Gẹnẹsisi 43 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 43:1-34

Ìrìnàjò ẹ̀ẹ̀kejì lọ sí Ejibiti

1Báyìí, ìyàn náà sì mú gidigidi ní ilẹ̀ náà. 2Nígbà tí wọ́n sì ti jẹ gbogbo ọkà tí wọ́n rà ní Ejibiti tan, baba wọn wí fún wọn pé, “Ẹ padà lọ ra oúnjẹ díẹ̀ si wá fún wa.”

3Ṣùgbọ́n Juda wí fún un pé, “Ọkùnrin náà tẹnumọ́ ọn nínú ìkìlọ̀ rẹ̀ fún wa pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò rí ojúrere mi mọ́, àyàfi bí arákùnrin yín bá bá a yín wá’. 4Tí ìwọ yóò bá rán Benjamini arákùnrin wa lọ pẹ̀lú wa, a ó lọ ra oúnjẹ wá fún ọ. 5Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ni jẹ́ kí ó bá wa lọ, àwa kì yóò lọ, nítorí ọkùnrin náà sọ fún wa pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò rí ojúrere mi mọ́ àyàfi bí arákùnrin yín bá bá a yín wá.’ ”

6Israẹli béèrè pé, “Èéṣe tí ẹ fi kó ìdààmú yìí bá mi nípa sísọ fún ọkùnrin náà wí pé ẹ ní arákùnrin mìíràn?”

7Wọ́n dáhùn pé, “Ọkùnrin náà fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ wádìí lọ́wọ́ wa nípa ìdílé wa àti àwa fúnra wa. Ó béèrè pé, ‘Ṣe baba yín ṣì wà láààyè? Ǹjẹ́ ẹ tún ní arákùnrin mìíràn?’ A kàn dáhùn ìbéèrè rẹ̀ ni. Báwo ni a ṣe le mọ̀ pé yóò wí pé, ‘Ẹ mú arákùnrin yín wá’?”

8Juda sì wí fún Israẹli baba rẹ̀, “Jẹ́ kí ọmọkùnrin náà lọ pẹ̀lú mi, a ó sì lọ ní kíákíá, kí àwa àti ìwọ àti àwọn ọmọ wa le yè, kí a má sì kú. 9Èmi fúnra mi yóò ṣe onídùúró fún un, èmi ni kí o gbà pé o fi lé lọ́wọ́. Bí n kò bá sì mú un padà tọ̀ ọ́ wá, jẹ́ kí ẹ̀bi rẹ̀ kí ó jẹ́ tèmi ní gbogbo ọjọ́ ayé mi níwájú rẹ. 10Bí ó bá ṣe pé a kò fi falẹ̀ ni, àwa ìbá ti lọ, à bá sì ti padà ní ìgbà méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀.”

11Nígbà náà ni Israẹli baba wọn wí fún wọn, “Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, èyí ni kí ẹ ṣe: Ẹ mú àwọn ohun dáradára ilẹ̀ yìí lọ́wọ́ lọ bí ẹ̀bùn fún ọkùnrin náà—ìkunra díẹ̀, oyin díẹ̀, tùràrí àti òjìá, èso pisitakio àti èso almondi 12ìlọ́po owó méjì ni kí ẹ mú lọ́wọ́, nítorí ẹ gbọdọ̀ dá owó tí ẹ bá lẹ́nu àpò yín padà. Bóyá ẹnìkan ló ṣèèṣì fi síbẹ̀. 13Ẹ mú arákùnrin yín lọ́wọ́ pẹ̀lú ki ẹ sì tọ arákùnrin náà lọ. 14Kí Ọlọ́run alágbára (Eli-Ṣaddai) jẹ́ kí ẹ rí àánú gbà lọ́dọ̀ ọkùnrin náà kí ó ba à le jẹ́ kí arákùnrin yín tí ó wà lọ́hùn ún àti Benjamini padà wá pẹ̀lú yín. Ní tèmi, bí mo bá pàdánù àwọn ọmọ mi, n ó ṣọ̀fọ̀ wọn náà ni.”

15Nítorí náà wọ́n mú àwọn ẹ̀bùn náà àti owó ìlọ́po méjì àti Benjamini, wọ́n sì yára lọ sí ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Josẹfu. 16Nígbà tí Josẹfu rí Benjamini pẹ̀lú wọn, ó sọ fún ìránṣẹ́ ilé rẹ̀, “Mú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí lọ sí ilé mi, pa ẹran kí o sì ṣe àsè; wọn ó jẹun ọ̀sán pẹ̀lú mi.”

17Ọkùnrin náà sì ṣe bí Josẹfu ti wí fún un, ó sì mú àwọn ọkùnrin náà lọ sí ilé Josẹfu. 18Ẹ̀rù sì ba àwọn ọkùnrin náà nígbà tí wọ́n mú wọn lọ sí ilé Josẹfu. Wọ́n rò ó pé, “A mú wa wá sí ìhín nítorí owó tí a fi sí inú àpò wa ní ìgbà àkọ́kọ́. Ó fẹ́ bá wa jà, kí ó mú wa lẹ́rú kí ó sì gba àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wa.”

