Gẹnẹsisi 19 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 19:1-38

Ìparun Sodomu àti Gomorra

1Ní àṣálẹ́, àwọn angẹli méjì sì wá sí ìlú Sodomu, Lọti sì jókòó ní ẹnu ibodè ìlú. Bí ó sì ti rí wọn, ó sì dìde láti pàdé wọn, ó kí wọn, ó sì foríbalẹ̀ fún wọn. 2Ó wí pé, “Ẹ̀yin olúwa mi, èmi bẹ̀ yín, ẹ yà sí ilé ìránṣẹ́ yín kí ẹ sì wẹ ẹsẹ̀ yín, kí n sì gbà yín lálejò, ẹ̀yin ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ láti máa bá ìrìnàjò yín lọ.”

Wọ́n sì wí pé, “Rárá o, àwa yóò dúró ní ìgboro ní òru òní.”

3Ṣùgbọ́n Lọti rọ̀ wọ́n gidigidi tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n gbà láti bá a lọ sì ilé. Ó sì ṣe àsè fún wọn, ó sì dín àkàrà aláìwú fún wọ́n, wọ́n sì jẹ. 4Ṣùgbọ́n kí ó tó di pé wọ́n lọ sùn, àwọn ọkùnrin ìlú Sodomu tọmọdé tàgbà yí ilé náà ká. 519.5-8: On 19.22-24.Wọ́n pe Lọti pé, “Àwọn ọkùnrin tí ó wọ̀ sí ilé rẹ lálẹ́ yìí ńkọ́? Mú wọn jáde fún wa, kí a le ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú wọn.”

6Lọti sì jáde láti pàdé wọn, ó sì ti ìlẹ̀kùn lẹ́yìn rẹ̀ bí ó ti jáde. 7Ó sì wí pé; “Rárá, ẹ̀yin ará mi, ẹ má ṣe ṣe ohun búburú yìí, 8kíyèsi i, mo ní ọmọbìnrin méjì tí kò mọ ọkùnrin rí, ẹ jẹ́ kí n mú wọn tọ̀ yín wá kí ẹ sì ṣe ohun tí ẹ fẹ́ pẹ̀lú wọn. Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣe àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ní ibi kan nítorí wọ́n wá wọ̀ lábẹ́ ààbò ní ilé mi.”

9Wọ́n sì wí fún pé, “Bì sẹ́yìn fún wa. Èyí yìí wá ṣe àtìpó láàrín wa, òun sì fẹ́ ṣe onídàájọ́! Aburú tí a ó fi ṣe ọ́ yóò pọ̀ ju tí wọn lọ.” Wọn rọ́ lu Lọti, wọ́n sì súnmọ́ ọn láti fọ́ ìlẹ̀kùn.

10Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà nawọ́ fa Lọti wọlé, wọ́n sì ti ìlẹ̀kùn. 1119.11: 2Ki 6.18.Wọ́n sì bu ìfọ́jú lu àwọn ọkùnrin tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà ilé náà, àti èwe àti àgbà: wọ́n kò sì rí ẹnu-ọ̀nà mọ́.

12Àwọn ọkùnrin náà sì wí fún Lọti pé, “Ǹjẹ́ ó ní ẹlòmíràn ní ìlú yìí bí? Àna rẹ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ lọ́kùnrin àti lóbìnrin, tàbí ẹnikẹ́ni tí ìwọ ní ní ìlú yìí, kó wọn jáde kúrò ní ibí yìí, 13nítorí a ó pa ìlú yìí run, nítorí igbe iṣẹ́ búburú wọn ń dí púpọ̀ níwájú Olúwa, Olúwa sì rán wa láti pa á run.”

14Nígbà náà ni Lọti jáde, ó sì wí fún àwọn àna rẹ̀ ọkùnrin tí ó ti bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fẹ́ àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ ṣe kánkán, kí ẹ jáde ní ìlú yìí, nítorí Olúwa fẹ́ pa ìlú yìí run!” Ṣùgbọ́n àwọn ọkọ ọmọ rẹ̀ wọ̀nyí rò pé àwàdà ló ń ṣe.

