Filipi 1 – YCB & SNC

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Filipi 1:1-30

11.1: Ap 16.1,12-40; Ro 1.1; 2Kọ 1.1; Ga 1.10; Kl 1.1; 1Tẹ 1.1; 2Tẹ 1.1; Fm 1.Paulu àti Timotiu, àwọn ìránṣẹ́ Jesu Kristi.

Sí gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ nínú Kristi Jesu tí ó wà ní Filipi, pẹ̀lú àwọn alábojútó àti àwọn díákónì.

21.2: Ro 1.7.Oore-ọ̀fẹ́ sí yín, àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa, àti Olúwa wa Jesu Kristi.

Àdúrà àti Ọpẹ́

3Mo ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run mi ní gbogbo ìgbà tí mo bá rántí yín: 4Nínú gbogbo àdúrà mi fún un yín, èmi ń fi ayọ̀ gbàdúrà, 5nítorí ìdàpọ̀ yín nínú ìhìnrere láti ọjọ́ kìn-ín-ní wá títí di ìsinsin yìí. 61.6,10: 1Kọ 1.8.Ohun kan yìí sá à dá mi lójú pé, ẹni tí ó ti bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rere nínú yín, yóò ṣe àṣepé rẹ̀ títí di ọjọ́ náà tí Jesu Kristi yóò dé:

71.7: Ap 21.33; 2Kọ 7.3; Ef 6.20.Gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ fún mi láti ro èyí nípa gbogbo yín, nítorí tí mo fi yín sọ́kàn, bí mo tilẹ̀ wà nínú ìdè tàbí ìdáhùn ẹjọ́, àti ìfẹsẹ̀múlẹ̀ ìhìnrere, gbogbo yín jẹ́ alábápín oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run pẹ̀lú mi. 8Nítorí Ọlọ́run ni ẹlẹ́rìí mi, bí mo ti ń ṣàfẹ́rí yín gidigidi nínú ìfẹ́ Jesu Kristi.

9Èyí sì ni àdúrà mi: pé kí ìfẹ́ yín lè máa pọ̀ síwájú àti síwájú sí i nínú ìfẹ́ àti ìmọ̀ ìjìnlẹ̀, 10kí ẹ̀yin kí ó lè ní òye ohun tí ó dára jùlọ; kí ó sì jásí òdodo àti aláìjẹ́ ohun ìkọ̀sẹ̀ títí di ọjọ́ dídé Jesu Kristi: 11Lẹ́yìn ìgbà ti ẹ ti kún fún àwọn ìwà òdodo láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi, fún ògo àti ìyìn Ọlọ́run.

Ìrírí Paulu nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́

121.12: Lk 21.13.Ǹjẹ́ èmi fẹ́ kí ẹ̀yin kí ó mọ̀, ará, pé ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí mi jásí àtẹ̀gùn sí ìlọsíwájú ìhìnrere. 131.13: Ap 28.30; 2Tm 2.9.Nítorí ìdí èyí, ó ti hàn gbangba sí gbogbo àwọn ẹ̀ṣọ́ ààfin àti sí àwọn ẹlòmíràn wí pé mo wà nínú ìdè fún Kristi. 14Nítorí ìdè mi, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ará nínú Olúwa ni a ti mú lọ́kàn le láti sọ̀rọ̀ Ọlọ́run sí i pẹ̀lú ìgboyà àti láìbẹ̀rù.

15Òtítọ́ ni pé àwọn ẹlòmíràn tilẹ̀ ń fi ìjà àti ìlara wàásù Kristi, ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn sì ń fi inú rere ṣe é. 16Àwọn kan ń fi ìjà wàásù Kristi, kì í ṣe pẹ̀lú òtítọ́ inú, wọ́n ń gbèrò láti fi ìpọ́njú kún ìdè mi: 17Àwọn kan ẹ̀wẹ̀ si ń fi ìfẹ́ ṣe é, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé a gbé mi dìde láti dá ààbò bo iṣẹ́ ìhìnrere. 18Kí ló tún kù? Kìkì í pé níbi gbogbo, ìbá à ní ìfẹ̀tànṣe tàbí ni ti òtítọ́ a sá à n wàásù Kristi, èmi sì ń yọ̀ nítorí èyí.

