Gẹnẹsisi 3 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 3:1-24

Ìṣubú ènìyàn

13.1: If 12.9; 20.2.Ejò sá à ṣe alárékérekè ju àwọn ẹranko igbó yòókù tí Olúwa Ọlọ́run dá lọ. Ó sọ fún obìnrin náà pé, “Ǹjẹ́ òtítọ́ ha ni Ọlọ́run wí pé, ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ èso èyíkéyìí lára àwọn igi tí ó wà nínú ọgbà’?”

2Obìnrin náà dá ejò lóhùn pé, “Àwa lè jẹ lára àwọn èso igi tí ó wà nínú ọgbà, 3ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ pé, ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ lára èso igi tí ó wà láàrín ọgbà, ẹ kò sì gbọdọ̀ fi ọwọ́ kàn án, bí ẹ̀yin bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin yóò kùú.’ ”

43.4: 2Kọ 11.3.Ejò wí fún obìnrin náà pé, “Ẹ̀yin kì yóò kú ikúkíkú kan.” 5“Nítorí Ọlọ́run mọ̀ wí pé, bí ẹ̀yin bá jẹ nínú rẹ̀, ojú yín yóò là, ẹ̀yin yóò sì dàbí Ọlọ́run, ẹ̀yin yóò sì mọ rere yàtọ̀ sí búburú.”

6Nígbà tí obìnrin náà rí i wí pé èso igi náà dára fún oúnjẹ àti pé, ó sì dùn ún wò, àti pé ó ń mú ni ní ọgbọ́n, ó mú díẹ̀ níbẹ̀, ó sì jẹ ẹ́. Ó sì mú díẹ̀ fún ọkọ rẹ̀, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, òun náà sì jẹ ẹ́. 7Nígbà náà ni ojú àwọn méjèèjì sì là, wọ́n sì mọ̀ pé àwọn wà ní ìhòhò; wọ́n sì rán ewé ọ̀pọ̀tọ́ pọ̀, wọ́n sì fi bo ara wọn.

8Nígbà náà ni ọkùnrin náà àti aya rẹ̀ gbọ́ ìró Olúwa Ọlọ́run bí ó ti ń rìn nínú ọgbà, nígbà tí ojú ọjọ́ tura, wọ́n sì fi ara pamọ́ kúrò níwájú Olúwa Ọlọ́run sí àárín àwọn igi inú ọgbà. 9Ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run ké pe ọkùnrin náà pé, “Níbo ni ìwọ wà?”

10Ó dáhùn pé, “Mo gbúròó rẹ̀ nínú ọgbà, ẹ̀rù sì bà mí, nítorí pé, mo wà ní ìhòhò, mo sì fi ara pamọ́.”

11Ọlọ́run wí pé, “Ta ni ó wí fún ọ pé ìhòhò ni ìwọ wà? Ṣé ìwọ ti jẹ nínú èso igi tí mo pàṣẹ fún ọ pé ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀ ni?”

12Ọkùnrin náà wí pé, “Obìnrin tí ìwọ fi fún mi, ni ó fún mi nínú èso igi náà, mo sì jẹ ẹ́.”

133.13: 2Kọ 11.3; 1Tm 2.14.Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run wí pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe yìí?”

Obìnrin náà dáhùn pé, “Ejò ni ó tàn mí jẹ, mo sì jẹ ẹ́.”

143.14,15: If 12.9; 20.2.Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run wí fún ejò náà pé, “Nítorí tí ìwọ ti ṣe èyí,

“Ègún ni fún ọ ju gbogbo ohun ọ̀sìn

àti gbogbo ẹranko igbó tókù lọ!

Àyà rẹ ni ìwọ yóò fi máa wọ́,

ìwọ yóò sì máa jẹ erùpẹ̀ ilẹ̀

ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.

153.15: If 12.17.Èmi yóò sì fi ọ̀tá

sí àárín ìwọ àti obìnrin náà,

àti sí àárín irú-ọmọ rẹ àti irú-ọmọ obìnrin náà;

òun yóò fọ́ orí rẹ,

ìwọ yóò sì bù ú jẹ ní gìgísẹ̀.”

16Ọlọ́run wí fún obìnrin náà pé:

“Èmi yóò fi kún ìrora rẹ ní àkókò ìbímọ;

ni ìrora ni ìwọ yóò máa bí ọmọ.

Ọ̀dọ̀ ọkọ rẹ ni ìfẹ́ rẹ yóò máa fà sí,

òun ni yóò sì máa ṣe àkóso rẹ.”

173.17,18: Hb 6.8.Ọlọ́run sì wí fún Adamu pé, “Nítorí pé ìwọ fetí sí aya rẹ, ìwọ sì jẹ nínú èso igi tí mo pàṣẹ fún ọ pé ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀,’

“Ègún ni fún ilẹ̀ nítorí rẹ;

nínú ọ̀pọ̀ làálàá ni ìwọ yóò jẹ nínú rẹ̀,

ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.

18Ilẹ̀ yóò sì hu ẹ̀gún àti èṣùṣú fún ọ,

ewéko igbó ni ìwọ yóò sì máa jẹ.

19Nínú òógùn ojú rẹ

ni ìwọ yóò máa jẹun

títí tí ìwọ yóò fi padà sí ilẹ̀,

nítorí inú ilẹ̀ ni a ti mú ọ jáde wá;

erùpẹ̀ ilẹ̀ sá à ni ìwọ,

ìwọ yóò sì padà di erùpẹ̀.”

