Kaini àti Abeli
1Adamu sì bá aya rẹ̀ Efa lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Kaini. Ó wí pé, “Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Olúwa ni mo bí ọmọ ọkùnrin.” 2Lẹ́yìn náà, ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn tí a pè ní Abeli.
Abeli jẹ́ darandaran, Kaini sì jẹ́ àgbẹ̀. 3Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Kaini mú ọrẹ wá fún Olúwa nínú èso ilẹ̀ rẹ̀. 44.4: Hb 11.4.Ṣùgbọ́n Abeli mú ẹran tí ó sanra wá fún Olúwa nínú àkọ́bí ẹran ọ̀sìn rẹ̀. Olúwa sì fi ojúrere wo Abeli àti ọrẹ rẹ̀, 5ṣùgbọ́n Olúwa kò fi ojúrere wo Kaini àti ẹbọ rẹ̀. Nítorí náà inú bí Kaini gidigidi, ojú rẹ̀ sì fàro.
6Nígbà náà ni Olúwa bi Kaini pé, “Èéṣe tí ìwọ ń bínú? Èéṣe tí ojú rẹ sì fàro? 7Bí ìwọ bá ṣe ohun tí ó tọ́, ṣé ìwọ kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà? Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ṣe ohun tí ó tọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ń bẹ ní ẹnu-ọ̀nà rẹ, ó fẹ́ ní ọ ní ìní, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ ṣe àkóso rẹ̀.”
84.8: 1Jh 3.12.Kaini wí fún Abeli arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ kí a lọ sí oko.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti wà ní oko; Kaini da ojú ìjà kọ Abeli arákùnrin rẹ̀, ó sì pa á.
9Nígbà náà ni Olúwa béèrè lọ́wọ́ Kaini pé, “Níbo ni Abeli arákùnrin rẹ wà?”
Ó sì dáhùn pé, “Èmi kò mọ ibi tí ó wà, èmí ha ń ṣe olùṣọ́ arákùnrin mi bí?”
10Olúwa wí pé, “Kín ni ohun tí ìwọ ṣe yìí? Gbọ́! Ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ ń kígbe pè mí láti ilẹ̀ wá. 11Láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ ti wà lábẹ́ ègún, a sì ti lé ọ lórí ilẹ̀ tí ó ya ẹnu gba ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ lọ́wọ́ rẹ. 12Bí ìwọ bá ro ilẹ̀, ilẹ̀ kì yóò fi agbára rẹ̀ so èso rẹ̀ fún ọ mọ́. Ìwọ yóò sì jẹ́ ìsáǹsá àti alárìnkiri ni orí ilẹ̀ ayé.”
13Kaini wí fún Olúwa pé, “Ẹrù ìyà ẹ̀ṣẹ̀ mi pọ̀ ju èyí tí mo le rù lọ. 14Lónìí, ìwọ lé mi kúrò lórí ilẹ̀, mó sì di ẹni tí ó fi ara pamọ́ kúrò ní ojú rẹ, èmi yóò sì di ìsáǹsá àti alárìnkiri ní ayé, ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi, yóò sì pa mí.”
15Ṣùgbọ́n, Olúwa wí fún pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ẹnikẹ́ni bá pa Kaini, èmi yóò gbẹ̀san ní ara onítọ̀hún ní ìgbà méje.” Nígbà náà ni Ọlọ́run fi ààmì sí ara Kaini, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá ri má ba à pa á. 16Kaini sì kúrò níwájú Ọlọ́run, ó sì ń gbé ilẹ̀ Nodi ní ìhà ìlà-oòrùn Edeni.
17Kaini sì bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Enoku. Kaini sì tẹ ìlú kan dó, ó sì fi orúkọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Enoku sọ ìlú náà. 18Enoku sì bí Iradi, Iradi sì ni baba Mehujaeli, Mehujaeli sì bí Metuṣaeli, Metuṣaeli sì ni baba Lameki.
19Lameki sì fẹ́ aya méjì, orúkọ èkínní ni Adah, àti orúkọ èkejì ni Silla. 20Adah sì bí Jabali: òun ni baba irú àwọn tí ń gbé inú àgọ́, tí wọ́n sì ń sin ẹran ọ̀sìn. 21Orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Jubali, òun ni baba irú àwọn tí ń tẹ dùùrù tí wọ́n sì ń fọn fèrè. 22Silla náà sì bí ọmọkùnrin tí ń jẹ́ Tubali-Kaini, tí ó ń rọ oríṣìíríṣìí ohun èlò láti ara idẹ àti irin. Arábìnrin Tubali-Kaini ni Naama.
23Lameki wí fún àwọn aya rẹ̀,
“Adah àti Silla, ẹ tẹ́tí sí mi;
ẹ̀yin aya Lameki, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.
