Gẹnẹsisi 10 – YCB & CCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 10:1-32

Ìran àwọn ọmọ Noa

1Èyí ni ìran àwọn ọmọ Noa: Ṣemu, Hamu àti Jafeti, tí àwọn náà sì bí ọmọ lẹ́yìn ìkún omi.

Ìran Jafeti

2Àwọn ọmọ Jafeti ni:

Gomeri, Magogu, Madai, Jafani, Tubali, Meṣeki àti Tirasi.

3Àwọn ọmọ Gomeri ni:

Aṣkenasi, Rifàti àti Togarma.

4Àwọn ọmọ Jafani ni:

Eliṣa, Tarṣiṣi, Kittimu, àti Dodanimu. 5(Láti ọ̀dọ̀ àwọn wọ̀nyí ni àwọn tí ń gbé agbègbè tí omi wà ti tàn ká agbègbè wọn, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, ìdílé wọn ní orílẹ̀-èdè wọn, olúkúlùkù pẹ̀lú èdè tirẹ̀).

Ìran Hamu

6Àwọn ọmọ Hamu ni:

Kuṣi, Misraimu, Puti àti Kenaani.

7Àwọn ọmọ Kuṣi ni:

Seba, Hafila, Sabta, Raama, àti Ṣabteka.

Àwọn ọmọ Raama ni:

Ṣeba àti Dedani.

8Kuṣi sì bí Nimrodu, ẹni tí ó di alágbára jagunjagun ní ayé. 9Ó sì jẹ́ ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa; nítorí náà ni a ṣe ń wí pé, “Bí Nimrodu, ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa.” 10Ìjọba rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni Babeli, Ereki, Akkadi, Kalne, gbogbo wọn wà ní ilẹ̀ Ṣinari. 11Láti ilẹ̀ náà ni ó ti lọ sí Asiria, níbi tí ó ti tẹ ìlú Ninefe, Rehoboti àti Kala, 12àti Resini, tí ó wà ní àárín Ninefe àti Kala, tí ó jẹ́ ìlú olókìkí.

13Misraimu sì bí

Ludimu, Anamimu, Lehabimu, Naftuhimu. 14Patrusimu, Kasluhimu, (láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwọn ará Filistini ti wá) àti àwọn ará Kaftorimu.

15Kenaani sì bí Sidoni àkọ́bí rẹ̀,

àti Heti. 16Àti àwọn ará Jebusi, àti àwọn ará Amori, àti àwọn ará Girgaṣi, 17àti àwọn ará Hifi, àti àwọn ará Arki, àti àwọn ará Sini, 18àti àwọn ará Arfadi, àti àwọn ará Ṣemari, àti àwọn ará Hamati.

Lẹ́yìn èyí ni àwọn ẹ̀yà Kenaani tànkálẹ̀. 19Ààlà ilẹ̀ àwọn ará Kenaani sì dé Sidoni, lọ sí Gerari títí dé Gasa, lọ sí Sodomu, Gomorra, Adma àti Ṣeboimu, títí dé Laṣa.

20Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Hamu, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, àti èdè wọn, ní ìpínlẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.

Ìran Ṣemu

21A bí àwọn ọmọ fún Ṣemu tí Jafeti jẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin: Ṣemu sì ni baba gbogbo àwọn ọmọ Eberi.

22Àwọn ọmọ Ṣemu ni:

Elamu, Aṣuri, Arfakṣadi, Ludi àti Aramu.

23Àwọn ọmọ Aramu ni:

Usi, Huli, Geteri àti Meṣeki.

24Arfakṣadi sì bí Ṣela,

Ṣela sì bí Eberi.

25Eberi sì bí ọmọ méjì:

ọ̀kan ń jẹ́ Pelegi, nítorí ní ìgbà ọjọ́ rẹ̀ ni ilẹ̀ ya; orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Joktani.

26Joktani sì bí

Almodadi, Ṣelefi, Hasarmafeti, Jera. 27Hadoramu, Usali, Dikla, 28Obali, Abimaeli, Ṣeba. 29Ofiri, Hafila àti Jobabu. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Joktani.

30Agbègbè ibi tí wọn ń gbé bẹ̀rẹ̀ láti Meṣa títí dé Sefari, ní àwọn ilẹ̀ tó kún fún òkè ní ìlà-oòrùn.

31Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Ṣemu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, ní èdè wọn, ní ilẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.

32Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Noa gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, ní orílẹ̀-èdè wọn. Ní ipasẹ̀ wọn ni àwọn ènìyàn ti tàn ká ilẹ̀ ayé lẹ́yìn ìkún omi.

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

创世记 10:1-32

挪亚三个儿子的后代

1洪水以后,挪亚的儿子雅弗都生养了儿女,以下是他们的后代。

2雅弗的儿子是歌篾玛各玛代雅完土巴米设提拉3歌篾的儿子是亚实基拿利法陀迦玛4雅完的儿子是以利沙他施基提多单5雅弗的这些后裔按宗族、语言和民族分散在各海岛。

6的儿子是古实麦西10:6 麦西”希伯来文是Mizraim,就是“埃及”,13节亦同。迦南7古实的儿子是西巴哈腓拉撒弗他拉玛撒弗提迦拉玛的儿子是示巴底但

8古实也是宁录之父,宁录是世上第一位勇士, 9在耶和华眼中是个孔武有力的猎人,因此有俗话说:“要像宁录那样在耶和华眼中是个孔武有力的猎人。” 10他首先在示拿地区的巴别以力亚甲甲尼各地建国, 11后来扩展到亚述,在那里建立了尼尼微利河伯迦拉各城, 12又在尼尼微迦拉之间建立了利鲜大城。

13麦西的后代有路低人、亚拿米人、利哈比人、拿弗土希人、 14帕斯鲁细人、迦斯路希人和迦斐托人。非利士人是迦斐托人的后代。

15迦南生长子西顿和次子16他的后代还有耶布斯人、亚摩利人、革迦撒人、 17希未人、亚基人、西尼人、 18亚瓦底人、洗玛利人和哈马人。后来迦南各宗族散居在各地。 19迦南的疆域从西顿基拉耳延伸,远至迦萨,再向所多玛蛾摩拉押玛洗扁延伸,远至拉沙20以上记载的都是的子孙,他们根据自己的宗族、语言、地域和民族散居各处。

21雅弗的哥哥希伯子孙的祖先。 22的儿子是以拦亚述亚法撒路德亚兰23亚兰的儿子是乌斯户勒基帖玛施24亚法撒沙拉沙拉希伯25希伯有两个儿子,一个名叫法勒,意思是分开,因为那时人们分地而居。法勒的兄弟叫约坍26约坍亚摩答沙列哈萨玛非耶拉27哈多兰乌萨德拉28俄巴路亚比玛利示巴29阿斐哈腓拉约巴。这些都是约坍的儿子。 30他们居住的地方,从米沙直到东边的西发山区。 31以上记载的都是的子孙,他们按着自己的宗族、语言、地域和民族散居各处。

32这些人都是洪水以后挪亚三个儿子所生的子孙,他们按着自己的族系散居在各地,后来成为地上不同的民族。