Gẹnẹsisi 44 – YCB & CARST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 44:1-34

Kọ́ọ̀bù idẹ nínú àpò

1Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Di oúnjẹ kún inú àpò àwọn ọkùnrin náà tó ìwọ̀n èyí tí wọ́n le rù, kí o sì mú owó olúkúlùkù àwọn ọkùnrin náà padà sí ẹnu àpò rẹ̀. 2Nígbà náà ni kí o mú kọ́ọ̀bù idẹ mi sí ẹnu àpò èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn nínú wọn pẹ̀lú owó tí ó fi ra ọkà,” ó sì ṣe bí Josẹfu ti sọ.

3Bí ilẹ̀ ti ń mọ́, wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà lọ pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn. 4Wọn kò tí ì rìn jìnnà sí ìlú náà tí Josẹfu fi wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Lépa àwọn ọkùnrin náà, nígbà tí o bá sì bá wọn, kí o wí pé, ‘Èéṣe ti ẹ fi búburú san rere? 5Èyí ha kọ́ ni kọ́ọ̀bù tí olúwa mi ń lò fún ohun mímu tí ó sì tún ń fi í ṣe àyẹ̀wò? Ohun tí ẹ ṣe yìí burú púpọ̀.’ ”

6Nígbà tí ó sì bá wọn, o sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún wọn 7Ṣùgbọ́n wọ́n dá a lóhùn pé, “Kí ló dé tí olúwa mi sọ irú nǹkan wọ̀nyí? Ká má rí i! Àwọn ìránṣẹ́ rẹ kò le ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀! 8A tilẹ̀ mú owó tí a rí lẹ́nu àpò wa padà tọ̀ ọ́ wá láti ilẹ̀ Kenaani. Nítorí náà èéṣe tí àwa yóò fi jí wúrà tàbí idẹ ní ilé olúwa à rẹ? 9Bí a bá rí i lọ́wọ́ èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ, kíkú ni yóò kú, àwọn tí ó kù yóò sì di ẹrú fún olúwa à rẹ.”

10Ó wí pé, “Ó dára, kí ó rí bí ẹ ti ṣe sọ; Ẹnikẹ́ni tí mo bá rí i lọ́wọ́ rẹ̀ yóò di ẹrú mi. Ẹ̀yin tí ó kù yóò sì wà láìlẹ́bi.”

11Olúkúlùkù wọn yára sọ àpò rẹ̀ kalẹ̀, wọ́n sì tú u. 12Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí ní í wá a, bẹ̀rẹ̀ láti orí ẹ̀gbọ́n títí lọ sórí àbúrò pátápátá. Ó sì rí kọ́ọ̀bù náà nínú àpò ti Benjamini. 13Nígbà tí wọ́n rí èyí, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọ́n sì banújẹ́ gidigidi, wọn tún ẹrù wọn dì sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọ́n sì padà sí inú ìlú.

14Josẹfu sì wà nínú ilé nígbà tí Juda àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wọlé wá. Gbogbo wọn sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀. 15Josẹfu wí fún wọn pé, “Èwo ni èyí tí ẹ ṣe yìí? Ṣe ẹ kò mọ pé, ènìyàn bí èmi le è rí ìdí nǹkan nípa ṣíṣe àyẹ̀wò?”

16Juda dáhùn pé, “Kí ni à bá sọ fún olúwa mi? Báwo ni a ṣe lè wẹ ara wa mọ́? Ọlọ́run ti tú àṣírí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, a ti di ẹrú olúwa à mi báyìí àwa fúnra wa àti ẹni náà tí a rí kọ́ọ̀bù lọ́wọ́ rẹ̀.”

17Ṣùgbọ́n Josẹfu dáhùn pé, “Ká má rí i pé mo ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀! Ẹni tí a bá kọ́ọ̀bù mi lọ́wọ́ rẹ̀ nìkan ni yóò di ẹrú mi, ẹ̀yin tí ó kù, ẹ máa lọ sọ́dọ̀ baba yín ní àlàáfíà.”

