Gẹnẹsisi 24 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 24:1-67

Isaaki àti Rebeka

1Abrahamu sì ti di arúgbó ní àkókò yìí, Olúwa sì ti bùkún fún un ni gbogbo ọ̀nà, 2Abrahamu wí fún olórí àwọn ìránṣẹ́ ilẹ̀ rẹ̀, tí ó jẹ́ alábojútó ohun gbogbo tí ó ní pé, “Fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi. 3Èmi yóò mú ọ búra lórúkọ Olúwa Ọlọ́run ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ kì yóò fẹ́ aya fún ọmọ mi nínú àwọn ọmọbìnrin ará Kenaani, láàrín àwọn ẹni tí èmi ń gbé. 4Ṣùgbọ́n, ìwọ yóò lọ sí orílẹ̀-èdè mi, láàrín àwọn ará mi láti fẹ́ aya fún Isaaki, ọmọ mi.”

5Ìránṣẹ́ náà bi í wí pé, “Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà bá kọ̀ láti bá mi wá sí ilẹ̀ yìí ńkọ́? Ǹjẹ́ mo lè mú ọmọ rẹ padà lọ sí orílẹ̀-èdè níbi tí ìwọ ti wá?”

6Abrahamu sì wí fún un pé, “Rí i dájú pé ìwọ kò mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.” 7Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run tí ó mú mi jáde láti ilẹ̀ baba mi àti ní ilẹ̀ tí a bí mi, tí ó bá mi sọ̀rọ̀ tí ó sì búra fún mi pé, ‘Irú-ọmọ rẹ ni n ó fi ilẹ̀ yìí fún,’ yóò rán angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ, kí ìwọ kí ó lè rí aya fẹ́ wá fún ọmọ mi láti ibẹ̀. 8Bí obìnrin náà kò bá fẹ́ tẹ̀lé ọ wá, nígbà náà ni a tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ìbúra yìí, ṣùgbọ́n pàtàkì ni pé ìwọ kò gbọdọ̀ mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.” 9Ìránṣẹ́ náà sì fi ọwọ́ rẹ̀ sí abẹ́ itan Abrahamu olúwa rẹ̀, ó sì búra fún nítorí ọ̀rọ̀ náà.

10Ìránṣẹ́ náà sì mú ìbákasẹ mẹ́wàá, pẹ̀lú onírúurú ohun dáradára láti ọ̀dọ̀ olúwa rẹ̀, ó sì dìde ó sì lọ sí Aramu-Naharaimu, sí ìlú Nahori, 11Ó sì mú àwọn ìbákasẹ náà kúnlẹ̀ nítòsí kànga lẹ́yìn ìlú, ó ti ń di ọwọ́ ìrọ̀lẹ́ ní àkókò tí àwọn obìnrin máa ń lọ pọn omi.

12Ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa à mi; jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lónìí, sì fi àánú hàn fún Abrahamu olúwa mi. 13Kíyèsi i, mo dúró ní ẹ̀bá kànga omi yìí, àwọn ọmọbìnrin ìlú yìí sì ń jáde wá pọn omi. 14Jẹ́ kí ó ṣe pé nígbà tí mo bá wí fún ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin pe, ‘Jọ̀wọ́ sọ ládugbó rẹ kalẹ̀, kí n le mu omi,’ tí ó bá sì wí pé, ‘mu ún, èmi ó sì fún àwọn ìbákasẹ rẹ náà mu pẹ̀lú,’ jẹ́ kí ó ṣe èyí tí o yàn fún ìránṣẹ́ rẹ Isaaki. Nípa èyí ni n ó fi mọ̀ pé o ti fi àánú hàn fún olúwa mi.”

15Kí o tó di pé, ó parí àdúrà, Rebeka dé pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀. Ọmọ Betueli ni. Betueli yìí ni Milka bí fún Nahori arákùnrin Abrahamu. 16Ọmọbìnrin náà rẹwà, wúńdíá ni, kò sì tí ì mọ ọkùnrin, ó lọ sí ibi ìsun omi náà, ó sì pọn omi sínú ìkòkò omi, ó sì gbé e, ó ń gòkè bọ̀ kúrò níbi omi.

17Ìránṣẹ́ náà súré lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fun un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ni omi díẹ̀ nínú ìkòkò omi rẹ.”

