Esra 10 – YCB & CCBT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Esra 10:1-44

Ìjẹ́wọ́ ẹsẹ̀ àwọn ènìyàn

1Nígbà tí Esra ń gbàdúrà tí ó sì ń jẹ́wọ́, ti ó ń sọkún ti ó sì ń gbárayílẹ̀ níwájú ilé Ọlọ́run, ogunlọ́gọ̀ àwọn ọmọ Israẹli ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ọmọdé pagbo yí i ká. Àwọn náà ń sọkún kíkorò. 2Nígbà náà ni Ṣekaniah ọmọ Jehieli, ọ̀kan lára ìran Elamu, sọ fún Esra pé, Àwa ti jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì láàrín àwọn ènìyàn tí ó wà yí wa ká. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ náà, ìrètí sì wà fún Israẹli 3Ní ṣinṣin yìí, ẹ jẹ́ kí a dá májẹ̀mú níwájú Ọlọ́run wa láti lé àwọn obìnrin yìí àti àwọn ọmọ wọn lọ. Gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀ràn Esra olúwa mi àti ti àwọn tí ó bẹ̀rù àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa. Ẹ jẹ́ kí a ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin. 4Dìde, nítorí, ọ̀rọ̀ tìrẹ ni èyí. Gbogbo wà yóò wá pẹ̀lú rẹ, mú ọkàn le kí o sì ṣe é.

5Nígbà náà ni Esra dìde, ó sì fi àwọn aṣíwájú àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo Israẹli sí abẹ́ ìbúra, láti ṣe ohun tí wọ́n dá lábàá. Wọ́n sì búra. 6Nígbà náà ni Esra padà sẹ́yìn kúrò níwájú ilé Ọlọ́run, ó sì lọ sí iyàrá Jehohanani ọmọ Eliaṣibu. Nígbà tí ó wà níbẹ̀, kò jẹ oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi, nítorí ó sì ń káàánú fún àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn.

7Ìkéde kan jáde lọ jákèjádò Juda àti Jerusalẹmu fún gbogbo àwọn ìgbèkùn láti péjọ sí Jerusalẹmu. 8Ẹnikẹ́ni tí ó ba kọ̀ láti jáde wá láàrín ọjọ́ mẹ́ta yóò pàdánù ohun ìní rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìpinnu àwọn ìjòyè àti àwọn àgbàgbà, àti pé a ó lé òun fúnrarẹ̀ jáde kúrò láàrín ìpéjọpọ̀ àwọn ìgbèkùn.

9Láàrín ọjọ́ mẹ́ta náà, gbogbo àwọn ọkùnrin Juda àti Benjamini tí péjọ sí Jerusalẹmu. Ní ogúnjọ́ oṣù kẹsànán, gbogbo àwọn ènìyàn jókòó sí ìta gbangba iwájú ilé Ọlọ́run, wọ́n wà nínú ìbànújẹ́ ńlá nítorí ọ̀ràn yìí, àti nítorí òjò púpọ̀ tó tì rọ̀. 10Nígbà náà ni àlùfáà Esra dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe àìṣòótọ́, ẹ ti fẹ́ obìnrin àjèjì, ẹ ti dá kún ẹ̀bi Israẹli. 11Nísinsin yìí, ẹ jẹ́wọ́ níwájú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba yín, kí ẹ sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn tí ó yí i yín ká àti láàrín àwọn ìyàwó àjèjì yín.”

12Àpéjọpọ̀ ènìyàn náà sì dáhùn lóhùn rara pé: ohun tí ó sọ dára! A gbọdọ̀ ṣe bí o ti wí. 13Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ni ó wà ni ibi yìí síbẹ̀ àkókò òjò ni; àwa kò sì lè dúró ní ìta. Yàtọ̀ sí èyí, a kò le è yanjú ọ̀rọ̀ yìí láàrín ọjọ́ kan tàbí ọjọ́ méjì, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa pọ̀ jọjọ lórí àwọn nǹkan wọ̀nyí. 14Jẹ́ kí àwọn ìjòyè wa ṣojú fún gbogbo ìjọ ènìyàn, lẹ́yìn náà, jẹ́ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú àwọn ìlú wa tí ó ti fẹ́ obìnrin àjèjì wá ní àsìkò tí a yàn, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà àti àwọn onídàájọ́ ìlú kọ̀ọ̀kan, títí ìbínú gíga Ọlọ́run wa lórí ọ̀rọ̀ yìí yóò fi kúrò ní orí wa. 15Jonatani ọmọ Asaheli àti Jahseiah ọmọ Tikfa nìkan pẹ̀lú àtìlẹ́yìn Meṣullamu àti Ṣabbetai ará Lefi, ni wọ́n tako àbá yìí.

16Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe fi ẹnu kò sí. Àlùfáà Esra yan àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé, ẹnìkọ̀ọ̀kan láti ìdílé kọ̀ọ̀kan, gbogbo wọn ni a sì mọ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, wọ́n jókòó láti ṣe àyẹ̀wò àwọn ẹjọ́ náà, 17Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni wọn parí pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì.

Àwọn tó jẹ̀bi ẹ̀sùn ìgbéyàwó pẹ̀lú àjèjì

18Lára ìran àwọn àlùfáà àwọn wọ̀nyí fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì:

Nínú ìran Jeṣua ọmọ Josadaki, àti àwọn arákùnrin rẹ:

Maaseiah, Elieseri, Jaribi àti Gedaliah. 19Gbogbo wọn ni wọ́n ṣe ìpinnu láti lé àwọn ìyàwó wọn lọ, wọ́n sì fi àgbò kan láàrín agbo ẹran lélẹ̀ fún ẹ̀bi wọn gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀.

20Nínú ìran Immeri:

Hanani àti Sebadiah.

21Nínú ìran Harimu:

Maaseiah, Elijah, Ṣemaiah, Jehieli àti Ussiah.

22Nínú ìran Paṣuri:

Elioenai, Maaseiah, Iṣmaeli, Netaneli, Josabadi àti Eleasa.

23Lára àwọn ọmọ Lefi:

Josabadi, Ṣimei, Kelaiah (èyí tí í ṣe Kelita), Petahiah, Juda àti Elieseri.

24Nínú àwọn akọrin:

Eliaṣibu.

Nínú àwọn aṣọ́nà:

Ṣallumu, Telemu àti Uri.

25Àti lára àwọn ọmọ Israẹli tókù:

Nínú ìran Paroṣi:

Ramiah, Issiah, Malkiah, Mijamini, Eleasari, Malkiah àti Benaiah.

26Nínú ìran Elamu:

Mattaniah, Sekariah, Jehieli, Abdi, Jerimoti àti Elijah.

27Nínú àwọn ìran Sattu:

Elioenai, Eliaṣibu, Mattaniah, Jerimoti, Sabadi àti Asisa.

28Nínú àwọn ìran Bebai:

Jehohanani, Hananiah, Sabbai àti Atlai.

29Nínú àwọn ìran Bani:

Meṣullamu, Malluki, Adaiah, Jaṣubu, Ṣeali àti Jerimoti.

30Nínú àwọn Pahati-Moabu:

Adma, Kelali, Benaiah, Maaseiah, Mattaniah, Besaleli, Binnui àti Manase.

31Nínú àwọn ìran Harimu:

Elieseri, Iṣiah, Malkiah àti Ṣemaiah, Simeoni, 32Benjamini, Malluki àti Ṣemariah.

33Nínú àwọn ìran Haṣumu:

Mattenai, Mattatta, Sabadi, Elifaleti, Jeremai, Manase àti Ṣimei.

34Nínú àwọn ìran Bani:

Maadai, Amramu, Ueli, 35Benaiah, Bediah, Keluhi 36Faniah, Meremoti, Eliaṣibu, 37Mattaniah, Mattenai àti Jaasu.

38Àti Bani, àti Binnui:

Ṣimei, 39Ṣelemiah, Natani, Adaiah, 40Maknadebai, Sasai, Ṣarai, 41Asareeli, Ṣelemiah, Ṣemariah, 42Ṣallumu, Amariah àti Josẹfu.

43Nínú àwọn ìran Nebo:

Jeieli, Mattitiah, Sabadi, Sebina, Jaddai, Joeli àti Benaiah.

44Gbogbo àwọn wọ̀nyí ló fẹ́ obìnrin àjèjì, àwọn mìíràn nínú wọn sì bi ọmọ ní ipasẹ̀ àwọn ìyàwó wọ̀nyí.

