Gẹnẹsisi 7 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 7:1-24

1Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Noa pé, “Wọ inú ọkọ̀ lọ ìwọ àti gbogbo ìdílé rẹ, nítorí ìwọ nìkan ni mo rí bí olódodo nínú ìran yìí. 2Mú méje méje nínú àwọn ẹran tí ó mọ́, akọ àti abo, mú méjì méjì takọ tabo nínú àwọn ẹran aláìmọ́. 3Sì mú méje méje pẹ̀lú nínú onírúurú ẹyẹ, takọ tabo ni kí o mú wọn, wọlé sínú ọkọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí á ba à lè pa wọ́n mọ́ láààyè ní gbogbo ayé. 4Nítorí ní ọjọ́ méje sí ìhín, èmi yóò rọ òjò sórí ilẹ̀ fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi yóò sì pa gbogbo ohun alààyè tí mo ti dá run kúrò lórí ilẹ̀.”

5Noa sì ṣe ohun gbogbo tí Ọlọ́run pàṣẹ fún un.

6Noa jẹ́ ọmọ ẹgbẹ̀ta ọdún (600) nígbà tí ìkún omi dé sórí ilẹ̀. 77.7: Mt 24.38; Lk 17.27.Noa àti ìyàwó rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn aya ọmọ rẹ̀ sì wọ inú ọkọ láti sá àsálà fún ìkún omi. 8Méjì méjì ni àwọn ẹran tí ó mọ́ àti aláìmọ́, ti ẹyẹ àti ti gbogbo àwọn ẹ̀dá afàyàfà, 9akọ àti abo ni wọ́n wọlé pẹ̀lú Noa sínú ọkọ̀ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún Noa. 10Lẹ́yìn ọjọ́ keje, ìkún omi sì dé sí ayé.

117.11,12: 2Pt 3.6.Ní ọjọ́ kẹtà-dínlógún oṣù kejì, tí Noa pé ọmọ ẹgbẹ̀ta ọdún, ni gbogbo ìsun ibú ya, fèrèsé ìṣàn omi ọ̀run sì ṣí sílẹ̀. 12Òjò àrọ̀ìrọ̀dá sì rọ̀ fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru.

13Ní ọjọ́ tí ìkún omi yóò bẹ̀rẹ̀ gan an ni Noa àti Ṣemu, Hamu àti Jafeti pẹ̀lú aya Noa àti aya àwọn ọmọ rẹ̀ wọ inú ọkọ̀. 14Wọ́n mú ẹranko igbó àti ohun ọ̀sìn ní onírúurú wọn, àwọn ẹ̀dá afàyàfà àti ẹyẹ àti àwọn ohun abìyẹ́ ni onírúurú wọn. 15Méjì méjì ni gbogbo ẹ̀dá tí ó ní èémí ìyè nínú wọlé pẹ̀lú Noa sínú ọkọ̀. 16Gbogbo wọ́n wọlé ní takọ tabo bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún Noa, Olúwa sì tì wọn mọ́ inú ọkọ̀.

17Òjò náà sì rọ̀ ní àrọ̀ìrọ̀dá fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, ọkọ̀ náà sì ń léfòó lórí omi, kúrò lórí ilẹ̀ bí omi náà ti ń pọ̀ sí i. 18Bí omi náà ti ń pọ̀ sí i, bẹ́ẹ̀ náà ni ọkọ̀ náà sì ń léfòó lójú omi. 19Omi náà pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó bo gbogbo àwọn òkè gíga tí ó wà lábẹ́ ọ̀run. 20Omi náà kún bo àwọn òkè, bí ìwọ̀n ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún. 21Gbogbo ohun alààyè tí ó wà lórí ilẹ̀ parun: ẹyẹ, ohun ọ̀sìn, ẹranko igbó, àwọn ẹ̀dá afàyàfà àti ènìyàn. 22Gbogbo ohun tí ó wà lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ tó ní èémí ìyè ní ihò imú wọn ni ó kú. 23Gbogbo ohun alààyè tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé ni a parẹ́: ènìyàn àti ẹranko, àwọn ohun tí ń rìn nílẹ̀, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run pátápátá ló ṣègbé. Noa àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ọkọ̀ ni ó ṣẹ́kù.

