Efesu 5 – YCB & SZ-PL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Efesu 5:1-33

1Nítorí náà, ẹ máa ṣe àfarawé Ọlọ́run bí àwọn olùfẹ́ ọmọ, 25.2: Ek 29.18; El 20.41.ẹ sì máa rìn ní ìfẹ́, gẹ́gẹ́ bí Kristi pẹ̀lú ti fẹ́ wa, tí ó sì fi ara rẹ̀ fún wa ní ọrẹ àti ẹbọ fún Ọlọ́run fún òórùn dídùn.

3Ṣùgbọ́n àgbèrè àti gbogbo ìwà èérí, tàbí ojúkòkòrò, kí a má tilẹ̀ dárúkọ rẹ̀ láàrín yín mọ́, bí ó ti yẹ àwọn ènìyàn mímọ́; 4Ìbá à ṣe ìwà ọ̀bùn, àti ìṣọ̀rọ̀ òmùgọ̀, tàbí ìṣẹ̀fẹ̀ àwọn ohun tí kò tọ́; ṣùgbọ́n ẹ kúkú máa dúpẹ́. 5Nítorí ẹ̀yin mọ èyí dájú pé, kò sí panṣágà, tàbí aláìmọ́ ènìyàn, tàbí wọ̀bìà, (tí í ṣé abọ̀rìṣà) tí yóò ni ìpín kan ni ìjọba Kristi àti Ọlọ́run. 6Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni fi ọ̀rọ̀ asán tàn yín jẹ: nítorí nípasẹ̀ nǹkan wọ̀nyí ní ìbínú Ọlọ́run fi ń bọ̀ wá sórí àwọn ọmọ aláìgbọ́ràn. 7Nítorí náà ẹ má ṣe jẹ́ alájọpín pẹ̀lú wọn.

8Nítorí ẹ̀yin tí jẹ́ òkùnkùn lẹ́ẹ̀kan ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin dí ìmọ́lẹ̀, nípa tí Olúwa: Ẹ máa rín gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ ìmọ́lẹ̀: 9(Nítorí èso Ẹ̀mí ni ìṣoore, àti òdodo àti òtítọ́). 10Ẹ sì máa wádìí ohun tí í ṣe ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa. 11Ẹ má sì ṣe bá àwọn oníṣẹ́ òkùnkùn kẹ́gbẹ́ pọ̀, ṣùgbọ́n ẹ kúkú máa bá wọn wí. 12Nítorí ìtìjú tilẹ̀ ni láti máa sọ̀rọ̀ nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí àwọn aláìgbọ́ràn ń ṣe ní ìkọ̀kọ̀. 13Ṣùgbọ́n ohun gbogbo tí a tú síta ni ìmọ́lẹ̀ ń fì hàn: nítorí ohunkóhun tí ó bá fi nǹkan hàn, ìmọ́lẹ̀ ni. 14Nítorí náà ni ó ṣe wí pé,

“Jí, ìwọ̀ ẹni tí ó sun,

sí jíǹde kúrò nínú òkú

Kristi yóò sì fún ọ ní ìmọ́lẹ̀.”

15Nítorí náà ẹ kíyèsi láti máa rìn ní ìwà pípé, kì í ṣé bí àwọn òmùgọ̀, ṣùgbọ́n bí àwọn ọlọ́gbọ́n; 165.16: Kl 4.5.Ẹ máa ra ìgbà padà, nítorí búburú ní àwọn ọjọ́. 17Nítorí náà, ẹ má ṣé jẹ aláìlóye, ṣùgbọ́n ẹ máa mòye ohun tí ìfẹ́ Olúwa jásí. 18Ẹ má sí ṣe mú wáìnì ní àmupara, nínú èyí tí rúdurùdu wà; ṣùgbọ́n ẹ kún fún Ẹ̀mí Mímọ́. 195.19: Kl 3.16-17.Ẹ sì máa bá ara yín sọ̀rọ̀ nínú Saamu, àti orin ìyìn, àti orin Ẹ̀mí, ẹ máa kọrin, kí ẹ sì máa kọrin dídùn ní ọkàn yín sí Olúwa. 20Ẹ máa dúpẹ́ nígbà gbogbo fún ohun gbogbo lọ́wọ́ Ọlọ́run, àní Baba, ní orúkọ Jesu Kristi Olúwa wá.