15Ní àfẹ̀mọ́júmọ́, àwọn angẹli náà rọ Lọti pé, “Ṣe wéré, mú aya rẹ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì tí ó wà níhìn-ín, àìṣe bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò parun pẹ̀lú ìlú yìí nígbà tí wọ́n bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”

1619.16: 2Pt 2.7.Nígbà tí ó ń jáfara, àwọn ọkùnrin náà nawọ́ mú un lọ́wọ́, wọ́n sì nawọ́ mú aya rẹ̀ náà lọ́wọ́ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ méjèèjì, wọ́n sì mú wọn jáde sẹ́yìn odi ìlú, nítorí Olúwa ṣàánú fún wọn. 17Ní kété tí wọ́n mú wọn jáde sẹ́yìn odi tán, ọ̀kan nínú wọn wí pé, “Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe wo ẹ̀yìn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó má ṣe dúró ní gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀! Sá àsálà lọ sí orí òkè, kí ìwọ ó má ba ṣègbé!”

18Ṣùgbọ́n Lọti wí fún wọn pé, “Rárá, ẹ̀yin Olúwa mi, ẹ jọ̀wọ́! 19Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ ti rí ojúrere rẹ, tí o sì ti fi àánú rẹ hàn nípa gbígba ẹ̀mí mi là, Èmi kò le è sálọ sórí òkè, kí búburú yìí má ba à lé mi bá, kí n sì kú. 20Wò ó, ìlú kékeré kan nìyí ní tòsí láti sá sí: jẹ́ kí n sálọ síbẹ̀, ìlú kékeré ha kọ́? Ẹ̀mí mi yóò sì yè.”

21Ó sì wí fún un pé, “Ó dára, mo gba ẹ̀bẹ̀ rẹ. Èmi kì yóò run ìlú náà tí ìwọ sọ̀rọ̀ rẹ̀. 22Tètè! Sálọ síbẹ̀, nítorí èmi kò le ṣe ohun kan àyàfi tí ó bá dé ibẹ̀,” (ìdí nìyí tí a fi ń pe ìlú náà ní Soari).

23Nígbà tí Lọti yóò fi dé ìlú Soari, oòrùn ti yọ. 2419.24,25: Mt 10.15; 11.23,24; Lk 10.12; 17.29; 2Pt 2.6; On 7.Nígbà náà ni Olúwa rọ̀jò iná àti Sulfuru (òkúta iná) sórí Sodomu àti Gomorra—láti ọ̀run lọ́dọ̀ Olúwa wá. 25Báyìí ni ó run àwọn ìlú náà àti gbogbo ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó wà ní ìlú ńláńlá wọ̀n-ọn-nì àti ohun gbogbo tí ó hù jáde nílẹ̀. 2619.26: Lk 17.32.Ṣùgbọ́n aya Lọti bojú wo ẹ̀yìn, ó sì di ọ̀wọ́n iyọ̀.

27Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Abrahamu sì dìde ó sì padà lọ sí ibi tí ó gbé dúró níwájú Olúwa. 2819.28: If 9.2.Ó sì wo ìhà Sodomu àti Gomorra àti àwọn ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, ó sì rí èéfín tí ń ti ibẹ̀ jáde bí èéfín iná ìléru.

29Ọlọ́run sì rántí Abrahamu, nígbà tí ó run ìlú pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀n-ọn-nì tan, ó sì mú Lọti jáde kúrò láàrín ìparun náà, tí ó kọlu ìlú tí Lọti ti gbé.

