Gẹnẹsisi 12 – YCB & NSP

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 12:1-20

Ìpè Abramu

112.1: Ap 7.3; Hb 11.8.Olúwa sì wí fún Abramu, “Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.

212.2: Gẹ 15.5; 17.4,5; 18.18; 22.17; 28.14; 32.12; 35.11; 46.3.“Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá

Èmi yóò sì bùkún fún ọ.

Èmi yóò sọ orúkọ rẹ di ńlá,

ìbùkún ni ìwọ yóò sì jásí.

312.3: Gẹ 18.18; 22.17,18; 26.4; 28.14; Ga 3.8.Èmi yóò bùkún fún àwọn tí ó súre fún ọ,

ẹni tí ó fi ọ́ ré ni Èmi yóò fi ré;

nínú rẹ ni a ó bùkún

gbogbo ìdílé ayé.”

4Bẹ́ẹ̀ ni Abramu lọ bí Olúwa ti sọ fún un. Lọti náà sì bá a lọ. Abramu jẹ́ ẹni àrùndínlọ́gọ́rin (75) ọdún nígbà tí ó jáde kúrò ní Harani. 5Abramu sì mú Sarai aya rẹ̀, àti Lọti ọmọ arákùnrin rẹ̀: gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti kójọ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n ní ní Harani. Wọ́n sì jáde lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Wọ́n sì gúnlẹ̀ síbẹ̀.

6Abramu sì rìn la ilẹ̀ náà já títí dé ibi igi ńlá kan tí à ń pè ni More ní Ṣekemu. Àwọn ará Kenaani sì wà ní ilẹ̀ náà. 712.7: Gẹ 13.15; 15.18; 17.8; 24.7; 26.3; 28.4,13; 35.12; 48.4; Ap 7.5; Ga 3.16.Olúwa sì farahan Abramu, ó sì wí fún un pé, “Irú-ọmọ rẹ ni Èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún.” Abramu tẹ́ pẹpẹ kan síbẹ̀ fún Olúwa tí ó fi ara hàn án.

8Ó sì kúrò níbẹ̀ lọ sí agbègbè àwọn òkè kan ní ìhà ìlà-oòrùn Beteli, ó sì pàgọ́ rẹ̀ síbẹ̀. Beteli wà ní ìwọ̀-oòrùn, Ai wà ní ìlà-oòrùn. Ó tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ó sì ké pe orúkọ Olúwa.

9Nígbà náà ni Abramu tẹ̀síwájú sí ìhà gúúsù.

Abramu ní Ejibiti

1012.10-20: Gẹ 20.1-18; 26.7-11.Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, Abramu sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ṣe àtìpó níbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, nítorí ìyàn náà mú gidigidi. 11Bí ó ti ku díẹ̀ kí ó wọ Ejibiti, ó wí fún Sarai, aya rẹ̀ pé, “Mo mọ̀ pé arẹwà obìnrin ni ìwọ, 12nígbà tí àwọn ará Ejibiti bá rí ọ, wọn yóò wí pé, ‘Aya rẹ̀ nìyí.’ Wọn yóò si pa mí, ṣùgbọ́n wọn yóò dá ọ sí. 13Nítorí náà, sọ pé, arábìnrin mi ni ìwọ, wọn yóò sì ṣe mí dáradára, a ó sì dá ẹ̀mí mi sí nítorí tìrẹ.”

14Nígbà tí Abramu dé Ejibiti, àwọn ará Ejibiti ri i pé aya rẹ̀ rẹwà gidigidi. 15Nígbà tí àwọn ìjòyè Farao sì rí i, wọ́n ròyìn rẹ̀ níwájú Farao, wọ́n sì mú un lọ sí ààfin, 16Ó sì kẹ́ Abramu dáradára nítorí Sarai, Abramu sì ní àgùntàn àti màlúù, akọ àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin, pẹ̀lú ìbákasẹ.

17Olúwa sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn búburú sí Farao àti ilé rẹ̀, nítorí Sarai aya Abramu. 18Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Abramu, ó sì wí fun pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé aya rẹ ní í ṣe? 19Èéṣe tí o fi wí pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ tí èmi sì fi fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí aya? Nítorí náà nísinsin yìí, aya rẹ náà nìyí, mú un kí o sì máa lọ.” 20Nígbà náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ nípa Abramu, wọ́n sì lé e jáde ti òun ti aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.

New Serbian Translation

1. Мојсијева 12:1-20

Бог позива Аврама

1Господ рече Авраму: „Иди из своје земље, од своје родбине и дома свога оца у земљу коју ћу ти показати.

2Учинићу од тебе велики народ,

благословићу те

и име ти учинити славним;

ти сам ћеш бити благослов.

3Благословићу оне који тебе благослове,

а проклећу оног који тебе проклиње.

По теби ће бити благословена

сва племена на земљи.“

4Аврам је кренуо онако како му је рекао Господ. Са њим је пошао и Лот. Авраму је било седамдесет пет година када је отишао из Харана. 5Аврам је повео са собом своју жену Сарају и Лота, сина свога брата, и сву имовину коју су стекли, заједно са свим слугама које су прибавили у Харану, те сви пођу за Ханан. Дошавши у Ханан, 6Аврам је путовао до места Сихема – до великог храста Море. У то време су Хананци живели у земљи. 7Господ се указао Авраму и рекао му: „Твоме потомству ћу дати ову земљу.“ На том месту је Аврам саградио жртвеник Господу који му се указао.

8Одатле је продужио према брдима источно од Ветиља, те је поставио свој шатор између Ветиља на западу и Гаја на истоку. Ту је Аврам саградио жртвеник Господу и призвао име Господње.

9Аврам је потом наставио да путује од места до места према Негеву.

Аврам у Египту

10Али кад је у земљи настала глад, Аврам се спустио у Египат да тамо проведе неко време; у земљи је, наиме, завладала велика глад. 11Кад је био надомак Египта, Аврам рече својој жени Сараји: „Брине ме што си лепа жена. 12Када те Египћани виде, рећи ће: ’То је његова жена.’ Онда ће ме убити, а тебе оставити на животу. 13Зато реци да си моја сестра, да би се добро опходили према мени, те да би ми, због тебе, поштедели живот.“ 14Кад је Аврам ушао у Египат, опазе Египћани да је жена веома лепа. 15А кад су је опазиле и фараонове слуге, похвалиле су је пред фараоном, па су је одвеле на фараонов двор. 16Због ње се фараон показао добрим према Авраму, тако да је овај стекао ситну и крупну стоку, магарце, слуге и слушкиње, магарице и камиле.

17Али Господ удари фараона и сав његов дом опаким пошастима12,17 Исти израз за болест је употребљен у Левитској књизи (трећа књига Мојсијева), а означава неку врсту кожне болести. због Аврамове жене Сараје. 18Фараон позва Аврама и рече му: „Шта си ми то учинио? Зашто ми ниси рекао да је она твоја жена? 19Зашто си рекао: ’Она је моја сестра’, а ја је узео себи за жену? Ево ти сад твоје жене. Узми је и одлази!“ 20Фараон га онда преда својим људима, а ови га испрате с његовом женом и свом његовом имовином.