Gẹnẹsisi 8 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 8:1-22

Ìkún omi gbẹ

1Ọlọ́run sì rántí Noa àti ohun alààyè gbogbo tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, bí àwọn ẹranko igbó àti ohun ọ̀sìn, ó sì mú kí afẹ́fẹ́ fẹ́ sórí ilẹ̀, omi náà sì fà. 2Gbogbo ìsun ibú àti fèrèsé ìṣàn ọ̀run tì, òjò pẹ̀lú sì dáwọ́ rírọ̀ dúró. 3Omi sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gbẹ kúrò lórí ilẹ̀, lẹ́yìn àádọ́jọ ọjọ́, ó sì ti ń fà. 4Ní ọjọ́ kẹtà-dínlógún oṣù kejì ni ọkọ̀ náà gúnlẹ̀ sórí òkè Ararati. 5Omi náà sì ń gbẹ si títí di oṣù kẹwàá. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, orí àwọn òkè sì farahàn.

6Lẹ́yìn ogójì ọjọ́, Noa sí fèrèsé tí ó ṣe sára ọkọ̀. 7Ó sì rán ẹyẹ ìwò kan jáde, tí ó ń fò káàkiri síwá àti sẹ́yìn títí omi fi gbẹ kúrò ní orí ilẹ̀. 8Ó sì rán àdàbà kan jáde láti wò ó bóyá omi ti gbẹ kúrò lórí ilẹ̀. 9Ṣùgbọ́n àdàbà náà kò rí ìyàngbẹ ilẹ̀ bà lé nítorí omi kò tí ì tan lórí ilẹ̀, ó sì padà sọ́dọ̀ Noa. Noa na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú ẹyẹ náà wọlé sọ́dọ̀ ara rẹ̀ nínú ọkọ̀. 10Ó sì dúró fún ọjọ́ méje sí i; ó sì tún rán àdàbà náà jáde láti inú ọkọ̀. 11Nígbà tí àdàbà náà padà sọ́dọ̀ rẹ̀ ní àṣálẹ́, ó já ewé igi olifi tútù há ẹnu! Nígbà náà ni Noa mọ̀ pé omi ti ń gbẹ kúrò lórí ilẹ̀. 12Noa tún mú sùúrù fún ọjọ́ méje, ó sì tún rán àdàbà náà jáde, ṣùgbọ́n àdàbà náà kò padà sọ́dọ̀ rẹ̀ mọ́.

13Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ní ọdún kọ́kànlélẹ́gbẹ̀ta (601) ni omi náà gbẹ kúrò lórí ilẹ̀; Noa sì ṣí ọkọ̀, ó sì ri pé ilẹ̀ ti gbẹ. 14Ní ọjọ́ kẹtà-dínlọ́gbọ̀n oṣù kejì, ilẹ̀ ti gbẹ pátápátá.

15Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Noa pé. 16“Jáde kúrò nínú ọkọ̀, ìwọ àti aya rẹ, pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ àti àwọn aya wọn. 17Kó gbogbo àwọn ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú rẹ jáde: àwọn ẹyẹ, ẹranko àti gbogbo àwọn ẹ̀dá tí ń rìn nílẹ̀, kí wọn lè bí sí i, kí wọn sì pọ̀ sí i, kí wọn sì máa gbá yìn lórí ilẹ̀.”

18Noa, àwọn ọmọ rẹ̀, aya rẹ̀ àti àwọn aya ọmọ rẹ̀ sì jáde. 19Gbogbo àwọn ẹranko àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn nílẹ̀ àti gbogbo ẹyẹ pátápátá ni ó jáde kúrò nínú ọkọ̀, ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ní irú tiwọn.

20Noa sì mọ pẹpẹ fún Olúwa, ó sì mú lára àwọn ẹran tí ó mọ́ àti ẹyẹ tí ó mọ́, ó sì fi rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ. 21Olúwa sì gbọ́ òórùn dídùn; ó sì wí ní ọkàn rẹ̀: “Èmi kì yóò tún fi ilẹ̀ ré nítorí ènìyàn mọ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo èrò inú rẹ̀ jẹ́ ibi láti ìgbà èwe rẹ̀ wá, èmi kì yóò pa gbogbo ohun alààyè run mọ́ láé, bí mo ti ṣe.