18Òun náà dáhùn pé, “Mu, olúwa mi,” ó sì yára sọ ìkòkò omi náà ka ọwọ́ rẹ̀, ó sì fún un mu.

19Lẹ́yìn tí ó ti fún un ni omi mu tán, ó wí pé, “Èmi ó bu omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú títí wọn yóò fi mu àmutẹ́rùn.” 20Ó sì yára da omi inú ìkòkò omi rẹ̀ sínú ìbùmu, ó sáré padà lọ sí ibi omi láti pọn sí i wá fún àwọn ìbákasẹ, títí tí ó fi pọn fún gbogbo wọn. 21Láìsọ ọ̀rọ̀ kan, ìránṣẹ́ yìí ń wo ọmọbìnrin náà fínní fínní láti mọ̀ bóyá Ọlọ́run ti ṣe ìrìnàjò òun ní rere tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.

22Lẹ́yìn tí àwọn ìbákasẹ náà ti mu omi tán, ni ọkùnrin náà mú òrùka wúrà ààbọ̀ ìwọ̀n ṣékélì àti júfù méjì fún ọwọ́ rẹ̀, tí ìwọ̀n ṣékélì wúrà mẹ́wàá. 23Lẹ́yìn náà, ó béèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ í ṣe? Jọ̀wọ́ wí fún mi, ǹjẹ́ ààyè wà ní ilé baba rẹ láti wọ̀ sí ní alẹ́ yìí?”

24Ó dáhùn pé, “Betueli ọmọ tí Milka bí fún Nahori ni baba mi” 25Ó sì fi kún un pé, “Àwa ní koríko àti ṣakaṣaka tó pẹ̀lú, àti ààyè láti wọ̀ sí.”

26Nígbà náà ni ọkùnrin náà tẹríba, ó sì sin Olúwa, 27wí pe, “Olùbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi ti kò jẹ́ kí àánú àti òtítọ́ rẹ̀ kí ó yẹ̀ lọ́dọ̀ olúwa mi. Ní ti èmi Olúwa ti darí ìrìnàjò mi sí ilé ìbátan olúwa mi.”

28Ọmọbìnrin náà sì sáré, ó sì lọ sọ ohun gbogbo wọ̀nyí fún àwọn ará ilé ìyá rẹ̀. 29Rebeka ní arákùnrin tí ń jẹ́ Labani; Labani sì sáré lọ bá ọkùnrin náà ní etí odò. 30Bí ó sì ti rí òrùka imú àti ẹ̀gbà ní ọwọ́ arábìnrin rẹ̀ tí ó sì tún gbọ́ ohun tí Rebeka sọ pé ọkùnrin náà sọ fún òun, ó jáde lọ bá ọkùnrin náà, ó sì bá a, ó dúró ti ìbákasẹ wọ̀n-ọn-nì ní ẹ̀bá ìsun omi. 31Ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Wá, ìwọ ẹni ìbùkún Olúwa, Èéṣe tí o dúró sí ìta níhìn-ín? Mo ti pèsè ààyè sílẹ̀ fún ọ àti ààyè fún àwọn ìbákasẹ rẹ.”

32Ọkùnrin náà sì bá Labani lọ ilé, ó sì tú ẹrù orí ìbákasẹ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fún wọn ni koríko àti oúnjẹ. Ó sì bu omi fún ọkùnrin náà àti àwọn arákùnrin rẹ̀ láti wẹ ẹsẹ̀ wọn. 33Wọ́n sì gbé oúnjẹ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n, ó wí pé, “Èmi kò ní jẹun àyàfi bí mo bá sọ ohun tí mo ní í sọ.”

Labani sì wí pé, “Kò burú, sọ ọ́.”

34Nítorí náà, ó wí pé, “ìránṣẹ́ Abrahamu ni èmi. 35Olúwa sì ti bùkún olúwa mi gidigidi. Ó sì ti di ọlọ́rọ̀, Ó sì ti fún un ní àgùntàn, màlúù, àti fàdákà àti wúrà, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin àti ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. 36Sara aya olúwa mi sì ti bí ọmọkùnrin kan fún un, ní ìgbà ogbó rẹ̀, olúwa mi sì ti fún ọmọ náà ní ohun gbogbo tí ó ní. 37Olúwa mi sì ti mú mi búra wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani, ní ilẹ̀ ibi tí èmi ń gbé, 38Ṣùgbọ́n lọ sí ìdílé baba mi láàrín àwọn ìbátan mi kí o sì fẹ́ aya fún ọmọ mi.’

