Gẹnẹsisi 50 – YCB & CARSA

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 50:1-26

1Josẹfu sì ṣubú lé baba rẹ̀, ó sọkún, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu. 2Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún àwọn oníṣègùn tí ó wà ní ìkáwọ́ rẹ̀ pé kí wọn kí ó ṣe òkú Israẹli baba rẹ̀ lọ́jọ̀, àwọn oníṣègùn náà sì ṣe bẹ́ẹ̀, 3Fún ogójì ọjọ́ ni wọ́n fi ṣe èyí, nítorí èyí ni àsìkò tí a máa ń fi ṣe ẹ̀ǹbáàmù òkú. Àwọn ará Ejibiti sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀ fún àádọ́rin ọjọ́.

4Nígbà tí ọjọ́ ìṣọ̀fọ̀ náà kọjá. Josẹfu wí fún àwọn ará ilé Farao pé, “Bí mo bá bá ojúrere yín pàdé, ẹ bá mi sọ fún Farao. 550.5: Gẹ 47.29-31.‘Baba mi mú mi búra ó sì wí fún mi pé, “Mo ti fẹ́rẹ kú: sinmi sínú ibojì tí mo gbẹ́ fún ara mi ní ilẹ̀ Kenaani.” Nísinsin yìí, jẹ́ kí n lọ kí n sì sìnkú baba mi, lẹ́yìn náà èmi yóò padà wa.’ ”

6Farao wí pé, “Gòkè lọ, kí o sì sin baba rẹ, bí ó tí mú ọ búra.”

7Báyìí ni Josẹfu gòkè lọ láti sìnkú baba rẹ̀. Gbogbo àwọn ìjòyè Farao ni ó sìn ín lọ—àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀, àti gbogbo àwọn àgbàgbà ilẹ̀ Ejibiti. 8Yàtọ̀ fún gbogbo àwọn ará ilé Josẹfu àti ti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti àwọn tí ó jẹ́ ilé baba rẹ̀, àwọn ọmọ wọn nìkan àti agbo ẹran pẹ̀lú agbo màlúù ni ó sẹ́ kù ní Goṣeni. 9Kẹ̀kẹ́-ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin pẹ̀lú gòkè lọ. Àìmoye ènìyàn ni ó lọ.

10Nígbà tí wọ́n dé ilẹ̀ ìpakà Atadi, ní ẹ̀bá Jordani, wọn pohùnréré ẹkún; Níbẹ̀ ni Josẹfu sì tún dúró ṣọ̀fọ̀ baba rẹ̀ fún ọjọ́ méje. 11Nígbà tí àwọn ará Kenaani tí ń gbé níbẹ̀ rí i bí wọ́n ti ń ṣọ̀fọ̀ náà ni ilẹ̀ ìpakà Atadi, wọ́n wí pé, “Ọ̀fọ̀ ńlá ni àwọn ará Ejibiti ń ṣe yìí.” Ìdí èyí ni a fi ń pe ibẹ̀ ní Abeli-Misraimu (Ìṣọ̀fọ̀ àwọn ará Ejibiti). Kò sì jìnnà sí Jordani.

12Báyìí ni àwọn ọmọ Jakọbu ṣe ohun tí baba wọn pàṣẹ fún wọn. 1350.13: Ap 7.16.Wọ́n gbé e lọ sí ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì sin ín sínú ihò àpáta tí ó wà ní oko Makpela, ní tòsí i Mamre tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti, pẹ̀lú ilẹ̀ náà. 14Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti sìnkú baba rẹ̀ tan, Josẹfu padà sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀ àti àwọn mìíràn tí ó tẹ̀lé e lọ láti sin baba rẹ̀.

Josẹfu fi ọkàn àwọn arákùnrin rẹ̀ balẹ̀

15Nígbà tí àwọn arákùnrin Josẹfu rí i pé baba wọn kú, wọ́n wí fún ara wọn pé, “Ǹjẹ́ bí ó bá ṣe pé Josẹfu ṣì fi wá sínú ńkọ́, tí ó sì fẹ́ gbẹ̀san gbogbo aburú tí a ti ṣe sí i?” 16Nítorí náà wọ́n ránṣẹ́ sí Josẹfu wí pé, “Baba rẹ fi àṣẹ yìí sílẹ̀ kí ó tó lọ wí pé: 17‘Èyí ni kí ẹ̀yin kí ó sọ fún Josẹfu: Mo bẹ̀ ọ́ kí o dáríjì àwọn arákùnrin rẹ, gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àti aburú tí wọ́n ṣe sí ọ, èyí tí ó mú ibi bá ọ’. Nísinsin yìí, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run baba rẹ jì wọ́n.” Nígbà tí iṣẹ́ ti wọ́n rán dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Josẹfu sọkún.

18Àwọn arákùnrin rẹ̀ wá, wọ́n sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, wọ́n wí pé, “Ẹrú rẹ ni a jẹ́.” 19Ṣùgbọ́n Josẹfu wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù, èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run bí? 20Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ gbèrò láti ṣe mi ní ibi, ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbèrò láti fi ṣe rere tí ń ṣe lọ́wọ́ yìí; ni gbígba ẹ̀mí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn là. 21Nítorí náà, ẹ má ṣe bẹ̀rù. Èmi yóò pèsè fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín.” Ó tún fi wọ́n lọ́kàn balẹ̀, ó sì sọ ọ̀rọ̀ rere fun wọn.

