Gẹnẹsisi 10 – YCB & CCBT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 10:1-32

Ìran àwọn ọmọ Noa

1Èyí ni ìran àwọn ọmọ Noa: Ṣemu, Hamu àti Jafeti, tí àwọn náà sì bí ọmọ lẹ́yìn ìkún omi.

Ìran Jafeti

2Àwọn ọmọ Jafeti ni:

Gomeri, Magogu, Madai, Jafani, Tubali, Meṣeki àti Tirasi.

3Àwọn ọmọ Gomeri ni:

Aṣkenasi, Rifàti àti Togarma.

4Àwọn ọmọ Jafani ni:

Eliṣa, Tarṣiṣi, Kittimu, àti Dodanimu. 5(Láti ọ̀dọ̀ àwọn wọ̀nyí ni àwọn tí ń gbé agbègbè tí omi wà ti tàn ká agbègbè wọn, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, ìdílé wọn ní orílẹ̀-èdè wọn, olúkúlùkù pẹ̀lú èdè tirẹ̀).

Ìran Hamu

6Àwọn ọmọ Hamu ni:

Kuṣi, Misraimu, Puti àti Kenaani.

7Àwọn ọmọ Kuṣi ni:

Seba, Hafila, Sabta, Raama, àti Ṣabteka.

Àwọn ọmọ Raama ni:

Ṣeba àti Dedani.

8Kuṣi sì bí Nimrodu, ẹni tí ó di alágbára jagunjagun ní ayé. 9Ó sì jẹ́ ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa; nítorí náà ni a ṣe ń wí pé, “Bí Nimrodu, ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa.” 10Ìjọba rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni Babeli, Ereki, Akkadi, Kalne, gbogbo wọn wà ní ilẹ̀ Ṣinari. 11Láti ilẹ̀ náà ni ó ti lọ sí Asiria, níbi tí ó ti tẹ ìlú Ninefe, Rehoboti àti Kala, 12àti Resini, tí ó wà ní àárín Ninefe àti Kala, tí ó jẹ́ ìlú olókìkí.

13Misraimu sì bí

Ludimu, Anamimu, Lehabimu, Naftuhimu. 14Patrusimu, Kasluhimu, (láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwọn ará Filistini ti wá) àti àwọn ará Kaftorimu.

15Kenaani sì bí Sidoni àkọ́bí rẹ̀,

àti Heti. 16Àti àwọn ará Jebusi, àti àwọn ará Amori, àti àwọn ará Girgaṣi, 17àti àwọn ará Hifi, àti àwọn ará Arki, àti àwọn ará Sini, 18àti àwọn ará Arfadi, àti àwọn ará Ṣemari, àti àwọn ará Hamati.

Lẹ́yìn èyí ni àwọn ẹ̀yà Kenaani tànkálẹ̀. 19Ààlà ilẹ̀ àwọn ará Kenaani sì dé Sidoni, lọ sí Gerari títí dé Gasa, lọ sí Sodomu, Gomorra, Adma àti Ṣeboimu, títí dé Laṣa.

20Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Hamu, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, àti èdè wọn, ní ìpínlẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.

Ìran Ṣemu

21A bí àwọn ọmọ fún Ṣemu tí Jafeti jẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin: Ṣemu sì ni baba gbogbo àwọn ọmọ Eberi.

22Àwọn ọmọ Ṣemu ni:

Elamu, Aṣuri, Arfakṣadi, Ludi àti Aramu.

23Àwọn ọmọ Aramu ni:

Usi, Huli, Geteri àti Meṣeki.

24Arfakṣadi sì bí Ṣela,

Ṣela sì bí Eberi.

25Eberi sì bí ọmọ méjì:

ọ̀kan ń jẹ́ Pelegi, nítorí ní ìgbà ọjọ́ rẹ̀ ni ilẹ̀ ya; orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Joktani.

26Joktani sì bí

Almodadi, Ṣelefi, Hasarmafeti, Jera. 27Hadoramu, Usali, Dikla, 28Obali, Abimaeli, Ṣeba. 29Ofiri, Hafila àti Jobabu. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Joktani.

30Agbègbè ibi tí wọn ń gbé bẹ̀rẹ̀ láti Meṣa títí dé Sefari, ní àwọn ilẹ̀ tó kún fún òkè ní ìlà-oòrùn.

31Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Ṣemu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, ní èdè wọn, ní ilẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.

32Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Noa gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, ní orílẹ̀-èdè wọn. Ní ipasẹ̀ wọn ni àwọn ènìyàn ti tàn ká ilẹ̀ ayé lẹ́yìn ìkún omi.

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

創世記 10:1-32

挪亞三個兒子的後代

1洪水以後,挪亞的兒子雅弗都生養了兒女,以下是他們的後代。

2雅弗的兒子是歌篾瑪各瑪代雅完土巴米設提拉3歌篾的兒子是亞實基拿利法陀迦瑪4雅完的兒子是以利沙他施基提多單5雅弗的這些後裔按宗族、語言和民族分散在各海島。

6的兒子是古實麥西10·6 麥西」希伯來文是Mizraim,就是「埃及」,13節亦同。迦南7古實的兒子是西巴哈腓拉撒弗他拉瑪撒弗提迦拉瑪的兒子是示巴底但

8古實也是寧錄之父,寧錄是世上第一位勇士, 9在耶和華眼中是個孔武有力的獵人,因此有俗話說:「要像寧錄那樣在耶和華眼中是個孔武有力的獵人。」 10他首先在示拿地區的巴別以力亞甲甲尼各地建國, 11後來擴展到亞述,在那裡建立了尼尼微利河伯迦拉各城, 12又在尼尼微迦拉之間建立了利鮮大城。

13麥西的後代有路低人、亞拿米人、利哈比人、拿弗土希人、 14帕斯魯細人、迦斯路希人和迦斐托人。非利士人是迦斐托人的後代。

15迦南生長子西頓和次子16他的後代還有耶布斯人、亞摩利人、革迦撒人、 17希未人、亞基人、西尼人、 18亞瓦底人、洗瑪利人和哈馬人。後來迦南各宗族散居在各地。 19迦南的疆域從西頓基拉耳延伸,遠至迦薩,再向所多瑪蛾摩拉押瑪洗扁延伸,遠至拉沙20以上記載的都是的子孫,他們根據自己的宗族、語言、地域和民族散居各處。

21雅弗的哥哥希伯子孫的祖先。 22的兒子是以攔亞述亞法撒路德亞蘭23亞蘭的兒子是烏斯戶勒基帖瑪施24亞法撒沙拉沙拉希伯25希伯有兩個兒子,一個名叫法勒,意思是分開,因為那時人們分地而居。法勒的兄弟叫約坍26約坍亞摩答沙列哈薩瑪非耶拉27哈多蘭烏薩德拉28俄巴路亞比瑪利示巴29阿斐哈腓拉約巴。這些都是約坍的兒子。 30他們居住的地方,從米沙直到東邊的西發山區。 31以上記載的都是的子孫,他們按著自己的宗族、語言、地域和民族散居各處。

32這些人都是洪水以後挪亞三個兒子所生的子孫,他們按著自己的族系散居在各地,後來成為地上不同的民族。