39“Mo sì bí olúwa mi léèrè pé, ‘Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà kò bá fẹ́ bá mi wá ńkọ́?’

40“Ó sì dáhùn wí pé, ‘Olúwa, níwájú ẹni tí èmi ń rìn yóò rán Angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ yóò sì jẹ́ kí o ṣe àṣeyọrí ní ìrìnàjò rẹ, kí ìwọ kí ó ba le fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ìbátan mi, àti láàrín àwọn ìdílé baba mi. 41Nígbà tí ìwọ bá lọ sí ọ̀dọ̀ ìdílé baba mi (gẹ́gẹ́ bí mo tí wí), nígbà náà ni ìwọ tó bọ́ nínú ìbúra yìí.’

42“Nígbà tí mo dé ibi ìsun omi lónìí, mo wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, bí ìwọ bá fẹ́, jọ̀wọ́ jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lórí ohun tí mo bá wá yìí, 43Wò ó, mo dúró ní ẹ̀bá ìsun omi yìí, kí ó ṣe pé, nígbà tí wúńdíá kan bá jáde wá pọn omi, tí èmi sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ìwọ̀nba omi díẹ̀ mu nínú ládugbó rẹ,” 44tí ó bá sì wí fún mi pé, “Mu ún, èmi yóò sì tún pọn omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú,” Jẹ́ kí ẹni náà jẹ́ ẹni tí Olúwa yàn fún ọmọ Abrahamu, olúwa mi.’

45“Kí n sì tó gbàdúrà tán nínú ọkàn mi, Rebeka jáde wá pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀, ó sì lọ sí ibi ìsun omi ó sì pọn omi. Mo sì wí fun un pé, ‘Jọ̀wọ́ fún mi ni omi mu.’

46“Kíákíá ni ó sọ ìkòkò rẹ̀ kalẹ̀ láti èjìká rẹ̀, ó sì wí fún mi pé, ‘Mu ún, èmi yóò sì tún fún àwọn ìbákasẹ rẹ mu pẹ̀lú.’ Mo sì mu, ó sì tún fún àwọn ìbákasẹ mi mu pẹ̀lú.

47“Mo béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, ‘Ọmọ ta ní ìwọ í ṣe?’

“Ó sì wí fún mi pé, ‘ọmọbìnrin Betueli tí í ṣe ọmọ Nahori ni òun, Milka sì ni ìyá òun.’

“Nígbà náà ni mo fi òrùka náà bọ imú rẹ̀, mo sì fi ẹ̀gbà ọwọ́ náà si ní ọwọ́. 48Èmi sì tẹríba, mo sì wólẹ̀ fún Olúwa, mó sì fi ìbùkún fún Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, ẹni tí ó mú mi tọ ọ̀nà títọ́ láti rí ọmọ ọmọ arákùnrin olúwa mi mú wá fún ọmọ rẹ̀. 49Ǹjẹ́ nísinsin yìí bí ẹ̀yin yóò bá fi inú rere àti òtítọ́ bá olúwa mi lò, ẹ sọ fún mi, bí bẹ́ẹ̀ sì kọ́, ẹ sọ fún mi, kí ń le è mọ ọ̀nà tí èmi yóò yà sí.”

50Labani àti Betueli sì dáhùn pé, “Lọ́dọ̀ Olúwa ni èyí ti wá, nítorí náà àwa kò le sọ rere tàbí búburú fún ọ. 51Rebeka nìyí, mú un kí ó máa lọ, kí ó sì di aya ọmọ olúwa à rẹ, bí Olúwa ti fẹ́.”

52Nígbà tí ọmọ ọ̀dọ̀ Abrahamu gbọ́ ohun tí wọ́n wí, ó wólẹ̀ níwájú Olúwa. 53Nígbà náà ni ó kó ohun èlò wúrà àti fàdákà jáde àti aṣọ, ó sì fi wọ́n fún Rebeka, ó fún arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ ní ẹ̀bùn olówó iyebíye pẹ̀lú. 54Lẹ́yìn náà ni òun àti àwọn ọkùnrin tí ó bá a wá tó jẹ, tí wọ́n sì mu, tí wọn sì sùn níbẹ̀ ní òru ọjọ́ náà.

Bí wọ́n ti dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó wí pé, “Ẹ rán mi padà lọ sí ọ̀dọ̀ olúwa mi.”