20Adamu sì sọ aya rẹ̀ ní Efa nítorí òun ni yóò di ìyá gbogbo alààyè.

21Olúwa Ọlọ́run, sì dá ẹ̀wù awọ fún Adamu àti aya rẹ̀, ó sì fi wọ̀ wọ́n. 223.22,24: If 2.7; 22.2,14,19.Olúwa Ọlọ́run sì wí pé, “Ọkùnrin náà ti dàbí ọ̀kan lára wa, ó mọ rere àti búburú. A kò gbọdọ̀ jẹ́ kí ó na ọwọ́ rẹ̀ kí ó mú lára èso igi ìyè kí ó sì jẹ, kí ó sì wà láààyè títí láéláé.” 23Nítorí náà, Olúwa Ọlọ́run lé e kúrò nínú ọgbà Edeni láti lọ máa ro ilẹ̀ nínú èyí tí a ti mú un jáde wá. 24Lẹ́yìn tí ó ti lé ènìyàn jáde tán, ó fi àwọn Kérúbù àti idà iná tí ó ń kọ mọ̀nàmọ́ná síwájú àti sẹ́yìn láti ṣọ́ ọ̀nà tí ó lọ sí ibi igi ìyè, ní ìhà ìlà-oòrùn ọgbà Edeni.

Swedish Contemporary Bible

1 Moseboken 3:1-24

Adam och Eva syndar

1Ormen var det listigaste av alla vilda djur som Herren Gud hade skapat. Ormen frågade kvinnan: ”Har Gud verkligen sagt att ni inte får äta av något träd i trädgården?” 2”Vi får äta frukt av träden”, svarade kvinnan. 3”Det är bara av trädet mitt i trädgården som vi inte får äta. Gud har sagt att vi inte får äta eller ens röra dess frukt, för då kommer vi att dö.” 4Ormen svarade: ”Ni kommer visst inte att dö! 5Gud vet att den dag ni äter av frukten kommer era ögon att öppnas och ni blir som Gud3:5 Eller: gudar, med kunskap om gott och ont.”

6Kvinnan såg att trädet var gott att äta av, och det var vackert och lockande, eftersom det gav vishet. Hon åt av frukten och gav också till sin man, som var med henne, och han åt. 7Då öppnades deras ögon, och de insåg att de var nakna. Därför band de ihop fikonlöv runt höfterna för att skyla sig.

8När de den kvällen, i den svala kvällsvinden, hörde Herren Gud vandra omkring i trädgården, gömde de sig för honom bland träden. 9Herren Gud ropade till Adam: ”Adam, var är du?” 10Adam svarade: ”Jag hörde dig i trädgården, och blev rädd eftersom jag är naken. Därför gömde jag mig.” 11”Vem har talat om för dig att du är naken?” frågade Gud. ”Har du ätit av frukten från trädet som jag förbjöd dig att äta av?” 12Adam svarade: ”Kvinnan, som jag fick av dig, gav mig av trädet, och jag åt.”

13Då sa Herren Gud till kvinnan: ”Vad har du gjort?” ”Ormen lurade mig, och jag åt”, svarade hon. 14Herren Gud sa till ormen: ”Eftersom du gjorde detta,

ska du vara förbannad

och skild från alla husdjur

och vilda djur på hela jorden.

På din buk ska du kräla

och jord ska du äta så länge du lever.

15Jag ska sätta fiendskap

mellan dig och kvinnan

och mellan din avkomma3:15 Bokstavligen din säd. Se not till 1 Mos 12:7 och hennes.

Han kommer att krossa ditt huvud,

och du kommer att hugga3:15 Hebreiskan använder samma ord för krossa och hugga. honom i hälen.”

16Till kvinnan sa han:

”Din möda under havandeskapet ska jag göra stor.

Du kommer att föda barn under smärta.

Du kommer att åtrå din man,

och han kommer att råda över dig.”

17Till Adam sa han: ”Eftersom du lyssnade till din hustru och åt av trädet, fast jag förbjudit dig och sagt att du inte fick,

låter jag en förbannelse vila över marken för din skull.

Hela ditt liv kommer du att få skaffa ditt uppehälle med möda.

18Marken ska ge dig tistlar och törnen,

och du ska äta dess växter.

19Hela livet ända tills du dör

kommer du att få svettas och kämpa för ditt bröd.

Sedan kommer du att återvända

till den jord du kommit ifrån,

för du formades av jord,

och jord ska du en gång åter bli.”

20Mannen kallade sin hustru Eva3:20 Namnet kommer från hebreiskans verb för leva., för han sa: ”Hon ska bli mor till alla som lever.” 21Och Herren Gud gjorde kläder av djurhudar åt Adam och hans hustru.

22Herren Gud sa: ”Eftersom människan har blivit som en av oss, med kunskap om det goda och det onda, får hon inte ta och äta också av livets träd och så leva i evighet.” 23Därför visade Herren Gud ut dem ur Edens trädgård och skickade bort dem för att bruka den jord de hade skapats av. 24Herren drev ut människan och öster om Edens trädgård placerade han keruberna3:24 Himmelska väsen, som vanligen avbildas med vingar och som framträder med uppdrag att bl.a. beskydda det heliga (jfr t.ex. 2 Mos 25:18-22). och ett flammande svärd för att skydda vägen till livets träd.