Gẹnẹsisi 12 – YCB & KJV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 12:1-20

Ìpè Abramu

112.1: Ap 7.3; Hb 11.8.Olúwa sì wí fún Abramu, “Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.

212.2: Gẹ 15.5; 17.4,5; 18.18; 22.17; 28.14; 32.12; 35.11; 46.3.“Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá

Èmi yóò sì bùkún fún ọ.

Èmi yóò sọ orúkọ rẹ di ńlá,

ìbùkún ni ìwọ yóò sì jásí.

312.3: Gẹ 18.18; 22.17,18; 26.4; 28.14; Ga 3.8.Èmi yóò bùkún fún àwọn tí ó súre fún ọ,

ẹni tí ó fi ọ́ ré ni Èmi yóò fi ré;

nínú rẹ ni a ó bùkún

gbogbo ìdílé ayé.”

4Bẹ́ẹ̀ ni Abramu lọ bí Olúwa ti sọ fún un. Lọti náà sì bá a lọ. Abramu jẹ́ ẹni àrùndínlọ́gọ́rin (75) ọdún nígbà tí ó jáde kúrò ní Harani. 5Abramu sì mú Sarai aya rẹ̀, àti Lọti ọmọ arákùnrin rẹ̀: gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti kójọ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n ní ní Harani. Wọ́n sì jáde lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Wọ́n sì gúnlẹ̀ síbẹ̀.

6Abramu sì rìn la ilẹ̀ náà já títí dé ibi igi ńlá kan tí à ń pè ni More ní Ṣekemu. Àwọn ará Kenaani sì wà ní ilẹ̀ náà. 712.7: Gẹ 13.15; 15.18; 17.8; 24.7; 26.3; 28.4,13; 35.12; 48.4; Ap 7.5; Ga 3.16.Olúwa sì farahan Abramu, ó sì wí fún un pé, “Irú-ọmọ rẹ ni Èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún.” Abramu tẹ́ pẹpẹ kan síbẹ̀ fún Olúwa tí ó fi ara hàn án.

8Ó sì kúrò níbẹ̀ lọ sí agbègbè àwọn òkè kan ní ìhà ìlà-oòrùn Beteli, ó sì pàgọ́ rẹ̀ síbẹ̀. Beteli wà ní ìwọ̀-oòrùn, Ai wà ní ìlà-oòrùn. Ó tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ó sì ké pe orúkọ Olúwa.

9Nígbà náà ni Abramu tẹ̀síwájú sí ìhà gúúsù.

Abramu ní Ejibiti

1012.10-20: Gẹ 20.1-18; 26.7-11.Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, Abramu sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ṣe àtìpó níbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, nítorí ìyàn náà mú gidigidi. 11Bí ó ti ku díẹ̀ kí ó wọ Ejibiti, ó wí fún Sarai, aya rẹ̀ pé, “Mo mọ̀ pé arẹwà obìnrin ni ìwọ, 12nígbà tí àwọn ará Ejibiti bá rí ọ, wọn yóò wí pé, ‘Aya rẹ̀ nìyí.’ Wọn yóò si pa mí, ṣùgbọ́n wọn yóò dá ọ sí. 13Nítorí náà, sọ pé, arábìnrin mi ni ìwọ, wọn yóò sì ṣe mí dáradára, a ó sì dá ẹ̀mí mi sí nítorí tìrẹ.”

14Nígbà tí Abramu dé Ejibiti, àwọn ará Ejibiti ri i pé aya rẹ̀ rẹwà gidigidi. 15Nígbà tí àwọn ìjòyè Farao sì rí i, wọ́n ròyìn rẹ̀ níwájú Farao, wọ́n sì mú un lọ sí ààfin, 16Ó sì kẹ́ Abramu dáradára nítorí Sarai, Abramu sì ní àgùntàn àti màlúù, akọ àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin, pẹ̀lú ìbákasẹ.

17Olúwa sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn búburú sí Farao àti ilé rẹ̀, nítorí Sarai aya Abramu. 18Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Abramu, ó sì wí fun pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé aya rẹ ní í ṣe? 19Èéṣe tí o fi wí pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ tí èmi sì fi fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí aya? Nítorí náà nísinsin yìí, aya rẹ náà nìyí, mú un kí o sì máa lọ.” 20Nígbà náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ nípa Abramu, wọ́n sì lé e jáde ti òun ti aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.

King James Version

Genesis 12:1-20

1Now the LORD had said unto Abram, Get thee out of thy country, and from thy kindred, and from thy father’s house, unto a land that I will shew thee: 2And I will make of thee a great nation, and I will bless thee, and make thy name great; and thou shalt be a blessing: 3And I will bless them that bless thee, and curse him that curseth thee: and in thee shall all families of the earth be blessed.

4So Abram departed, as the LORD had spoken unto him; and Lot went with him: and Abram was seventy and five years old when he departed out of Haran. 5And Abram took Sarai his wife, and Lot his brother’s son, and all their substance that they had gathered, and the souls that they had gotten in Haran; and they went forth to go into the land of Canaan; and into the land of Canaan they came.

6¶ And Abram passed through the land unto the place of Sichem, unto the plain of Moreh. And the Canaanite was then in the land.12.6 plain: Heb. plains 7And the LORD appeared unto Abram, and said, Unto thy seed will I give this land: and there builded he an altar unto the LORD, who appeared unto him. 8And he removed from thence unto a mountain on the east of Beth-el, and pitched his tent, having Beth-el on the west, and Hai on the east: and there he builded an altar unto the LORD, and called upon the name of the LORD. 9And Abram journeyed, going on still toward the south.12.9 going…: Heb. in going and journeying

10¶ And there was a famine in the land: and Abram went down into Egypt to sojourn there; for the famine was grievous in the land. 11And it came to pass, when he was come near to enter into Egypt, that he said unto Sarai his wife, Behold now, I know that thou art a fair woman to look upon: 12Therefore it shall come to pass, when the Egyptians shall see thee, that they shall say, This is his wife: and they will kill me, but they will save thee alive. 13Say, I pray thee, thou art my sister: that it may be well with me for thy sake; and my soul shall live because of thee.

14¶ And it came to pass, that, when Abram was come into Egypt, the Egyptians beheld the woman that she was very fair. 15The princes also of Pharaoh saw her, and commended her before Pharaoh: and the woman was taken into Pharaoh’s house. 16And he entreated Abram well for her sake: and he had sheep, and oxen, and he asses, and menservants, and maidservants, and she asses, and camels. 17And the LORD plagued Pharaoh and his house with great plagues because of Sarai Abram’s wife. 18And Pharaoh called Abram, and said, What is this that thou hast done unto me? why didst thou not tell me that she was thy wife? 19Why saidst thou, She is my sister? so I might have taken her to me to wife: now therefore behold thy wife, take her, and go thy way. 20And Pharaoh commanded his men concerning him: and they sent him away, and his wife, and all that he had.