55Ṣùgbọ́n arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ fèsì pé, “A fẹ́ kí Rebeka wà pẹ̀lú wa fún nǹkan bí ọjọ́ mẹ́wàá sí i, lẹ́yìn èyí, ìwọ le máa mu lọ.”

56Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá mi dúró, Olúwa sá à ti ṣe ọ̀nà mi ní rere. Ẹ rán mi lọ, kí èmi kí ó le è tọ olúwa à mi lọ.”

57Nígbà náà ni wọ́n sọ pé, “Jẹ́ kí a pe ọmọ náà gan an kí a sì bi í” 58Wọ́n sì pe Rebeka wọ́n sì bi í, wí pé, “Ṣe ìwọ yóò bá ọkùnrin yìí lọ.”

Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi yóò lọ.”

59Wọ́n sì gbà kí Rebeka àti olùtọ́jú rẹ̀, pẹ̀lú ìránṣẹ́ Abrahamu àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ máa lọ. 60Wọ́n sì súre fún Rebeka, wọn sì wí fun un pé,

“Ìwọ ni arábìnrin wa,

ìwọ yóò di ìyá ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún;

Ǹjẹ́ kí àwọn irú-ọmọ rẹ

kí ó ni ẹnu ibodè ọ̀tá wọn.”

61Nígbà náà ni Rebeka àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ múra, wọn sì gun àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì bá ọkùnrin náà padà lọ. Ìránṣẹ́ náà sì mú Rebeka, ó sì bá tirẹ̀ lọ.

62Isaaki sì ń ti ọ̀nà kànga Lahai-Roi bọ, nítorí ìhà gúúsù ni ó ń gbé. 63Isaaki sì jáde lọ sí oko ni ìrọ̀lẹ́ láti ṣe àṣàrò, bí ó sì ti gbé ojú sókè, ó rí àwọn ìbákasẹ tí ń bọ̀ wá. 64Rebeka pẹ̀lú sì gbójú sókè, ó sì rí Isaaki. Ó sọ̀kalẹ̀ lórí ìbákasẹ, 65Ó sì béèrè lọ́wọ́ ìránṣẹ́ náà wí pé, “Ta ni ọkùnrin tí ń bọ̀ wá pàdé wa láti inú oko?”

Ìránṣẹ́ náà sì wí fun un pé, “Olúwa mi ni,” nítorí náà ni Rebeka mú ìbòjú, ó sì bo ojú rẹ̀.

66Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà ròyìn fún Isaaki ohun gbogbo tí ó ti ṣe. 67Nígbà náà ni Isaaki mú Rebeka wọ inú àgọ́ ìyá rẹ̀, Sara, ó sì di aya rẹ̀, ó sì fẹ́ràn rẹ̀; ó sì jẹ́ ìtùnú fún Isaaki lẹ́yìn ikú ìyá rẹ̀.

Swedish Contemporary Bible

1 Moseboken 24:1-67

Isak gifter sig med Rebecka

1Abraham var nu en mycket gammal man och Gud hade välsignat honom på alla sätt. 2Abraham sa till sin förvaltare och äldste tjänare: ”Lägg din hand under min höft och 3svär24:3 En sedvänja när man svor en ed som återkommer i Gamla testamentet. Den exakta innebörden har gått förlorad. vid Herren, himlens och jordens Gud, att du inte tar en hustru åt min son av de kanaaneiska flickorna på orten där jag nu bor! 4Gå i stället till mitt hemland, till mina släktingar, och ta en hustru åt min son Isak där!”

5”Men om jag inte kan hitta en flicka som vill följa med mig till det här landet?” frågade tjänaren, ”ska jag då ta med din son dit, tillbaka till det land som du kommer ifrån?” 6”Nej, det får du inte göra vad som än händer”, svarade Abraham. 7Herren, himlens Gud, förde mig bort från mitt hem, mina fäders land, och svor under ed att ge mig och mina ättlingar detta land. Han ska skicka sin ängel framför dig, och du ska finna en flicka därifrån som kan bli min sons hustru. 8Om hon inte vill följa med dig är du fri från denna ed, men under inga omständigheter får du ta med dig min son dit.”

