Gẹnẹsisi 48 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 48:1-22

Manase àti Efraimu

1Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀ si, a wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ ń ṣàìsàn,” nítorí náà, ó mú àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì, Manase àti Efraimu lọ́wọ́ lọ pẹ̀lú rẹ̀. 2Nígbà tí a sọ fún Jakọbu pé, “Josẹfu ọmọ rẹ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,” Israẹli rọ́jú dìde jókòó lórí ibùsùn rẹ̀.

348.3,4: Gẹ 28.13,14.Jakọbu wí fún Josẹfu pé, “Ọlọ́run Olódùmarè (Eli-Ṣaddai) fi ara hàn mí ní Lusi ní ilẹ̀ Kenaani, níbẹ̀ ni ó sì ti súre fún mi. 4Ó sì wí fún mi pé, ‘Èmi yóò mú kí o bí sí i, ìwọ yóò sì pọ̀ sí i, Èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, Èmi yóò sì fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ ní ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ohun ìní ayérayé.’

5“Nítorí náà báyìí, àwọn ọmọ rẹ méjèèjì tí a bí fún ọ ní ilẹ̀ Ejibiti, kí èmi kí ó tó tọ̀ ọ́ wá ní ìhín, ni mo sọ di ọmọ mi fúnra mi. Manase àti Efraimu yóò jẹ́ tèmi gẹ́gẹ́ bí Reubeni àti Simeoni ti jẹ́ tèmi. 6Àwọn ọmọ mìíràn tí ìwọ bá bí lẹ́yìn wọn yóò jẹ́ ọmọ rẹ. Ní ilẹ̀ tí wọn yóò jogún, orúkọ arákùnrin wọn ni a ó máa fi pè wọ́n. 748.7: Gẹ 35.16-19.Bí mo ti ń padà láti Padani, Rakeli kú ní ọ̀nà nígbà tí ó ṣì wà ní ilẹ̀ Kenaani, èyí tó mú ìbànújẹ́ bá mi, níbi tí kò jìnnà sí Efrata: Nítorí náà èmí sì sin ín sí ẹ̀bá ọ̀nà tí ó lọ sí Efrata” (tí ṣe Bẹtilẹhẹmu).

8Nígbà tí Israẹli rí àwọn ọmọ Josẹfu, ó béèrè wí pé, “Àwọn wo nìyí?”

9Josẹfu fún baba rẹ̀ lésì pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi fún mi ní ìhín.”

Nígbà náà ni Israẹli wí pé, “Kó wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi kí èmi kí ó ba à le súre fún wọn.”

10Báyìí, ojú Israẹli ti ń di bàìbàì nítorí ogbó, agbára káká sì ni ó fi ń ríran. Josẹfu sì kó àwọn ọmọ rẹ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, baba rẹ̀ fẹnukò wọ́n ni ẹnu, ó sì dì mọ́ wọn.

11Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Èmi kò lérò rárá pé, mo tún le rí ojú rẹ mọ́ láéláé, ṣùgbọ́n Ọlọ́run tún fún mi ní àǹfààní, mo sì tún rí àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú.”

12Nígbà náà ni Josẹfu kó àwọn ọmọ náà kúrò ní orí eékún baba rẹ̀, ó wólẹ̀, ó sì tẹríba. 13Josẹfu sì mú àwọn méjèèjì, Efraimu ni o fi sí ọwọ́ ọ̀tún òun tìkára rẹ̀, èyí tí í ṣe ọwọ́ òsì fún Israẹli, ó sì fi Manase sí ọwọ́ òsì ara rẹ̀, èyí tí ó bọ́ sí ọwọ́ ọ̀tún Israẹli. 14Israẹli sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ jáde, ó sì gbe lé Efraimu lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun ni àbúrò, ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ tàsé ara wọn, ó sì na ọwọ́ òsì lé Manase lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Manase ni àkọ́bí.

15Nígbà náà ni ó súre fún Josẹfu wí pé,

“Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run, ẹni tí baba mi

Abrahamu àti Isaaki rìn níwájú rẹ̀,

Ọlọ́run tí ó ti jẹ́ olùtọ́jú àti aláàbò

mi ní gbogbo ọjọ́ ayé mi títí di òní,

16Angẹli tí ó dá mi ní ìdè kúrò lọ́wọ́ gbogbo ewu,

kí ó súre fún àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí.

Kí a máa fi orúkọ mi pè wọ́n àti orúkọ àwọn baba mi

Abrahamu àti Isaaki,

kí wọn kí ó sì pọ̀ sí i lọ́pọ̀lọpọ̀

lórí ilẹ̀ ayé.”

17Nígbà tí Josẹfu rí i pé baba òun gbé ọwọ́ ọ̀tún lé Efraimu lórí, inú rẹ̀ bàjẹ́, ó sì gbá ọwọ́ baba rẹ̀ mú láti gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lórí Efraimu lọ sí orí Manase. 18Josẹfu wí fun pé, “Rárá, baba mi, èyí ni àkọ́bí, orí rẹ̀ ni kí ìwọ kí o gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ lé.”

19Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ kò gbà, ó wí pé, “Mo mọ̀, ọmọ mi, mo mọ̀. Òun náà yóò di orílẹ̀-èdè, òun náà yóò sì di ńlá. Ṣùgbọ́n àbúrò rẹ̀ yóò di ẹni ńlá jù ú lọ, irú-ọmọ rẹ yóò sì di ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.” 2048.20: Hb 11.21.Ó súre fún wọn lọ́jọ́ náà pé,

“Ní orúkọ yín ni Israẹli yóò máa súre yìí pé:

‘Kí Ọlọ́run ṣe ọ́ bí i ti Efraimu àti Manase.’ ”

Ó sì gbé Efraimu gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ́n sí Manase.

