Gẹnẹsisi 10 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 10:1-32

Ìran àwọn ọmọ Noa

1Èyí ni ìran àwọn ọmọ Noa: Ṣemu, Hamu àti Jafeti, tí àwọn náà sì bí ọmọ lẹ́yìn ìkún omi.

Ìran Jafeti

2Àwọn ọmọ Jafeti ni:

Gomeri, Magogu, Madai, Jafani, Tubali, Meṣeki àti Tirasi.

3Àwọn ọmọ Gomeri ni:

Aṣkenasi, Rifàti àti Togarma.

4Àwọn ọmọ Jafani ni:

Eliṣa, Tarṣiṣi, Kittimu, àti Dodanimu. 5(Láti ọ̀dọ̀ àwọn wọ̀nyí ni àwọn tí ń gbé agbègbè tí omi wà ti tàn ká agbègbè wọn, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, ìdílé wọn ní orílẹ̀-èdè wọn, olúkúlùkù pẹ̀lú èdè tirẹ̀).

Ìran Hamu

6Àwọn ọmọ Hamu ni:

Kuṣi, Misraimu, Puti àti Kenaani.

7Àwọn ọmọ Kuṣi ni:

Seba, Hafila, Sabta, Raama, àti Ṣabteka.

Àwọn ọmọ Raama ni:

Ṣeba àti Dedani.

8Kuṣi sì bí Nimrodu, ẹni tí ó di alágbára jagunjagun ní ayé. 9Ó sì jẹ́ ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa; nítorí náà ni a ṣe ń wí pé, “Bí Nimrodu, ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa.” 10Ìjọba rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni Babeli, Ereki, Akkadi, Kalne, gbogbo wọn wà ní ilẹ̀ Ṣinari. 11Láti ilẹ̀ náà ni ó ti lọ sí Asiria, níbi tí ó ti tẹ ìlú Ninefe, Rehoboti àti Kala, 12àti Resini, tí ó wà ní àárín Ninefe àti Kala, tí ó jẹ́ ìlú olókìkí.

13Misraimu sì bí

Ludimu, Anamimu, Lehabimu, Naftuhimu. 14Patrusimu, Kasluhimu, (láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwọn ará Filistini ti wá) àti àwọn ará Kaftorimu.

15Kenaani sì bí Sidoni àkọ́bí rẹ̀,

àti Heti. 16Àti àwọn ará Jebusi, àti àwọn ará Amori, àti àwọn ará Girgaṣi, 17àti àwọn ará Hifi, àti àwọn ará Arki, àti àwọn ará Sini, 18àti àwọn ará Arfadi, àti àwọn ará Ṣemari, àti àwọn ará Hamati.

Lẹ́yìn èyí ni àwọn ẹ̀yà Kenaani tànkálẹ̀. 19Ààlà ilẹ̀ àwọn ará Kenaani sì dé Sidoni, lọ sí Gerari títí dé Gasa, lọ sí Sodomu, Gomorra, Adma àti Ṣeboimu, títí dé Laṣa.

20Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Hamu, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, àti èdè wọn, ní ìpínlẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.

Ìran Ṣemu

21A bí àwọn ọmọ fún Ṣemu tí Jafeti jẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin: Ṣemu sì ni baba gbogbo àwọn ọmọ Eberi.

22Àwọn ọmọ Ṣemu ni:

Elamu, Aṣuri, Arfakṣadi, Ludi àti Aramu.

23Àwọn ọmọ Aramu ni:

Usi, Huli, Geteri àti Meṣeki.

24Arfakṣadi sì bí Ṣela,

Ṣela sì bí Eberi.

25Eberi sì bí ọmọ méjì:

ọ̀kan ń jẹ́ Pelegi, nítorí ní ìgbà ọjọ́ rẹ̀ ni ilẹ̀ ya; orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Joktani.

26Joktani sì bí

Almodadi, Ṣelefi, Hasarmafeti, Jera. 27Hadoramu, Usali, Dikla, 28Obali, Abimaeli, Ṣeba. 29Ofiri, Hafila àti Jobabu. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Joktani.