9Tjänaren lade då handen under sin herre Abrahams höft och svor en ed att göra så. 10Han tog med sig tio av sin husbondes kameler, lastade med gåvor av allt det bästa hans husbonde ägde, och reste till den stad där Nachor bodde, i Aram Naharajim24:10 Aram Naharajim betyder Aram vid de två floderna. Man tror att staden låg mellan Eufrat och Tigris, i nordvästra Mesopotamien. Den grekiska översättningen av Aram Naharajim är också helt enkelt Mesopotamien.. 11Där lät han kamelerna lägga sig ner bredvid en källa utanför staden. Det var kväll och byns kvinnor kom ut för att hämta vatten.

12Herre, min husbonde Abrahams Gud”, bad han, ”visa att du är god mot min husbonde Abraham och hjälp mig att lyckas. 13Här står jag nu bredvid denna källa och byns flickor kommer ut för att hämta vatten. 14Om jag ber en av dem: ’Låna mig din kruka så att jag får dricka’ och hon då säger: ’Javisst, och jag ska ge vatten åt dina kameler också’, så låt det då vara den som du har utsett till din tjänare Isak. Då vet jag att du har visat godhet mot min husbonde.”

15Innan han knappt hunnit be färdigt, kom Rebecka, dotter till Betuel, son till Milka, Abrahams bror Nachors hustru, med en vattenkruka på sin axel. 16Hon var mycket vacker och orörd, ingen man hade haft henne. Hon gick ner till källan, fyllde sin kruka och kom upp igen. 17Tjänaren skyndade fram till henne och bad om vatten att dricka.

18”Javisst, min herre”, sa hon och böjde snabbt ner krukan åt honom så att han kunde dricka. 19Sedan sa hon: ”Jag ska hämta vatten åt dina kameler också, så att de kan dricka sig otörstiga.”

20Hon tömde krukan i vattenhon och sprang ner till källan igen och fortsatte att bära vatten åt kamelerna, tills de slutligen hade fått nog. 21Tjänaren betraktade henne tyst för att se om Herren låtit hans färd lyckas eller inte. 22När kamelerna hade slutat dricka, tog han fram en näsring av guld som vägde en halv sikel24:22 Se not till 20:16., och två guldarmband som vägde tio siklar.

23”Säg mig, vems dotter är du?” frågade han. ”Kan det vara så att din far har någon plats, där han kan ta emot oss över natten?” 24”Min far heter Betuel, son till Milka och hennes man Nachor”, svarade hon, 25och fortsatte: ”Vi har gott om halm och mat åt kamelerna, och gästrum har vi också.”

26Då föll mannen ner på marken och tillbad Herren 27och sa: ”Lovad vare Herren, min herre Abrahams Gud, som inte har upphört med att visa sin godhet och trofasthet gentemot min herre! Och mig har Herren lett till en familj som är släkt med min husbonde.”

28Flickan sprang hem för att berätta för sin mor och sina närmaste vad som hänt. 29Rebeckas bror Laban skyndade sig ut till mannen vid källan. 30Laban hade sett näsringen och ringarna på sin systers armar och hört henne berätta vad mannen sagt till henne. Då kom han nu till mannen som fortfarande stod med sina kameler vid källan. 31Laban sa till honom: ”Kom, du Herrens välsignade! Varför står du här ute? Vi har redan gjort i ordning ett rum åt dig. Och plats finns också för dina kameler.”

32Då följde mannen med till huset. Man lastade av kamelerna och gav dem halm och foder. Sedan gav han vatten åt Abrahams tjänare och hans medresenärer, så att de kunde tvätta sina fötter. 33När maten serverades sa mannen: ”Jag tänker inte äta förrän jag har berättat för er varför jag är här!” Laban sa: ”Ja, naturligtvis. Berätta ditt ärende!”

34”Jag är Abrahams tjänare”, förklarade han. 35Herren har välsignat min husbonde mycket och gett honom en stor rikedom, får och boskapshjordar, silver och guld, slavar och slavinnor, kameler och åsnor.

36När Sara, min husbondes hustru, var mycket gammal, födde hon en son åt honom, och min husbonde har gett honom allt han äger. 37Nu har min husbonde fått mig att svära på att inte låta sin son gifta sig med någon av flickorna i Kanaan, det land där min husbonde bor. 38Därför skulle jag bege mig hit till hans fars familj och hans egen släkt, för att hämta en flicka härifrån, som kan gifta sig med hans son. 39Jag frågade då min herre: ’Men om jag inte kan hitta en flicka som vill komma med mig?’ 40Han svarade: ’Herren, i vars gemenskap jag har levt, ska skicka sin ängel med dig och se till att ditt uppdrag kommer att lyckas, så att du får en hustru åt min son från min släkt och min fars familj. 41Du blir löst från din ed, om mina släktingar, när du kommit till dem, inte vill ge henne åt dig.’

