Gẹnẹsisi 47 – YCB & GKY

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 47:1-31

1Josẹfu lọ sọ fún Farao pé, “Baba mi àti àwọn arákùnrin mi, pẹ̀lú agbo ẹran, agbo màlúù àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, ti dé láti ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì ti wà ní ilẹ̀ Goṣeni báyìí.” 2Ó yan márùn-ún àwọn arákùnrin rẹ́, ó sì fi wọ́n han Farao.

3Farao béèrè lọ́wọ́ àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Kí ni iṣẹ́ yín?”

Wọ́n sì fèsì pé, “Darandaran ni àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti jẹ́ darandaran” 4Wọ́n sì tún sọ fun un síwájú sí i pé, “A wá láti gbé ìhín yìí fún ìgbà díẹ̀ nítorí ìyàn náà mú púpọ̀ ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ohun ọ̀sìn àwa ìránṣẹ́ rẹ kò sì rí ewéko jẹ. Nítorí náà jọ̀wọ́ má ṣàì jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni.”

5Farao wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ àti àwọn arákùnrin rẹ tọ̀ ọ́ wá, 6Ilẹ̀ Ejibiti sì nìyí níwájú rẹ: Mú àwọn arákùnrin rẹ tẹ̀dó sí ibi tí ó dára jù nínú ilẹ̀ náà. Jẹ́ kí wọn máa gbé ní Goṣeni. Bí o bá sì mọ ẹnikẹ́ni nínú wọn tí ó ní ẹ̀bùn ìtọ́jú ẹran, fi wọ́n ṣe olùtọ́jú ẹran ọ̀sìn mi.”

7Nígbà náà ni Josẹfu mú Jakọbu baba rẹ̀ wọlé wá sí iwájú Farao. Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu súre fún Farao tán. 8Farao béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ọmọ ọdún mélòó ni ọ́?”

9Jakọbu sì dá Farao lóhùn, “Ọdún ìrìnàjò ayé mi jẹ́ àádóje (130), ọjọ́ mi kò pọ̀, ó sì kún fún wàhálà, síbẹ̀ kò ì tí ì tó ti àwọn baba mi.” 10Nígbà náà ni Jakọbu tún súre fún Farao, ó sì jáde lọ kúrò níwájú rẹ̀.

11Josẹfu sì fi baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ sí ilẹ̀ Ejibiti, ó sì fún wọn ní ohun ìní ní ibi tí ó dára jù ní ilẹ̀ náà, ní agbègbè Ramesesi bí Farao ti pàṣẹ. 12Josẹfu sì pèsè oúnjẹ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi iye àwọn ọmọ wọn.

Josẹfu àti ìyàn ní ilẹ̀ Ejibiti

13Ṣùgbọ́n kò sí oúnjẹ ní gbogbo ilẹ̀ náà nítorí tí ìyàn náà mú púpọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ Ejibiti àti ilẹ̀ Kenaani gbẹ nítorí ìyàn náà. 14Josẹfu gba gbogbo owó tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti àti Kenaani ní ìpààrọ̀ fún ti ọkà tí wọn ń rà, ó sì mú owó náà wá sí ààfin Farao. 15Nígbà tí owó wọn tán pátápátá ní Ejibiti àti Kenaani, gbogbo Ejibiti wá bá Josẹfu, wọ́n wí pé, “Fún wa ní oúnjẹ, èéṣe tí a ó fi kú ní ojú rẹ? Gbogbo owó wa ni a ti ná tán.”

16Josẹfu wí pé, “Ẹ mú àwọn ẹran ọ̀sìn yín wá, èmi yóò fún un yín ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn yín, níwọ̀n bí owó yín ti tan.” 17Nítorí náà wọ́n mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn tọ Josẹfu wá, ó sì fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹṣin, àgùntàn, ewúrẹ́, màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn. Ó sì mú wọn la ọdún náà já, tí ó ń fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn wọn.

18Nígbà tí ọdún náà parí, wọn padà tọ̀ ọ́ wá ní ọdún tí ó tẹ̀lé, wọn wí pé, “A kò le fi pamọ́ fun olúwa wa pé níwọ̀n bí owó wa ti tan tí gbogbo ẹran ọ̀sìn wa sì ti di tirẹ̀ pé, kò sí ohunkóhun tókù fún olúwa wa bí kò ṣe ara wa àti ilẹ̀ wa. 19Èéṣe tí àwa yóò fi parun lójú rẹ, ra àwa tìkára wa àti ilẹ̀ wa ní ìpààrọ̀ fún oúnjẹ, àwa àti ilẹ̀ wa yóò sì wà nínú ìgbèkùn Farao. Fún wa ni oúnjẹ kí àwa kí ó má ba à kú, kí ilẹ̀ wa má ba à di ahoro.”

