Gẹnẹsisi 15 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 15:1-21

Májẹ̀mú Ọlọ́run pẹ̀lú Abramu

1Lẹ́yìn èyí, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Abramu wá lójú ìran pé:

“Abramu má ṣe bẹ̀rù,

Èmi ni ààbò rẹ,

Èmi sì ni èrè ńlá rẹ.”

2Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, kí ni ìwọ yóò fi fún mi níwọ̀n ìgbà tí èmi kò bímọ, Elieseri ará Damasku ni yóò sì jogún mi,” 3Abramu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Ìwọ kò fún mi ní ọmọ, nítorí náà ẹrú nínú ilé mi sì ni yóò jẹ́ àrólé mi.”

415.4: Gẹ 17.16,21; 18.10; 21.2.Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ ọ́ wá pé: “Ọkùnrin yìí kọ́ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ bí kò ṣe ọmọ tí ìwọ bí fúnrarẹ̀ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ.” 515.5: Ro 4.18; Hb 11.12.Olúwa sì mú Abramu jáde sí ìta ó sì wí fún un pé, “Gbé ojú sókè sí ọ̀run kí o sì ka àwọn ìràwọ̀ bí ó bá ṣe pé ìwọ le è kà wọ́n.” Ó sì wí fun un pé, “Nítorí náà, báyìí ni irú-ọmọ rẹ yóò rí.”

615.6: Ro 4.3; Ga 3.6; Jk 2.23.Abramu gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.

7Ó sì tún wí fún un pé, “Èmi ni Olúwa tí ó mú ọ jáde láti Uri ti Kaldea láti fún ọ ní ilẹ̀ yìí láti jogún.”

8Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, báwo ni mo ṣe lè mọ̀ pé ilẹ̀ náà yóò jẹ́ ohun ìní mi?”

9Nítorí náà, Olúwa wí fún un pé, “Mú abo màlúù, ewúrẹ́ àti àgbò ọlọ́dún mẹ́ta mẹ́ta wá, àti àdàbà kan àti ọmọ ẹyẹlé kan.”

10Abramu sì mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí wá, ó sì là wọ́n sí méjì méjì, ó sì fi ẹ̀là èkínní kọjú sí èkejì, ṣùgbọ́n kò la àwọn ẹyẹ ní tiwọn. 11Àwọn ẹyẹ igún sì ń wá sórí òkú ẹran náà, Abramu sì ń lé wọn.

1215.12: Jb 4.13,14.Bí oòrùn ti ń wọ̀, Abramu sùn lọ fọnfọn, òkùnkùn biribiri tí ó kún fún ẹ̀rù sì bò ó. 1315.13: Ek 1.1-14; Ap 7.6.15.13-14: Ek 12.40,41; Ap 7.7.Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abramu pé, “Mọ èyí dájú pé, irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì, wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irínwó ọdún (400). 14Ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́, lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀. 15Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tọ àwọn baba rẹ lọ ni àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò sì di arúgbó kí a tó gbé ọ sin. 16Ní ìran kẹrin àwọn ìran rẹ yóò padà wá sí ibi. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ará Amori kò ì tí ì kún òṣùwọ̀n.”

17Nígbà tí oòrùn wọ̀ tí ilẹ̀ sì ṣú, ìkòkò iná tí ń ṣèéfín àti ọwọ́ iná sì ń kọjá láàrín ẹ̀là ẹran náà. 1815.18: Gẹ 17.2,7,9-14,21.Ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa dá májẹ̀mú pẹ̀lú Abramu, ó sì wí pé, “Àwọn ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún, láti odò Ejibiti dé odò ńlá Eufurate: 19ilẹ̀ àwọn ará Keni, àti ti ará Kenissiti, àti ará Kadmoni, 20àti ti ará Hiti, àti ti ará Peresi, àti ti ará Refaimu. 21Àti ti ará Amori, àti ti ará Kenaani, àti ti ará Girgaṣi àti ti ará Jebusi.”

Swedish Contemporary Bible

1 Moseboken 15:1-21

Gud lovar Abram en son

1Något senare kom Herrens ord till Abram i en syn:

”Var inte rädd, Abram!

Jag är din sköld och ska ge dig rik belöning.”

2Men Abram svarade: ”Herre, Herre, vad kan du ge mig? Jag går ju bort barnlös. Min tjänare Elieser från Damaskus kommer att ärva mig.”15:2 Den sista satsen i versen är svåröversättlig och grundtextens innebörd osäker. 3Abram sa vidare: ”Du har ju inte gett mig några barn. Då blir det min tjänare som ärver mig.”

4Då kom Herrens ord till honom igen: ”Nej, din tjänare kommer inte att bli din arvinge, för du ska få en son som ska ärva dig.” 5Sedan förde Gud ut Abram och sa till honom: ”Se upp mot himlen och räkna stjärnorna, om du kan. Så talrika ska dina efterkommande15:5 Ordagrant: din säd bli.” 6Och Abram trodde Herren, och därför räknade Herren honom som rättfärdig.15:6 Ordagrant: och han räknade honom det till rättfärdighet

7Han sa till honom: ”Jag är Herren, som förde dig ut från Ur i Kaldéen för att ge dig detta land som egendom.” 8Men Abram svarade: ”Herre, Herre, hur kan jag veta att jag ska få det här?” 9Då sa Herren till honom att hämta en tre år gammal kviga, en tre år gammal get, en tre år gammal bagge, en turturduva och en ung duva. 10Abram hämtade djuren och styckade dem i två delar och lade delarna mitt emot varandra, men fåglarna delade han inte.15:10 Se not till 15:17. 11Och när rovfåglar angrep de slaktade djuren, schasade Abram bort dem.

12När solen gick ner den kvällen föll en tung sömn över Abram, och ett fruktansvärt, skrämmande mörker kom över honom.

13Då sa Herren till Abram: ”Du ska veta att dina efterkommande ska bo i ett främmande land och bli slavar och förtryckas under fyrahundra år. 14Men jag ska döma det folk som gör dem till slavar, och efter det ska de gå därifrån med stora rikedomar. 15Själv kommer du att dö i frid och begravas hos dina fäder vid hög ålder. 16I den fjärde generationen ska dina ättlingar komma tillbaka hit, för amoréerna kommer inte att ha fyllt sina synders mått förrän då.”

17När solen gick ner och det blev mörkt, syntes ett rykande fyrfat och en flammande fackla som passerade mellan de slaktade djurhalvorna.15:17 Den flammande facklan är en symbol för Guds närvaro. Det var vanligt på den tiden att två parter som ville ingå förbund vandrade mellan två rader av slaktade djur. Innebörden var: ”Om jag bryter förbundet, ska det gå med mig på samma sätt”.

18Den dagen upprättade Herren detta förbund med Abram: ”Jag ger detta land till dina ättlingar, ända från Egyptens flod till den stora floden Eufrat, 19kenitéernas, kenisséernas, kadmonéernas, 20hettiternas, perisséernas, refaéernas, 21amoréernas, kanaanéernas, girgashéernas och jevuséernas land.”