Gẹnẹsisi 14 – YCB & NSP

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 14:1-24

Abramu gba Lọti là

1Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu 2jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Ṣeboimu àti ọba Bela (èyí nì ni Soari) jagun. 3Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí Àfonífojì Siddimu (Òkun iyọ̀). 4Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.

5Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu, 6àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù. 7Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (èyí yìí ni Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.

8Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Ṣeboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu, 9láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún). 10Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà-ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè. 11Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ. 12Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.

13Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀. 14Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó-lé-lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn (318), ó sì lépa wọn títí dé Dani. 15Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku. 16Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.

1714.17-20: Hb 7.1-10.Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní Àfonífojì Ṣafe (èyí tí ó túmọ̀ sí Àfonífojì Ọba).

18Melkisedeki ọba Salẹmu (Jerusalẹmu) sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo. 19Ó sì súre fún Abramu wí pé,

“Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo

Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.

20Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ,

tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.”

Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.

21Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”

22Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè, 23pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’ 24Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”

New Serbian Translation

1. Мојсијева 14:1-24

Аврам избавља Лота

1У те дане, Амрафел цар Сенара, Ариох цар Еласара, Кедор-Лаомер цар Елама и Тидал цар Гојима, 2поведу рат против Бере, цара содомског, Варсе, цара гоморског, Шинаба, цара Адме, Симовора, цара Севојима и цара Вале, то јест Соара. 3Сви се они скупе у долину Сидим, где је Мртво море14,3 Дословно: Слано море.. 4Дванаест година су били потчињени Кедор-Лаомеру, али тринаесте године се побуне.

5Четрнаесте године дође Кедор-Лаомер с царевима што су му били савезници и потуку Рефаимце у Астарот-Карнајиму, Зузејце у Аму и Емијце на равници киријатајимској, 6те Хоријце на њиховој гори Сир, близу Ел-Фарана, што је покрај пустиње. 7Онда се врате назад и дођу у Ен-Миспат, то јест Кадис, и освоје целу област Амаличана и Аморејаца, који су живели у Хасасон-Тамару.

8Тада се дигне цар Содоме, цар Гоморе, цар Адме, цар Севојима и цар Вале, то јест Соара, па заметну битку против оних у долини Сидим: 9Кедор-Лаомера, цара Елама, Тидала, цара Гојима, Амрафела, цара Сенара, Ариоха, цара Еласара – четири цара против петорице. 10Долина Сидим је била пуна јама са смолом. Цареви Содоме и Гоморе, бежећи, упадну у њих, а остали побегну у горе. 11А победници однесу сва добра Содоме и Гоморе и сву храну, па оду. 12Одвели су и Лота, Аврамовог синовца, који је живео у Содоми, са свим његовим добрима.

13Али неки бегунац дође и све исприча Авраму Јеврејину, док је боравио код храстова Аморејца Мамрије, брата Есхола и Анера, који су били његови савезници. 14Кад је Аврам чуо да му је синовац заробљен, сабере своје људе вичне боју – рођене у његовом дому – њих три стотине осамнаест, па крене у потеру до Дана. 15Онда их је поделио у две групе, па је ноћу напао ону војску и потукао је. Гонио их је све до Хове, северно од Дамаска 16и повратио сав плен. Вратио је и свога синовца, Лота, са његовим добрима, жене и остали свет.

Мелхиседек благосиља Аврама

17Кад се након победе над Кедор-Лаомером и царевима који су били с њим, Аврам вратио у долину Саве, то јест у Царску долину, изађе му у сусрет цар Содоме.

18Тада Мелхиседек, цар Салима, донесе хлеб и вино. Он је био свештеник Бога Свевишњега. 19Он благослови Аврама рекавши:

„Нека Бог Свевишњи,

створитељ неба и земље, благослови Аврама!

20Нека је благословен Бог Свевишњи,

што теби у руке изручи непријатеље твоје!“

Аврам му тада даде десетак од свега.

21А цар содомски рече Авраму: „Мени дај људе, а ти узми добра.“ 22Али Аврам му рече: „Подижем руку пред Господом, Богом Свевишњим, створитељем неба и земље, 23да нећу узети ни кончића с ремена од обуће, нити ишта што ти припада, да не би рекао: ’Ја сам учинио Аврама богатим!’ 24За себе нећу ништа, осим што су моји момци појели. Део плена нека узму људи који су пошли са мном – Анер, Есхол и Мамрије.“