Efesu 5 – YCB & CARS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Efesu 5:1-33

1Nítorí náà, ẹ máa ṣe àfarawé Ọlọ́run bí àwọn olùfẹ́ ọmọ, 25.2: Ek 29.18; El 20.41.ẹ sì máa rìn ní ìfẹ́, gẹ́gẹ́ bí Kristi pẹ̀lú ti fẹ́ wa, tí ó sì fi ara rẹ̀ fún wa ní ọrẹ àti ẹbọ fún Ọlọ́run fún òórùn dídùn.

3Ṣùgbọ́n àgbèrè àti gbogbo ìwà èérí, tàbí ojúkòkòrò, kí a má tilẹ̀ dárúkọ rẹ̀ láàrín yín mọ́, bí ó ti yẹ àwọn ènìyàn mímọ́; 4Ìbá à ṣe ìwà ọ̀bùn, àti ìṣọ̀rọ̀ òmùgọ̀, tàbí ìṣẹ̀fẹ̀ àwọn ohun tí kò tọ́; ṣùgbọ́n ẹ kúkú máa dúpẹ́. 5Nítorí ẹ̀yin mọ èyí dájú pé, kò sí panṣágà, tàbí aláìmọ́ ènìyàn, tàbí wọ̀bìà, (tí í ṣé abọ̀rìṣà) tí yóò ni ìpín kan ni ìjọba Kristi àti Ọlọ́run. 6Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni fi ọ̀rọ̀ asán tàn yín jẹ: nítorí nípasẹ̀ nǹkan wọ̀nyí ní ìbínú Ọlọ́run fi ń bọ̀ wá sórí àwọn ọmọ aláìgbọ́ràn. 7Nítorí náà ẹ má ṣe jẹ́ alájọpín pẹ̀lú wọn.

8Nítorí ẹ̀yin tí jẹ́ òkùnkùn lẹ́ẹ̀kan ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin dí ìmọ́lẹ̀, nípa tí Olúwa: Ẹ máa rín gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ ìmọ́lẹ̀: 9(Nítorí èso Ẹ̀mí ni ìṣoore, àti òdodo àti òtítọ́). 10Ẹ sì máa wádìí ohun tí í ṣe ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa. 11Ẹ má sì ṣe bá àwọn oníṣẹ́ òkùnkùn kẹ́gbẹ́ pọ̀, ṣùgbọ́n ẹ kúkú máa bá wọn wí. 12Nítorí ìtìjú tilẹ̀ ni láti máa sọ̀rọ̀ nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí àwọn aláìgbọ́ràn ń ṣe ní ìkọ̀kọ̀. 13Ṣùgbọ́n ohun gbogbo tí a tú síta ni ìmọ́lẹ̀ ń fì hàn: nítorí ohunkóhun tí ó bá fi nǹkan hàn, ìmọ́lẹ̀ ni. 14Nítorí náà ni ó ṣe wí pé,

“Jí, ìwọ̀ ẹni tí ó sun,

sí jíǹde kúrò nínú òkú

Kristi yóò sì fún ọ ní ìmọ́lẹ̀.”

15Nítorí náà ẹ kíyèsi láti máa rìn ní ìwà pípé, kì í ṣé bí àwọn òmùgọ̀, ṣùgbọ́n bí àwọn ọlọ́gbọ́n; 165.16: Kl 4.5.Ẹ máa ra ìgbà padà, nítorí búburú ní àwọn ọjọ́. 17Nítorí náà, ẹ má ṣé jẹ aláìlóye, ṣùgbọ́n ẹ máa mòye ohun tí ìfẹ́ Olúwa jásí. 18Ẹ má sí ṣe mú wáìnì ní àmupara, nínú èyí tí rúdurùdu wà; ṣùgbọ́n ẹ kún fún Ẹ̀mí Mímọ́. 195.19: Kl 3.16-17.Ẹ sì máa bá ara yín sọ̀rọ̀ nínú Saamu, àti orin ìyìn, àti orin Ẹ̀mí, ẹ máa kọrin, kí ẹ sì máa kọrin dídùn ní ọkàn yín sí Olúwa. 20Ẹ máa dúpẹ́ nígbà gbogbo fún ohun gbogbo lọ́wọ́ Ọlọ́run, àní Baba, ní orúkọ Jesu Kristi Olúwa wá.

Àwọn aya àti ọkọ

21Ẹ máa tẹríba fún ara yín ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.

225.22–6.9: Kl 3.18–4.1.Ẹ̀yin aya, ẹ máa tẹríba fún àwọn ọkọ yín, gẹ́gẹ́ bí fún Olúwa. 23Nítorí pé ọkọ ni ó ń ṣe orí aya, gẹ́gẹ́ bí Kristi tí i ṣe orí ìjọ, tí òun si ń ṣe ara rẹ̀, Òun sì ni Olùgbàlà rẹ̀. 24Nítorí náà gẹ́gẹ́ bí ìjọ tí i tẹríba fún Kristi, bẹ́ẹ̀ sì ní kì àwọn aya máa ṣe sí ọkọ wọn ní ohun gbogbo.

