lú, nígbà tí Ọlọ́run rán àkọ́bí rẹ̀ wá si ayé wa yìí. Ó pàṣẹ pé,

“Ẹ jẹ́ kí gbogbo àwọn angẹli Ọlọ́run foríbalẹ̀ fún un.”

71.7: Sm 104.4.Àti nípa ti àwọn angẹli, ó wí pé;

“Ẹni tí ó dá àwọn angẹli rẹ̀ ní ẹ̀mí,

àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ní ọwọ́ iná.”

81.8-9: Sm 45.6-7.Ṣùgbọ́n ó sọ nípa tí Ọmọ rẹ̀ pé,

“Ìtẹ́ rẹ, Ọlọ́run, láé àti láéláé ni,

ọ̀pá aládé òdodo ni ọ̀pá ìjọba rẹ.

9Ìwọ fẹ́ òdodo, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kórìíra iṣẹ́ búburú;

nítorí èyí ni Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ ṣe fi ààmì òróró ayọ̀ yàn ọ

tí ó gbé ọ ju àwọn ẹgbẹ́ rẹ lọ.”

10Ó tún sọ pé,

“Ní àtètèkọ́ṣe, ìwọ Olúwa, ìwọ fi ìdí ayé sọlẹ̀,

àwọn ọ̀run sì jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ ara rẹ.

11Wọn yóò ṣègbé, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà síbẹ̀

gbogbo wọn ni yóò di àkísà bí ẹ̀wù.

12Ní kíká ni ìwọ yóò ká wọn bí aṣọ,

bí ìpààrọ̀ aṣọ ni a ó sì pààrọ̀ wọn.

Ṣùgbọ́n ìwọ fúnrarẹ̀ kì yóò yípadà

àti pé ọdún rẹ kì yóò ní òpin.”

131.13: Sm 110.1.Èwo nínú àwọn angẹli ní a gbọ́ pé Ọlọ́run fi ìgbà kan wí fún pé,

“Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi

títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ

di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ”?

14Kì í ha á ṣe ẹ̀mí tí ń jíṣẹ́ ni àwọn angẹli í ṣe bí; tí a rán lọ síta láti máa ṣiṣẹ́ fún àwọn tí yóò jogún ìgbàlà?

Japanese Contemporary Bible

へブル人への手紙 1:1-14

1

御子と天使

1神は昔、幻や夢や、時には直接の啓示などいろいろな方法で、預言者を通してご自分の計画を少しずつ明らかになさいました。 2しかし今の時代には、ご自分の御子(イエス・キリスト)を通して語っておられます。神は、彼によって世界とその中のすべてのものをお造りになり、その御子にすべてを受け継がせたのです。 3御子は神の栄光を受けて、まばゆいばかりに輝いています。また、その人格と行動すべてにおいて神であることを示し、力あることばによって万物を治めておられます。そればかりか、私たちのすべての罪の記録を消し去ってきよめるために死んでくださいました。そして今は、最高の栄誉を受けて、天におられる偉大な神のそばにいらっしゃるのです。 4こうして、父なる神がお与えになった「神の御子」という名が、天使たちの名よりさらにすぐれていたように、この方は天使よりもはるかにまさった存在となりました。

5神はどの天使に対しても、「あなたはわたしの子。今日、わたしがあなたを生んだ」詩篇2・7などと言われたことはありません。しかし、イエスに対しては、そう言われたのです。さらに、「わたしは彼の父となり、彼はわたしの子となる」Ⅱサムエル7・14と宣言されました。 6それから、長子であるイエスを地上に送る時、「天使はみな、彼を拝め」と言われました。 7天使たちについて神は、「風のように速い使者、燃える炎のような力を持つしもべ」詩篇114・4と紹介しましたが、 8御子についてはこう言われました。

「神(神の子)よ。あなたの国は永遠に続く。

その支配は、いつも公平で正しい。

9あなたは正義を愛し、悪を憎む。

それであなたの神(父なる神)は、

ほかのだれよりも多く、

あなたに喜びを注がれた。」詩篇45・6-7

10また、御子を「主」と呼んで、こう言われました。

「主よ。あなたは世の初めに地を造った。

天も、あなたの手による作品である。

11これらは、やがて無に返る。

しかしあなたは、いつまでも変わらない。

すべてのものは、古着のようにすり切れる。

12いつかあなたは、それらを捨て、

別のものと取り替える。

しかしあなたは、決して変わらず、

あなたの年には終わりがない。」詩篇102・25―27

13神が天使に、次のようなことばをおかけになったことがありますか。

「わたしがあなたの敵を

完全に征服するまで、

わたしの右に座っていなさい。」詩篇110・1

14天使は、救われる人々を助けるために遣わされた、霊の使者なのです。