Ikú Josẹfu

22Josẹfu sì ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ìdílé baba rẹ̀. Ó sì wà láààyè fún àádọ́fà (110) ọdún. 23Ó sì rí ìran kẹta ọmọ Efraimu-Àwọn ọmọ Makiri, ọmọkùnrin Manase ni a sì gbé le eékún Josẹfu nígbà tí ó bí wọn.

24Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Mo ti fẹ́rẹ kú, ṣùgbọ́n dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, yóò sì mú un yín jáde kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí ó ti ṣèlérí ní ìbúra fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.” 25Josẹfu sì mú kí àwọn ọmọ Israẹli búra májẹ̀mú kan wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, nígbà náà ni ẹ gbọdọ̀ kó egungun mi lọ́wọ́ kúrò ní ìhín.”

26Báyìí ni Josẹfu kú nígbà tí ó pé àádọ́fà (110) ọdún. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ṣe òkú rẹ̀ lọ́jọ̀ tan, a gbé e sí inú pósí ní Ejibiti.

Священное Писание (Восточный перевод), версия с «Аллахом»

Начало 50:1-26

Смерть и погребение Якуба

1Юсуф припал к отцу, заплакал над ним и поцеловал его. 2Он приказал своим слугам-врачам набальзамировать тело отца, и врачи набальзамировали Исраила. 3У них ушло на это сорок дней, потому что таков полный срок бальзамирования. И египтяне оплакивали его семьдесят дней.

4Когда прошли дни плача, Юсуф сказал придворным фараона:

– Если я нашёл расположение в ваших глазах, то попросите за меня фараона; скажите ему: 5«Мой отец велел мне дать клятву и сказал: „Я умираю; похорони меня в могиле, которую я выкопал себе в земле Ханаана“. Позволь же мне пойти и похоронить моего отца; после этого я вернусь».

6Фараон сказал:

– Иди и похорони отца так, как ты поклялся ему.

7И Юсуф пошёл хоронить своего отца, и с ним пошли все придворные фараона, старейшины двора, и все старейшины Египта, 8и весь дом Юсуфа, и его братья, и весь дом его отца. Только их дети и стада крупного и мелкого скота остались в Гошене. 9Их сопровождали колесницы и всадники; это была великая процессия.

10Они пришли к гумну Атада, что рядом с рекой Иордан, и там стали громко и горько плакать. Там Юсуф семь дней оплакивал отца. 11Когда хананеи, обитатели той земли, увидели плач у гумна Атада, они сказали: «У египтян великий плач и горе». Вот почему то место рядом с Иорданом называется Авель-Мицраим («плач египтян»).

12Так сыновья Якуба исполнили его наказ: 13они отнесли его в землю Ханаана и похоронили в пещере на поле Махпела, рядом с Мамре; эту пещеру Ибрахим купил у хетта Эфрона вместе с полем, чтобы было у него место для погребения. 14Похоронив отца, Юсуф возвратился в Египет вместе с братьями и всеми, кто ходил с ним хоронить отца.

Юсуф прощает братьев

15Когда отец умер, братья Юсуфа подумали: «Что, если Юсуф таит на нас злобу и теперь отплатит нам за всё зло, которое мы ему причинили?» 16И они послали к Юсуфу сказать:

– Перед смертью отец оставил такие наставления: 17«Вот что вы должны сказать вашему брату Юсуфу: „Я прошу тебя простить твоим братьям их вину и грехи, которые они совершили, поступив с тобой так скверно“». И теперь, пожалуйста, прости грехи рабов Бога отца твоего.

Получив это послание, Юсуф заплакал.

18Его братья пришли, пали перед ним на землю и сказали:

– Мы твои рабы.

19Юсуф ответил:

– Не бойтесь. Разве я Аллах? 20Вы замыслили против меня зло, но Аллах обратил его ко благу, чтобы совершить то, что происходит теперь: спасение многих жизней. 21Поэтому не бойтесь: я прокормлю и вас, и ваших детей.

Он успокоил их и говорил с ними ласково.

Смерть Юсуфа

22Юсуф жил в Египте вместе со всей семьёй своего отца и прожил сто десять лет. 23Он застал ещё третье поколение потомков Ефраима; и детей Махира, сына Манассы, тоже положили при рождении на колени Юсуфа50:23 Здесь упоминается обряд усыновления..

24Юсуф сказал братьям:

– Я умираю, но Аллах непременно придёт к вам на помощь и выведет вас из этой земли в землю, которую Он с клятвой обещал Ибрахиму, Исхаку и Якубу.

25Юсуф велел сыновьям Исраила дать клятву и сказал:

– Аллах непременно придёт к вам на помощь, и тогда вы должны вынести мои кости отсюда.

26Юсуф умер в возрасте ста десяти лет, и его набальзамировали и положили в гроб50:26 Гроб – это был необычный для иудеев способ захоронения, к которому они были вынуждены прибегнуть, чтобы в будущем исполнить просьбу Юсуфа. в Египте.