21Nígbà náà ni Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Ọjọ́ ikú mi súnmọ́ etílé, ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò wà pẹ̀lú yín, yóò sì mú un yín padà sí ilẹ̀ àwọn baba yín. 22Pẹ̀lúpẹ̀lú èmi yóò fún ọ ní ìpín kan ju ti àwọn arákùnrin rẹ lọ. Ilẹ̀ tí mo fi idà àti ọ̀kọ̀ mi gbà lọ́wọ́ àwọn ará Amori.”

Nouă Traducere În Limba Română

Geneza 48:1-22

Iacov îi binecuvântează pe fiii lui Iosif

1După toate acestea, i s‑a zis lui Iosif: „Iată, tatăl tău este bolnav.“ Atunci acesta i‑a luat cu el pe cei doi fii ai săi – pe Manase și pe Efraim. 2Când i s‑a spus lui Iacov: „Iată, fiul tău Iosif a venit la tine“, Israel și‑a adunat puterile și s‑a ridicat în șezut, pe pat.

3Iacov i‑a zis lui Iosif:

– Dumnezeul cel Atotputernic3 Ebr.: El‑Șadai mi S‑a arătat la Luz, în țara Canaan, m‑a binecuvântat 4și mi‑a zis: „Iată, te voi face roditor și te voi înmulți. Te voi face o mulțime de popoare și voi da țara aceasta seminței tale după tine, ca pe o proprietate veșnică.“

5Acum, cei doi fii ai tăi, care ți s‑au născut în țara Egiptului, vor fi ai mei. Efraim și Manase vor fi ai mei așa cum sunt Ruben și Simeon. 6Dar urmașii care ți s‑au născut după ei vor fi ai tăi. Ei vor fi numiți după numele fraților lor în teritoriul moștenirii lor. 7După ce m‑am întors din Padan7 Un alt nume pentru Aram Naharaim, în NV Mesopotamiei., Rahela a murit pe drum lângă mine,7 Sau: pe drum, spre mâhnirea mea. în țara Canaan, înainte de a ajunge la Efrata. Am îngropat‑o acolo, pe drumul spre Efrata, adică Betleem.

8Când Israel i‑a văzut pe fiii lui Iosif, a întrebat:

– Cine sunt aceștia?

9Iosif i‑a zis tatălui său:

– Sunt fiii mei, pe care mi i‑a dat Dumnezeu aici.

Israel a zis:

– Adu‑i, te rog, la mine ca să‑i binecuvântez.

10Ochii lui Israel erau îngreunați de bătrânețe; nu mai putea să vadă bine. Iosif i‑a apropiat de Israel pe cei doi fii ai săi, iar acesta i‑a sărutat și i‑a îmbrățișat.

11Apoi Israel i‑a zis lui Iosif:

– Nu mi‑am închipuit că o să‑ți mai văd fața, dar iată că Dumnezeu m‑a ajutat să‑ți văd și sămânța.

12Iosif i‑a îndepărtat de lângă genunchii tatălui său12 Vezi 30:3. A ține un copil pe genunchi făcea parte din ritualul adopției. și s‑a plecat cu fața la pământ. 13Apoi Iosif i‑a luat pe amândoi, pe Efraim la dreapta sa și la stânga lui Israel, iar pe Manase la stânga sa și la dreapta lui Israel și i‑a apropiat de el. 14Dar Israel, încrucișându‑și mâinile, și‑a întins mâna dreaptă și a pus‑o pe capul lui Efraim, care era mai tânăr, iar mâna stângă a pus‑o pe capul lui Manase, deși el era întâiul născut.

15El l‑a binecuvântat pe Iosif și a zis:

– Dumnezeul înaintea Căruia au umblat părinții mei, Avraam și Isaac,

Dumnezeul Care a fost Păstorul vieții mele până astăzi,

16Îngerul Care m‑a răscumpărat din orice rău,

să‑i binecuvânteze pe acești băieți.

Ei să fie numiți după numele meu

și după numele părinților mei, Avraam și Isaac,

și să se înmulțească foarte mult pe pământ.

17Lui Iosif nu i‑a plăcut când a văzut că tatăl său și‑a pus mâna dreaptă pe capul lui Efraim, și a apucat mâna tatălui său ca s‑o mute de pe capul lui Efraim pe capul lui Manase.

18Iosif i‑a zis tatălui său:

– Nu așa, tată! Acesta este întâiul născut. Pe capul lui pune‑ți mâna dreaptă.

19Dar tatăl său a refuzat și a zis:

– Știu, fiule, știu! Și el va ajunge un popor, și el va fi mare. Totuși, fratele său mai mic va fi mai mare decât el, iar sămânța lui va ajunge o mulțime de neamuri.

20Israel i‑a binecuvântat în ziua aceea, zicând:

– În numele tău va binecuvânta Israel și va zice:

„Dumnezeu să te facă precum Efraim și Manase.“

Astfel, el l‑a pus pe Efraim înaintea lui Manase.

21Apoi Israel i‑a zis lui Iosif:

– Iată, eu sunt pe moarte, dar Dumnezeu va fi cu voi și vă va întoarce în țara părinților voștri. 22Ție, care ești deasupra fraților tăi, îți dau Șechemul pe care l‑am luat cu sabia și cu arcul meu din mâna amoriților.