Nítòótọ́, èmi ó sì máa yọ̀, 191.19: Ap 16.7; 2Kọ 1.11.nítorí tí mo mọ̀ pé èyí ni yóò yọrí sí ìgbàlà fún mi láti inú àdúrà yín wá, àti ìfikún ẹ̀mí Jesu Kristi, 201.20: Ro 14.8. Gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn àti ìrètí mi pé kí ojú kí ó má ṣe ti mi ní ohunkóhun, ṣùgbọ́n kí èmi kí ó le máa ni ìgboyà ní ìgbà gbogbo àti nísinsin yìí, kí a lè ti ipasẹ̀ mi gbé Kristi ga lára mi, ìbá à ṣe pé mo wà láààyè, tàbí mo kú. 211.21: Ga 2.20.Nítorí, ní ti èmi, láti wa láààyè jẹ́ Kristi, láti kú pẹ̀lú sì jẹ́ èrè fún mi. 22Ṣùgbọ́n bí èmi bá le è ṣe iṣẹ́ ti ó ni àpẹẹrẹ nípa wíwà láààyè nínú ara, ṣùgbọ́n ohun ti èmi ó yàn, èmi kò mọ̀. 23Ṣùgbọ́n èmi n ṣiyèméjì, nítorí ti èmi fẹ́ láti lọ kúrò nínú ayé yìí, láti wà lọ́dọ̀ Kristi; nítorí ó dára púpọ̀ jù: 24Síbẹ̀ láti wà láààyè jẹ́ àǹfààní nítorí tiyín. 25Bí èyí sì ti dá mi lójú, mo mọ̀ pé èmi ó dúró, èmi ó sì máa wà pẹ̀lú yín fún ìtẹ̀síwájú àti ayọ̀ yín nínú ìgbàgbọ́, 26kí ìṣògo yín kí ó lè di púpọ̀ gidigidi nínú Jesu Kristi, àti nínú mi nípa ìpadà wá mi sọ́dọ̀ yín.

27Ohun yówù kó ṣẹlẹ̀, ẹ jẹ́ kí ìgbé ayé yín ri gẹ́gẹ́ bí ìhìnrere Kristi: pé yálà bi mo tilẹ̀ wá wò yín, tàbí bí èmi kò wá, kí èmi kí ó lè máa gbúròó bí ẹ ti ń ṣe, pé ẹ̀yin dúró ṣinṣin nínú Ẹ̀mí kan, ẹ̀yin jùmọ̀ jìjàkadì nítorí ìgbàgbọ́ ìhìnrere, pẹ̀lú ọkàn kan; 281.28: 2Tẹ 1.5.Kí ẹ má sì jẹ́ ki àwọn ọ̀tá dẹ́rùbà yin ni ohunkóhun: èyí tí í ṣe ààmì tí ó dájú pé a ó pa wọ́n run, ṣùgbọ́n Ọlọ́run tìkára rẹ̀ ni yóò gbà yin là. 29Nítorí tí a ti fún yin ni àǹfààní, kì í ṣe láti gba Kristi gbọ́ nìkan, ṣùgbọ́n láti jìyà nítorí rẹ̀ pẹ̀lú: 301.30: Ap 16.19-40; 1Tẹ 2.2.Ẹ sì máa ja ìjà kan náà, èyí ti ẹ̀yin ti ri, ti ẹ sì ti gbọ́ pé èmi n jà pẹ̀lú.

