Gẹnẹsisi 14 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 14:1-24

Abramu gba Lọti là

1Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu 2jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Ṣeboimu àti ọba Bela (èyí nì ni Soari) jagun. 3Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí Àfonífojì Siddimu (Òkun iyọ̀). 4Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.

5Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu, 6àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù. 7Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (èyí yìí ni Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.

8Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Ṣeboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu, 9láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún). 10Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà-ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè. 11Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ. 12Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.

13Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀. 14Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó-lé-lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn (318), ó sì lépa wọn títí dé Dani. 15Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku. 16Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.

1714.17-20: Hb 7.1-10.Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní Àfonífojì Ṣafe (èyí tí ó túmọ̀ sí Àfonífojì Ọba).

18Melkisedeki ọba Salẹmu (Jerusalẹmu) sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo. 19Ó sì súre fún Abramu wí pé,

“Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo

Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.

20Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ,

tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.”

Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.

21Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”

22Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè, 23pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’ 24Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”

Nouă Traducere În Limba Română

Geneza 14:1-24

Avram îl salvează pe Lot

1În zilele lui Amrafel, regele Șinarului1, 9 Sau: Babiloniei., a lui Ariok, regele Elasarului, a lui Chedorlaomer, regele Elamului, și a lui Tidal, regele Goyimului, s‑a întâmplat că 2ei au pornit la luptă împotriva lui Bera, regele Sodomei, a lui Birșa, regele Gomorei, a lui Șinab, regele Admei, a lui Șemeber, regele Țeboimului, și împotriva regelui Belei (care este Țoarul). 3Toți aceștia din urmă s‑au unit în valea Sidimului, adică Marea Sărată3 Marea Moartă.. 4Ei îl slujiseră pe Chedorlaomer timp de doisprezece ani, dar în al treisprezecelea an s‑au răsculat.

5În al paisprezecelea an, Chedorlaomer și regii care erau cu el au venit și i‑au învins pe refaiți la Aștarot-Karnaim, pe zuziți la Ham, pe emiți la Șave Chiriatayim 6și pe horiți la muntele lor, din Seir până la El‑Paran, care este lângă pustie. 7Apoi s‑au întors și au venit la En‑Mișpat sau Kadeș, unde au cucerit tot teritoriul amalekiților, precum și pe amoriții care locuiau în Hațațon-Tamar.

8Atunci regele Sodomei, regele Gomorei, regele Admei, regele Țeboimului și regele Belei (care este Țoarul), au ieșit și s‑au pregătit de luptă, în valea Sidimului, 9împotriva lui Chedorlaomer, regele Elamului, a lui Tidal, regele Goyimului, a lui Amrafel, regele Șinarului și a lui Ariok, regele Elasarului – patru regi împotriva a cinci. 10Valea Sidimului era plină de gropi cu smoală. Regii Sodomei și Gomorei au fugit și au căzut în ele, iar cei rămași au fugit înspre dealuri. 11Cei patru regi au luat toate bunurile Sodomei și Gomorei, precum și toată hrana acestora, și au plecat. 12Ei l‑au luat și pe Lot, fiul fratelui lui Avram, împreună cu bunurile lui, și au plecat (Lot locuia în Sodoma).

13Un om care a scăpat cu viață a venit și i‑a spus acest lucru lui Avram, evreul, care locuia lângă stejarii amoritului Mamre, fratele13 Sau: ruda; sau: aliatul. lui Eșcol și al lui Aner. Aceștia erau aliați cu Avram prin legământ. 14Când a auzit Avram că nepotul său fusese luat captiv, și‑a mobilizat cei trei sute optsprezece oameni instruiți pentru luptă, născuți în casa lui, și i‑a urmărit pe regi până la Dan. 15Apoi și‑a împărțit slujitorii în timpul nopții, i‑a învins pe regi și i‑a urmărit până la Hoba, care este la nord15 Lit.: stânga. În vremea aceea, în Orient punctele cardinale erau determinate de poziția cu fața spre răsărit, nu spre nord. de Damasc. 16Avram a adus înapoi toate bunurile. L‑a adus înapoi și pe nepotul său, Lot, împreună cu toate bunurile lui, precum și pe femei și pe ceilalți oameni.

17După ce Avram s‑a întors de la înfrângerea lui Chedorlaomer și a regilor care erau cu el, regele din Sodoma i‑a ieșit în întâmpinare în valea Șave, adică Valea Regelui. 18Melchisedek, regele Salemului18 Probabil Ierusalimul., a adus pâine și vin. Acesta era preot al Dumnezeului cel Preaînalt18 Ebr.: El‑Elion [peste tot în capitol].. 19El l‑a binecuvântat pe Avram și a zis:

„Binecuvântat să fie Avram de Dumnezeul cel Preaînalt,

Creatorul19, 22 Este posibil ca termenul ebraic să aibă și sensul de proprietar, posesor. cerurilor și al pământului,

20și binecuvântat să fie Dumnezeul cel Preaînalt,

Care i‑a dat pe vrăjmașii tăi în mâinile tale!“

Și Avram i‑a dat zeciuială din toate.

21Apoi regele din Sodoma i‑a zis lui Avram:

– Dă‑mi oamenii și păstrează bunurile pentru tine.

22Dar Avram i‑a răspuns regelui din Sodoma:

– I‑am jurat Domnului, Dumnezeul cel Preaînalt, Creatorul cerurilor și al pământului, 23că nu voi lua nici măcar un fir de ață sau o curea de sanda din ceea ce este al tău, pentru ca să nu spui că l‑ai îmbogățit pe Avram. 24Eu nu voi lua nimic, în afară de ceea ce au mâncat oamenii mei și de partea celor care au mers împreună cu mine – Aner, Eșkol și Mamre. Ei să‑și ia partea lor.