20Nítorí náà Josẹfu ra gbogbo ilẹ̀ tí ó wà ní Ejibiti fún Farao, kò sí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù ní Ejibiti tí kò ta ilẹ̀ tirẹ̀ nítorí ìyàn náà mú jù fún wọn. Gbogbo ilẹ̀ náà sì di ti Farao, 21Josẹfu sì sọ gbogbo ará Ejibiti di ẹrú láti igun kan dé èkejì 22Ṣùgbọ́n ṣá, kò ra ilẹ̀ àwọn àlùfáà, nítorí wọ́n ń gba ìpín oúnjẹ lọ́wọ́ Farao, wọn sì ní oúnjẹ tí ó tó láti inú ìpín tí Farao ń fún wọn. Ìdí nìyí tí wọn kò fi ta ilẹ̀ wọn.

23Josẹfu wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Níwọ́n ìgbà tí mo ti ra ẹ̀yin àti ilẹ̀ yín tan lónìí fún Farao, irúgbìn rèé, ẹ lọ gbìn ín sí ilẹ̀ náà. 24Ṣùgbọ́n nígbà tí ìre oko náà bá jáde, ẹ ó mú ìdákan nínú ìdámárùn-ún rẹ̀ fún Farao. Ẹ le pa ìdámẹ́rin tókù mọ́ fún ara yín àti ìdílé yín àti àwọn ọmọ yín.”

25Wọ́n dá á lóhùn pé, “O ti gbà wá là, Ǹjẹ́ kí a rí ojúrere níwájú olúwa wa, àwa yóò di ẹrú Farao.”

26Nítorí náà Josẹfu sọ ọ́ di òfin nípa ọ̀rọ̀ ilẹ̀ ni Ejibiti, ó sì wà bẹ́ẹ̀ di òní olónìí pé, ìdákan nínú ìdámárùn-ún ìre oko jẹ́ ti Farao, ilẹ̀ àwọn àlùfáà nìkan ni kò di ti Farao.

27Àwọn ará Israẹli sì tẹ̀dó sí Ejibiti ní agbègbè Goṣeni. Wọ́n ní ohun ìní fún ara wọn, wọ́n sì bí sí i tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n pọ̀ si gidigidi ní iye.

28Jakọbu gbé ní Ejibiti fún ọdún mẹ́tà-dínlógún (17) iye ọdún ọjọ́ ayé rẹ̀ sì jẹ́ ẹ̀tàdín ní àádọ́jọ (147). 2947.29,30: Gẹ 49.29-32; 50.6.Nígbà tí àkókò ń súnmọ́ etílé fún Israẹli láti kú, ó pe Josẹfu, ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Bí mo bá rí ojúrere ni ojú rẹ̀ fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi, kí o sì ṣe ìlérí pé ìwọ yóò fi àánú àti òtítọ́ hàn sí mi. Má ṣe sin òkú mi sí ilẹ̀ Ejibiti, 30Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo bá sinmi pẹ̀lú àwọn baba mi, gbé mí jáde kúrò ní Ejibiti kí o sì sin mí sí ibi tí wọ́n sin àwọn baba mi sí.”

Josẹfu sì dáhùn wí pé, “Èmi ó ṣe bí ìwọ ti wí.”

31Jakọbu wí pé, “Búra fún mi,” Josẹfu sì búra fún un. Israẹli sì tẹ orí rẹ̀ ba, bí ó ti sinmi lé orí ibùsùn rẹ̀.

Holy Bible in Gĩkũyũ

Kĩambĩrĩria 47:1-31

147:1 Kĩam 46:31Jusufu agĩthiĩ akĩĩra Firaũni atĩrĩ, “Baba na ariũ a baba hamwe na ndũũru ciao cia mbũri na cia ngʼombe na indo ciao ciothe nĩmokĩte kuuma bũrũri wa Kaanani, na rĩu marĩ Gosheni.” 2Ningĩ agĩthuura ariũ a ithe atano na akĩmatwara mbere ya Firaũni.

347:3 Kĩam 46:33Firaũni akĩmooria atĩrĩ, “Mũrutaga wĩra ũrĩkũ?”

