Gẹnẹsisi 49 – YCB & CST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 49:1-33

Ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Jakọbu sí àwọn ọmọ rẹ̀

1Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.

2“Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu;

Ẹ fetí sí Israẹli baba yín.

3“Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi,

agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi,

títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.

4Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́,

nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ,

lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́

(ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).

5“Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin—

idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.

6Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn,

kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn,

nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn,

wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.

7Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó

gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà.

Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu,

èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.

8“Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ,

ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ,

àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.

949.9,10: Nu 24.9; If 5.5.Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda,

o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi.

Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún,

Ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?

10Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda

bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀,

títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé,

tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.

11Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà,

àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù.

Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì

àti ẹ̀wù rẹ̀ nù nínú omi-pupa ti èso àjàrà (gireepu).

12Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ,

eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.

13“Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun,

yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi,

agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.

14“Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára

tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.

15Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó,

àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó,

yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà,

yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.

16“Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀

gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.

17Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà

àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà,

tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀,

kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.

18“Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.

19“Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi,

ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.

20“Oúnjẹ Aṣeri yóò dára;

yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.

21“Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín

tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.

22“Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso,

àjàrà eléso ní etí odò,

tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.

23Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́,

wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra,

24Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára,

ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le,

nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu,

nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,

25nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́,

nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ

pẹ̀lú láti ọ̀run wá,

ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀,

ìbùkún ti ọmú àti ti inú.

26Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀

ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì,

ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé.

Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu,

lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.

27“Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú;

ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ,

ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”

28Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.

Ikú Jakọbu

29Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni. 3049.30: Gẹ 23.3-20.Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀. 3149.31: Gẹ 25.9,10; Gẹ 35.29.Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí. 32Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”

3349.33: Ap 7.15.Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.

Nueva Versión Internacional (Castilian)

Génesis 49:1-33

Jacob bendice a sus hijos

1Jacob llamó a sus hijos y les dijo: «Reuníos, que voy a declararos lo que os va a suceder en el futuro:

2»Hijos de Jacob: acercaos y escuchad;

prestad atención a vuestro padre Israel.

3»Tú, Rubén, eres mi primogénito,

primer fruto de mi fuerza y virilidad,

primero en honor y en poder.

4Impetuoso como un torrente,

ya no serás el primero:

te acostaste en mi cama;

profanaste la cama de tu propio padre.

5»Simeón y Leví son chacales;49:5 chacales (lectura probable); hermanos (TM).

sus espadas49:5 espadas. Palabra de difícil traducción. son instrumentos de violencia.

6¡No quiero participar de sus reuniones,

ni arriesgar mi honor en sus asambleas!

En su furor mataron hombres,

y por capricho mutilaron toros.

7¡Malditas sean la violencia de su enojo

y la crueldad de su furor!

Los dispersaré en el país de Jacob,

los desparramaré en la tierra de Israel.

8»Tú, Judá, serás alabado49:8 En hebreo, Judá suena como el verbo que significa alabar. por tus hermanos;

dominarás a tus enemigos,

y tus propios hermanos se inclinarán ante ti.

9Mi hijo Judá es como un cachorro de león

que se ha nutrido de la presa.

Se tiende al acecho como león,

como leona que nadie se atreve a molestar.

10El cetro no se apartará de Judá,

ni de entre sus pies el bastón de mando,

hasta que llegue el verdadero rey,49:10 el verdadero rey. Alt. Siló. Texto de difícil traducción.

quien merece la obediencia de los pueblos.

11Judá amarra su asno a la vid,

y la cría de su asno a la mejor cepa;

lava su ropa en vino;

su manto, en la sangre de las uvas.

12Sus ojos son más oscuros que el vino;

sus dientes, más blancos que la leche.49:12 Sus ojos … la leche. Alt. Sus ojos están oscurecidos por el vino; sus dientes, blanqueados por la leche.

13»Zabulón vivirá a la orilla del mar;

será puerto seguro para las naves,

y sus fronteras llegarán hasta Sidón.

14»Isacar es un asno fuerte

echado entre dos alforjas.

15Al ver que el establo era bueno

y que la tierra era agradable,

agachó el hombro para llevar la carga

y se sometió a la esclavitud.

16»Dan hará justicia en su pueblo,

como una de las tribus de Israel.

17Dan es una serpiente junto al camino,

una víbora junto al sendero,

que muerde los talones del caballo

y hace caer de espaldas al jinete.

18»¡Señor, espero tu salvación!

19»Las hordas atacan a Gad,

pero él las atacará por la espalda.

20»Aser disfrutará de comidas deliciosas;

ofrecerá manjares de reyes.

21»Neftalí es una gacela libre,

que tiene hermosos cervatillos.49:21 que … cervatillos. Alt. que pronuncia hermosas palabras.

22»José es un retoño fértil,

fértil retoño junto al agua,

cuyas ramas trepan por el muro.

23Los arqueros lo atacaron sin piedad;

le tiraron flechas, lo hostigaron.

24Pero su arco se mantuvo firme,

porque sus brazos son fuertes.

¡Gracias al Dios fuerte de Jacob,

al Pastor y Roca de Israel!

25¡Gracias al Dios de tu padre, que te ayuda!

¡Gracias al Todopoderoso, que te bendice!

¡Con bendiciones de lo alto!

¡Con bendiciones del abismo!

¡Con bendiciones de los pechos y del seno materno!

26Son mejores las bendiciones de tu padre

que las de los montes de antaño,

que la abundancia de las colinas eternas.

¡Que descansen estas bendiciones

sobre la cabeza de José,

sobre la frente del escogido entre sus hermanos!

27»Benjamín es un lobo rapaz

que en la mañana devora la presa

y en la tarde reparte los despojos».

28Estas son las doce tribus de Israel, y esto es lo que su padre les dijo cuando impartió a cada una de ellas su bendición.

Muerte de Jacob

29Además, Jacob les dio estas instrucciones: «Ya estoy a punto de reunirme con los míos. Enterradme junto a mis antepasados, en la cueva que está en el campo de Efrón el hitita. 30Se trata de la cueva de Macpela, frente a Mamré, en la tierra de Canaán. Está en el campo que Abraham le compró a Efrón el hitita, para que fuera el sepulcro de la familia. 31Allí fueron sepultados Abraham y su esposa Sara, Isaac y su esposa Rebeca, y allí también enterré a Lea. 32Ese campo y su cueva se les compró a los hititas».

33Cuando Jacob terminó de dar estas instrucciones a sus hijos, volvió a acostarse, exhaló el último suspiro, y fue a reunirse con sus antepasados.