Habakuku 1 – YCB & NASV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Habakuku 1:1-17

1Àsọtẹ́lẹ̀ tí wòlíì Habakuku rí.

Ìráhùn Habakuku

21.2: Isa 13.1–14.23; 47; Jr 50–51.Olúwa, èmi yóò ti ké pẹ́ tó fún ìrànlọ́wọ́,

Ṣùgbọ́n ti ìwọ kò ni fetí sí mi?

Tàbí kígbe sí ọ ní ti, “Ìwà ipá!”

ṣùgbọ́n tí ìwọ kò sì gbàlà?

3Èéṣe tí ìwọ fi mú mi rí àìṣedéédéé

Èéṣe tí ìwọ sì fi ààyè gba ìwà ìkà?

Ìparun àti ìwà ipá wà ní iwájú mi;

ìjà ń bẹ, ìkọlù sì wà pẹ̀lú.

4Nítorí náà, òfin di ohun àìkàsí,

ìdájọ́ òdodo kò sì borí.

Àwọn ẹni búburú yí àwọn olódodo ká,

Nítorí náà ni ìdájọ́ òdodo ṣe yí padà.

Ìdáhùn Olúwa

51.5: Ap 13.41.“Ẹ wo inú àwọn kèfèrí, ki ẹ sí wòye,

Kí háà kí ó sì ṣe yin gidigidi.

Nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín

tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́,

bí a tilẹ̀ sọ fún yin.

61.6: If 20.9.Nítorí pé, èmi yóò gbé àwọn ara Babeli dìde,

àwọn aláìláàánú àti onínú-fùfù ènìyàn

tí ó rin gbogbo ilẹ̀ ayé já

láti fi agbára gbà àwọn ibùgbé tí kì í ṣe tiwọn.

7Wọn jẹ́ ènìyàn ti a bẹ̀rù, tí a sì páyà,

ìdájọ́ wọn, àti ọláńlá wọn,

Yóò máa ti inú wọn jáde.

8Ẹṣin wọn yára ju ẹkùn lọ,

wọ́n sì gbóná jú ìkookò àṣálẹ́ lọ

àwọn ẹlẹ́ṣin wọn yóò sí tan ara wọn ká;

wọn yóò sì wá láti ọ̀nà jíjìn réré,

wọn yóò sí fò bí ẹyẹ igún tí ń wá láti jẹrun

9Gbogbo wọn sì wà fún ìwà ipá

ìwò ojú wọn yóò sì wá síwájú;

wọn sì ko ìgbèkùn jọ bí iyanrìn.

10Wọn ó si máa fi àwọn ọba ṣẹ̀sín

wọn ó sì tún kẹ́gàn àwọn aládé.

Wọn yóò sì fi gbogbo ìlú odi alágbára nì rẹ́rìn-ín;

Nítorí pé, wọn yóò ko erùpẹ̀ jọ, wọn yóò sì gbà á

11Nígbà náà ni inú rẹ̀ yóò yípadà,

yóò sì rékọjá, yóò si ṣẹ̀ ní kíka agbára rẹ̀ yìí sí iṣẹ́ òrìṣà rẹ̀.”

Ìráhùn lẹ́ẹ̀kejì Habakuku

12Olúwa, ǹjẹ́ láti ayérayé kọ ni ìwọ tí wà?

Olúwa Ọlọ́run mi. Ẹni mímọ́ mi, àwa kì yóò kú

Olúwa, ìwọ tí yàn wọn fún ìdájọ́;

Ọlọ́run alágbára, ìwọ tí fi ẹsẹ̀ wọn múlẹ̀ fún ìbáwí

13Ojú rẹ mọ́ tónítóní láti wo ibi;

ìwọ kò le gbà ìwà ìkà

nítorí kí ni ìwọ ṣe gba àwọn alárékérekè láààyè?

Nítorí kí ni ìwọ ṣe dákẹ́ nígbà tí ẹni búburú ń pa

ẹni tí i ṣe olódodo ju wọn lọ run?

14Ìwọ sì tí sọ ènìyàn di bí ẹja inú Òkun,

bí ohun tí ń rákò tí wọn ko ni alákòóso

15Àwọn ènìyàn búburú fi àwọ̀n wọn gbé wọn sókè

ó sì kó wọn jọ nínú àwọ̀n ńlá rẹ̀;

nítorí náà, ó dunnú, ó sì yọ̀ pẹ̀lú.

16Nítorí náà, ó rú ẹbọ sí àwọ̀n rẹ̀,

ó sì ń sun tùràrí fún àwọ̀n ńlá rẹ̀

nítorí pẹ̀lú àwọ̀n rẹ̀ ni ó fi ń gbé ní ìgbádùn

tí ó sì ń gbádùn pẹ̀lú oúnjẹ tí ó bá wù ú.