22“Níwọ́n ìgbà tí ayé bá sì wà,

ìgbà ọ̀gbìn àti ìgbà ìkórè

ìgbà òtútù àti ìgbà ooru,

ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn àti ìgbà òjò,

ìgbà ọ̀sán àti ìgbà òru,

yóò wà títí láé.”

La Bible du Semeur

Genèse 8:1-22

Le retour à l’ordre

1Mais Dieu n’avait pas oublié Noé et toutes les bêtes sauvages et les bestiaux qui étaient avec lui dans le bateau. Il fit souffler un vent sur la terre ; alors les eaux se mirent à baisser. 2Les sources des eaux souterraines et les écluses du ciel se refermèrent. La pluie cessa de tomber. 3Peu à peu, les eaux se retirèrent de dessus la terre. Au bout des cent cinquante jours, elles commencèrent à baisser.

4Le dix-septième jour du septième mois, le bateau s’échoua dans le massif montagneux d’Ararat. 5Les eaux continuèrent à baisser jusqu’au dixième mois ; le premier jour de ce mois, les sommets des montagnes apparurent. 6Quarante jours après, Noé ouvrit la fenêtre qu’il avait ménagée dans le bateau 7et lâcha un corbeau ; celui-ci s’envola, il revint et repartit à plusieurs reprises jusqu’à ce que les eaux se soient résorbées sur la terre. 8Puis Noé lâcha une colombe pour voir si les eaux avaient baissé sur la terre ; 9mais n’ayant pas trouvé où se poser, celle-ci revint vers lui dans le bateau, car toute la terre était encore inondée. Noé tendit la main, prit la colombe et la ramena auprès de lui dans le bateau. 10Il attendit encore sept autres jours et lâcha de nouveau la colombe hors du bateau ; 11elle revint vers lui sur le soir, tenant dans son bec une feuille d’olivier toute fraîche ; Noé sut ainsi que les eaux s’étaient résorbées sur la terre. 12Il attendit encore sept autres jours et relâcha la colombe ; cette fois, elle ne revint plus vers lui.

13L’an 601 de la vie de Noé, le premier jour du premier mois, les eaux s’étaient retirées sur la terre, Noé enleva la couverture du bateau ; il regarda dehors et constata que la surface du sol avait séché. 14Le vingt-septième jour du deuxième mois, la terre était sèche. 15Alors Dieu dit à Noé : 16Sors du bateau avec ta femme, tes fils et tes belles-filles. 17Fais sortir aussi tous les animaux de toutes sortes qui sont avec toi : les oiseaux, les bestiaux et toutes les bêtes qui se meuvent à ras de terre : qu’ils prolifèrent sur la terre, et qu’ils s’y reproduisent et s’y multiplient.

18Noé sortit avec ses fils, sa femme et ses belles-filles. 19Tous les animaux, les bêtes qui se meuvent à ras de terre et les oiseaux, tous les êtres qui remuent sur la terre sortirent du bateau par familles.

20Noé érigea un autel pour l’Eternel, il prit de tous les animaux purs et de tous les oiseaux purs, et les offrit en holocauste8.20 Dans l’holocauste, l’animal est brûlé presque entièrement sur l’autel (voir Lv 1). C’est le premier sacrifice de ce genre mentionné dans la Bible. sur l’autel. 21L’Eternel sentit le parfum apaisant du sacrifice8.21 Expression indiquant que le sacrifice est accepté par Dieu. et se dit en lui-même : Jamais plus je ne maudirai la terre à cause de l’homme, puisque le cœur de l’homme est porté au mal dès son enfance, et je ne détruirai plus tous les êtres vivants comme je viens de le faire.

22Aussi longtemps ╵que durera la terre,

semailles et moissons,

froid et chaleur,

été, hiver,

et jour et nuit

jamais ne cesseront.