18Nígbà náà ni Juda súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó sọ ọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi, má ṣe bínú sí ìránṣẹ́ rẹ bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ pẹ̀lú láṣẹ bí i ti Farao. 19Olúwa mi béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ǹjẹ́ ó ní baba tàbí arákùnrin?’ 20Àwa sì wí fún olúwa mi pé, ‘A ni baba tí ó ti darúgbó, ọmọkùnrin kan sì wà pẹ̀lú tí a bí fún un ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀, baba rẹ̀ sì fẹ́ràn án rẹ̀.’

21“Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ mu un tọ̀ mí wá kí n le fojú ara mi rí i.’ 22A sì sọ fún olúwa à mi pé, ‘Ọmọkùnrin náà kò le è fi baba rẹ̀ sílẹ̀, bí ó bá dán an wò baba rẹ̀ yóò kú.’ 23Ṣùgbọ́n ìwọ wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ má ṣe padà tọ̀ mí wá àyàfi bí àbíkẹ́yìn yín bá bá yín wá.’ 24Nígbà tí a padà lọ sọ́dọ̀ baba wa, tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ, a sọ ohun tí olúwa à mi wí fún un.

25“Nígbà náà ni baba wa wí pé, ‘Ẹ padà lọ láti lọ ra oúnjẹ díẹ̀ wá.’ 26Ṣùgbọ́n a wí pe, ‘Àwa kò le è padà lọ, àyàfi bí àbúrò wa pátápátá yóò bá bá wa lọ. A kò le è rí ojú ọkùnrin náà àyàfi tí àbúrò wa bá lọ pẹ̀lú wa.’

27“Baba mi, ìránṣẹ́ rẹ wí fún wa pé, ‘Ẹ mọ̀ pé ìyàwó mi bí ọmọkùnrin méjì fún mi. 28Ọ̀kan nínú wọn lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, mo sì wí pé, “Dájúdájú a ti fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.” N kò sì tí ì ri láti ọjọ́ náà. 29Tí ẹ bá tún mú èyí lọ, kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ohunkóhun bá ṣe é, ìbànújẹ́ ni ẹ ó fi mú ewú orí mi lọ sí ipò òkú.’

30“Nítorí náà, bí a bá padà tọ baba wa lọ láìsí ọmọ náà pẹ̀lú wa nígbà tí a mọ̀ pé, ọmọ náà ni ẹ̀mí baba wa. 31Tí ó bá ri pé ọmọkùnrin náà kò wá pẹ̀lú wa, yóò kùú. Àwọn ìránṣẹ́ rẹ yóò wá mú baba wa tòun ti ewú orí lọ sí ipò òkú ní ìbànújẹ́. 32Ìránṣẹ́ rẹ ló ṣe onídùúró fún ààbò ọmọ náà lọ́dọ̀ baba mi. Mo wí pé, ‘Bí n kò bá mú un padà tọ̀ ọ́ wá, baba mi, èmi ó ru ẹ̀bi rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé mi!’

33“Nítorí náà, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó dúró ní ìhín lọ́dọ̀ olúwa à mi bí ẹrú dípò ọmọ náà. Kí ọmọ náà bá àwọn arákùnrin rẹ̀ padà. 34Báwo ni mo ṣe lè padà tọ baba mi lọ láì bá ṣe pé ọmọ náà wà pẹ̀lú mi? Rárá, èmi kò fẹ́ kí n rí ìbànújẹ́ tí yóò dé bá baba mi.”

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

Начало 44:1-34

Потерянная чаша

1Юсуф приказал своему управляющему:

– Наполни мешки этих людей едой, сколько смогут унести, и положи серебро каждому обратно в мешок. 2Положи мою чашу, мою серебряную чашу, в мешок к младшему вместе с его серебром за зерно.

И тот сделал, как велел Юсуф.

3Как только рассвело, братьев отправили в путь вместе с их ослами. 4Они были ещё недалеко от города, когда Юсуф сказал управляющему:

– Немедленно отправляйся в погоню за этими людьми и, когда догонишь, скажи им: «Почему вы заплатили злом за добро? 5Ведь это чаша моего господина, из которой он пьёт и на которой он гадает!44:5 Гадание – ненавистно для Всевышнего и запрещено законами Таврота (см. Лев. 19:26; Втор. 18:10-12). Может быть, Юсуф никогда сам не гадал, но сказал это с определённой целью. Но также не исключено, что Юсуф был повинен в этом грехе, так как все люди, даже пророки, не без греха (см. 20:1-7; 2 Цар. 11–12; Рим. 3:23), исключая лишь Исо (см. 1 Пет. 2:21-23; 2 Кор. 5:20-21; Евр. 4:15). См. также ст. 15. Вы совершили недобрый поступок!»