Mo ti pa ọkùnrin kan tí ó kọlù mí,
ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó pa mí lára.
24Bí a ó bá gbẹ̀san Kaini ní ìgbà méje,
ǹjẹ́ kí a gba ti Lameki nígbà mẹ́tà-dínlọ́gọ́rin.”
25Adamu sì tún bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Seti, tí ó túmọ̀ sí pé, “Ọlọ́run fún mi ní ọmọkùnrin mìíràn ní ipò Abeli tí Kaini pa.” 26Seti náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Enoṣi.
Láti àkókò náà lọ ni àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní ké pe orúkọ Olúwa.
L’intrusion de la violence
1L’homme s’unit à Eve, sa femme ; elle devint enceinte et donna naissance à Caïn. Elle dit : J’ai formé un homme avec l’aide de l’Eternel.
2Elle mit encore au monde le frère de Caïn, Abel. Abel devint berger et Caïn cultivateur.
3Au bout d’un certain temps, Caïn présenta des produits de la terre en offrande à l’Eternel. 4Abel, lui aussi, fit une offrande : il présenta les premiers-nés de son troupeau et en offrit les meilleurs morceaux. L’Eternel prêta attention à Abel et à son offrande4.4 Allusion en Hé 11.4. ; 5mais pas à Caïn et son offrande. Cela mit Caïn dans une grande colère, et son visage s’assombrit.
6L’Eternel dit à Caïn : Pourquoi es-tu en colère et pourquoi ton visage est-il sombre ? 7Si tu agis bien, tu le relèveras. Mais si tu n’agis pas bien, le péché est tapi à ta porte : son désir se porte vers toi, mais toi, domine-le !
8Mais Caïn dit à son frère Abel : Allons aux champs4.8 D’après le Pentateuque samaritain et les versions syriaques ; manque dans le texte hébreu traditionnel..
Et lorsqu’ils furent dans les champs, Caïn se jeta sur son frère Abel et le tua4.8 Voir Mt 23.35 ; 1 Jn 3.12..
9Alors l’Eternel demanda à Caïn : Où est ton frère Abel ?
– Je n’en sais rien, répondit-il. Suis-je le gardien de mon frère ?
10Dieu lui dit : Qu’as-tu fait ? J’entends le sang de ton frère crier vengeance depuis la terre jusqu’à moi. 11Maintenant, tu es maudit et chassé loin du sol qui a bu le sang de ton frère versé par ta main. 12Lorsque tu cultiveras le sol, il te refusera désormais ses produits, tu seras errant et fugitif sur la terre.
13Caïn dit à l’Eternel : Ma faute est trop lourde à porter. 14Voici que tu me chasses aujourd’hui loin du sol fertile, et je devrai me cacher loin de toi, je serai errant et fugitif sur la terre et si quelqu’un me trouve, il me tuera.
15L’Eternel lui dit : Eh bien ! Si on tue Caïn, il sera vengé sept fois.
Et l’Eternel marqua Caïn d’un signe pour qu’il ne soit pas tué par qui le rencontrerait.
16Caïn partit loin de l’Eternel : il alla séjourner au pays de Nod, le pays de l’Errance, à l’orient d’Eden, le pays des Délices.
La lignée de Caïn
17Caïn s’unit à sa femme, elle devint enceinte et mit au monde Hénok. Caïn bâtissait une ville qu’il appela Hénok, du nom de son fils.
18Hénok fut l’ancêtre d’Irad, qui eut pour descendants : Mehouyaël, Metoushaël et Lémek.
19Lémek prit deux femmes pour épouses : l’une s’appelait Ada et l’autre Tsilla. 20Ada mit au monde Yabal, le père des nomades habitant sous des tentes et au milieu de leurs troupeaux. 21Il avait pour frère Youbal, le père de tous ceux qui jouent de la lyre et de la flûte. 22Tsilla, de son côté, mit au monde Toubal-Caïn, qui forgeait tous les instruments de bronze et de fer. La sœur de Toubal-Caïn s’appelait Naama.
23Lémek dit à ses femmes :
Ada et Tsilla, ╵écoutez-moi bien,
femmes de Lémek, ╵et prêtez l’oreille ╵à ce que je dis :
J’ai tué un homme ╵pour une blessure
et un jeune enfant ╵pour prix de ma plaie.
24Caïn sera vengé sept fois
et Lémek soixante-dix-sept fois.
25Adam s’unit encore à sa femme et elle mit au monde un fils qu’elle nomma Seth car, dit-elle, Dieu m’a suscité une autre descendance pour remplacer Abel que Caïn a tué. 26Seth aussi eut un fils qu’il appela Enosh. C’est à cette époque-là qu’on a commencé à prier l’Eternel.