42När jag i dag kom till brunnen, bad jag denna bön: ’Herre, min herre Abrahams Gud, visa mig om du vill låta mitt uppdrag lyckas. 43Här står jag nu bredvid denna brunn. Jag tänker säga till en av flickorna som kommer hit för att hämta vatten: ”Var snäll och ge mig lite vatten att dricka” 44och hon ska svara: ”Javisst! Och jag ska vattna dina kameler också.” Låt den flickan vara den som Herren har utvalt till att bli hustru åt min husbondes son.’

45Innan jag hade slutat tala, kom Rebecka med sin vattenkruka på axeln, och hon gick ner till brunnen och hämtade vatten och fyllde krukan. Jag sa till henne: ’Ge mig vatten att dricka!’ 46Snabbt lyfte hon ner krukan från axeln och sa till mig: ’Javisst, herre, och jag ska ge dina kameler vatten också!’ Så drack jag, och hon vattnade också kamelerna. 47Då frågade jag henne: ’Vems dotter är du?’ Hon sa till mig: ’Betuels, Nachors och hans hustru Milkas son.’ Då gav jag henne näsringen och armbanden. 48Sedan föll jag ner på marken och tillbad Herren, min herre Abrahams Gud, för att han hade lett mig rätt i mitt sökande efter en flicka från min husbondes brors familj. 49Säg därför nu: Vill ni visa godhet och trofasthet mot min husbonde? Vill ni inte, säg mig då det, så vet jag vad nästa steg ska bli, om jag ska gå i den ena eller den andra riktningen.”

50Då svarade Laban och Betuel: ”Detta måste komma från Herren, så vad kan vi säga? 51Här är Rebecka. Ta henne och gå! Låt henne bli hustru till din husbondes son, precis som Herren har sagt.”

52Vid detta svar föll Abrahams tjänare ner och tillbad inför Herren. 53Sedan gav han Rebecka guld- och silversmycken och kläder. Han gav också många värdefulla presenter till hennes mor och bror. 54Sedan åt och drack tjänaren och de män som var med honom och stannade där över natten. När de gick upp nästa morgon sa tjänaren: ”Låt mig resa tillbaka till min husbonde!” 55”Låt Rebecka stanna här hos oss åtminstone tio dagar eller så!” bad hennes mor och bror. ”Sedan kan hon resa.” 56Men tjänaren bad: ”Hindra mig inte från att resa! Herren har sett till att mitt uppdrag lyckats. Låt mig nu återvända till min husbonde.”

57”Nåväl”, sa de. ”Vi ska ropa på flickan och fråga henne vad hon tycker.” 58Då ropade de på Rebecka. ”Är du villig att resa med denne man?” frågade de henne. Hon svarade: ”Ja, det vill jag.”

59De lät då sin syster Rebecka och hennes amma följa med Abrahams tjänare och hans män. 60De välsignade Rebecka med denna välsignelse:

”Må du, vår syster,

bli mor till många miljoner!

Måtte dina ättlingar

inta sina fienders städer.”

61Rebecka och hennes tjänarinnor steg sedan upp på kamelerna och följde med mannen. Så tog tjänaren Rebecka med sig och började resan tillbaka.

62Under tiden hade Isak, vars hem låg i Negev, återvänt till Beer Lachaj Roi24:62 Beer Lachaj Roi betyder Den Levandes brunn, han som ser mig. Se 16:14.. 63När han en kväll tog en promenad över fälten försjunken i tankar24:63 Grundtextens innebörd är osäker., tittade han upp och såg kamelerna komma. 64Rebecka lade märke till honom och steg snabbt ner. 65”Vem är den där mannen, som vandrar över fälten för att möta oss?” frågade hon tjänaren. Han svarade: ”Det är min husbondes son.” Då dolde hon sig i sin slöja. 66Sedan berättade tjänaren hela historien för Isak. 67Isak förde Rebecka till sin mor Saras tält, och hon blev hans hustru. Han älskade henne och hon blev till stor tröst för honom, eftersom han förlorat sin mor.