Gẹnẹsisi 14 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 14:1-24

Abramu gba Lọti là

1Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu 2jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Ṣeboimu àti ọba Bela (èyí nì ni Soari) jagun. 3Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí Àfonífojì Siddimu (Òkun iyọ̀). 4Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.

5Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu, 6àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù. 7Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (èyí yìí ni Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.

8Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Ṣeboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu, 9láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún). 10Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà-ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè. 11Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ. 12Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.

13Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀. 14Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó-lé-lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn (318), ó sì lépa wọn títí dé Dani. 15Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku. 16Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.

1714.17-20: Hb 7.1-10.Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní Àfonífojì Ṣafe (èyí tí ó túmọ̀ sí Àfonífojì Ọba).

18Melkisedeki ọba Salẹmu (Jerusalẹmu) sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo. 19Ó sì súre fún Abramu wí pé,

“Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo

Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.

20Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ,

tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.”

Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.

21Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”

22Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè, 23pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’ 24Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”

New International Reader’s Version

Genesis 14:1-24

Abram Saves Lot

1Amraphel was the king of Babylon. Arioch was the king of Ellasar. Kedorlaomer was the king of Elam. And Tidal was the king of Goyim. 2They went to war against five other kings. They were Bera king of Sodom, Birsha king of Gomorrah, Shinab king of Admah, Shemeber king of Zeboyim, and the king of Bela. Bela was also called Zoar. 3These five kings all gathered their armies together in the Valley of Siddim. It was also called the valley of the Dead Sea. 4For 12 years Kedorlaomer had ruled over them. But in the 13th year they opposed him.

5So in the 14th year, Kedorlaomer and the kings who helped him went to war. They won the battle against the Rephaites in Ashteroth Karnaim. They also won the battle against the Zuzites in Ham and the Emites in Shaveh Kiriathaim. 6They did the same thing to the Horites in the hill country of Seir. They marched all the way to El Paran near the desert. 7Then they turned back and went to En Mishpat. En Mishpat was also called Kadesh. They took over the whole territory of the Amalekites. They also won the battle against the Amorites who were living in Hazezon Tamar.

8Then the kings of Sodom, Gomorrah, Admah, Zeboyim and Bela marched out. Bela was also called Zoar. They lined up their armies for battle in the Valley of Siddim. 9They got ready to fight against Kedorlaomer king of Elam, Tidal king of Goyim, Amraphel king of Babylonia, and Arioch king of Ellasar. There were four kings against five. 10The Valley of Siddim was full of tar pits. The kings of Sodom and Gomorrah ran away from the battle. Some of their men fell into the pits, but the rest escaped to the hills. 11The four kings took all the things that belonged to Sodom and Gomorrah. They also took all their food and then left. 12They carried away Abram’s nephew Lot and the things he owned. Lot was living in Sodom at that time.

13A man escaped and came to report everything to Abram. Abram was a Hebrew. He was living near the large trees of Mamre the Amorite. Mamre was a brother of Eshkol and Aner. All of them helped Abram. 14Abram heard that Lot had been captured. So he called out his 318 trained men. All of them were sons of his servants. Abram and his men chased their enemies as far as Dan. 15During the night Abram separated his men into groups. They attacked their enemies and drove them away. They chased them north of Damascus as far as Hobah. 16Abram took back everything the kings had taken. He brought back his nephew Lot and the things Lot owned. He also brought back the women and the other people.

17After Abram won the battle over Kedorlaomer and the kings who helped him, he returned home. The king of Sodom came out to meet him in the Valley of Shaveh. It was also called the King’s Valley.

18Melchizedek was the king of Jerusalem. He brought out bread and wine. He was the priest of the Most High God. 19He gave a blessing to Abram. He said,

“May the Most High God bless Abram.

May the Creator of heaven and earth bless him.

20Give praise to the Most High God.

He gave your enemies into your hand.”

Then Abram gave Melchizedek a tenth of everything.

21The king of Sodom said to Abram, “Give me the people. Keep everything else for yourself.”

22But Abram said to the king of Sodom, “I have raised my hand to make a promise to the Lord. He is the Most High God. He is the Creator of heaven and earth. 23I’ve said I will not accept anything that belongs to you. I will not take even a thread or the strap of a sandal. You will never be able to say, ‘I made Abram rich.’ 24I’ll accept only what my men have eaten and what belongs to Aner, Eshkol and Mamre. These three men went with me. Let them have their share.”