17Ǹjẹ́ wọn yóò ha máa pa àwọ̀n wọn mọ́ ní òfìfo bí,

tí wọn yóò sì pa orílẹ̀-èdè run láìsí àánú?

New Amharic Standard Version

ዕንባቆም 1:1-17

1ነቢዩ ዕንባቆም የተቀበለው ንግር፤

የዕንባቆም ማጕረምረም

2እግዚአብሔር ሆይ፤ ለርዳታ እየተጣራሁ፣

አንተ የማትሰማው እስከ መቼ ነው?

“ግፍ በዛ” ብዬ እየጮኽሁ፣

አንተ የማታድነው እስከ መቼ ነው?

3ስለ ምን በደልን እንዳይ አደረግኸኝ?

እንዴትስ ግፍ ሲፈጸም ትታገሣለህ?

ጥፋትና ግፍ በፊቴ አለ፤

ጠብና ግጭት በዝቷል።

4ስለዚህ ሕግ ላልቷል፤

ፍትሕ ድል አይነሣም፤

ፍትሕ ይጣመም ዘንድ፣

ክፉዎች ጻድቃንን ይከብባሉ።

የእግዚአብሔር መልስ

5“ቢነገራችሁም እንኳ፣

የማታምኑትን እናንተን፣

በዘመናችሁ አንድ ነገር ስለማደርግ፣

እነሆ፤ ሕዝቡን እዩ፤ ተመልከቱም፤

እጅግም ተደነቁ።

6የራሳቸው ያልሆኑትን መኖሪያ ስፍራዎች ለመያዝ፣

ምድርን ሁሉ የሚወርሩትን፣

ጨካኝና ፈጣን የሆኑትን፣

ባቢሎናውያንን1፥6 ከለዳውያን ማለት ነው። አስነሣለሁ።

7እነርሱም የሚያስፈሩና የሚያስደነግጡ ናቸው፤

ፍርዳቸውና ክብራቸው፣

ከራሳቸው ይወጣል።

8ፈረሶቻቸው ከነብር ይልቅ ፈጣኖች፣

ከማታም ተኵላ ይልቅ ጨካኞች ናቸው።

ፈረሰኞቻቸው በፍጥነት ይጋልባሉ፤

ከሩቅ ስፍራም ይመጣሉ።

ነጥቆ ለመብላት እንደሚቸኵል አሞራ ይበርራሉ፤

9ሁሉም ለዐመፅ ታጥቀው ይመጣሉ።

ሰራዊታቸው1፥9 የዕብራይስጡ ቃል ትርጕም በትክክል አይታወቅም። እንደ ምድረ በዳ ነፋስ ወደ ፊት ይገሠግሣል፤

ምርኮኞችንም እንደ አሸዋ ይሰበስባል።

10ነገሥታትን ይንቃል፤

በገዦችም ላይ ያፌዛል፤

በምሽግ ሁሉ ላይ ይሥቃል፤

የዐፈር ቍልል ሠርቶም ይይዘዋል።

11ከዚያም በኋላ እንደ ነፋስ ዐልፎ ይሄዳል፤

ጕልበታቸውን አምላካቸው ያደረጉ በደለኞች ናቸው።”

የዕንባቆም ዳግመኛ ማጕረምረም

12እግዚአብሔር ሆይ፤ ከዘላለም ጀምሮ ያለህ አይደለህምን?

የእኔ አምላክ፣ የእኔ ቅዱስ እኛ አንሞትም፤

እግዚአብሔር ሆይ፤ እንዲፈርዱ ሾመሃቸዋል፤

ዐለት ሆይ፤ ይቀጡ ዘንድ ሥልጣን ሰጠሃቸው።

13ዐይኖችህ ክፉውን እንዳያዩ እጅግ ንጹሓን ናቸው፤

አንተ በደልን መታገሥ አትችልም፤

ታዲያ፣ አታላዮችን ለምን ትታገሣለህ?

ክፉው ከራሱ ይልቅ ጻድቅ የሆነውን ሲውጠውስ፣

ለምን ዝም ትላለህ?

14አንተ ሰዎችን በባሕር ውስጥ እንዳለ ዓሣ፣

ገዥ እንደሌላቸውም የባሕር ፍጥረታት አደረግህ።

15ክፉ ጠላት ሁሉንም በመንጠቆ ያወጣቸዋል፤

በመረቡ ይይዛቸዋል፤

በአሽክላው ውስጥ ይሰበስባቸዋል፤

በዚህም ይደሰታል፤ ሐሤትም ያደርጋል።

16በእነርሱ ተዝናንቶ ይኖራልና፤

ምግቡም ሠብቷል።

ስለዚህ ለመረቡ ይሠዋል፤

ለአሽክላውም ያጥናል።

17ታዲያ መረቡን ባለማቋረጥ መጣል፣

ሕዝቦችንስ ያለ ርኅራኄ መግደል አለበትን?