Gẹnẹsisi 26 – YCB & CARSA

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 26:1-35

Isaaki àti Abimeleki

1Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, yàtọ̀ fún èyí tí ó mú ní ìgbà ayé Abrahamu, Isaaki sì lọ sọ́dọ̀ Abimeleki ọba àwọn Filistini ni Gerari. 2Olúwa sì fi ara han Isaaki, ó sì wí pé, “Má ṣe sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti: Jókòó ní ilẹ̀ tí èmi ó fún ọ. 326.3,4: Gẹ 22.16-18.Máa ṣe àtìpó ní ilẹ̀ yìí fún ìgbà díẹ̀, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ, Èmi yóò sì bùkún fún ọ. Nítorí ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ni èmi yóò fi gbogbo àwọn ilẹ̀ wọ̀nyí fún, èmi yóò sì fi ìdí ìbúra tí mo ṣe fún Abrahamu baba rẹ múlẹ̀. 4Èmi yóò sọ ìran rẹ di púpọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, èmi yóò sì fi gbogbo ilẹ̀ yìí fún irú àwọn ọmọ rẹ, àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, 5nítorí tí Abrahamu gba ohùn mi gbọ́, ó sì pa gbogbo ìkìlọ̀, àṣẹ, ìlànà àti òfin mi mọ́.” 6Nítorí náà Isaaki jókòó ní Gerari.

726.7: Gẹ 12.13; 20.2.Nígbà tí àwọn ọkùnrin ìlú náà bi í léèrè ní ti aya rẹ̀, ó sì wí pé, “Arábìnrin mi ní í ṣe,” nítorí tí ó bẹ̀rù láti jẹ́wọ́ wí pé, “Aya mi ni.” Ó ń rò wí pé, “Kí àwọn ọkùnrin ibẹ̀ náà má ba à pa mí nítorí Rebeka, nítorí tí òun ní ẹwà púpọ̀.”

8Nígbà tí Isaaki sì ti wà níbẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, Abimeleki ọba Filistini yọjú lójú fèrèsé, ó sì rí Isaaki ń bá Rebeka aya rẹ̀ tage. 9Nígbà náà ni Abimeleki ránṣẹ́ pe Isaaki ó sì wí fun pé, “Nítòótọ́, aya rẹ ni obìnrin yìí í ṣe, èéṣe tí ìwọ fi wí fún wa pé arábìnrin mi ni?”

Isaaki sì fèsì pé, “Nítorí mo rò pé mo le pàdánù ẹ̀mí mi nítorí rẹ̀.”

10Nígbà náà ni Abimeleki dáhùn pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Bí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá ti bá a lòpọ̀ ńkọ́? Ìwọ ìbá wá mú ẹ̀bi wá sórí wa.”

11Nígbà náà ni Abimeleki pàṣẹ fún gbogbo ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin yìí tàbí aya rẹ̀ yóò jẹ̀bi ikú.”

12Ní ọdún náà, Isaaki gbin ohun ọ̀gbìn sí ilẹ̀ náà, ó sì kórè rẹ̀ ní ìlọ́po ọgọ́ọ̀rún ni ọdún kan náà, nítorí Ọlọ́run bùkún un. 13Ọkùnrin náà sì di ọlọ́rọ̀ púpọ̀, ọrọ̀ rẹ̀ sì ń pọ̀ si, títí ó fi di ènìyàn ńlá. 14Ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn àti agbo ẹran àti àwọn ìránṣẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn Filistini ń ṣe ìlara rẹ̀. 15Nítorí náà àwọn ará Filistini ru erùpẹ̀ di gbogbo kànga tí àwọn ìránṣẹ́ Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́.

16Nígbà náà ni Abimeleki wí fún Isaaki pé, “Jáde kúrò ní ilẹ̀ wa, nítorí tí ìwọ ti di alágbára púpọ̀ jù wá lọ.”

17Isaaki sì ṣí kúrò níbẹ̀, ó sì pàgọ́ sí Àfonífojì Gerari ó sì ń gbé ibẹ̀. 18Isaaki sì ṣe àtúngbẹ́ àwọn kànga tí Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́ nígbà ayé rẹ̀, èyí tí àwọn Filistini ti dí lẹ́yìn ikú Abrahamu baba rẹ̀, ó sì fún wọn lórúkọ tí baba rẹ̀ ti sọ wọ́n tẹ́lẹ̀.

19Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki sì gbẹ́ kànga ní àfonífojì náà, wọ́n kan ìsun omi níbẹ̀. 20Ṣùgbọ́n àwọn darandaran Gerari ń bá àwọn darandaran Isaaki jà sí kànga náà pé àwọn ni àwọn ni í. Nítorí náà ni ó fi pe orúkọ kànga náà ní Eseki, nítorí pé wọ́n bá a jà sí kànga náà. 21Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki tún gbẹ́ kànga mìíràn, wọ́n sì tún jà nítorí rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Sitna (kànga àtakò). 22Ó sì tún kúrò níbẹ̀, ó sì gbẹ́ kànga mìíràn, wọn kò sì jásí èyí rárá, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Rehoboti, ó wí pé, “Nísinsin yìí, Olúwa ti fi ààyè gbà wá, a ó sì gbilẹ̀ si ní ilẹ̀ náà.”

23Láti ibẹ̀, ó kúrò lọ sí Beerṣeba 24Ní òru ọjọ́ tí ó dé ibẹ̀, Olúwa sì fi ara hàn án, ó sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run Abrahamu baba rẹ: Má ṣe bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùsi fún ọ, èmi yóò sì sọ iye ìran rẹ di púpọ̀, nítorí Abrahamu ìránṣẹ́ mi.”

25Isaaki sì kọ́ pẹpẹ kan síbẹ̀, ó sì pe orúkọ Olúwa. Níbẹ̀ ni ó pàgọ́ rẹ̀ sí, àwọn ìránṣẹ́ rẹ sì gbẹ́ kànga kan níbẹ̀.

2626.26: Gẹ 21.22.Nígbà náà ni Abimeleki tọ̀ ọ́ wá láti Gerari, àti Ahussati, olùdámọ̀ràn rẹ̀ àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀. 27Isaaki sì bi wọ́n léèrè pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin tọ̀ mí wá, níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀yin kórìíra mi tí ẹ sì lé mi jáde kúrò lọ́dọ̀ yín?”

28Wọ́n dáhùn pé, “A rí i dájú pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nítorí náà ni a fi rò ó wí pé, ó yẹ kí májẹ̀mú kí o wà láàrín àwa àti ìwọ. Jẹ́ kí a ṣe àdéhùn 29pé ìwọ kì yóò ṣe wá ní ibi, bí àwa pẹ̀lú kò ti ṣe ọ́ ní aburú, tí a sì ń ṣe ọ́ dáradára, tí a sì rán ọ jáde ní àlàáfíà láìṣe ọ́ ní ibi, kíyèsi Olúwa sì ti bùkún fún ọ.”

30Isaaki sì ṣe àsè fún wọn, wọn sì jẹ, wọ́n sì mu. 31Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì wọn búra fún ara wọn. Isaaki sì rán wọn lọ, wọ́n sì lọ ní àlàáfíà.

32Ní ọjọ́ náà gan an ni àwọn ìránṣẹ́ Isaaki wá sọ fún un pé àwọn ti kan omi ní kànga kan tí àwọn gbẹ́. 3326.33: Gẹ 21.31.Ó sì pe orúkọ kànga náà ní Ṣiba (kànga májẹ̀mú), títí di òní olónìí, orúkọ ìlú náà ni Beerṣeba.

34Nígbà tí Esau pé ọmọ ogójì ọdún (40) ó fẹ́ ọmọbìnrin kan tí a ń pè ní Juditi, ọmọ Beeri, ará Hiti, ó sì tún fẹ́ Basemati, ọmọ Eloni ará Hiti. 35Fífẹ́ tí a fẹ́ àwọn obìnrin wọ̀nyí jẹ́ ìbànújẹ́ fún Isaaki àti Rebeka.

Священное Писание (Восточный перевод), версия с «Аллахом»

Начало 26:1-35

Исхак и Рабига у Ави-Малика

1В земле был голод, – не тот прежний голод, который был при Ибрахиме, – и Исхак пошёл к Ави-Малику, царю филистимлян, в Герар. 2Вечный явился Исхаку и сказал:

– Не иди в Египет; живи на той земле, где Я скажу тебе жить. 3Поселись на этой земле на время, и Я буду с тобой и благословлю тебя, потому что Я исполню клятву, которую дал твоему отцу Ибрахиму, и дам все эти земли тебе и твоим потомкам. 4Я сделаю твоё потомство многочисленным, как звёзды на небе, и дам им все эти земли, и через твоё потомство26:4 Или: «семя». получат благословение все народы на земле, 5потому что Ибрахим слушался Меня и хранил Мои повеления, заповеди, уставы и законы.