Nao magĩcookeria Firaũni atĩrĩ, “Ithuĩ ndungata ciaku tũrĩ arĩithi, o ta ũrĩa maithe maitũ maarĩ.” 447:4 Kĩam 46:34Ningĩ makĩmwĩra atĩrĩ, “Tũũkĩte gũikara gũkũ kwa ihinda, tondũ ngʼaragu ĩno nĩ nene kũu Kaanani, na ndũũru cia ndungata ciaku nĩ ciagĩte ũrĩithio. Nĩ ũndũ ũcio twagũthaitha wĩtĩkĩrie ndungata ciaku itũũre Gosheni.”

5Firaũni akĩĩra Jusufu atĩrĩ, “Thoguo na ariũ a thoguo mokĩte kũrĩ we, 647:6 Thaam 18:21na bũrũri wa Misiri ũrĩ mbere yaku; he thoguo na ariũ a thoguo mwena ũrĩa mwega mũno wa bũrũri ũyũ. Reke maikare Gosheni. Na rĩrĩ, angĩkorwo nĩũũĩ amwe ao marĩ na ũũgĩ wa mwanya-rĩ, matue arũgamĩrĩri a mahiũ makwa.”

747:7 2Sam 14:22Ningĩ Jusufu akĩrehe ithe Jakubu mbere ya Firaũni. Na Jakubu aarĩkia kũrathima Firaũni-rĩ, 8Firaũni akĩmũũria atĩrĩ, “Ũrĩ na mĩaka ĩigana?”

947:9 Kĩam 25:7Nake Jakubu akĩĩra Firaũni atĩrĩ, “Mĩaka yakwa ya kũũrũũra nĩ igana rĩmwe na mĩrongo ĩtatũ. Mĩaka yakwa ĩkoretwo ĩrĩ mĩnini na ya mĩtangĩko, na ndĩigana mĩaka ya kũũrũũra kwa maithe makwa.” 1047:10 Kĩam 47:7Jakubu agĩcooka akĩrathima Firaũni na akĩehera akiuma hau Firaũni aarĩ.

1147:11 Ndar 33:3, 5Nĩ ũndũ ũcio Jusufu akĩhe ithe na ariũ a ithe ũtũũro kũu Misiri na akĩmahe mĩgũnda mwena ũrĩa mwega mũno wa bũrũri ũcio, rũgongo rwa Ramesese o ta ũrĩa Firaũni aathanĩte. 1247:12 Kĩam 45:11Ningĩ Jusufu nĩaheaga ithe na ariũ a ithe na andũ a nyũmba ya ithe othe irio kũringana na mũigana wa ciana ciao.

Jusufu na Ngʼaragu

1347:13 Kĩam 12:10Na rĩrĩ, gũtiarĩ irio mwena ũcio wothe, tondũ ngʼaragu yarĩ nene mũno; na Misiri na Kaanani cierĩ nĩ ciahinyĩrĩrĩkĩte nĩ ũndũ wa ngʼaragu ĩyo. 1447:14 Thaam 7:23Jusufu akĩũngania mbeeca iria ciothe ingĩonekire bũrũri wa Misiri na wa Kaanani, irĩ irĩhi rĩa ngano ĩrĩa andũ maagũraga, nake agĩcitwara nyũmba-inĩ ya ũthamaki ya Firaũni. 1547:15 Thaam 16:3Na rĩrĩa mbeeca cia andũ a Misiri na cia andũ a Kaanani ciathirire-rĩ, andũ a Misiri othe magĩthiĩ kũrĩ Jusufu, makĩmwĩra atĩrĩ, “Tũhe irio. Tũngĩgĩkua ũtwĩroreire nĩkĩ? Mbeeca ciitũ nĩithirĩte biũ.”

1647:16 Kĩam 47:18, 19Nake Jusufu akĩmacookeria atĩrĩ, “Ndeherai mahiũ manyu, na nĩngũmwenderia irio nĩ ũndũ wa mo tondũ mbeeca nĩ thiru.” 1747:17 Thaam 14:9Nĩ ũndũ ũcio magĩtwarĩra Jusufu mahiũ mao, nake akĩmakũũranĩria irio na mbarathi ciao, na ngʼondu na mbũri ciao, na ngʼombe na ndigiri ciao. Nake Jusufu akĩmateithĩrĩria mwaka ũcio wothe na irio, magĩcikũũrania na mahiũ mao mothe.