19Nítorí náà wọ́n lọ bá ìránṣẹ́ Josẹfu, wọ́n sì ba sọ̀rọ̀ ní ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ilé náà. 20Wọ́n wí pé, “Jọ̀wọ́ ọ̀gá, ní òtítọ́ ni àwa ti sọ̀kalẹ̀ síhìn-ín láti wá ra oúnjẹ ní ìṣáájú. 21Ṣùgbọ́n níbi tí a ti dúró ní ọ̀nà láti sùn ní alẹ́, nígbà tí a tú àpò oúnjẹ wa, ẹnìkọ̀ọ̀kan wa bá owó oúnjẹ tirẹ̀ tí ó rà lẹ́nu àpò láì lé, láì dín. Nítorí náà òun nìyí, a ti mu un padà wá pẹ̀lú wa. 22A sì tún mú owó mìíràn lọ́wọ́ láti fi ra oúnjẹ. A ò mọ ẹni tí ó fi owó wa sí ẹnu àpò.”

23Ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà ni fún yín, ẹ má bẹ̀rù, Ọlọ́run yín, àní Ọlọ́run baba yín ni ó fi ìṣúra sí inú àpò yín; mo rí owó tí ẹ san gbà.” Nígbà náà ni ó mú Simeoni jáde tọ̀ wọ́n wá.

24Ìránṣẹ́ náà mú àwọn ọkùnrin náà lọ sí ilé Josẹfu, ó fún wọn ní omi láti fi wẹ ẹsẹ̀ wọn nu, ó sì fún àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn lóúnjẹ pẹ̀lú. 25Wọ́n pèsè ẹ̀bùn wọn sílẹ̀ fún Josẹfu di ọ̀sán nígbà tí yóò dé, nítorí wọ́n ti gbọ́ pé ibẹ̀ ni àwọn yóò ti jẹun ọ̀sán.

26Nígbà tí Josẹfu dé sí ilé, wọ́n kó àwọn ẹ̀bùn tí wọ́n ti mú wá fún un, wọ́n sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀. 27Ó béèrè àlàáfíà wọn, ó sì wí pé, “Ṣé àlàáfíà ni baba yín wà, baba arúgbó tí ẹ sọ̀rọ̀ rẹ̀ fún mi, ṣé ó sì wà láààyè?”

28Wọ́n dáhùn pé, “ìránṣẹ́ rẹ, baba wa sì wà láààyè, àlàáfíà sì ni ó wà pẹ̀lú.” Wọn sì tẹríba láti bọ̀wọ̀ fún un.

29Bí ó ti wò yíká tí ó sì rí Benjamini àbúrò rẹ̀, tí í ṣe ọmọ ìyá rẹ̀ gan an. Ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣe àbúrò yín tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn tí ẹ sọ fún mi nípa rẹ̀ nìyìí?” Ó sì tún wí pe, “Kí Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún ọ, ọmọ mi” 30Ọkàn rẹ̀ sì fà sí i gidigidi nígbà tí ó rí arákùnrin rẹ̀, nítorí náà Josẹfu yára jáde láti wá ibi tí ó ti le sọkún. Ó lọ sí iyàrá rẹ̀, ó sì sọkún níbẹ̀.

31Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti bọ́jú tan, ó jáde wá, ó ṣe ọkàn ọkùnrin, ó sì wí fún wọn pé, kí wọ́n gbé oúnjẹ wá kí wọ́n le è jẹun.

32Wọ́n gbé oúnjẹ tirẹ̀ fún un lọ́tọ̀, àti fún àwọn ará Ejibiti tí ó wá ba jẹun náà lọ́tọ̀, nítorí ará Ejibiti kò le bá ará Heberu jẹun nítorí ìríra pátápátá ló jẹ́ fún àwọn Ejibiti. 33A mú àwọn ọkùnrin náà jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bí wọ́n ṣe dàgbà sí, láti orí ẹ̀gbọ́n pátápátá dé orí èyí tí ó kéré pátápátá, wọ́n sì ń wo ara wọn tìyanu tìyanu. 34A sì bu oúnjẹ fún wọn láti orí tábìlì Josẹfu. Oúnjẹ Benjamini sì tó ìlọ́po márùn-ún ti àwọn tókù. Wọ́n ń jẹ, wọ́n sì ń mu lọ́dọ̀ rẹ̀ láìsí ìdíwọ́.

Swedish Contemporary Bible

1 Moseboken 43:1-34

Benjamin reser till Josef

1Men svälten var fruktansvärd i landet. 2När säden som de hade fört med sig från Egypten var slut, sa fadern till dem: ”Res dit igen och köp lite mat åt oss!”