24Omi náà sì bo ilẹ̀ fún àádọ́jọ ọjọ́ (150).

La Bible du Semeur

Genèse 7:1-24

L’embarquement

1Puis l’Eternel dit à Noé : Entre dans le bateau, toi et toute ta famille car je ne vois que toi qui sois juste parmi tes contemporains. 2Prends sept couples des animaux purs7.2 C’est-à-dire les animaux que la Loi de Moïse déclarera aptes à être mangés ou offerts en sacrifice (voir Lv 11). Certains seront offerts en sacrifice à la fin du déluge (8.20)., sept mâles et sept femelles, et un couple de tous les animaux qui ne sont pas purs, le mâle et sa femelle. 3Prends aussi sept couples de chaque espèce d’oiseaux pour en perpétuer la race sur toute la terre. 4Car dans sept jours, je vais faire pleuvoir sur la terre durant quarante jours et quarante nuits et j’effacerai de la surface de la terre tous les êtres que j’ai créés.

5Noé fit tout ce que l’Eternel lui avait ordonné.

6Noé était âgé de six cents ans quand le déluge vint sur la terre. 7Il entra dans le bateau avec ses fils, sa femme et ses belles-filles pour échapper aux eaux du déluge7.7 Cité en Mt 24.38 ; Lc 17.27.. 8Un couple d’animaux – un mâle et une femelle de ceux qui sont purs et de ceux qui ne le sont pas – ainsi que des oiseaux et de tout ce qui se meut à ras de terre 9deux par deux, vinrent trouver Noé pour entrer dans le bateau, comme Dieu l’avait prescrit à Noé. 10Au bout de sept jours, les eaux du déluge s’abattirent sur la terre.

Le déluge

11L’an 600 de la vie de Noé, le dix-septième jour du deuxième mois de l’année, quand toutes les sources d’eaux souterraines jaillirent et les écluses du ciel s’ouvrirent, 12et la pluie tomba sur la terre durant quarante jours et quarante nuits. 13Ce même jour, Noé entra dans le bateau ainsi que ses fils, Sem, Cham et Japhet, sa femme et ses trois belles-filles. 14Avec eux était entrée chaque espèce d’animaux sauvages, de bestiaux, de bêtes qui se meuvent à ras de terre, d’oiseaux, de petits oiseaux et tous les volatiles. 15Un couple de tout être vivant était venu trouver Noé pour entrer dans le bateau. 16Ils étaient arrivés deux par deux, mâle et femelle, comme Dieu l’avait ordonné. Puis l’Eternel referma la porte derrière Noé, 17et le déluge s’abattit durant quarante jours sur la terre, les eaux montèrent et soulevèrent le bateau, qui se mit à flotter au-dessus de la terre.

18Les eaux montèrent, grossirent considérablement sur la terre et le bateau vogua sur les flots. 19Le niveau de l’eau montait de plus en plus, de sorte que toutes les hautes montagnes sous tous les cieux furent submergées. 20Les eaux s’élevèrent de sept à huit mètres7.20 L’hébreu a : quinze coudées. au-dessus des montagnes qui disparurent sous les flots, 21et toute créature qui bougeait sur la terre périt : les oiseaux, le bétail et les animaux sauvages, toutes les bestioles qui pullulaient sur la terre, et tous les hommes. 22Tout ce qui respirait sur la terre ferme mourut. 23Ainsi l’Eternel effaça de la surface du sol tous les êtres vivants, depuis l’homme jusqu’au bétail, jusqu’aux animaux qui se meuvent à ras de terre et jusqu’aux oiseaux du ciel. Ils furent effacés de la terre et il ne resta que Noé et ceux qui étaient avec lui dans le bateau. 24La crue des eaux au-dessus de la terre dura cent cinquante jours.