Lọti àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin

30Lọti àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin méjèèjì sì kúrò ní Soari, wọ́n sì ń lọ gbé ní orí òkè ní inú ihò àpáta, nítorí ó bẹ̀rù láti gbé ní ìlú Soari. 31Ní ọjọ́ kan, èyí ẹ̀gbọ́n sọ fún àbúrò rẹ̀ pé, “Baba wa ti dàgbà, kò sì sí ọkùnrin kankan ní agbègbè yìí tí ìbá bá wa lòpọ̀, bí ìṣe gbogbo ayé. 32Wá, jẹ́ kí a mú baba wa mu ọtí yó, kí ó ba à le bá wa lòpọ̀, kí àwa kí ó lè bí ọmọ, kí ìran wa má ba à parẹ́.”

33Ní òru ọjọ́ náà, wọ́n rọ baba wọn ní ọtí yó. Èyí ẹ̀gbọ́n sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a lòpọ̀, baba wọn kò mọ̀ ìgbà tí ó sùn ti òun àti ìgbà tí ó dìde.

34Ní ọjọ́ kejì èyí ẹ̀gbọ́n wí fún àbúrò rẹ̀ pé, “Ní àná mo sùn ti baba mi. Jẹ́ kí a tún wọlé tọ̀ ọ́, kí a lè ní irú-ọmọ láti ọ̀dọ̀ baba wa.” 35Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún fún baba wọn ní ọtí mu yó ni alẹ́ ọjọ́ náà, èyí àbúrò náà sì wọlé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a lòpọ̀, kò sì tún mọ ìgbà tí ó wọlé sùn ti òun tàbí ìgbà tí ó dìde.

36Àwọn ọmọbìnrin Lọti méjèèjì sì lóyún fún baba wọn. 37Èyí ẹ̀gbọ́n sì bí ọmọkùnrin, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Moabu. Òun ni baba ńlá àwọn ará Moabu lónìí. 38Èyí àbúrò náà sì bí ọmọkùnrin, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Bene-Ami. Òun ni baba ńlá àwọn ará Ammoni lónìí.

Swedish Contemporary Bible

1 Moseboken 19:1-38

Gud räddar Lot

1När de två änglarna samma kväll kom till Sodom, satt Lot i stadsporten. När han såg dem, reste han sig upp för att möta dem och han bugade sig med ansiktet mot marken. 2”Mina herrar”, sa han. ”Kom till mitt hem och stanna över natten, så att ni får tvätta era fötter. Sedan kan ni resa vidare i morgon bitti.” ”Nej”, svarade de. ”Vi stannar här ute på gatan över natten.”

3Men Lot var så angelägen att de slutligen gick med honom hem, och han bjöd dem på mat och nybakat, osyrat bröd, och de åt. 4Innan de hunnit lägga sig, omringades huset av stadens män. De hade kommit allesammans från alla håll i staden, både yngre och äldre. 5De skrek till Lot: ”Var är de där männen som kom till dig i kväll? För ut dem till oss, så att vi kan ligga med dem!”

6Lot gick då ut för att tala med dem och stängde dörren efter sig. 7Han bad dem: ”Mina vänner, gör inte något så ont. 8Jag har två döttrar, som är oskulder. Ni kan ta dem och göra vad ni vill med dem, men lämna dessa män i fred, för de har kommit för att få skydd under mitt tak.”

9”Flytta på dig”, skrek de. ”Denne har kommit hit som främling och nu vill han vara vår domare! Nu ska vi behandla dig mycket värre än vad vi tänkte behandla dem.” Så trängde de sig fram till Lot och började bryta sönder dörren.

10Men de två männen i huset sträckte sig ut efter Lot, drog in honom och låste dörren 11och förblindade dem som stod utanför, unga som gamla, så att de inte kunde hitta dörren.

12”Vilka släktingar har du här i staden?” frågade männen Lot. ”För ut dem härifrån allihop, mågar, söner, döttrar, vilka de än är! 13Vi ska nämligen utplåna staden. Herren har hört ett stort klagorop om staden och skickat oss hit för att förgöra den.”