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

以斯拉記 10:1-44

終止雜婚

1以斯拉禱告、認罪、哭泣、俯伏在上帝的殿前時,一大群以色列人,包括男女和孩子,都聚集到他那裡,與他一起痛哭。 2以攔宗族耶歇的兒子示迦尼以斯拉說:「我們對我們的上帝不忠,娶這地方的外族女子為妻,但以色列還有希望。 3現在,我們來與我們的上帝立約,聽從你和那些敬畏我們上帝誡命之人的指示,遵照律法而行,送走這些妻子和她們的兒女。 4起來吧!這事由你處理,我們支持你,放膽去做吧!」

5於是,以斯拉起來,要祭司長、利未人和所有以色列人起誓照這話去做,他們就都起了誓。 6以斯拉從上帝的殿前起來,進了以利亞實的兒子約哈難的房間。他在那裡不吃不喝,為流亡歸來者的不忠而憂傷。

7他們在猶大耶路撒冷發出通告,要求所有流亡歸來的人在耶路撒冷集合。 8按照眾首領和長老的決定,三天之內未到者,其財產會被沒收,他本人也要被逐出流亡歸來者的會。

9三天內,所有的猶大人和便雅憫人都聚集在耶路撒冷。九月二十日,大家都坐在上帝的殿前面的廣場上。因為這事,加上當時下大雨,眾人都戰戰兢兢。

10以斯拉祭司站起來對他們說:「你們對上帝不忠,娶外族的女子為妻,加重了以色列的罪惡。 11現在,你們要向你們祖先的上帝耶和華認罪,遵行祂的旨意,與這地方的人和你們的外族妻子斷絕關係。」

12會眾都高聲回答說:「你說的對,我們必照你的話做。 13可是,人這麼多,又逢大雨季節,我們不能總站在外面,並且這事一兩天也解決不了,因為我們在這事上犯了大罪。 14不如讓我們的首領為全體會眾處理這事,讓那些娶了外族女子為妻的人在指定的時間與本城的長老和審判官一起來找首領解決,直到我們的上帝因這事而發的烈怒離開我們。」

15只有撒黑的兒子約拿單特瓦的兒子雅哈謝反對這事,支持他們的還有米書蘭利未沙比太

16流亡歸來的人都遵照建議而行。以斯拉祭司按家族選出各族長,都是點名指定的。他們從十月一日開始著手查辦這事, 17到次年一月一日才查清娶外族女子為妻的人。

18祭司中娶外族女子為妻的有耶書亞的子孫約薩達的兒子及其弟兄瑪西雅以利以謝雅立基大利19他們答應休掉自己的妻子,並從羊群中獻上一隻公綿羊為自己贖罪。 20音麥的子孫中有哈拿尼西巴第雅21哈琳的子孫中有瑪西雅以利雅示瑪雅耶歇烏西雅22巴施戶珥的子孫中有以利約乃瑪西雅以實瑪利拿坦業約撒拔以利亞撒

23利未人中有約撒拔示每基拉雅——又名基利他毗他希雅猶大以利以謝24歌樂手中有以利亞實。殿門守衛中有沙龍提聯烏利

25其他以色列人中有巴錄的子孫拉米耶西雅瑪基雅米雅民以利亞撒瑪基雅比拿雅26以攔的子孫中有瑪他尼撒迦利亞耶歇押底耶利末以利雅27薩土的子孫中有以利約乃以利亞實瑪他尼耶利末撒拔亞西撒28比拜的子孫中有約哈難哈拿尼雅薩拜亞勒29巴尼的子孫中有米書蘭瑪鹿亞大雅雅述示押耶利末30巴哈·摩押的子孫中有阿底拿基拉比拿雅瑪西雅瑪他尼比撒列賓內瑪拿西31哈琳的子孫中有以利以謝伊示雅瑪基雅示瑪雅西緬32便雅憫瑪鹿示瑪利雅33哈順的子孫中有瑪特乃瑪達他撒拔以利法列耶利買瑪拿西示每34巴尼的子孫中有瑪玳暗蘭烏益35比拿雅比底雅基祿36瓦尼雅米利末以利亞實37瑪他尼瑪特乃雅掃38賓內的子孫中有示每39示利米雅拿單亞大雅40瑪拿底拜沙賽沙賴41亞薩利示利米雅示瑪利雅42沙龍亞瑪利雅約瑟43尼波的子孫中有耶利瑪他提雅撒拔西比拿雅玳約珥比拿雅

44以上這些人都娶了外族女子為妻,其中有些還生了子女。