Slovo na cestu

Filipským 1:1-30

Radostný pozdrav z římského vězení

1-2Milí křesťané ve Filipech, přijměte pozdrav ode mne i Timotea. Vám všem, vašim správcům a pomocníkům přejeme milost a pokoj od našeho nebeského Otce a od Ježíše Krista, našeho Pána.

3-5Kdykoliv si na vás vzpomenu, děkuji za vás všechny Bohu, že od chvíle, kdy jste poprvé slyšeli radostné poselství o Kristu, nepřestali jste mi pomáhat v jeho šíření. Za to jsem velmi vděčen. 6Nepochybuji, že když Bůh své dobré dílo u vás započal, dovede je až k slavnému konci v den Kristova návratu.

7Nemohu o vás smýšlet jinak; stali jste se mi zvlášť blízkými svou vnitřní účastí na všem, co jsem prožíval, ať už to bylo ve vězení nebo na svobodě, při obhajování pravdy o Kristu. 8Bůh ví, jak po vás všech toužím. Láska, kterou mne naplňuje Ježíš, mne táhne k vám.

9Prosím Boha, aby vás obdaroval poznáním a moudrostí a zdokonalil vás v lásce, 10abyste vždy správně rozlišovali dobré od zlého a neposkvrnili se ničím špatným až do příchodu Ježíšova. 11Každý váš skutek ať svědčí o Kristově moci ve vás a oslavuje tak Boha.

Pavlovo utrpení prospělo jiným

12Chci vám sdělit, bratři, že moje uvěznění se stalo vynikající reklamou pro Kristovu věc. 13I ten poslední písař u soudu totiž ví, že mým jediným proviněním je má víra v Krista, 14a zdá se, že ostatním bratřím to pomohlo zbavit se strachu, takže teď o Kristu hovoří daleko otevřeněji než dříve. 15Je sice pravda, že někteří to dělají jen ze závisti a ctižádosti, aby také získali pověst neohrožených kazatelů, a myslí si, že jim tady ve vězení budu závidět jejich úspěchy. 16Ale jiní mluví o Kristu z lásky k němu a ve mně vidí obhájce jeho učení. 17Ať však už rozhlašují Krista z pohnutek čistých nebo s postranními úmysly, jen když je hlásána zvěst o Kristu. Z toho se mohu vždy jen radovat.

Kdo je připraven pro Krista zemřít, ten umí i žít

18Vím, že soudní přelíčení tak či onak povede k dobrému. To mi zaručují vaše modlitby i Duch svatý, který stojí při mně. 19-20Proto doufám a těším se na to, že budu moci mluvit stejně směle, jak jsem to dělal dosud, a že z této pře vyjde Kristus vítězně, ať už sám vyváznu se zdravou kůží či nikoliv. 21Vždyť mým životem je Kristus, a proto i smrt mi bude ziskem. 22Zůstanu-li ovšem na živu, mohl bych ještě být užitečný lidem. 23Takže kdybych měl možnost volit, sám nevím, čemu bych dal přednost: zemřít a být s Kristem (to by mě přitahovalo nejvíc), 24anebo žít dál kvůli vám, což by bylo zase potřebnější. 25Ale nějak cítím, že mne ještě mezi vámi čeká práce, a tak se kloním k přesvědčení, že tentokrát tu ještě zůstanu, 26abyste rostli v radostné víře a měli v mém vysvobození další důvod k oslavě Krista.

27Bez ohledu na můj příští osud myslete však na to, abyste žili tak, jak se sluší na Kristovy vyznavače. A ať už vás budu moci navštívit nebo o vás jen uslyším, chci se dovídat, že držíte pevně pohromadě, spojeni úsilím o šíření Kristova poselství 28přes všechny zuřivé útoky nepřítele. Ten v tom bude vidět předzvěst své záhuby, ale pro vás je to důkaz, že Bůh je s vámi a že vám dal věčný život. 29Vždyť vám bylo dopřáno nejen v Krista uvěřit, 30ale také pro něho trpět ve stejném boji, jaký vedu já.