14Då gick Lot ut för att berätta detta för sina blivande svärsöner: ”Skynda er, skynda er ut ur staden, för Herren tänker förgöra den!” Men svärsönerna trodde att han bara skämtade.

15Vid gryningen nästa morgon blev änglarna allt mer angelägna: ”Skynda dig”, sa de till Lot. ”Ta din hustru och dina döttrar som är här och ge dig av medan du kan, för annars kommer du att förgås med stadens synd.”

16När Lot fortfarande tvekade, tog männen honom och hans hustru och döttrar vid handen, eftersom Herren ville skona honom, och förde dem i säkerhet utanför staden. Där lämnade de dem.

17”Fly för livet”, sa han19:17 Det framkommer inte vem subjektet var, men uppenbarligen en av änglarna, snarare än Herren själv. Samtidigt är det dock Herren Lot åtminstone tidvis verkar tilltala här. medan de fördes ut. ”Och se dig inte tillbaka! Fly till bergen! Stanna inte här nere på slätten, för då kommer du att förintas.” 18”Nej, Herre19:18 Eller: min herre eller: mina herrar”, bad Lot. 19”Du har visat mig, din tjänare, den välviljan och den stora nåden att rädda mitt liv. Men jag hinner inte fly upp i bergen förrän olyckan är ifatt mig, och då dör jag. 20Staden där ligger så nära att jag kan fly dit och den är liten. Låt mig få gå dit i stället. Du ser väl hur liten den är! Då kommer mitt liv att räddas.”

21Han sa: ”Du ska få som du vill också den här gången. Jag ska inte förstöra staden du talar om. 22Men skynda dig dit, för jag kan inte göra något förrän du är där.” Så fick staden heta Soar19:22 Namnet Soar kommer från hebreiskans ord för liten..

23Solen var redan på väg upp över jorden, när Lot nådde fram till staden. 24Då lät Herren eld och flammande svavel regna ner från himlen, från Herren, över Sodom och Gomorra. 25Han förstörde dessa städer helt och hållet tillsammans med hela slätten och utplånade allt liv i dem, även vegetationen. 26Men Lots hustru såg sig om och blev förvandlad till en saltpelare.

27På morgonen var Abraham uppe tidigt och gick ut till platsen där han hade stått inför Herren. 28Han såg ut över slätten mot Sodom och Gomorra och såg röken från jorden stiga upp som från en brännugn. 29När Gud utplånade städerna på slätten, tänkte han på Abraham och förde ut Lot undan förödelsen som drabbade städerna där Lot bott.

Lots döttrar

30Efteråt lämnade Lot med sina döttrar Soar, för han var rädd för att bo där. Han bosatte sig i stället i en grotta i bergen tillsammans med sina två döttrar.

31En dag sa den äldre dottern till sin syster: ”Vår far är gammal, och det finns ingen man här i landet som skulle kunna komma till oss som man brukar göra överallt på jorden. 32Kom, så ger vi vår far vin att dricka, och sedan ligger vi med honom, så att vi får barn genom vår far.”

33Den kvällen såg de till att fadern blev berusad, och den äldre dottern gick in och låg med sin far. Men han visste varken när hon lade sig där eller gick upp.

34Följande dag sa hon till sin yngre syster: ”Jag låg med vår far i natt. Låt oss fylla honom med vin i kväll igen, och sedan går du in och ligger med honom så att vi får barn genom honom.” 35Också den kvällen fick de honom drucken, och den yngre dottern gick in och låg med honom, och inte heller nu märkte han när hon lade sig eller gick upp. 36På så sätt blev Lots båda döttrar med barn genom sin far.

37Den äldre dottern födde en son som hon gav namnet Moab19:37 I hebreiskan anspelning på genom sin far. Han blev stamfar till vår tids moabiter. 38Den yngre födde också en son som hon gav namnet Ben-Ammi19:38 Betyder: son till mitt folk. Han blev stamfar till vår tids ammoniter.