18Naguo mwaka ũcio wathira-rĩ, magĩũka kũrĩ we mwaka ũyũ ũngĩ, makĩmwĩra atĩrĩ, “Tũtingĩhota kũhitha mwathi witũ ũndũ, kuona atĩ mbeeca ciitũ nĩithirĩte, na mahiũ maitũ rĩu nĩ maku, na gũtirĩ kĩndũ gĩtigaire kĩa mwathi witũ tiga mĩĩrĩ iitũ na ithaka ciitũ. 19Tũngĩgĩkua ũtwĩroreire nĩkĩ, ithuĩ na ithaka ciitũ hamwe? Tũgũranĩrie hamwe na ithaka ciitũ, ũtũhe irio, na ithuĩ na ithaka ciitũ tũtuĩke ngombo cia Firaũni. Tũhe mbeũ nĩgeetha tũtũũre muoyo, tũtigakue, na nĩguo bũrũri witũ ndũkanangĩke.”

2047:20 Kĩam 12:10Nĩ ũndũ ũcio Jusufu akĩgũrĩra Firaũni bũrũri wothe wa Misiri. Nao andũ a Misiri makĩendia ithaka ciao, mũndũ o mũndũ, nĩ ũndũ ngʼaragu nĩyamahatĩrĩirie mũno. Naguo bũrũri wothe ũgĩtuĩka wa Firaũni. 21Nake Jusufu agĩgĩtua andũ ngombo kuuma mwena ũmwe wa Misiri nginya ũrĩa ũngĩ. 2247:22 Gũcook 14:28-29No rĩrĩ, ndaigana kũgũra ithaka cia athĩnjĩri-ngai akuo, tondũ o maarĩ na igai maaheagwo nĩ Firaũni, na maarĩ na irio cia kũmaigana kuuma kũrĩ igai rĩu Firaũni aamaheaga. Kĩu nĩkĩo gĩatũmire mage kwendia ithaka ciao.

2347:23 Neh 5:3Nake Jusufu akĩĩra andũ acio atĩrĩ, “Rĩu tondũ ũmũthĩ nĩndamũgũra hamwe na ithaka cianyu mũtuĩke a Firaũni-rĩ, mbeũ cianyu nĩcio ici; oyai mũkahaande mĩgũnda. 2447:24 Kĩam 41:34No rĩrĩa mũkaagetha, mũkaahe Firaũni gĩcunjĩ gĩa gatano. Icunjĩ icio ingĩ inya harĩ ithano no mwĩigĩre irĩ mbeũ cia kũhaanda na irio cianyu ene na cia nyũmba cianyu, na cia ciana cianyu.”

2547:25 Kĩam 32:5Nao makiuga atĩrĩ, “Nĩwahonokia mĩoyo iitũ. Tũroogĩtĩkĩrĩka maitho-inĩ ma mwathi witũ; ithuĩ tũgũtũũra tũrĩ ngombo cia Firaũni.”

2647:26 Kĩam 41:34Nĩ ũndũ ũcio Jusufu akĩruta watho ũkoniĩ ithaka cia Misiri, na nĩũtũire nginya ũmũthĩ, atĩ gĩcunjĩ gĩa gatano kĩa magetha nĩ kĩa Firaũni. No ithaka cia athĩnjĩri-ngai akuo itaatuĩkire cia Firaũni.

2747:27 Kĩam 1:22Nao andũ a Isiraeli magĩtũũra Misiri bũrũri-inĩ wa Gosheni. Makĩgĩa na indo kuo na magĩciarana, makĩingĩha mũno.

2847:28 Thab 105:23Jakubu aikarire Misiri mĩaka ikũmi na mũgwanja, nayo mĩaka yake ĩrĩa aatũũrire muoyo yarĩ mĩaka igana rĩmwe na mĩrongo ĩna na mũgwanja. 2947:29 Kĩam 24:32Na rĩrĩa ihinda rĩa Isiraeli rĩa gũkua rĩakuhĩrĩirie-rĩ, agĩtũmanĩra mũriũ wake Jusufu, akĩmwĩra atĩrĩ, “Angĩkorwo nĩnjĩtĩkĩrĩkĩte maitho-inĩ maku-rĩ, iga guoko gwaku rungu rwa kĩero gĩakwa, na ũnjĩĩre atĩ nĩũkanjĩka maũndũ ma ũtugi na ma wĩhokeku. Ndũkanaathike gũkũ Misiri, 3047:30 Josh 24:32no rĩrĩa ngaahurũka hamwe na maithe makwa, ũkanguua, ũndute Misiri, ũgaathike o harĩa mathikĩtwo.”

Nake Jusufu akiuga atĩrĩ, “Nĩngeeka o ũguo woiga.”

3147:31 Atiir 15:12Nake Isiraeli akĩmwĩra atĩrĩ, “Wĩhĩte na mwĩhĩtwa.” Nake Jusufu akĩĩhĩta harĩ we na mwĩhĩtwa, nake Isiraeli akĩhooya enyiitĩrĩire mũthĩgi wake.