Esra 10 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Esra 10:1-44

Ìjẹ́wọ́ ẹsẹ̀ àwọn ènìyàn

1Nígbà tí Esra ń gbàdúrà tí ó sì ń jẹ́wọ́, ti ó ń sọkún ti ó sì ń gbárayílẹ̀ níwájú ilé Ọlọ́run, ogunlọ́gọ̀ àwọn ọmọ Israẹli ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ọmọdé pagbo yí i ká. Àwọn náà ń sọkún kíkorò. 2Nígbà náà ni Ṣekaniah ọmọ Jehieli, ọ̀kan lára ìran Elamu, sọ fún Esra pé, Àwa ti jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì láàrín àwọn ènìyàn tí ó wà yí wa ká. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ náà, ìrètí sì wà fún Israẹli 3Ní ṣinṣin yìí, ẹ jẹ́ kí a dá májẹ̀mú níwájú Ọlọ́run wa láti lé àwọn obìnrin yìí àti àwọn ọmọ wọn lọ. Gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀ràn Esra olúwa mi àti ti àwọn tí ó bẹ̀rù àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa. Ẹ jẹ́ kí a ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin. 4Dìde, nítorí, ọ̀rọ̀ tìrẹ ni èyí. Gbogbo wà yóò wá pẹ̀lú rẹ, mú ọkàn le kí o sì ṣe é.

5Nígbà náà ni Esra dìde, ó sì fi àwọn aṣíwájú àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo Israẹli sí abẹ́ ìbúra, láti ṣe ohun tí wọ́n dá lábàá. Wọ́n sì búra. 6Nígbà náà ni Esra padà sẹ́yìn kúrò níwájú ilé Ọlọ́run, ó sì lọ sí iyàrá Jehohanani ọmọ Eliaṣibu. Nígbà tí ó wà níbẹ̀, kò jẹ oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi, nítorí ó sì ń káàánú fún àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn.

7Ìkéde kan jáde lọ jákèjádò Juda àti Jerusalẹmu fún gbogbo àwọn ìgbèkùn láti péjọ sí Jerusalẹmu. 8Ẹnikẹ́ni tí ó ba kọ̀ láti jáde wá láàrín ọjọ́ mẹ́ta yóò pàdánù ohun ìní rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìpinnu àwọn ìjòyè àti àwọn àgbàgbà, àti pé a ó lé òun fúnrarẹ̀ jáde kúrò láàrín ìpéjọpọ̀ àwọn ìgbèkùn.

9Láàrín ọjọ́ mẹ́ta náà, gbogbo àwọn ọkùnrin Juda àti Benjamini tí péjọ sí Jerusalẹmu. Ní ogúnjọ́ oṣù kẹsànán, gbogbo àwọn ènìyàn jókòó sí ìta gbangba iwájú ilé Ọlọ́run, wọ́n wà nínú ìbànújẹ́ ńlá nítorí ọ̀ràn yìí, àti nítorí òjò púpọ̀ tó tì rọ̀. 10Nígbà náà ni àlùfáà Esra dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe àìṣòótọ́, ẹ ti fẹ́ obìnrin àjèjì, ẹ ti dá kún ẹ̀bi Israẹli. 11Nísinsin yìí, ẹ jẹ́wọ́ níwájú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba yín, kí ẹ sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn tí ó yí i yín ká àti láàrín àwọn ìyàwó àjèjì yín.”

12Àpéjọpọ̀ ènìyàn náà sì dáhùn lóhùn rara pé: ohun tí ó sọ dára! A gbọdọ̀ ṣe bí o ti wí. 13Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ni ó wà ni ibi yìí síbẹ̀ àkókò òjò ni; àwa kò sì lè dúró ní ìta. Yàtọ̀ sí èyí, a kò le è yanjú ọ̀rọ̀ yìí láàrín ọjọ́ kan tàbí ọjọ́ méjì, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa pọ̀ jọjọ lórí àwọn nǹkan wọ̀nyí. 14Jẹ́ kí àwọn ìjòyè wa ṣojú fún gbogbo ìjọ ènìyàn, lẹ́yìn náà, jẹ́ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú àwọn ìlú wa tí ó ti fẹ́ obìnrin àjèjì wá ní àsìkò tí a yàn, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà àti àwọn onídàájọ́ ìlú kọ̀ọ̀kan, títí ìbínú gíga Ọlọ́run wa lórí ọ̀rọ̀ yìí yóò fi kúrò ní orí wa. 15Jonatani ọmọ Asaheli àti Jahseiah ọmọ Tikfa nìkan pẹ̀lú àtìlẹ́yìn Meṣullamu àti Ṣabbetai ará Lefi, ni wọ́n tako àbá yìí.

16Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe fi ẹnu kò sí. Àlùfáà Esra yan àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé, ẹnìkọ̀ọ̀kan láti ìdílé kọ̀ọ̀kan, gbogbo wọn ni a sì mọ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, wọ́n jókòó láti ṣe àyẹ̀wò àwọn ẹjọ́ náà, 17Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni wọn parí pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì.

