Gẹnẹsisi 11 – YCB & CARSA

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 11:1-32

Ilé ìṣọ́ Babeli

1Lẹ́yìn náà, gbogbo àgbáyé sì ń sọ èdè kan ṣoṣo. 2Bí àwọn ènìyàn ṣe ń tẹ̀síwájú lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, wọ́n rí pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan ní ilẹ̀ Ṣinari (Babeli), wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.

3Wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a mọ bíríkì kí a sì sún wọ́n jìnà.” Bíríkì ni wọ́n ń lò ní ipò òkúta, àti ọ̀dà-ilẹ̀ tí wọn ń lò láti mú wọn papọ̀ dípò ẹfun (òkúta láìmù tí wọ́n fi ń ṣe símẹ́ńtì àti omi). 4Nígbà náà ni wọ́n wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tẹ ìlú kan dó fún ara wa, kí a sì kọ́ ilé ìṣọ́ kan tí yóò kan ọ̀run, kí a ba à lè ní orúkọ (òkìkí) kí a má sì tú káàkiri sórí gbogbo ilẹ̀ ayé.”

5Ṣùgbọ́n, Olúwa sọ̀kalẹ̀ láti wo ìlú àti ilé ìṣọ́ tí àwọn ènìyàn náà ń kọ́. 6Olúwa wí pé, “Bí àwọn ènìyàn bá ń jẹ́ ọ̀kan àti èdè kan tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe iṣẹ́ yìí, kò sí ohun tí wọ́n gbèrò tí wọn kò ní le ṣe yọrí. 7Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ lọ, kí a da èdè wọn rú kí èdè wọn má ba à yé ara wọn mọ́.”

8Ọlọ́run sì tú wọn ká sórí ilẹ̀ gbogbo, wọ́n sì ṣíwọ́ ìlú náà tí wọn ń tẹ̀dó. 9Ìdí èyí ni a fi pè é ní Babeli11.9 Èyí ní Babiloni; Babeli ni èdé Heberu tí a mọ̀ sí ìdàrúdàpọ̀. nítorí ní ibẹ̀ ni Ọlọ́run ti da èdè gbogbo ayé rú, tí ó sì tú àwọn ènìyàn ká sí gbogbo orí ilẹ̀ ayé.

Ìran Ṣemu tó fi dé ti Abramu

10Wọ̀nyí ni ìran Ṣemu.

Ọdún méjì lẹ́yìn ìkún omi, tí Ṣemu pé ọgọ́rùn-ún ọdún (100) ni ó bí Arfakṣadi. 11Lẹ́yìn tí ó bí Arfakṣadi, Ṣemu tún wà láààyè fún ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọdún (500), ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.

12Nígbà tí Arfakṣadi pé ọdún márùn-dínlógójì (35) ni ó bí Ṣela. 13Arfakṣadi sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó (403) lẹ́yìn tí ó bí Ṣela, ó sì bí àwọn ọmọbìnrin àti àwọn ọmọkùnrin mìíràn.

14Nígbà tí Ṣela pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún (30) ni ó bí Eberi. 15Ṣela sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó (403) lẹ́yìn tí ó bí Eberi tán, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.

16Eberi sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n (34), ó sì bí Pelegi. 17Eberi sì wà láààyè fún irínwó ó-lé-ọgbọ̀n ọdún (430) lẹ́yìn tí ó bí Pelegi, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.

18Nígbà tí Pelegi pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún (30) ni ó bí Reu. 19Pelegi sì tún wà láààyè fún igba ó-lé-mẹ́sàn án ọdún (209) lẹ́yìn tí ó bí Reu, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.

20Nígbà tí Reu pé ọdún méjìlélọ́gbọ̀n (32) ni ó bí Serugu. 21Reu tún wà láààyè lẹ́yìn tí ó bí Serugu fún igba ó-lé-méje ọdún (207), ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn.

22Nígbà tí Serugu pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún (30) ni ó bí Nahori. 23Serugu sì wà láààyè fún igba ọdún (200) lẹ́yìn tí ó bí Nahori, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.

24Nígbà tí Nahori pé ọmọ ọdún mọ́kàn-dínlọ́gbọ̀n (29), ó bí Tẹra. 25Nahori sì wà láààyè fún ọdún mọ́kàn-dínlọ́gọ́fà (119) lẹ́yìn ìbí Tẹra, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.

26Lẹ́yìn tí Tẹra pé ọmọ àádọ́rin ọdún (70) ó bí Abramu, Nahori àti Harani.

27Wọ̀nyí ni ìran Tẹra.

