Habakuku 1 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Habakuku 1:1-17

1Àsọtẹ́lẹ̀ tí wòlíì Habakuku rí.

Ìráhùn Habakuku

21.2: Isa 13.1–14.23; 47; Jr 50–51.Olúwa, èmi yóò ti ké pẹ́ tó fún ìrànlọ́wọ́,

Ṣùgbọ́n ti ìwọ kò ni fetí sí mi?

Tàbí kígbe sí ọ ní ti, “Ìwà ipá!”

ṣùgbọ́n tí ìwọ kò sì gbàlà?

3Èéṣe tí ìwọ fi mú mi rí àìṣedéédéé

Èéṣe tí ìwọ sì fi ààyè gba ìwà ìkà?

Ìparun àti ìwà ipá wà ní iwájú mi;

ìjà ń bẹ, ìkọlù sì wà pẹ̀lú.

4Nítorí náà, òfin di ohun àìkàsí,

ìdájọ́ òdodo kò sì borí.

Àwọn ẹni búburú yí àwọn olódodo ká,

Nítorí náà ni ìdájọ́ òdodo ṣe yí padà.

Ìdáhùn Olúwa

51.5: Ap 13.41.“Ẹ wo inú àwọn kèfèrí, ki ẹ sí wòye,

Kí háà kí ó sì ṣe yin gidigidi.

Nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín

tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́,

bí a tilẹ̀ sọ fún yin.

61.6: If 20.9.Nítorí pé, èmi yóò gbé àwọn ara Babeli dìde,

àwọn aláìláàánú àti onínú-fùfù ènìyàn

tí ó rin gbogbo ilẹ̀ ayé já

láti fi agbára gbà àwọn ibùgbé tí kì í ṣe tiwọn.

7Wọn jẹ́ ènìyàn ti a bẹ̀rù, tí a sì páyà,

ìdájọ́ wọn, àti ọláńlá wọn,

Yóò máa ti inú wọn jáde.

8Ẹṣin wọn yára ju ẹkùn lọ,

wọ́n sì gbóná jú ìkookò àṣálẹ́ lọ

àwọn ẹlẹ́ṣin wọn yóò sí tan ara wọn ká;

wọn yóò sì wá láti ọ̀nà jíjìn réré,

wọn yóò sí fò bí ẹyẹ igún tí ń wá láti jẹrun

9Gbogbo wọn sì wà fún ìwà ipá

ìwò ojú wọn yóò sì wá síwájú;

wọn sì ko ìgbèkùn jọ bí iyanrìn.

10Wọn ó si máa fi àwọn ọba ṣẹ̀sín

wọn ó sì tún kẹ́gàn àwọn aládé.

Wọn yóò sì fi gbogbo ìlú odi alágbára nì rẹ́rìn-ín;

Nítorí pé, wọn yóò ko erùpẹ̀ jọ, wọn yóò sì gbà á

11Nígbà náà ni inú rẹ̀ yóò yípadà,

yóò sì rékọjá, yóò si ṣẹ̀ ní kíka agbára rẹ̀ yìí sí iṣẹ́ òrìṣà rẹ̀.”

Ìráhùn lẹ́ẹ̀kejì Habakuku

12Olúwa, ǹjẹ́ láti ayérayé kọ ni ìwọ tí wà?

Olúwa Ọlọ́run mi. Ẹni mímọ́ mi, àwa kì yóò kú

Olúwa, ìwọ tí yàn wọn fún ìdájọ́;

Ọlọ́run alágbára, ìwọ tí fi ẹsẹ̀ wọn múlẹ̀ fún ìbáwí

13Ojú rẹ mọ́ tónítóní láti wo ibi;

ìwọ kò le gbà ìwà ìkà

nítorí kí ni ìwọ ṣe gba àwọn alárékérekè láààyè?

Nítorí kí ni ìwọ ṣe dákẹ́ nígbà tí ẹni búburú ń pa

ẹni tí i ṣe olódodo ju wọn lọ run?