Àwọn tó jẹ̀bi ẹ̀sùn ìgbéyàwó pẹ̀lú àjèjì

18Lára ìran àwọn àlùfáà àwọn wọ̀nyí fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì:

Nínú ìran Jeṣua ọmọ Josadaki, àti àwọn arákùnrin rẹ:

Maaseiah, Elieseri, Jaribi àti Gedaliah. 19Gbogbo wọn ni wọ́n ṣe ìpinnu láti lé àwọn ìyàwó wọn lọ, wọ́n sì fi àgbò kan láàrín agbo ẹran lélẹ̀ fún ẹ̀bi wọn gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀.

20Nínú ìran Immeri:

Hanani àti Sebadiah.

21Nínú ìran Harimu:

Maaseiah, Elijah, Ṣemaiah, Jehieli àti Ussiah.

22Nínú ìran Paṣuri:

Elioenai, Maaseiah, Iṣmaeli, Netaneli, Josabadi àti Eleasa.

23Lára àwọn ọmọ Lefi:

Josabadi, Ṣimei, Kelaiah (èyí tí í ṣe Kelita), Petahiah, Juda àti Elieseri.

24Nínú àwọn akọrin:

Eliaṣibu.

Nínú àwọn aṣọ́nà:

Ṣallumu, Telemu àti Uri.

25Àti lára àwọn ọmọ Israẹli tókù:

Nínú ìran Paroṣi:

Ramiah, Issiah, Malkiah, Mijamini, Eleasari, Malkiah àti Benaiah.

26Nínú ìran Elamu:

Mattaniah, Sekariah, Jehieli, Abdi, Jerimoti àti Elijah.

27Nínú àwọn ìran Sattu:

Elioenai, Eliaṣibu, Mattaniah, Jerimoti, Sabadi àti Asisa.

28Nínú àwọn ìran Bebai:

Jehohanani, Hananiah, Sabbai àti Atlai.

29Nínú àwọn ìran Bani:

Meṣullamu, Malluki, Adaiah, Jaṣubu, Ṣeali àti Jerimoti.

30Nínú àwọn Pahati-Moabu:

Adma, Kelali, Benaiah, Maaseiah, Mattaniah, Besaleli, Binnui àti Manase.

31Nínú àwọn ìran Harimu:

Elieseri, Iṣiah, Malkiah àti Ṣemaiah, Simeoni, 32Benjamini, Malluki àti Ṣemariah.

33Nínú àwọn ìran Haṣumu:

Mattenai, Mattatta, Sabadi, Elifaleti, Jeremai, Manase àti Ṣimei.

34Nínú àwọn ìran Bani:

Maadai, Amramu, Ueli, 35Benaiah, Bediah, Keluhi 36Faniah, Meremoti, Eliaṣibu, 37Mattaniah, Mattenai àti Jaasu.

38Àti Bani, àti Binnui:

Ṣimei, 39Ṣelemiah, Natani, Adaiah, 40Maknadebai, Sasai, Ṣarai, 41Asareeli, Ṣelemiah, Ṣemariah, 42Ṣallumu, Amariah àti Josẹfu.

43Nínú àwọn ìran Nebo:

Jeieli, Mattitiah, Sabadi, Sebina, Jaddai, Joeli àti Benaiah.

44Gbogbo àwọn wọ̀nyí ló fẹ́ obìnrin àjèjì, àwọn mìíràn nínú wọn sì bi ọmọ ní ipasẹ̀ àwọn ìyàwó wọ̀nyí.

Persian Contemporary Bible

عزرا 10:1-44

جدايی از زنان غيريهودی

1همانطور كه عزرا در مقابل خانهٔ خدا روی بر زمين نهاده بود و گريه‌كنان دعا و اعتراف می‌كرد، عده زيادی از مردان و زنان و اطفال اسرائيلی نيز دورش جمع شدند و با او گريه كردند.

2سپس شكنيا پسر يحی‌ئيل كه از طايفهٔ عيلام بود به عزرا گفت: «ما اعتراف می‌كنيم كه نسبت به خدای خود گناه ورزيده‌ايم، چون با زنان غيريهودی ازدواج كرده‌ايم. ولی با وجود اين، باز اميدی برای بنی‌اسرائيل باقی است. 3اينک در حضور خدای خويش قول می‌دهيم كه از زنان خود جدا شويم و آنها را با فرزندانشان از اين سرزمين دور كنيم. ما در اين مورد از دستور تو و آنانی كه از خدا می‌ترسند پيروی می‌كنيم، و طبق شريعت عمل می‌نماييم. 4حال برخيز و به ما بگو چه كنيم. ما از تو پشتيبانی خواهيم كرد، پس نااميد نباش و آنچه لازم است انجام بده.»

5آنگاه عزرا بلند شد و از سران كاهنان و لاويان و تمام بنی‌اسرائيل خواست تا قسم بخورند كه هر چه شكنيا گفته است انجام دهند؛ و همه قسم خوردند. 6سپس عزرا از برابر خانهٔ خدا برخاست و به اتاق يهوحانان (پسر الياشيب) رفت و شب در آنجا ماند، ولی نه نان خورد و نه آب نوشيد، چون به سبب گناه قوم ماتم گرفته بود.