25Ẹ̀yin ọkọ, ẹ fẹ́ràn àwọn aya yín, gẹ́gẹ́ bí Kristi tí fẹ́ràn ìjọ, tí ó sì fi ara rẹ̀ fún un. 26Kí òun lè sọ ọ́ di mímọ́ lẹ́yìn tí ó tí fi ọ̀rọ̀ wẹ̀ ẹ́ nínú agbada omí. 27Kí òun lé mú un wá sọ́dọ̀ ara rẹ̀ bí ìjọ tí ó ní ògo ní àìlábàwọ́n, tàbí àlébù kan, tàbí irú nǹkan bá-wọ̀n-ọn-nì: ṣùgbọ́n kí ó lè jẹ́ mímọ́ àti aláìlábùkù. 28Bẹ́ẹ̀ ní ó tọ́ kí àwọn ọkùnrin máa fẹ́ràn aya wọn gẹ́gẹ́ bí ara àwọn fúnrawọn. 29Nítorí kò sì ẹnìkan tí ó ti kórìíra ara rẹ̀; bí kò ṣe pé kí ó máa bọ́ ọ kí ó sì máa ṣìkẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Kristi sì ti ń ṣe sí ìjọ. 30Nítorí pé àwa ni ẹ̀yà ara rẹ̀, àti tí ẹran-ara rẹ̀, àti egungun ara rẹ̀. 315.31: Gẹ 2.24.Nítorí èyí ní ọkùnrin yóò fi baba àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀, òun yóò sì dàpọ̀ mọ́ aya rẹ̀, àwọn méjèèjì yóò sì di ara kan. 32Àṣírí ńlá ní èyí: ṣùgbọ́n èmí ń sọ nípá ti Kristi àti tí ìjọ. 33Ṣùgbọ́n kí olúkúlùkù yín fẹ́ràn aya rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òun fúnrarẹ̀; kí aya kí ó sì bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀.

Священное Писание

Эфесянам 5:1-33

1Подражайте Всевышнему, будучи Его любимыми детьми. 2Живите в любви, как и Масих нас полюбил и отдал Самого Себя за нас как жертвенное приношение Всевышнему, в приятное благоухание. 3Среди вас ни в коем случае не должно быть даже намёка на разврат, или другую нечистоту, или жадность – это не подобает святому народу Всевышнего. 4В вашей речи не должно быть никаких непристойностей, пустой болтовни или грязных шуток, лучше благодарите Всевышнего. 5Знайте, что ни один человек: ни предающийся разврату, ни порочный, ни алчный – а это то же самое, что идолопоклонник, – не получит наследства в Царстве Масиха и Всевышнего. 6И пусть никто вас не обманывает, выступая против вышесказанного, потому что непокорность вызывает гнев Всевышнего. 7Не имейте ничего общего с такими людьми.

Дети света

8Когда-то вы были тьмой, но сейчас, в единении с Повелителем, вы стали светом. Живите как дети света. 9А плод света – это всякая доброта, праведность и истина. 10Старайтесь разузнать, что приятно Вечному Повелителю. 11Не участвуйте в бесплодных делах тьмы, напротив, обличайте эти дела. 12О том, чем такие люди занимаются втайне, даже стыдно говорить. 13Но всё тайное при свете становится явным. 14Свет делает всё видимым, поэтому и говорится:

«Проснись, спящий!

Воскресни из мёртвых!

И Масих осветит тебя»5:14 По всей вероятности, это были слова песни, которую пели в первых общинах последователей Масиха..

15Смотрите, живите не как глупые, но как мудрые. 16Дорожите временем, потому что в эти дни много зла. 17Не будьте легкомысленны, а лучше старайтесь понять, в чём заключена воля Вечного Повелителя. 18Не напивайтесь вином, это ведёт к распутству5:18 См. Мудр. 23:31-35; Ис. 5:11.. Но лучше исполняйтесь Духом. 19Наставляйте друг друга песнями из Забура, хвалебными и духовными песнопениями. Пойте и прославляйте Повелителя в ваших сердцах. 20Всегда и за всё благодарите Небесного Отца во имя нашего Повелителя Исы Масиха.

Взаимоотношения мужа и жены

21Подчиняйтесь друг другу из глубокого почтения к Масиху. 22Вы, жёны, подчиняйтесь вашим мужьям, как Повелителю Исе. 23Ведь муж – глава своей жене, как и Масих – глава и Спаситель Своего тела, вселенской общины Его последователей. 24И как эта община подчиняется Масиху, так и жёны должны во всём подчиняться своим мужьям.

25А вы, мужья, любите ваших жён так, как и Масих полюбил общину Своих последователей. Он Самого Себя отдал за неё, 26чтобы сделать её непорочной, очистив её водным омовением через слово5:26 Перед тем как выйти к своему жениху, невеста проходила церемонию омовения, и здесь, вероятно, представлена аллюзия на это событие. Комментаторы видят здесь очищение невесты, общины верующих, либо через слово Всевышнего (см. Ин. 15:3), либо символически, через обряд погружения в воду. В этом случае «слово» может относиться к исповедованию человеком, проходящим этот обряд, своей веры в Масиха., 27чтобы Ему поставить её перед Собой во всей её славе, как невесту, не имеющую пятна, или порока, или чего-то подобного, чтобы она была общиной святой и непорочной. 28Точно так и мужья должны любить своих жён, любить, как своё собственное тело. Тот, кто любит свою жену, любит самого себя. 29Ведь нет такого человека, кто бы ненавидел своё тело, но каждый питает своё тело и заботится о нём. Так и Масих заботится об общине Своих последователей, 30потому что мы – члены Его тела. 31«Поэтому оставит человек отца и мать и соединится со своей женой, и двое станут одной плотью»5:31 Нач. 2:24.. 32В этих словах скрыта великая истина, и я говорю вам, что они относятся к взаимоотношениям Масиха и вселенской общины Его последователей. 33А что касается вас, пусть каждый муж любит свою жену, как самого себя, и жена пусть почитает своего мужа.