Gẹnẹsisi 49 – YCB & HOF

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 49:1-33

Ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Jakọbu sí àwọn ọmọ rẹ̀

1Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.

2“Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu;

Ẹ fetí sí Israẹli baba yín.

3“Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi,

agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi,

títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.

4Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́,

nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ,

lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́

(ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).

5“Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin—

idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.

6Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn,

kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn,

nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn,

wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.

7Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó

gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà.

Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu,

èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.

8“Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ,

ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ,

àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.

949.9,10: Nu 24.9; If 5.5.Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda,

o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi.

Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún,

Ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?

10Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda

bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀,

títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé,

tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.

11Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà,

àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù.

Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì

àti ẹ̀wù rẹ̀ nù nínú omi-pupa ti èso àjàrà (gireepu).

12Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ,

eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.

13“Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun,

yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi,

agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.

14“Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára

tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.

15Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó,

àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó,

yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà,

yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.

16“Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀

gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.

17Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà

àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà,

tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀,

kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.

18“Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.

19“Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi,

ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.

20“Oúnjẹ Aṣeri yóò dára;

yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.

21“Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín

tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.

22“Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso,

àjàrà eléso ní etí odò,

tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.

23Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́,

wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra,

24Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára,

ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le,

nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu,

nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,

25nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́,

nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ

pẹ̀lú láti ọ̀run wá,

ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀,

ìbùkún ti ọmú àti ti inú.

26Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀

ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì,

ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé.

Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu,

lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.

27“Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú;

ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ,

ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”

28Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.

Ikú Jakọbu

29Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni. 3049.30: Gẹ 23.3-20.Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀. 3149.31: Gẹ 25.9,10; Gẹ 35.29.Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí. 32Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”

3349.33: Ap 7.15.Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.

Hoffnung für Alle

1. Mose 49:1-33

Jakobs Segen für seine Söhne

1Danach ließ Jakob alle seine Söhne herbeirufen. »Kommt an mein Bett«, forderte er sie auf, »ihr sollt wissen, was die Zukunft für euch bereithält. 2Meine Söhne, kommt zu mir, hört, was euer Vater Israel euch zu sagen hat!

3Ruben, du bist mein erster Sohn, geboren in der Zeit meiner größten Kraft. Du nimmst den höchsten Rang ein, genießt das größte Ansehen. 4Aber du kannst dich nicht im Zaum halten – darum wirst du nicht der Erste bleiben. Mit einer meiner Frauen hast du geschlafen und so das Ehebett deines eigenen Vaters entweiht.

5Simeon und Levi haben sich verbrüdert: Ihre Schwerter haben sie zu Mord und Totschlag missbraucht. 6Mit ihren finsteren Plänen will ich nichts zu tun haben, von ihren Vorhaben halte ich mich fern. In blinder Wut brachten sie Menschen um, mutwillig schnitten sie Stieren die Sehnen durch. 7Weil sie im Zorn so hart und grausam waren, müssen sie die Folgen tragen: Ihre Nachkommen erhalten kein eigenes Gebiet, sondern wohnen verstreut in ganz Israel.

8Juda, dich loben deine Brüder! Du bezwingst deine Feinde und wirst von allen Söhnen deines Vaters verehrt. 9Mein Sohn, du bist wie ein junger Löwe, der gerade seine Beute gerissen hat. Majestätisch legt er sich daneben. Wer würde es wagen, ihn zu stören? 10Juda, immer behältst du das Zepter in der Hand, Könige gehen aus deinem Stamm hervor – bis ein großer Herrscher kommt,49,10 Wörtlich: bis Schilo kommt. – Der hebräische Text ist nicht sicher zu deuten. dem alle Völker dienen. 11Juda wäscht seine Kleider in Wein – im Überfluss kann er den Saft der Trauben genießen; achtlos bindet er seinen Esel am besten Weinstock an – es wächst ja genug davon in seinem Land. 12Seine Augen sind dunkler als Wein und seine Zähne weißer als Milch.

13Sebulon – nah beim Meer wird er wohnen, sein Ufer ist ein Hafen für Schiffe. Bis nach Sidon erstreckt sich sein Gebiet.

14Issachar gleicht einem knochigen Esel, der zwischen den beiden Satteltaschen ruht. 15Für ein Stück gutes Land macht er sich zum Sklaven,49,15 Oder: nimmt er harte Arbeit auf sich. sein Rücken beugt sich unter der schweren Last.

16Dan verhilft seinem Volk zum Recht – nicht weniger, als die anderen Stämme in Israel es tun. 17Er ist wie eine kleine, aber giftige Schlange am Wegrand. Sie greift ein Pferd an, und nach ihrem Biss fällt der Reiter zu Boden.

18O Herr, ich warte darauf, dass du uns rettest!

19Gad wird von plündernden Horden bedrängt, aber er treibt sie zurück und schlägt sie in die Flucht.

20Assers Land bringt reiche Ernte; köstliche Früchte wachsen dort, es sind wohlschmeckende Speisen sogar für Könige.

21Naftali gleicht einer Hirschkuh, die leichtfüßig umherläuft und schöne Kälber wirft.

22Josef, du bist wie ein fruchtbarer Baum, der an einer Quelle wächst und dessen Zweige eine Mauer überragen. 23Manche hegen böse Absichten gegen dich und greifen dich an, sie verfolgen dich mit Pfeil und Bogen, 24aber dein Bogen bleibt unzerbrechlich. Deine Arme und Hände sind stark, weil Jakobs mächtiger Gott dir hilft. Er sorgt für Israel wie ein Hirte, gibt dem Volk Sicherheit wie ein starker Fels. 25Ja, der allmächtige Gott, dem schon dein Vater gedient hat, wird dir beistehen. Er ist es, der dich mit seinem Segen beschenkt: Regen bewässert dein Land von oben, und das Wasser aus den Tiefen der Erde macht deine Felder fruchtbar; Menschen und Tiere vermehren sich und breiten sich aus. 26Stell dir die Berge vor, deren Gipfel bis in den Himmel ragen: Dein Wohlstand und Segen wird noch viel größer sein!49,26 Der hebräische Text ist nicht sicher zu deuten. Dies steht dir zu, denn du nimmst einen besonderen Platz unter deinen Brüdern ein.

27Benjamin gleicht einem reißenden Wolf, der morgens seine Feinde verschlingt und abends seine Beute teilt.«

28Jedem seiner zwölf Söhne sagte Jakob ein besonderes Segenswort. Es galt zugleich für die zwölf Stämme Israels, die von ihnen abstammen sollten. 29-30»Ich muss bald sterben«, sagte er dann zu seinen Söhnen, »begrabt mich in unserem Familiengrab! Es ist die Höhle in Kanaan, bei Machpela, östlich von Mamre. Abraham hat sie dem Hetiter Efron abgekauft. 31Dort sind schon Abraham und Sara, Isaak und Rebekka begraben, und dort habe ich Lea beigesetzt. 32Die Höhle mit dem Grundstück gehört uns. Begrabt auch mich dort!«

33Nachdem Jakob seinen letzten Willen erklärt hatte, legte er sich aufs Bett zurück und starb; so wurde er im Tod mit seinen Vorfahren vereint.