Àwọn aya àti ọkọ

21Ẹ máa tẹríba fún ara yín ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.

225.22–6.9: Kl 3.18–4.1.Ẹ̀yin aya, ẹ máa tẹríba fún àwọn ọkọ yín, gẹ́gẹ́ bí fún Olúwa. 23Nítorí pé ọkọ ni ó ń ṣe orí aya, gẹ́gẹ́ bí Kristi tí i ṣe orí ìjọ, tí òun si ń ṣe ara rẹ̀, Òun sì ni Olùgbàlà rẹ̀. 24Nítorí náà gẹ́gẹ́ bí ìjọ tí i tẹríba fún Kristi, bẹ́ẹ̀ sì ní kì àwọn aya máa ṣe sí ọkọ wọn ní ohun gbogbo.

25Ẹ̀yin ọkọ, ẹ fẹ́ràn àwọn aya yín, gẹ́gẹ́ bí Kristi tí fẹ́ràn ìjọ, tí ó sì fi ara rẹ̀ fún un. 26Kí òun lè sọ ọ́ di mímọ́ lẹ́yìn tí ó tí fi ọ̀rọ̀ wẹ̀ ẹ́ nínú agbada omí. 27Kí òun lé mú un wá sọ́dọ̀ ara rẹ̀ bí ìjọ tí ó ní ògo ní àìlábàwọ́n, tàbí àlébù kan, tàbí irú nǹkan bá-wọ̀n-ọn-nì: ṣùgbọ́n kí ó lè jẹ́ mímọ́ àti aláìlábùkù. 28Bẹ́ẹ̀ ní ó tọ́ kí àwọn ọkùnrin máa fẹ́ràn aya wọn gẹ́gẹ́ bí ara àwọn fúnrawọn. 29Nítorí kò sì ẹnìkan tí ó ti kórìíra ara rẹ̀; bí kò ṣe pé kí ó máa bọ́ ọ kí ó sì máa ṣìkẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Kristi sì ti ń ṣe sí ìjọ. 30Nítorí pé àwa ni ẹ̀yà ara rẹ̀, àti tí ẹran-ara rẹ̀, àti egungun ara rẹ̀. 315.31: Gẹ 2.24.Nítorí èyí ní ọkùnrin yóò fi baba àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀, òun yóò sì dàpọ̀ mọ́ aya rẹ̀, àwọn méjèèjì yóò sì di ara kan. 32Àṣírí ńlá ní èyí: ṣùgbọ́n èmí ń sọ nípá ti Kristi àti tí ìjọ. 33Ṣùgbọ́n kí olúkúlùkù yín fẹ́ràn aya rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òun fúnrarẹ̀; kí aya kí ó sì bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀.

Słowo Życia

Efezjan 5:1-33

Czyńmy to, co podoba się Panu

1Podążajcie za wzorem wyznaczonym przez Boga, bo jesteście Jego ukochanymi dziećmi. 2Okazujcie innym miłość, tak jak Chrystus okazał ją nam. On oddał przecież za nas swoje życie, a Jego ofiara została przyjęta przez Boga.