7‏-8پس در سراسر يهودا و اورشليم اعلام شد كه تمام قوم بايد در عرض سه روز در اورشليم جمع شوند و اگر كسی از آمدن خودداری كند طبق تصميم سران و بزرگان قوم اموال او ضبط خواهد گرديد و خود او هم از ميان قوم اسرائيل طرد خواهد شد. 9پس از سه روز كه روز بيستم ماه نهم بود، تمام مردان يهودا و بنيامين در اورشليم جمع شدند و در ميدان جلو خانهٔ خدا نشستند. آنها به سبب اهميت موضوع و به خاطر باران شديدی كه می‌باريد، می‌لرزيدند. 10سپس عزرای كاهن بلند شد و به ايشان چنين گفت: «شما مرتكب گناه شده‌ايد، چون با زنان غيريهودی ازدواج كرده‌ايد و با اين كارتان به گناهان بنی‌اسرائيل افزوده‌ايد. 11حال در حضور خداوند، خدای اجدادتان به گناهان خود اعتراف كنيد و خواست او را به جا آوريد. خود را از قومهايی كه در اطراف شما هستند دور نگه دارید و از اين زنان بيگانه جدا شويد.»

12همه با صدای بلند جواب دادند: «آنچه گفته‌ای انجام می‌دهيم. 13ولی اين كار يكی دو روز نيست. چون عدهٔ كسانی كه به چنين گناهی آلوده شده‌اند زياد است. در ضمن باران هم به شدت می‌بارد و بيش از اين نمی‌توانيم در اينجا بايستيم. 14بگذار سران ما در اورشليم بمانند و به اين كار رسيدگی كنند. سپس هر كس كه زن غيريهودی دارد، در وقت تعيين شده با بزرگان و قضات شهر خود بيايد تا به وضعش رسيدگی شود و خشم خدای ما از ما برگردد.» 15كسی با اين پيشنهاد مخالفت نكرد، جز يوناتان (پسر عسائيل) و يحزيا (پسر تقوه) كه از پشتيبانی مشلام و شبتای لاوی برخوردار بودند.

16قوم اين روش را پذيرفتند و عزرای كاهن چند نفر از سران طايفه‌ها را انتخاب كرد و اسامی‌شان را نوشت. اين گروه، روز اول ماه دهم تحقيق خود را شروع كردند، 17و در عرض سه ماه به وضع مردانی كه همسران بيگانه داشتند رسيدگی نمودند.

اسامی مردانی كه زنان بيگانه داشتند

18اين است اسامی مردانی كه زنان بيگانه داشتند:

از كاهنان:

از طايفه يهوشع پسر يهوصادق و برادرانش: معسيا، اليعزر، ياريب، جدليا. 19اين مردان قول دادند كه از همسران بيگانهٔ خود جدا شوند و هر يک برای بخشيده شدن گناهش، يک قوچ برای قربانی تقديم كرد.

20از طايفهٔ امير: حنانی و زبديا.

21از طايفه حاريم: معسيا، ايليا، شمعيا، يحی‌ئيل، عزيا.

22از طايفه فشحور: اليوعينای، معسيا، اسماعيل، نتن‌ئيل، يوزاباد، العاسه.

23از لاويان:

يوزاباد، شمعی، قلايا (معروف به قليطا)، فتحيا، يهودا، اليعزر.

24از نوازندگان:

الياشيب.

از نگهبانان خانه خدا:

شلوم، طالم، اوری.

25از بقيه قوم:

از طايفه فرعوش: رميا، يزيا، ملكيا، ميامين، العازار، ملكيا، بنايا.

26از طايفه عيلام: متنيا، زكريا، يحی‌ئيل، عبدی، يريموت، ايليا.

27از طايفه زتو: اليوعينای، الياشيب، متنيا، يريموت، زاباد، عزيزا.

28از طايفه ببای: يهوحانان، حننيا، زبای، عتلای.

29از طايفهٔ بانی: مشلام، ملوک، عدايا، ياشوب، شآل، راموت.

30از طايفهٔ فحت موآب: عدنا، كلال، بنايا، معسيا، متنيا، بصل‌ئيل، بنوی، منسی.

31‏-32از طايفهٔ حاريم: اليعزر، اشياء، ملكيا، شمعيا، شمعون، بنيامين، ملوک، شمريا.

33از طايفهٔ حاشوم: متنای، متاته، زاباد، اليفلط، يريمای، منسی، شمعی.

34‏-37از طايفه بانی: معدای، عمرام، اوئيل، بنايا، بيديا، كلوهی، ونيا، مريموت، الياشيب، متنيا، متنای، يعسو.

38‏-42از طايفهٔ بنوی: شمعی، شلميا، ناتان، عدايا، مكندبای، شاشای، شارای، عزرئيل، شلميا، شمريا، شلوم، امريا، يوسف.

43از طايفه نبو: يعی‌ئيل، متتيا، زاباد، زبينا، يدو، يوئيل، بنايا.

44همهٔ اين مردان، زنان بيگانه گرفته بودند و بعضی از ايشان از اين زنان صاحب فرزندانی شده بودند.