14Ìwọ sì tí sọ ènìyàn di bí ẹja inú Òkun,

bí ohun tí ń rákò tí wọn ko ni alákòóso

15Àwọn ènìyàn búburú fi àwọ̀n wọn gbé wọn sókè

ó sì kó wọn jọ nínú àwọ̀n ńlá rẹ̀;

nítorí náà, ó dunnú, ó sì yọ̀ pẹ̀lú.

16Nítorí náà, ó rú ẹbọ sí àwọ̀n rẹ̀,

ó sì ń sun tùràrí fún àwọ̀n ńlá rẹ̀

nítorí pẹ̀lú àwọ̀n rẹ̀ ni ó fi ń gbé ní ìgbádùn

tí ó sì ń gbádùn pẹ̀lú oúnjẹ tí ó bá wù ú.

17Ǹjẹ́ wọn yóò ha máa pa àwọ̀n wọn mọ́ ní òfìfo bí,

tí wọn yóò sì pa orílẹ̀-èdè run láìsí àánú?

Nouă Traducere În Limba Română

Habacuc 1:1-17

1Rostirea pe care a văzut‑o profetul Habacuc.

Prima plângere a profetului

2– Până când, Doamne, voi striga după ajutor,

și Tu nu vei asculta?

Până când voi striga către Tine: „Violență!“,

și Tu nu vei izbăvi?

3De ce mă faci să privesc nelegiuirea

și Te uiți la necaz?

Distrugerea și violența sunt înaintea mea;

peste tot sunt dezbinări și se stârnesc certuri.

4De aceea Legea este fără putere

și dreptatea nu se arată niciodată.

Căci cel rău îl împresoară4 Sau: îl învinge. pe cel drept

și astfel dreptatea este pervertită.

Răspunsul Domnului

5– Uitați‑vă printre neamuri și priviți!

Mirați‑vă! Uimiți‑vă!

Căci în zilele voastre fac o lucrare

pe care n‑ați crede‑o

dacă v‑ar povesti‑o cineva!

6Iată, îi voi ridica pe caldeeni6 babilonieni.,

acel neam crud și năvalnic,

care străbate întinderile pământului

pentru a lua în stăpânire locuințe

care nu sunt ale lui!

7Ei sunt îngrozitori și de temut;

își au propria lege

și nu recunosc nicio altă autoritate!7 Lit.: înfricoșători; / judecata și demnitatea lor provin numai de la ei înșiși.

8Caii lor sunt mai rapizi decât leoparzii

și mai sprinteni decât lupii în amurg.

Călăreții lor se avântă,

călăreții lor vin de departe.

Zboară ca un vultur care se repede să devoreze;

9toți vin pentru violență.

Privirile lor sunt ațintite9 Sensul termenului ebraic este nesigur. tot înainte

și adună captivi ca nisipul de mulți.

10Își bat joc de regi

și‑i iau în derâdere pe conducători.

Râd de orice fortificație,

căci îngrămădesc pământ10 Sau: fac o rampă din pământ, tehnică militară, folosită de către asediatori. lângă ea și o cuceresc.

11Apoi trec ca vântul și merg mai departe11 Posibil: și depășesc limita.;

el se face astfel vinovat,

puterea lui fiindu‑i dumnezeul.

A doua plângere a profetului

12– Oare nu ești Tu din veșnicie, Doamne?

Dumnezeul meu, Sfântul meu, nu vom muri!

Doamne, Tu l‑ai rânduit pentru a face judecată!

Stânca mea, Tu l‑ai ridicat

ca să pedepsească!

13Ochii Tăi sunt prea curați ca să se uite la rău;

Tu nu poți să privești asuprirea!

De ce Te uiți la cei necredincioși

și taci când cel rău îl înghite

pe cel mai drept decât el?

14L‑ai făcut pe om asemenea peștilor mării,

asemenea vietății din mare care nu are stăpân.

15El îi scoate pe toți cu undița,

îi adună cu mreaja lui,

îi strânge în năvodul lui

și de aceea se bucură și se veselește.

16De aceea aduce el jertfe mrejei sale

și arde tămâie năvodului său!

Datorită lor, partea lui este bogată

și mâncarea lui este din abundență!

17Va continua el oare să‑și golească mreaja

și să ucidă neamuri fără să cruțe nimic?