Ìpohùnréré ẹkún fún Ejibiti
1Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá: wí pé: 2“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí o sì wí pé: ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí:
“ ‘Hu, kí o sì wí pé,
“Ó ṣe fún ọjọ́ náà!”
3Nítorí ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí
àní ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí
Ọjọ́ tí ọjọ́ ìkùùkuu ṣú dúdú,
àsìkò ìparun fún àwọn kèfèrí.
4Idà yóò wá sórí Ejibiti
ìrora ńlá yóò sì wá sórí Kuṣi
Nígbà tí àwọn tí a pa yóò ṣubú ní Ejibiti
wọn yóò kò ọrọ̀ rẹ̀ lọ
ìpìlẹ̀ rẹ̀ yóò sì wó lulẹ̀.
5Kuṣi àti Puti, Libia, Ludi àti gbogbo Arabia, Kubu àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó mulẹ̀ yóò ṣubú nípa idà pẹ̀lú Ejibiti.
6“ ‘Èyí yìí ní Olúwa wí:
“ ‘Àwọn àlejò Ejibiti yóò ṣubú
agbára ìgbéraga rẹ yóò kùnà
láti Migdoli títí dé Siene,
wọn yóò ti ipa idà ṣubú nínú rẹ;
ní Olúwa Olódùmarè wí.
7Wọn yóò sì wà
lára àwọn ilẹ̀ tí ó di ahoro,
ìlú rẹ yóò sì wà
ní ara àwọn ìlú tí ó di ahoro.
8Lẹ́yìn náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa,
nígbà tí mo bá gbé iná kalẹ̀ ní Ejibiti
tí gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ bá parun.
9“ ‘Ní ọjọ́ náà oníṣẹ́ yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde nínú ọkọ̀ ojú omi láti dẹ́rùbà Kuṣi tí ó wà nínú àlàáfíà. Ìrora yóò wá sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ ìparun Ejibiti: Kíyèsi i, ó dé.
10“ ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí:
“ ‘Èmi yóò mú òpin bá ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn
ènìyàn Ejibiti láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli.
11Òun àti àwọn ológun rẹ̀
ẹ̀rù àwọn orílẹ̀-èdè
ní a o mú wá láti pa ilẹ̀ náà run.
Wọn yóò fa idà wọn yọ sí Ejibiti
ilẹ̀ náà yóò sì kún fún àwọn tí a pa.
12Èmi yóò mú kí àwọn odò Naili gbẹ
Èmi yóò sì ta ilẹ̀ náà fún àwọn ènìyàn búburú:
láti ọwọ́ àwọn àjèjì ènìyàn
Èmi yóò jẹ́ kí ilẹ̀ náà àti gbogbo ohun tí ó wá nínú rẹ ṣòfò.
Èmi Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
13“ ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí:
“ ‘Èmi yóò pa àwọn òrìṣà run
Èmi yóò sì mú kí òpin dé bá ère gbígbẹ́ ni Memfisi.
Kò ní sí ọmọ-aládé mọ́ ní Ejibiti,
Èmi yóò mú kí ìbẹ̀rù gba gbogbo ilẹ̀ náà.
14Èmi yóò sì mú kí Paturosi di ahoro
èmi yóò fi iná sí Ṣoani
èmi yóò sì fi ìyà jẹ Tebesi.
15Èmi yóò tú ìbínú mi jáde sórí Pelusiumu
ìlú odi Ejibiti
èmi yóò sì ké àkójọpọ̀ Tebesi kúrò
16Èmi yóò ti iná bọ Ejibiti
Pelusiumu yóò japoró ní ìrora
Ìjì líle yóò jà ní Tebesi
Memfisi yóò wà ìpọ́njú ní ìgbà gbogbo
17Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ní Heliopolisi àti Bubasiti
yóò ti ipa idà ṣubú
wọn yóò sì kó àwọn ìlú wọn ní ìgbèkùn
18Ojú ọjọ́ yóò ṣókùnkùn ní Tafanesi
nígbà tí mo bá já àjàgà Ejibiti kúrò;
níbẹ̀ agbára iyì rẹ̀ yóò dópin
wọn yóò fi ìkùùkuu bò ó
àwọn abúlé rẹ ní wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
19Nítorí náà Èmi yóò mú ki ìjìyà wá sórí Ejibiti,
wọn yóò sì mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.’ ”
20Ní ọjọ́ keje oṣù kìn-ín-ní ọdún kọkànlá ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá: 21“Ọmọ ènìyàn, Èmi ti ṣẹ́ apá Farao ọba Ejibiti. A kò ì tí ì di apá náà papọ̀ láti mu kí ó san, a kò sì ti di i si àárín igi pẹlẹbẹ kí o lè ni agbára tó láti di idà mú. 22Nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí Farao ọba Ejibiti. Èmi yóò sẹ́ apá rẹ̀ méjèèjì, èyí tí ó dára àti èyí tí a ti ṣẹ́ pẹ̀lú, yóò sì mú kí idà bọ́ sọnù ní ọwọ́ rẹ̀. 23Èmi yóò sì fọ́n àwọn ènìyàn Ejibiti ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká gbogbo ilẹ̀. 24Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli ní agbára, èmi yóò sì fi idà mi sí ọwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ apá Farao, yóò sì kérora níwájú rẹ̀ bí ọkùnrin tí a sá ní àṣápa. 25Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli lé, ṣùgbọ́n apá Farao yóò sì rọ. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú idà mi sí ọwọ́ ọba Babeli yóò sì fi idà náà kọlu Ejibiti. 26Èmi yóò fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí gbogbo ilẹ̀. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”
A Lament Over Egypt
1The word of the Lord came to me: 2“Son of man, prophesy and say: ‘This is what the Sovereign Lord says:
“ ‘Wail and say,
“Alas for that day!”
