Gẹnẹsisi 3 – YCB & NRT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 3:1-24

Ìṣubú ènìyàn

13.1: If 12.9; 20.2.Ejò sá à ṣe alárékérekè ju àwọn ẹranko igbó yòókù tí Olúwa Ọlọ́run dá lọ. Ó sọ fún obìnrin náà pé, “Ǹjẹ́ òtítọ́ ha ni Ọlọ́run wí pé, ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ èso èyíkéyìí lára àwọn igi tí ó wà nínú ọgbà’?”

2Obìnrin náà dá ejò lóhùn pé, “Àwa lè jẹ lára àwọn èso igi tí ó wà nínú ọgbà, 3ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ pé, ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ lára èso igi tí ó wà láàrín ọgbà, ẹ kò sì gbọdọ̀ fi ọwọ́ kàn án, bí ẹ̀yin bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin yóò kùú.’ ”

43.4: 2Kọ 11.3.Ejò wí fún obìnrin náà pé, “Ẹ̀yin kì yóò kú ikúkíkú kan.” 5“Nítorí Ọlọ́run mọ̀ wí pé, bí ẹ̀yin bá jẹ nínú rẹ̀, ojú yín yóò là, ẹ̀yin yóò sì dàbí Ọlọ́run, ẹ̀yin yóò sì mọ rere yàtọ̀ sí búburú.”

6Nígbà tí obìnrin náà rí i wí pé èso igi náà dára fún oúnjẹ àti pé, ó sì dùn ún wò, àti pé ó ń mú ni ní ọgbọ́n, ó mú díẹ̀ níbẹ̀, ó sì jẹ ẹ́. Ó sì mú díẹ̀ fún ọkọ rẹ̀, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, òun náà sì jẹ ẹ́. 7Nígbà náà ni ojú àwọn méjèèjì sì là, wọ́n sì mọ̀ pé àwọn wà ní ìhòhò; wọ́n sì rán ewé ọ̀pọ̀tọ́ pọ̀, wọ́n sì fi bo ara wọn.

8Nígbà náà ni ọkùnrin náà àti aya rẹ̀ gbọ́ ìró Olúwa Ọlọ́run bí ó ti ń rìn nínú ọgbà, nígbà tí ojú ọjọ́ tura, wọ́n sì fi ara pamọ́ kúrò níwájú Olúwa Ọlọ́run sí àárín àwọn igi inú ọgbà. 9Ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run ké pe ọkùnrin náà pé, “Níbo ni ìwọ wà?”

10Ó dáhùn pé, “Mo gbúròó rẹ̀ nínú ọgbà, ẹ̀rù sì bà mí, nítorí pé, mo wà ní ìhòhò, mo sì fi ara pamọ́.”

11Ọlọ́run wí pé, “Ta ni ó wí fún ọ pé ìhòhò ni ìwọ wà? Ṣé ìwọ ti jẹ nínú èso igi tí mo pàṣẹ fún ọ pé ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀ ni?”

12Ọkùnrin náà wí pé, “Obìnrin tí ìwọ fi fún mi, ni ó fún mi nínú èso igi náà, mo sì jẹ ẹ́.”

133.13: 2Kọ 11.3; 1Tm 2.14.Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run wí pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe yìí?”

Obìnrin náà dáhùn pé, “Ejò ni ó tàn mí jẹ, mo sì jẹ ẹ́.”

143.14,15: If 12.9; 20.2.Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run wí fún ejò náà pé, “Nítorí tí ìwọ ti ṣe èyí,

“Ègún ni fún ọ ju gbogbo ohun ọ̀sìn

àti gbogbo ẹranko igbó tókù lọ!

Àyà rẹ ni ìwọ yóò fi máa wọ́,

ìwọ yóò sì máa jẹ erùpẹ̀ ilẹ̀

ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.

153.15: If 12.17.Èmi yóò sì fi ọ̀tá

sí àárín ìwọ àti obìnrin náà,

àti sí àárín irú-ọmọ rẹ àti irú-ọmọ obìnrin náà;

òun yóò fọ́ orí rẹ,

ìwọ yóò sì bù ú jẹ ní gìgísẹ̀.”

16Ọlọ́run wí fún obìnrin náà pé:

“Èmi yóò fi kún ìrora rẹ ní àkókò ìbímọ;

ni ìrora ni ìwọ yóò máa bí ọmọ.

Ọ̀dọ̀ ọkọ rẹ ni ìfẹ́ rẹ yóò máa fà sí,

òun ni yóò sì máa ṣe àkóso rẹ.”

173.17,18: Hb 6.8.Ọlọ́run sì wí fún Adamu pé, “Nítorí pé ìwọ fetí sí aya rẹ, ìwọ sì jẹ nínú èso igi tí mo pàṣẹ fún ọ pé ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀,’

“Ègún ni fún ilẹ̀ nítorí rẹ;

nínú ọ̀pọ̀ làálàá ni ìwọ yóò jẹ nínú rẹ̀,

ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.

18Ilẹ̀ yóò sì hu ẹ̀gún àti èṣùṣú fún ọ,

ewéko igbó ni ìwọ yóò sì máa jẹ.

19Nínú òógùn ojú rẹ

ni ìwọ yóò máa jẹun

títí tí ìwọ yóò fi padà sí ilẹ̀,

nítorí inú ilẹ̀ ni a ti mú ọ jáde wá;

erùpẹ̀ ilẹ̀ sá à ni ìwọ,

ìwọ yóò sì padà di erùpẹ̀.”

20Adamu sì sọ aya rẹ̀ ní Efa nítorí òun ni yóò di ìyá gbogbo alààyè.

