Gẹnẹsisi 46 – YCB & CARS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 46:1-34

Jakọbu lọ sí Ejibiti

1Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.

2Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!”

Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”

3Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀. 4Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnrarẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”

5Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀: 646.6: Ap 7.14,15.Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti. 7Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.

846.8-27: Ek 1.1-4; Nu 26.4-50.Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti Ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti:

Reubeni àkọ́bí Jakọbu.

9Àwọn ọmọkùnrin Reubeni:

Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.

10Àwọn ọmọkùnrin Simeoni:

Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.

11Àwọn ọmọkùnrin Lefi:

Gerṣoni, Kohati àti Merari.

12Àwọn ọmọkùnrin Juda:

Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani).

Àwọn ọmọ Peresi:

Hesroni àti Hamulu.

13Àwọn ọmọkùnrin Isakari!

Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.

14Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni:

Seredi, Eloni àti Jahaleli.

15Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.

16Àwọn ọmọkùnrin Gadi:

Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.

17Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri:

Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera.

Àwọn ọmọkùnrin Beriah:

Heberi àti Malkieli.

18Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìn-dínlógún (16) lápapọ̀.

19Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu:

Josẹfu àti Benjamini.

20Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.

21Àwọn ọmọ Benjamini:

Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.

22Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá (14) lápapọ̀.

23Àwọn ọmọ Dani:

Huṣimu.

24Àwọn ọmọ Naftali:

Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.

25Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.

26Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìn-dín-ní-àádọ́rin (66). 2746.27: Ap 7.14.Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin (70) lápapọ̀.

28Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni, 29Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.

30Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”

31Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá. 32Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.” 33Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe, 34ẹ fún un lésì pé, “àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.” Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni. Nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.

Священное Писание

Начало 46:1-34

Якуб со всей семьёй переселяется в Египет

1Исраил отправился в путь со всем, что у него было, пришёл в Беэр-Шеву и принёс там жертвы Богу своего отца Исхака. 2Всевышний говорил с Исраилом в ночном видении и сказал:

– Якуб! Якуб!

– Вот я, – ответил Якуб.

3И сказал Всевышний:

– Я Всевышний, Бог твоего отца. Не бойся пойти в Египет, потому что Я произведу от тебя там великий народ. 4Я пойду в Египет вместе с тобой, и Я же приведу тебя обратно. И глаза тебе закроет рука Юсуфа.

5Якуб отправился в путь из Беэр-Шевы. Сыновья Исраила посадили отца, детей и жён в колесницы, которые фараон прислал, чтобы перевезти его. 6Они взяли с собой скот и имущество, которое нажили в Ханаане; и Якуб со всем своим потомством пришёл в Египет. 7Он взял с собой в Египет сыновей и внуков, дочерей и внучек – всё своё потомство.

Список потомков Якуба

8Вот имена сыновей Исраила, которые пришли в Египет; Якуб и его потомки:

Рувим, первенец Якуба.

9Сыновья Рувима:

Ханох, Фаллу, Хецрон и Харми.

10Сыновья Шимона:

Иемуил, Иамин, Охад, Иахин, Цохар и Шаул, сын хананеянки.

11Сыновья Леви:

Гершон, Кааф и Мерари.

12Сыновья Иуды:

Ир, Онан, Шела, Фарец и Зерах (но Ир и Онан умерли в Ханаане).

Сыновьями Фареца были Хецрон и Хамул.

13Сыновья Иссахара:

Тола, Пуа, Иашув46:13 Букв.: «Иов»; в Книге Пророков, 1 Лет. 7:1 он назван Иашувом. и Шимрон.

14Сыновья Завулона:

Серед, Елон и Иахлеил.

15Это сыновья Лии, которых она родила Якубу в Паддан-Араме; она родила и дочь Дину; всего их было тридцать три человека.

16Сыновья Гада:

Цефон, Хагги, Шуни, Эцбон, Ери, Ароди и Арели.

17Сыновья Ашира:

Имна, Ишва, Ишви и Брия. Их сестра Серах. Сыновья Брии: Хевер и Малкиил.

18Это дети, рождённые Якубу Зелфой, которую Лаван дал в служанки своей дочери Лии; всего шестнадцать человек.

19Сыновья жены Якуба Рахили:

Юсуф и Вениамин. 20В Египте Асенефа, дочь Потифера, жреца города Она, родила Юсуфу Манассу и Ефраима.

21Сыновья Вениамина:

Бела, Бехер, Ашбел, Гера, Нааман, Ехи, Рош, Муппим, Хуппим и Ард.

22Это сыновья Рахили, которых она родила Якубу; всего четырнадцать человек.

23Сын Дана:

Хушим.

24Сыновья Неффалима:

Иахцеил, Гуни, Иецер и Шиллем.

25Это сыновья, рождённые Якубу Билхой, которую Лаван дал в служанки своей дочери Рахиле; всего семь человек.

26Всех, кто пришёл в Египет с Якубом, – его прямых потомков, не считая жён его сыновей, – было шестьдесят шесть человек. 27Сыновей Юсуфа, которые были рождены ему в Египте, было двое. Всего членов семьи Якуба, пришедших в Египет, было семьдесят человек.

Встреча Якуба с Юсуфом

28Якуб послал перед собой к Юсуфу Иуду, чтобы узнать путь в Гошен. И они прибыли туда. 29Юсуф запряг колесницу и поехал в Гошен, чтобы встретить своего отца Исраила. Он предстал перед отцом, обнял его и долго плакал.

30Исраил сказал Юсуфу:

– Теперь я могу и умереть, потому что увидел своими глазами, что ты жив.

31Юсуф сказал своим братьям и домашним отца:

– Я пойду к фараону и скажу ему: «Мои братья и дом моего отца, которые жили в земле Ханаана, пришли ко мне. 32Эти люди – пастухи; они разводят скот и привели с собой свои стада и принесли всё своё имущество». 33Когда фараон вызовет вас и спросит: «Чем вы занимаетесь?» – 34вы должны ответить: «Рабы твои с отрочества своего и доныне разводят скот, как делали и наши отцы». Тогда вам будет позволено поселиться в земле Гошен, потому что египтянам отвратительны пастухи.