3Men Juda43:3 Från och med nu är Juda den ledande av bröderna. Ruben var inte omtyckt av fadern. Se 35:22 och 49:4. sa till honom: ”Mannen menade allvar när han sa: ’Kom inte tillbaka till mig igen utan er bror!’ 4Låter du vår bror följa med oss, så reser vi för att köpa säd åt dig. 5Men om du inte låter honom följa med, kan vi inte resa. Mannen sa ju till oss att vi inte fick komma tillbaka till honom utan vår bror.”

6”Varför gjorde ni detta mot mig att ni berättade att ni hade en bror till?” sa Israel. 7”Mannen frågade noga om vår familj”, svarade de. ”Han ville veta om vår far fortfarande levde, och han frågade om vi hade ytterligare någon bror, och därför berättade vi det för honom. Hur kunde vi veta att han skulle säga: ’För hit er bror?’ ”

8Juda sa till sin far: ”Skicka pojken med mig, så att vi kan ge oss av och så får överleva, annars kommer vi att dö av svält allihop, både vi och våra barn. 9Jag garanterar hans trygghet. Du får hålla mig personligen ansvarig för honom. Om jag inte för honom tillbaka, så bär jag skulden inför dig resten av livet. 10Hade vi inte dröjt så här, skulle vi redan ha hunnit tillbaka för andra gången.”

11Till slut sa deras far Israel till dem: ”Om det inte går att undvika så gör så här: ta landets bästa produkter i era säckar som gåva åt den där mannen, lite balsam, lite honung, dragantgummi, myrra, pistagenötter och mandlar. 43:11 Se not till 37:25. 12Ta med er dubbelt så mycket pengar, så att ni kan betala tillbaka det som fanns i säckarna, eftersom det förmodligen berodde på ett misstag, 13och ta er bror och res iväg. 14Måtte Gud den Väldige låta mannen visa barmhärtighet mot er, så att han låter er andre bror och Benjamin följa med er tillbaka! Men om jag måste förlora mina barn, så får det bli som det blir.”

15Då tog de med sig gåvorna och dubbelt så mycket pengar som förra gången och även sin bror Benjamin. De skyndade sig att komma fram till Egypten, där de fick träda fram inför Josef.

16När Josef såg att Benjamin var med dem, sa han till sin närmaste man: ”Ta med dessa män hem till mig, slakta djur och laga maten, för de ska äta middag tillsammans med mig.” 17Mannen gjorde som han blev tillsagd och tog dem med sig till Josefs hus.

18Bröderna blev rädda när de fördes dit. ”Det är för att pengarna låg i säckarna förra gången som vi nu förs hit”, tänkte de. ”Nu kommer han att anfalla oss och övermanna oss. Sedan kommer han att göra oss till slavar och ta våra åsnor.”

19De gick fram till Josefs närmaste man vid ingången till Josefs hus och talade till honom: 20”Hör på oss, herre. När vi hade varit här första gången för att köpa mat, 21stannade vi över natten på vägen och öppnade våra säckar. Då fann vi att alla pengarna som vi betalt för säden låg överst i säckarna. Här är de. Vi har tagit dem med oss tillbaka, 22tillsammans med ytterligare pengar för att köpa säd. Vi vet inte vem som kan ha lagt pengarna i säckarna.” 23”Oroa er inte för det”, sa Josefs närmaste man till dem. ”Ni behöver inte vara rädda. Er Gud, er fars Gud har gett er en skatt i era säckar. Jag fick betalt för säden.”

Sedan förde mannen ut Simon till dem. 24Mannen visade dem in i huset, och de fick vatten att tvätta fötterna med, och deras åsnor fick foder. 25De tog sedan fram sina gåvor till Josef som skulle komma vid middagstiden, för de hade fått veta att de skulle äta där. 26När Josef kom hem, gav de honom gåvorna som de fört med sig till huset och bugade sig djupt inför honom.

27Han frågade hur de hade haft det och tillade: ”Och hur mår er gamle far, som ni berättade om? Lever han fortfarande?” 28”Ja”, svarade de. ”Vår far, din tjänare, lever och mår bra.” Sedan bugade de sig djupt inför honom igen.

29Josef såg på sin bror, sin mors son Benjamin och frågade: ”Är det här er yngste bror, som ni berättade om? Måtte Gud vara nådig mot dig, min son!” 30Sedan gick Josef snabbt ut därifrån, för han överväldigades av kärlek till sin bror och blev tvungen att hitta ett ställe där han kunde gråta. Han gick till sitt privata rum och grät där. 31Sedan tvättade han ansiktet och kom ut och försökte behärska sig och befallde att maten skulle serveras.

32Josef åt för sig själv, hans bröder serverades vid ett annat bord och egypterna vid ännu ett annat. Egypterna kunde nämligen inte äta tillsammans med hebréer, för det skulle ha varit avskyvärt för dem. 33Bröderna satt mitt emot Josef i åldersordning, från den äldste till den yngste. De såg förvånade på varandra.

34Maten serverades åt dem från hans eget bord. Han gav den största portionen till Benjamin – fem gånger så mycket som till någon av de andra. De åt och drack glatt tillsammans.