Filipi 4 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Filipi 4:1-23

1Nítorí náà ẹ̀yin ará mi olùfẹ́, ti mo sì ń ṣàfẹ́rí gidigidi, ayọ̀ àti adé mi, ẹ dúró ṣinṣin bẹ́ẹ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olùfẹ́ mi.

Àwọn ọ̀rọ̀ ìyànjú

2Èmi ń bẹ̀ Euodia, mo sì ń bẹ Sintike, kí wọn ní inú kan náà nínú Olúwa. 34.3: Lk 10.20.Mo sì bẹ̀ yin pẹ̀lú bí alájọru àjàgà mi tòótọ́, ran àwọn obìnrin wọ̀nyí lọ́wọ́, nítorí wọn bá mi ṣiṣẹ́ pọ̀ ní ìfẹ̀gbẹ́-kẹ̀gbẹ́ nínú ìhìnrere, àti Klementi pẹ̀lú, àti àwọn olùbáṣiṣẹ́ mi yòókù pẹ̀lú, orúkọ àwọn tí ń bẹ nínú ìwé ìyè.

4Ẹ máa yọ̀ nínú Olúwa nígbà gbogbo: mo sì tún wí pé. Ẹ máa yọ̀. 5Ẹ jẹ́ ki ìpamọ́ra yín di mímọ́ fún gbogbo ènìyàn, Olúwa ń bẹ nítòsí. 64.6: Mt 6.25-34.Ẹ má ṣe ṣe àníyàn ohunkóhun; ṣùgbọ́n nínú ohun gbogbo, nípa àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ pẹ̀lú ìdúpẹ́, ẹ máa fi ìbéèrè yín hàn fún Ọlọ́run. 7Àti àlàáfíà Ọlọ́run, tí ó ju ìmòye gbogbo lọ, yóò pa ọkàn àti èrò yín mọ nínú Kristi Jesu.

8Ní àkótán, ará, ohunkóhun tí í ṣe òtítọ́, ohunkóhun tí í ṣe ọ̀wọ̀, ohunkóhun tí í ṣe títọ́ ohunkóhun tí í ṣe mímọ́, ohunkóhun tí í ṣe fífẹ́, ohunkóhun tí ó ni ìròyìn rere, bí ìwà títọ́ kan bá wà, bí ìyìn kan bá sì wà, ẹ máa gba nǹkan wọ̀nyí rò. 94.9: Ro 15.33.Àwọn nǹkan tí ẹ̀yin ti kọ́, tí ẹ̀yin sì ti gbà, tí ẹ̀yin sì ti gbọ́, tí ẹ̀yin sì ti rí lọ́wọ́ mi, ẹ máa ṣe wọ́n: Ọlọ́run àlàáfíà yóò sì wà pẹ̀lú yín.

Àwọn ọpẹ́ fún àwọn ẹ̀bùn wọn

104.10: 2Kọ 11.9.Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa pé, nísinsin yìí, ẹ̀yin tún ti sọjí nínú àníyàn ọkàn yín sí mi, nítòótọ́ ọkàn yín ń fàmọ́ mi ṣùgbọ́n ẹ kò ní àǹfààní tó. 11Kì í ṣe pé èmi ń sọ nítorí àìní: nítorí pé ni ipòkípò tí mo bá wà, mo tí kọ́ láti ní ìtẹ́lọ́rùn nínú rẹ̀. 12Mo mọ̀ ohun tí o jẹ láti wa nínú àìní, mo sì mọ ohun tí ó jẹ láti ni lọ́pọ̀lọpọ̀. Nínú ohunkóhun àti nínú ohun gbogbo mo ti kọ́ àṣírí láti máa jẹ́ àjẹyó tàbí láti wà ni àìjẹun, láti máa ni ànító àti láti ṣe aláìní. 134.13: 2Kọ 12.9.Èmi le ṣe ohun gbogbo nínú Kristi ẹni ti ń fi agbára fún mi.

14Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ṣeun gidigidi ní ti pé ẹ̀yin ṣe alábápín nínú ìpọ́njú mi. 15Ẹ̀yin pàápàá sì mọ̀ pẹ̀lú, ẹ̀yin ará Filipi, pé ni ìbẹ̀rẹ̀ ìhìnrere, nígbà tí mo kúrò ni Makedonia, kò sí ìjọ kan ti ó bá mi ń ṣe alábápín ní ti gbígbà àti fífún ni, bí kò ṣe ẹ̀yin nìkan ṣoṣo. 164.16: Ap 17.1-9; 1Tẹ 2.9.Nítorí ní Tẹsalonika ẹ̀yin fi nǹkan ránṣẹ́, lẹ́ẹ̀kan fún àìní mi. 17Kì í ṣe nítorí ti èmi ń fẹ́ ẹ̀bùn náà: ṣùgbọ́n èmi ń fẹ́ èso ti yóò máa di púpọ̀ nítorí yín 18Ṣùgbọ́n mo ní ohun gbogbo, mo sì ti di púpọ̀: mo sì tún ni lọ́pọ̀lọpọ̀ nígbà ti mo tí gba nǹkan wọ̀nyí lọ́wọ́ Epafiroditu tí a ti rán wá láti lọ́dọ̀ yín, ọrẹ olóòórùn dídùn, ẹbọ ìtẹ́wọ́gbà, tì í ṣe inú dídùn gidigidi sí Ọlọ́run. 19Ṣùgbọ́n Ọlọ́run mi yóò pèsè ní kíkún fún gbogbo àìní yín, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ̀ nínú ògo nínú Kristi Jesu.

20Ṣùgbọ́n ògo ni fún Ọlọ́run àti Baba wa láé àti láéláé. Àmín.

Ọ̀rọ̀ ìkíni ìkẹyìn

21Ẹ kí olúkúlùkù ènìyàn mímọ́ nínú Kristi Jesu.

Àwọn ará tí ó wà pẹ̀lú mi kí yín.

22Gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ kí yín, pàápàá àwọn tí ń ṣe ti agbo ilé Kesari.

234.23: Ga 6.18; Fm 25.Oore-ọ̀fẹ́ Jesu Kristi Olúwa wa, kí ó wà pẹ̀lú ẹ̀mí yín. Àmín.

New International Reader’s Version

Philippians 4:1-23

Remain Strong in the Lord

1My brothers and sisters, in this way remain strong in the Lord. I love you and long for you. Dear friends, you are my joy and my crown.

2Here is what I’m asking Euodia and Syntyche to do. I’m asking them to work together in the Lord. That’s because they both belong to the Lord. 3My true companion, here is what I ask you to do. Help these women, because they have served at my side. They have worked with me to spread the good news. So have Clement and the rest of those who have worked together with me. Their names are all written in the book of life.

Final Commands

4Always be joyful because you belong to the Lord. I will say it again. Be joyful! 5Let everyone know how gentle you are. The Lord is coming soon. 6Don’t worry about anything. No matter what happens, tell God about everything. Ask and pray, and give thanks to him. 7Then God’s peace will watch over your hearts and your minds. He will do this because you belong to Christ Jesus. God’s peace can never be completely understood.

8Finally, my brothers and sisters, always think about what is true. Think about what is noble, right and pure. Think about what is lovely and worthy of respect. If anything is excellent or worthy of praise, think about those kinds of things. 9Do what you have learned or received or heard from me. Follow my example. The God who gives peace will be with you.

Paul Gives Thanks for the Philippians’ Gifts

10At last you are concerned about me again. That makes me very happy. We belong to the Lord. I know that you were concerned. But you had no chance to show it. 11I’m not saying this because I need anything. I have learned to be content no matter what happens to me. 12I know what it’s like not to have what I need. I also know what it’s like to have more than I need. I have learned the secret of being content no matter what happens. I am content whether I am well fed or hungry. I am content whether I have more than enough or not enough. 13I can do all this by the power of Christ. He gives me strength.

14But it was good of you to share in my troubles. 15And you believers at Philippi know what happened when I left Macedonia. Not one church helped me in the matter of giving and receiving. You were the only one that did. That was in the early days when you first heard the good news. 16Even when I was in Thessalonica, you sent me help when I needed it. And you did it more than once. 17It is not that I want your gifts. What I really want is what is best for you. 18I have received my full pay and have more than enough. I have everything I need. That’s because Epaphroditus brought me the gifts you sent. They are a sweet-smelling offering. They are a gift that God accepts. He is pleased with it. 19My God will meet all your needs. He will meet them in keeping with his wonderful riches. These riches come to you because you belong to Christ Jesus.

20Give glory to our God and Father for ever and ever. Amen.

Final Greetings

21Greet all God’s people. They belong to Christ Jesus.

The brothers and sisters who are with me send greetings.

22All God’s people here send you greetings. Most of all, those who live in the palace of Caesar send you greetings.

23May the grace of the Lord Jesus Christ be with your spirit. Amen.