Tẹra ni baba Abramu, Nahori àti Harani, Harani sì bí Lọti. 28Harani sì kú ṣáájú Tẹra baba rẹ̀ ní ilẹ̀ ìbí rẹ̀ ní Uri ti ilẹ̀ Kaldea. 29Abramu àti Nahori sì gbéyàwó. Orúkọ aya Abramu ni Sarai, nígbà tí aya Nahori ń jẹ́ Milka, tí ṣe ọmọ Harani. Harani ni ó bí Milka àti Iska. 30Sarai sì yàgàn, kò sì bímọ.

31Tẹra sì mú ọmọ rẹ̀ Abramu àti Lọti ọmọ Harani, ọmọ ọmọ rẹ̀, ó sì mú Sarai tí i ṣe aya ọmọ rẹ̀. Abramu pẹ̀lú gbogbo wọn sì jáde kúrò ní Uri ti Kaldea láti lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Ṣùgbọ́n nígbà tí wọn dé Harani wọ́n tẹ̀dó síbẹ̀.

32Nígbà tí Tẹra pé ọmọ igba ó-lé-márùn-ún ọdún (205) ni ó kú ní Harani.

Священное Писание (Восточный перевод), версия с «Аллахом»

Начало 11:1-32

Вавилонская башня

1Во всём мире был один язык и одно наречие. 2Двигаясь к востоку11:2 Или: «с востока»., люди вышли на равнину в Вавилонии и поселились там.

3Они сказали друг другу:

– Давайте сделаем кирпичи и обожжём их получше.

Кирпичи у них были вместо камня, а смола была вместо известкового раствора. 4Потом они сказали:

– Давайте построим себе город с башней до небес, чтобы прославить своё имя и не рассеяться по всей земле.

5Вечный сошёл посмотреть на город и башню, которые строили люди, 6и сказал:

– Все люди – один народ и у них один язык; вот они и затеяли такое; теперь не будет для них ничего невозможного. 7Сойдём же и смешаем им язык, чтобы они перестали понимать друг друга.

8И Вечный рассеял их оттуда по всему свету, и они перестали строить тот город. 9Вот почему он был назван Вавилоном («смешение»)11:9 На языке оригинала наблюдается игра слов: вавилонское баб-или («ворота бога») созвучно с еврейским глаголом «смешивать» (балал). – ведь Вечный смешал там язык всего мира. Оттуда Он рассеял их по всей земле.

Потомки от Сима до Ибрама

(1 Лет. 1:24-27)

10Вот родословие Сима.

Симу было сто лет, когда у него родился Арфаксад, через два года после потопа. 11После рождения Арфаксада Сим жил пятьсот лет, и у него были ещё сыновья и дочери.

12Когда Арфаксад прожил тридцать пять лет, у него родился Шелах. 13После рождения Шелаха Арфаксад жил четыреста три года, и у него были ещё сыновья и дочери.

14Когда Шелах прожил тридцать лет, у него родился Евер. 15После рождения Евера Шелах жил четыреста три года, и у него были ещё сыновья и дочери.

16Когда Евер прожил тридцать четыре года, у него родился Фалек. 17После рождения Фалека Евер жил четыреста тридцать лет, и у него были ещё сыновья и дочери.

18Когда Фалек прожил тридцать лет, у него родился Реу. 19После рождения Реу Фалек жил двести девять лет, и у него были ещё сыновья и дочери.

20Когда Реу прожил тридцать два года, у него родился Серуг. 21После рождения Серуга Реу жил двести семь лет, и у него были ещё сыновья и дочери.

22Когда Серуг прожил тридцать лет, у него родился Нахор. 23После рождения Нахора Серуг жил двести лет, и у него были ещё сыновья и дочери.

24Когда Нахор прожил двадцать девять лет, у него родился Терах. 25После рождения Тераха Нахор жил сто девятнадцать лет, и у него были ещё сыновья и дочери.

26После того как Терах прожил семьдесят лет, у него родились Ибрам, Нахор и Аран.

Родословие Тераха и его переселение с Халдейской земли в Харран

27Вот родословие Тераха.

У Тераха родились Ибрам, Нахор и Аран. У Арана родился Лут. 28Когда его отец Терах был ещё жив, Аран умер в Уре Халдейском, в земле, где он родился. 29Ибрам и Нахор взяли себе жён. Жену Ибрама звали Сара, а жену Нахора – Милка, она была дочерью Арана, отца Милки и Иски. 30Сара была бесплодна, и у неё не было детей.

31Терах взял своего сына Ибрама, своего внука Лута, сына Арана, и свою невестку Сару, жену Ибрама, и вместе они отправились из Ура Халдейского в Ханаан. Но дойдя до Харрана, они поселились там. 32Терах жил двести пять лет и умер в Харране.