Gẹnẹsisi 12 – YCB & CARS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 12:1-20

Ìpè Abramu

112.1: Ap 7.3; Hb 11.8.Olúwa sì wí fún Abramu, “Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.

212.2: Gẹ 15.5; 17.4,5; 18.18; 22.17; 28.14; 32.12; 35.11; 46.3.“Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá

Èmi yóò sì bùkún fún ọ.

Èmi yóò sọ orúkọ rẹ di ńlá,

ìbùkún ni ìwọ yóò sì jásí.

312.3: Gẹ 18.18; 22.17,18; 26.4; 28.14; Ga 3.8.Èmi yóò bùkún fún àwọn tí ó súre fún ọ,

ẹni tí ó fi ọ́ ré ni Èmi yóò fi ré;

nínú rẹ ni a ó bùkún

gbogbo ìdílé ayé.”

4Bẹ́ẹ̀ ni Abramu lọ bí Olúwa ti sọ fún un. Lọti náà sì bá a lọ. Abramu jẹ́ ẹni àrùndínlọ́gọ́rin (75) ọdún nígbà tí ó jáde kúrò ní Harani. 5Abramu sì mú Sarai aya rẹ̀, àti Lọti ọmọ arákùnrin rẹ̀: gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti kójọ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n ní ní Harani. Wọ́n sì jáde lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Wọ́n sì gúnlẹ̀ síbẹ̀.

6Abramu sì rìn la ilẹ̀ náà já títí dé ibi igi ńlá kan tí à ń pè ni More ní Ṣekemu. Àwọn ará Kenaani sì wà ní ilẹ̀ náà. 712.7: Gẹ 13.15; 15.18; 17.8; 24.7; 26.3; 28.4,13; 35.12; 48.4; Ap 7.5; Ga 3.16.Olúwa sì farahan Abramu, ó sì wí fún un pé, “Irú-ọmọ rẹ ni Èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún.” Abramu tẹ́ pẹpẹ kan síbẹ̀ fún Olúwa tí ó fi ara hàn án.

8Ó sì kúrò níbẹ̀ lọ sí agbègbè àwọn òkè kan ní ìhà ìlà-oòrùn Beteli, ó sì pàgọ́ rẹ̀ síbẹ̀. Beteli wà ní ìwọ̀-oòrùn, Ai wà ní ìlà-oòrùn. Ó tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ó sì ké pe orúkọ Olúwa.

9Nígbà náà ni Abramu tẹ̀síwájú sí ìhà gúúsù.

Abramu ní Ejibiti

1012.10-20: Gẹ 20.1-18; 26.7-11.Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, Abramu sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ṣe àtìpó níbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, nítorí ìyàn náà mú gidigidi. 11Bí ó ti ku díẹ̀ kí ó wọ Ejibiti, ó wí fún Sarai, aya rẹ̀ pé, “Mo mọ̀ pé arẹwà obìnrin ni ìwọ, 12nígbà tí àwọn ará Ejibiti bá rí ọ, wọn yóò wí pé, ‘Aya rẹ̀ nìyí.’ Wọn yóò si pa mí, ṣùgbọ́n wọn yóò dá ọ sí. 13Nítorí náà, sọ pé, arábìnrin mi ni ìwọ, wọn yóò sì ṣe mí dáradára, a ó sì dá ẹ̀mí mi sí nítorí tìrẹ.”

14Nígbà tí Abramu dé Ejibiti, àwọn ará Ejibiti ri i pé aya rẹ̀ rẹwà gidigidi. 15Nígbà tí àwọn ìjòyè Farao sì rí i, wọ́n ròyìn rẹ̀ níwájú Farao, wọ́n sì mú un lọ sí ààfin, 16Ó sì kẹ́ Abramu dáradára nítorí Sarai, Abramu sì ní àgùntàn àti màlúù, akọ àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin, pẹ̀lú ìbákasẹ.

17Olúwa sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn búburú sí Farao àti ilé rẹ̀, nítorí Sarai aya Abramu. 18Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Abramu, ó sì wí fun pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé aya rẹ ní í ṣe? 19Èéṣe tí o fi wí pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ tí èmi sì fi fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí aya? Nítorí náà nísinsin yìí, aya rẹ náà nìyí, mú un kí o sì máa lọ.” 20Nígbà náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ nípa Abramu, wọ́n sì lé e jáde ti òun ti aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.

Священное Писание

Начало 12:1-20

Избрание Ибрама Всевышним для благословения всех народов

1Вечный сказал Ибраму:

– Оставь свою страну, своих родственников и дом своего отца и иди в землю, которую Я тебе укажу. 2Я произведу от тебя великий народ и благословлю тебя; Я возвеличу твоё имя, и ты будешь благословением. 3Я благословлю тех, кто благословляет тебя, и прокляну тех, кто проклинает тебя; и через тебя получат благословение все народы на земле12:3 Это обещание, данное Ибраму (Ибрахиму), было исполнено в Исе Масихе. Радостная Весть о спасении через веру в жертву Масиха возвещается всем народам (см. Гал. 3:8)..

4И Ибрам отправился в путь, как сказал ему Вечный, и Лут пошёл вместе с ним. Ибраму было семьдесят пять лет, когда он ушёл из Харрана. 5Он взял с собой жену Сару, племянника Лута, всё имущество, которое они нажили, и людей, которых они приобрели в Харране. Они отправились в землю Ханаана и пришли туда.

6Ибрам прошёл по этой земле до того места в Шехеме, где стояло великое дерево Море; в то время там жили хананеи. 7Вечный явился Ибраму и сказал: «Я дам эту землю твоему потомству»12:7 Букв.: «твоему семени».. Ибрам построил там жертвенник Вечному, Который явился ему.

8Оттуда он двинулся в горную местность к востоку от Вефиля и поставил шатёр между Вефилем на западе и Гаем на востоке. Там он построил жертвенник Вечному, где и стал поклоняться Ему. 9Затем Ибрам снялся с места и продолжил путь к Негеву.

Переселение Ибрама и Сары в Египет

10На земле был голод, и Ибрам направился жить в Египет12:10 Букв.: «Мицраим» (здесь и везде, кроме Инджила). Ср. 10:6., потому что голод был очень силён. 11Когда они подходили к Египту, он сказал жене Саре:

– Я знаю, что ты красивая женщина. 12Когда египтяне увидят тебя, они скажут: «Это его жена» – и убьют меня, а тебя оставят в живых. 13Скажи, что ты моя сестра, чтобы ради тебя меня приняли хорошо, и благодаря тебе я остался бы жив.

14Когда Ибрам пришёл в Египет, египтяне увидели, что Сара очень красива, 15а когда её увидели придворные фараона, они расхвалили её фараону, и Сару взяли к нему во дворец. 16Он хорошо принял Ибрама ради неё, и Ибрам приобрёл мелкий и крупный скот, ослов и ослиц, слуг и служанок, и верблюдов.

17Но Вечный поразил фараона и весь его дом тяжёлыми болезнями из-за жены Ибрама Сары. 18Тогда фараон вызвал Ибрама и спросил:

– Что ты сделал со мной? Почему ты не сказал мне, что она твоя жена? 19Зачем ты сказал: «Она моя сестра»? Только из-за этого я взял её себе в жёны. Вот твоя жена. Забирай её и уходи!

20Фараон распорядился, и его люди отправили Ибрама в дорогу вместе с женой и всем, что у него было.