21Olúwa Ọlọ́run, sì dá ẹ̀wù awọ fún Adamu àti aya rẹ̀, ó sì fi wọ̀ wọ́n. 223.22,24: If 2.7; 22.2,14,19.Olúwa Ọlọ́run sì wí pé, “Ọkùnrin náà ti dàbí ọ̀kan lára wa, ó mọ rere àti búburú. A kò gbọdọ̀ jẹ́ kí ó na ọwọ́ rẹ̀ kí ó mú lára èso igi ìyè kí ó sì jẹ, kí ó sì wà láààyè títí láéláé.” 23Nítorí náà, Olúwa Ọlọ́run lé e kúrò nínú ọgbà Edeni láti lọ máa ro ilẹ̀ nínú èyí tí a ti mú un jáde wá. 24Lẹ́yìn tí ó ti lé ènìyàn jáde tán, ó fi àwọn Kérúbù àti idà iná tí ó ń kọ mọ̀nàmọ́ná síwájú àti sẹ́yìn láti ṣọ́ ọ̀nà tí ó lọ sí ibi igi ìyè, ní ìhà ìlà-oòrùn ọgbà Edeni.

New Russian Translation

Бытие 3:1-24

Начало греха

1Из всех диких зверей, которых создал Господь Бог, самым хитрым был змей. Он спросил женщину:

– Правда ли Бог сказал: «Не ешьте ни с какого дерева в саду»?

2Женщина ответила змею:

– Мы можем есть плоды с деревьев сада, 3но Бог сказал: «Не ешьте плодов с дерева, которое посередине сада, и не трогайте их, иначе вы умрете».

4– Нет, вы не умрете, – сказал змей женщине. 5– Просто Бог знает, что когда вы съедите их, ваши глаза откроются, и вы станете как Бог3:5 Или: «как боги»., познав добро и зло3:5 Или: «узнав все», также в ст. 3:22..

6Тогда женщина увидела, что плод дерева был хорош в пищу и приятен на вид, и что дерево было желанно, как источник мудрости; и она взяла один из плодов и съела. Она дала плод и мужу, который был с ней, и он ел его. 7Их глаза открылись, и они поняли, что наги; тогда они сшили себе повязки из листьев инжира.

8Подул ветерок3:8 Букв.: «В ветре дня». Это выражение указывает на вечернюю прохладу. Однако слово, стоящее в тексте оригинала, переводится и как ветер, и как дух, и потому оно здесь также говорит о приближении Бога., и они услышали, как Господь Бог ходит3:8 Они услышали, как Господь Бог ходит – или: «Они услышали голос Господа Бога, ходящего, … ». по саду. Адам и его жена спрятались от Господа Бога среди деревьев сада, 9но Господь Бог воззвал к Адаму:

– Где ты?

10Адам ответил:

– Я услышал Тебя3:10 Я услышал Тебя – или: «Я услышал Твой голос». в саду и испугался, потому что я наг, вот я и спрятался.

11Он спросил:

– Кто сказал тебе, что ты наг? Ты ел плоды дерева, с которого Я запретил тебе есть?

12Адам ответил:

– Женщина, которую Ты дал мне, чтобы она была со мной, – это она дала мне плод с того дерева, и я съел его.

13Тогда Господь Бог сказал женщине:

– Что же ты сделала?

Женщина ответила:

– Змей обманул меня, вот я и ела.

14Тогда Господь Бог сказал змею:

– За то, что ты сделал это,

проклят ты больше любого скота

и всех диких зверей!

Ты будешь ползать на брюхе,

ты будешь есть прах

во все дни твоей жизни.

15Я положу вражду

между тобой и женщиной

и между твоим потомком и ее потомком3:15 Еврейский термин «семя» – ключевой термин в Ветхом Завете. Он имеет форму единственного числа, но может указывать как на одного потомка человека, так и на все его потомство в целом. Весьма вероятно, что в большинстве случаев эта двусмысленность применялась намеренно. В данном переводе этот термин либо переводится буквально как «семя», либо как «потомок», «потомки» или «потомство» в зависимости от текстуального и богословского контекста.:

он будет поражать тебя в голову,

а ты будешь жалить его в пяту3:15 Эти слова служат пророчеством об Иисусе Христе (см. Гал. 4:4; 1 Ин. 3:8)..

16А женщине Он сказал:

– Я мучительной сделаю беременность твою:

в страдании ты будешь рожать детей.

Ты будешь желать мужа,

и он будет властвовать над тобою.

17Адаму же Он сказал:

– Так как ты послушался жены и съел плод с дерева,

о котором Я велел тебе: «Не ешь от него»,

проклята из-за тебя земля:

в тяжком труде ты будешь питаться от нее

во все дни твоей жизни.

18Она произрастит тебе колючки и сорняки,

ты будешь питаться полевыми злаками.

19В поте лица своего ты будешь есть свой хлеб,

пока не вернешься в землю,

из которой был взят;

потому что ты – прах,

и в прах ты вернешься.

20Адам назвал свою жену Ева3:20 Возможное значение этого имени (евр.: «Хавва»): «жизнь»., потому что она стала матерью всех живущих.

21Господь Бог сделал одежды из кожи и одел в них Адама и его жену. 22Потом Господь Бог сказал:

– Познав добро и зло, человек стал теперь как один из Нас. Нельзя, чтобы он протянул руку, и, сорвав плод также и с дерева жизни, съел его и стал жить вечно.

23И Господь Бог изгнал его из сада Эдем, чтобы он трудился на земле, из которой был взят. 24Изгнав человека, Он поставил на востоке от сада3:24 Или: «перед садом». Эдем херувимов3:24 Херувим – один из высших ангельских чинов. и вращающийся пламенный меч, чтобы охранять путь к дереву жизни.