6Догнав их, он повторил им эти слова. 7Они ответили:

– Почему господин говорит такие слова? Разве станут твои рабы делать подобное! 8Ведь мы даже принесли тебе обратно из земли Ханона то серебро, которое нашли у себя в мешках. Зачем же нам воровать серебро или золото из дома твоего господина? 9Если вещь найдётся у одного из нас, пусть он умрёт, а остальные станут рабами нашего господина.

10Он сказал:

– Хорошо, пусть будет так, как вы говорите: у кого найдётся чаша, тот станет моим рабом, а остальные будут свободны от ответа.

11Братья быстро опустили каждый свой мешок на землю и развязали их. 12Управляющий начал искать, начиная со старшего, кончая младшим; чаша нашлась в мешке у Вениамина. 13Они в скорби разорвали на себе одежду, нагрузили каждый своего осла и вернулись в город.

14Иуда и его братья вернулись в дом Юсуфа, который всё ещё был там. Они бросились перед ним на землю.

15Юсуф сказал им:

– Что же вы сделали? Разве вы не знали, что такой человек, как я, может всё узнать через гадание?

16– Что мы можем сказать моему господину? – ответил Иуда. – Как нам возразить? Как доказать нашу невиновность? Всевышний открыл нашу вину. Теперь мы рабы моего господина – и мы, и тот, у кого нашлась чаша.

17Юсуф сказал:

– Разве я стану делать такое! Только тот, у кого нашлась чаша, будет моим рабом, а вы возвращайтесь к отцу с миром.

Иуда просит об освобождении Вениамина

18Тогда Иуда подошёл к нему и сказал:

– Пожалуйста, мой господин, позволь твоему рабу сказать моему господину слово. Не гневайся на твоего раба, хотя ты равен самому фараону. 19Мой господин спросил своих рабов: «Есть ли у вас отец или брат?» 20И мы ответили: «У нас есть престарелый отец и есть его юный сын, рождённый ему в старости. Его родной брат умер, и из сыновей своей матери он остался один, поэтому отец особенно любит его».

21Тогда ты сказал своим рабам: «Приведите его ко мне, чтобы мне посмотреть на него». 22А мы ответили моему господину: «Мальчик не может оставить отца, а если оставит, то отец не переживёт разлуки с ним». 23Но ты сказал своим рабам: «Пока ваш брат не придёт сюда с вами, не показывайтесь мне на глаза».

24Вернувшись к твоему рабу, моему отцу, мы пересказали ему, что сказал мой господин. 25Наш отец сказал: «Вернитесь и купите ещё немного еды». 26Но мы ответили: «Мы не можем пойти; только если младший брат пойдёт с нами, тогда мы пойдём. Мы не можем и на глаза показаться тому человеку, если не будет с нами младшего брата».

27Твой раб, мой отец, сказал нам: «Вы сами знаете, что моя жена Рахиля родила мне двоих сыновей. 28Один из них ушёл от меня, и я сказал: „Конечно, он был растерзан на куски“, – и с тех пор я его не видел. 29Если вы возьмёте у меня и другого, и с ним случится беда, вы сведёте мою седую голову в могилу от горя».

30Поэтому, если мальчика не будет с нами, когда я вернусь к твоему рабу, моему отцу, и если мой отец, который так привязан к этому мальчику, 31увидит, что его с нами нет, он умрёт. Твои рабы этой скорбью сведут седую голову нашего отца в могилу. 32Твой раб поручился за безопасность мальчика перед отцом. Я сказал: «Если я не приведу его к тебе, то вина перед тобой, отец, будет на мне всю жизнь».

33Итак, молю тебя, мой господин, позволь твоему рабу остаться здесь вместо мальчика, и позволь мальчику вернуться с братьями. 34Как я могу вернуться к отцу, если мальчика со мной не будет? Да не увижу я горя моего отца.