3For the day is near,
the day of the Lord is near—
a day of clouds,
a time of doom for the nations.
4A sword will come against Egypt,
and anguish will come upon Cush.30:4 That is, the upper Nile region; also in verses 5 and 9
When the slain fall in Egypt,
her wealth will be carried away
and her foundations torn down.
5Cush and Libya, Lydia and all Arabia, Kub and the people of the covenant land will fall by the sword along with Egypt.
6“ ‘This is what the Lord says:
“ ‘The allies of Egypt will fall
and her proud strength will fail.
From Migdol to Aswan
they will fall by the sword within her,
declares the Sovereign Lord.
7“ ‘They will be desolate
among desolate lands,
and their cities will lie
among ruined cities.
8Then they will know that I am the Lord,
when I set fire to Egypt
and all her helpers are crushed.
9“ ‘On that day messengers will go out from me in ships to frighten Cush out of her complacency. Anguish will take hold of them on the day of Egypt’s doom, for it is sure to come.
10“ ‘This is what the Sovereign Lord says:
“ ‘I will put an end to the hordes of Egypt
by the hand of Nebuchadnezzar king of Babylon.
11He and his army—the most ruthless of nations—
will be brought in to destroy the land.
They will draw their swords against Egypt
and fill the land with the slain.
12I will dry up the waters of the Nile
and sell the land to an evil nation;
by the hand of foreigners
I will lay waste the land and everything in it.
I the Lord have spoken.
13“ ‘This is what the Sovereign Lord says:
“ ‘I will destroy the idols
and put an end to the images in Memphis.
No longer will there be a prince in Egypt,
and I will spread fear throughout the land.
14I will lay waste Upper Egypt,
set fire to Zoan
and inflict punishment on Thebes.
15I will pour out my wrath on Pelusium,
the stronghold of Egypt,
and wipe out the hordes of Thebes.
16I will set fire to Egypt;
Pelusium will writhe in agony.
Thebes will be taken by storm;
Memphis will be in constant distress.
17The young men of Heliopolis and Bubastis
will fall by the sword,
and the cities themselves will go into captivity.
18Dark will be the day at Tahpanhes
when I break the yoke of Egypt;
there her proud strength will come to an end.
She will be covered with clouds,
and her villages will go into captivity.
19So I will inflict punishment on Egypt,
and they will know that I am the Lord.’ ”
Pharaoh’s Arms Are Broken
20In the eleventh year, in the first month on the seventh day, the word of the Lord came to me: 21“Son of man, I have broken the arm of Pharaoh king of Egypt. It has not been bound up to be healed or put in a splint so that it may become strong enough to hold a sword. 22Therefore this is what the Sovereign Lord says: I am against Pharaoh king of Egypt. I will break both his arms, the good arm as well as the broken one, and make the sword fall from his hand. 23I will disperse the Egyptians among the nations and scatter them through the countries. 24I will strengthen the arms of the king of Babylon and put my sword in his hand, but I will break the arms of Pharaoh, and he will groan before him like a mortally wounded man. 25I will strengthen the arms of the king of Babylon, but the arms of Pharaoh will fall limp. Then they will know that I am the Lord, when I put my sword into the hand of the king of Babylon and he brandishes it against Egypt. 26I will disperse the Egyptians among the nations and scatter them through the countries. Then they will know that I am the Lord.”