6И Исхак поселился в Гераре. 7Когда жители того места спросили у него о его жене, он сказал: «Это моя сестра», потому что боялся сказать: «Это моя жена». Он думал: «Жители этого места могут убить меня из-за Рабиги, потому что она красива».

8Однажды, когда Исхак уже долгое время прожил там, Ави-Малик, царь филистимлян, выглянул из окна и увидел, как Исхак ласкает свою жену Рабигу. 9Ави-Малик вызвал Исхака и сказал:

– Итак, она твоя жена! Почему же ты сказал: «Она моя сестра»?

Исхак ответил ему:

– Потому что я думал, что могу за неё поплатиться жизнью.

10Тогда Ави-Малик сказал:

– Что же ты сделал с нами? Один из мужчин мог лечь с твоей женой, и ты навлёк бы на нас вину.

11Ави-Малик приказал всему народу:

– Всякий, кто тронет этого человека или его жену, непременно будет предан смерти.

Спор с филистимлянами о колодцах

12Исхак засеял поля в той земле и в тот же год собрал урожай стократно, и Вечный благословил его: 13он разбогател, и состояние его всё росло, пока он не стал очень богатым. 14У него были такие большие стада мелкого и крупного скота и столько слуг, что филистимляне завидовали ему. 15Они засыпали землёй все колодцы, которые ещё во времена его отца выкопали слуги отца его Ибрахима.

16И Ави-Малик сказал Исхаку:

– Уходи от нас; ты стал слишком силён для нас.

17Исхак ушёл оттуда, поселился в Герарской долине и обосновался там. 18Исхак расчистил колодцы, которые были выкопаны во времена его отца Ибрахима, а затем засыпаны филистимлянами после его смерти, и дал им те же названия, какие прежде дал его отец.

19Слуги Исхака стали копать в долине и открыли там колодец с родниковой водой, 20но герарские пастухи затеяли ссору с пастухами Исхака, говоря: «Это наша вода!» Исхак назвал колодец Есек («спор»), потому что они спорили с ним. 21Потом они выкопали другой колодец, но и из-за него вышла ссора, поэтому он назвал его Ситна («вражда»). 22Он ушёл оттуда и выкопал ещё один колодец, из-за которого ссоры не было, и он назвал его Реховот («просторные места»), говоря: «Теперь Вечный дал нам место, и мы умножимся в этой земле».

23Он направился оттуда в Беэр-Шеву. 24В ту ночь Вечный явился ему и сказал:

– Я – Бог твоего отца Ибрахима. Не бойся, потому что Я с тобой; Я благословлю тебя и увеличу число твоих потомков ради Моего раба Ибрахима.

25Исхак построил там жертвенник и призвал имя Вечного и поставил там шатёр, а его слуги выкопали колодец.

26Ави-Малик пришёл к нему из Герара вместе с Ахуззатом, своим личным советником, и Фихолом, начальником его войска. 27Исхак спросил их:

– Зачем вы пришли, ведь вы были враждебны ко мне и прогнали меня?

28Они ответили:

– Теперь нам ясно, что с тобой Вечный, и мы решили: у нас должно быть клятвенное соглашение, между нами и тобой. Давай заключим договор, 29что ты не причинишь нам вреда, как и мы не тронули тебя, но всегда обходились с тобой хорошо и отпустили тебя с миром. А теперь ты благословлён Вечным.

30Исхак устроил для них пир, и они ели и пили. 31На другой день рано утром они дали друг другу клятву; Исхак простился с ними, и они ушли от него с миром.

32В тот же день слуги Исхака пришли и рассказали ему о колодце, который они выкопали. Они сказали:

– Мы нашли воду!

33Он назвал его Шева («клятва»), и до сего дня имя этого города – Беэр-Шева («колодец клятвы», «колодец семи»).

Жёны Есава

34Когда Есаву было сорок лет, он женился на Иегудифи, дочери хетта Беэри, и на Басемафе, дочери хетта Елона; 35и от них было много огорчения Исхаку и Рабиге.