3Nie dawajcie nikomu najmniejszych podstaw do tego, aby podejrzewał was o rozwiązłość seksualną, nieczystość lub zachłanność—takie rzeczy nie pasują do życia świętych. 4Unikajcie nieprzyzwoitych i bezsensownych rozmów oraz dwuznacznych żartów. Niech z waszych ust płyną raczej słowa wdzięczności dla Boga. 5Możecie być pewni, że żaden człowiek, który prowadzi rozwiązłe lub nieczyste życie, nie wejdzie do królestwa Bożego. Nie znajdą się tam również ci, którzy są zachłanni—ich prawdziwym bogiem są bowiem pieniądze. 6Nie wierzcie w fałszywe, puste obietnice głoszące, że wszystko będzie w porządku! Bóg ukarze bowiem tych, którzy nie są Mu posłuszni i dopuszczają się wymienionych wcześniej grzechów. 7Unikajcie więc towarzystwa takich ludzi! 8Kiedyś i wy żyliście w ciemności, ale teraz, dzięki Panu, jesteście światłem! Niech więc będzie ono widoczne w waszym życiu! 9Owocem tego światła jest wszelkie dobro, prawość i prawda.

10Dążcie do tego, co się podoba naszemu Panu. 11Nie czyńcie zaś tego, co pochodzi z ciemności i jest bezwartościowe. Potępiajcie wszelkie takie zachowanie. 12Wstyd bowiem nawet mówić o tym, czego dokonują ludzie, którzy są nieposłuszni Bogu. Czyny te nie są jawne, 13ale gdy wychodzą na światło dzienne, okazuje się, jak bardzo są złe. 14To bowiem, co zostaje ujawnione, staje się widoczne w pełnym świetle. Dlatego mówi się:

„Obudź się, śpiący,

i powstań z martwych,

a Chrystus stanie się twoim światłem”.

15Uważajcie więc na to, jak postępujecie. Nie zachowujcie się jak głupcy, ale jak ludzie mądrzy. 16Wykorzystujcie każdą możliwość, aby w tych złych czasach czynić dobro. 17Nie bądźcie bezmyślni, ale starajcie się odkrywać wolę Pana. 18Nie upijajcie się, bo to rujnuje życie, ale bądźcie pełni Ducha Świętego. 19Gdy spotykacie się, śpiewajcie psalmy, hymny oraz inne duchowe pieśni, z głębi waszych serc oddając chwałę Panu. 20Zawsze i za wszystko dziękujcie Bogu Ojcu w imieniu naszego Pana, Jezusa Chrystusa.

Żony i mężowie

21Ze względu na Chrystusa okazujcie sobie nawzajem uległość.

22Żony, bądźcie uległe wobec swoich mężów, tak jak wobec Pana. 23Mąż jest bowiem głową żony, tak jak Chrystus jest Głową kościoła—Jego ciała. Jest też jego Zbawicielem! 24Tak jak kościół jest uległy wobec Chrystusa, tak wy macie być we wszystkim uległe wobec swoich mężów.

25A wy, mężowie, kochajcie żony z takim oddaniem, z jakim Chrystus pokochał kościół. On oddał za niego życie, 26aby uczynić go świętym i aby oczyścić go przez obmycie Bożym słowem. 27Chrystus uczynił to, aby przygotować dla siebie kościół jako wspaniałą narzeczoną—świętą i nienaganną, pozbawioną jakiejkolwiek skazy lub wady. 28Mężowie powinni więc kochać swoje żony jak własne ciało. Kto okazuje żonie miłość, okazuje ją własnemu ciału. 29Nikt przecież nie chce szkodzić własnemu ciału! Przeciwnie, każdy odżywia je i pielęgnuje. W taki sam sposób Chrystus troszczy się o kościół, 30który jest Jego ciałem i do którego należymy. 31Pismo mówi:

„Dlatego mężczyzna opuści rodziców

i złączy się z żoną,

tak że ci dwoje staną się jednym ciałem”.

32Jest to niezwykła tajemnica, ale ja na tym przykładzie chcę zobrazować jedność Chrystusa i Jego kościoła. 33Niech więc każdy mąż kocha żonę jak samego siebie, a żona niech okazuje szacunek mężowi.