Gẹnẹsisi 16 – YCB & NSP

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 16:1-16

Hagari àti Iṣmaeli

1Sarai, aya Abramu kò bímọ fún un, ṣùgbọ́n ó ní ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin ará Ejibiti kan tí ń jẹ́ Hagari. 2Nítorí náà, Sarai wí fún Abramu pé, “Kíyèsi i Olúwa ti sé mi ní inú, èmi kò sì bímọ, wọlé tọ ọmọ ọ̀dọ̀ mi lọ, bóyá èmi yóò le ti ipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.”

Abramu sì gba ohun tí Sarai sọ. 3Lẹ́yìn ọdún mẹ́wàá tí Abramu ti ń gbé ni Kenaani ni Sarai mú ọmọbìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Hagari, tí í ṣe ará Ejibiti fún Abramu ọkọ rẹ̀ láti fi ṣe aya. 4Abramu sì bá Hagari lòpọ̀, ó sì lóyún.

Nígbà tí ó sì ti mọ̀ pé òun lóyún, ó bẹ̀rẹ̀ sì ní kẹ́gàn ọ̀gá rẹ̀. 5Nígbà náà ni Sarai wí fún Abramu pé, “Ìwọ ni ó jẹ́ kí ẹ̀gbin yìí máa jẹ mí, mo fa ọmọ ọ̀dọ̀ mi lé ọ lọ́wọ́, nígbà tí ó sì rí i pé òun lóyún, mo di ẹni ẹ̀gàn ní ojú rẹ̀. Kí Olúwa kí ó ṣe ìdájọ́ láàrín tèmi tìrẹ.”

6Abramu dáhùn pé, “Ìwọ ló ni ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ, ṣe ohunkóhun tí ó bá tọ́ ní ojú rẹ sí i.” Nígbà náà ni Sarai fi ìyà jẹ Hagari, ó sì sálọ.

7Angẹli Olúwa sì rí Hagari ní ẹ̀gbẹ́ ìsun omi ní ijù, ìsun omi tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà tí ó lọ sí Ṣuri. 8Ó sì wí pé, “Hagari, ìránṣẹ́ Sarai, níbo ni o ti ń bọ̀, níbo sì ni ìwọ ń lọ?”

Ó sì dáhùn pé, “Mo ń sálọ kúrò lọ́dọ̀ ọ̀gá mi Sarai ni.”

9Angẹli Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ kí o sì tẹríba fún un.” 10Angẹli Olúwa náà sì fi kún fún un pé, “Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, ìran rẹ kì yóò sì lóǹkà.”

11Angẹli Olúwa náà sì wí fún un pé,

“Ìwọ ti lóyún, ìwọ yóò sì bí

ọmọkùnrin kan,

ìwọ yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli,

nítorí tí Olúwa ti rí ìpọ́njú rẹ.

12Òun yóò jẹ́ oníjàgídíjàgan ènìyàn

ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára ènìyàn gbogbo,

ọwọ́ ènìyàn gbogbo yóò sì wà lára rẹ̀,

yóò sì máa gbé ní ìkanra

pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀.”

13Ó sì pe orúkọ Olúwa tí o bá sọ̀rọ̀ ní, “Ìwọ ni Ọlọ́run tí ó rí mi,” nítorí tí ó wí pé, “Mo ti ri ẹni tí ó rí mi báyìí.” 14Nítorí náà ni a ṣe ń pe kànga náà ní Beeri-Lahai-Roi: kànga ẹni alààyè tí ó rí mi. Ó wà ní agbede-méjì Kadeṣi àti Beredi.

1516.15: Ga 4.22.Hagari sì bí ọmọkùnrin kan fún Abramu, Abramu sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli. 16Abramu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndín-láàádọ́rùn-ún (86) nígbà tí Hagari bí Iṣmaeli fún un.

New Serbian Translation

1. Мојсијева 16:1-16

Исмаилово рођење

1Но, Аврамова жена Сараја није Авраму рађала деце. Она је имала слушкињу Египћанку која се звала Агара. 2Сараја рече Авраму: „Ево, Господ ме је учинио нероткињом. Иди и лези с мојом слушкињом, можда ћу преко ње стећи потомство.“

Аврам је послушао што му је Сараја рекла. 3Тада је Аврамова жена Сараја довела Авраму своју слушкињу Агару Египћанку и дала му је за жену (било је то десет година након што се Аврам населио у Хананској земљи). 4Аврам легне са Агаром и она затрудни.

Кад је видела да је затруднела, с презиром је гледала на своју господарицу. 5Сараја тада рече Авраму: „Твоја је кривица што ми се наноси ова неправда. Предала сам своју слушкињу у твој загрљај, али откако је опазила да је затруднела, почела је с презиром да гледа на мене. Нека Господ пресуди ко је од нас двоје крив!“

6Аврам одговори Сараји: „Ево, твоја слушкиња је у твојој власти. Како ти се чини да је добро, тако поступи према њој.“ Сараја поче тако злостављати Агару, да је ова побегла од ње.

7Но, Анђео Господњи је нађе код извора што је на путу за Сур, 8па је запита: „Агаро, слушкињо Сарајина, одакле долазиш и куда идеш?“

Агара одговори: „Бежим од своје господарице Сараје.“

9Тада јој Анђео Господњи рече: „Врати се својој господарици и покори јој се!“ 10Анђео Господњи јој уз то рече: „Веома ћу умножити твоје потомство, тако да се неће моћи пребројити!“

11Још јој рече Анђео Господњи:

„Ево, зачела си

и родићеш сина.

Даћеш му име ’Исмаило’16,11 Исмаило значи Бог је чуо.,

јер је Господ чуо за твоју невољу.

12Он ће бити као дивљи магарац:

рука ће се његова на свакога дизати,

и свачија рука на њега ће се дизати,

са свом својом браћом

у непријатељству ће живети.“16,12 Дословно: пред лицем све своје браће ће живети.

13Агара је назвала Господа који јој је говорио: „Ти си Бог који ме види!“ Агара је, наиме, рекла: „Уистину, видела сам онога који ме види!“ 14Зато се тај извор зове „Вир Лахај Рој“16,14 Вир Лахај Рој значи Извор онога што живи и види ме. и налази се између Кадиса и Варада.

15Агара је Авраму родила сина. Аврам је сину кога му је Агара родила, дао име Исмаило. 16Авраму је било осамдесет шест година када му је Агара родила Исмаила.