30Agbègbè ibi tí wọn ń gbé bẹ̀rẹ̀ láti Meṣa títí dé Sefari, ní àwọn ilẹ̀ tó kún fún òkè ní ìlà-oòrùn.

31Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Ṣemu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, ní èdè wọn, ní ilẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.

32Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Noa gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, ní orílẹ̀-èdè wọn. Ní ipasẹ̀ wọn ni àwọn ènìyàn ti tàn ká ilẹ̀ ayé lẹ́yìn ìkún omi.

New International Version

Genesis 10:1-32

The Table of Nations

1This is the account of Shem, Ham and Japheth, Noah’s sons, who themselves had sons after the flood.

The Japhethites

2The sons10:2 Sons may mean descendants or successors or nations; also in verses 3, 4, 6, 7, 20-23, 29 and 31. of Japheth:

Gomer, Magog, Madai, Javan, Tubal, Meshek and Tiras.

3The sons of Gomer:

Ashkenaz, Riphath and Togarmah.

4The sons of Javan:

Elishah, Tarshish, the Kittites and the Rodanites.10:4 Some manuscripts of the Masoretic Text and Samaritan Pentateuch (see also Septuagint and 1 Chron. 1:7); most manuscripts of the Masoretic Text Dodanites 5(From these the maritime peoples spread out into their territories by their clans within their nations, each with its own language.)

The Hamites

6The sons of Ham:

Cush, Egypt, Put and Canaan.

7The sons of Cush:

Seba, Havilah, Sabtah, Raamah and Sabteka.

The sons of Raamah:

Sheba and Dedan.

8Cush was the father10:8 Father may mean ancestor or predecessor or founder; also in verses 13, 15, 24 and 26. of Nimrod, who became a mighty warrior on the earth. 9He was a mighty hunter before the Lord; that is why it is said, “Like Nimrod, a mighty hunter before the Lord.” 10The first centers of his kingdom were Babylon, Uruk, Akkad and Kalneh, in10:10 Or Uruk and Akkad—all of them in Shinar.10:10 That is, Babylonia 11From that land he went to Assyria, where he built Nineveh, Rehoboth Ir,10:11 Or Nineveh with its city squares Calah 12and Resen, which is between Nineveh and Calah—which is the great city.

13Egypt was the father of

the Ludites, Anamites, Lehabites, Naphtuhites, 14Pathrusites, Kasluhites (from whom the Philistines came) and Caphtorites.

15Canaan was the father of

Sidon his firstborn,10:15 Or of the Sidonians, the foremost and of the Hittites, 16Jebusites, Amorites, Girgashites, 17Hivites, Arkites, Sinites, 18Arvadites, Zemarites and Hamathites.

Later the Canaanite clans scattered 19and the borders of Canaan reached from Sidon toward Gerar as far as Gaza, and then toward Sodom, Gomorrah, Admah and Zeboyim, as far as Lasha.

20These are the sons of Ham by their clans and languages, in their territories and nations.

The Semites

21Sons were also born to Shem, whose older brother was10:21 Or Shem, the older brother of Japheth; Shem was the ancestor of all the sons of Eber.

22The sons of Shem:

Elam, Ashur, Arphaxad, Lud and Aram.

23The sons of Aram:

Uz, Hul, Gether and Meshek.10:23 See Septuagint and 1 Chron. 1:17; Hebrew Mash.

24Arphaxad was the father of10:24 Hebrew; Septuagint father of Cainan, and Cainan was the father of Shelah,

and Shelah the father of Eber.

25Two sons were born to Eber:

One was named Peleg,10:25 Peleg means division. because in his time the earth was divided; his brother was named Joktan.

26Joktan was the father of

Almodad, Sheleph, Hazarmaveth, Jerah, 27Hadoram, Uzal, Diklah, 28Obal, Abimael, Sheba, 29Ophir, Havilah and Jobab. All these were sons of Joktan.

30The region where they lived stretched from Mesha toward Sephar, in the eastern hill country.

31These are the sons of Shem by their clans and languages, in their territories and nations.

32These are the clans of Noah’s sons, according to their lines of descent, within their nations. From these the nations spread out over the earth after the flood.