Deuteronomi 1 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Deuteronomi 1:1-46

Àṣẹ láti jáde kúrò ní Horebu

1Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah: ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu. 2(Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)

3Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Ọlọ́run pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn. 4Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.

5Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:

6Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó. 7Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori: Ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate. 8Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín: Ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”

Yíyan àwọn olórí

91.9-15: Nu 11.10-25.Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé. 10Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run. 11Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí. 12Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín? 13Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”

14Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”

15Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín: olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín. 161.16-18: El 18.25,26.Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé: Ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò. 17Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́: Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ. 18Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.

A rán àwọn Ayọ́lẹ̀wò jáde

19Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea. 20Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa. 21Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, Ẹ má sì ṣe fòyà.”

221.22-46: Nu 13.1–14.45; 32.8-13.Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”

23Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. 24Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí Àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò. 25Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”

Ìṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa

26Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín. 27Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run. 28Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’ ”

29Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn. 30Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín 311.31: Ap 13.18.àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”

32Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín, 33tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.

34Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé: 35“Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín. 36Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”

37Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà, 38ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà. 39Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà. 40Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun pupa.”

41Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.

42Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’ ”

43Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà. 44Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma. 45Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín. 46Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.

Swedish Contemporary Bible

5 Moseboken 1:1-46

Återblick på ökentiden: Moses första tal

(1:1—4:43)

1Detta är det tal Mose höll till Israels folk i Moabs öken på östra sidan av floden Jordan mitt emot Suf mellan Paran och Tofel, Laban, Haserot och Di Sahav. 2Det tar elva dagar att gå från berget Horeb1:2 Horeb är ett annat namn på berget Sinai. till Kadesh Barnea om man tar vägen genom Seirs bergsbygd.1:2 Det tog Israel elva dagar att komma till Kanaans land första gången. Nu står de återigen vid gränsen, 38 år senare. Se v. 14,15. 3I det fyrtionde året1:3 Efter uttåget ur Egypten., på den första dagen i elfte månaden, meddelade Mose folket allt det som Herren hade befallt honom att säga till dem. 4Då hade Mose besegrat amoréernas kung Sichon som styrde i Heshbon. Vid Edrei hade han besegrat Og, kungen i Bashan, som styrde i Ashtarot. 5Det var öster om Jordan i Moab som Mose började undervisa om lagen. Han sa:

Ledare från varje stam

(2 Mos 18:13-27)

6Herren, vår Gud, sa till oss vid berget Horeb: ”Nu har ni stannat här tillräckligt länge. 7Gå nu till amoréernas bergsbygd och deras grannar i Jordandalen, bergsbygden, Låglandet, Negev och kusten, till Kanaans land och Libanon, ända till den stora floden Eufrat. 8Jag har gett er detta land. Gå nu och ta det land i besittning som Herren med ed lovade era förfäder Abraham, Isak och Jakob och alla deras ättlingar.”

9Då sa jag till er: ”Jag orkar inte bära ansvaret för er alldeles ensam, 10för Herren, er Gud, har förökat er så att ni är lika talrika som stjärnorna på himlen. 11Måtte han föröka er tusen gånger till och välsigna er som han har lovat, 12men hur ska jag ensam kunna bära den tunga börda ni är och de tvister som uppstår bland er? 13Välj alltså ut män från varje stam, sådana som är visa, erfarna och förståndiga, så ska jag låta dem bli era ledare!”

14Ni gick med på förslaget. 15Jag tog ledarna, kloka och erfarna män från varje stam, och lät dem bli ledare för er med ansvar över tusen, hundra, femtio eller tio. 16Jag förmanade era domare: ”Lyssna på era bröder och var rättvisa, såväl i tvister mellan bröder som i tvister med en utlänning. 17När ni dömer ska ni inte vara partiska. Lyssna till låg som hög. Var inte rädda för någon, för domen är Guds. Om det dyker upp något fall som ni tycker är för svårt, kan ni låta mig ta hand om det.” 18Samtidigt gav jag er också andra instruktioner om vad ni skulle göra.

De spejarna

(4 Mos 13:1-33)

19Sedan lämnade vi berget Horeb och vandrade genom den väldiga och fruktansvärda öken som ni ju själva har sett, tills vi slutligen kom fram till amoréernas bergsbygd, så som Herren, vår Gud, hade befallt oss. Vi kom till Kadesh Barnea. 20Där sa jag till er: ”Ni har nu kommit till amoréernas bergsbygd som Herren, vår Gud, har gett oss. 21Se, Herren, din Gud, har lagt landet framför dig! Gå nu och inta det, så som Herren, dina fäders Gud, har befallt. Var inte rädd och tveka inte!”

22Men då kom ni till mig och svarade: ”Låt oss först skicka iväg spejare som kan undersöka var det går bäst att ta sig in i landet och till vilka städer vi ska komma.”

23Det verkade vara ett bra förslag, så jag valde ut tolv spejare, en från varje stam. 24De gick över bergen och kom till Druvdalen och utforskade den. 25Sedan kom de tillbaka med olika frukter de plockat i landet. De rapporterade att det verkligen var ett bördigt land som Herren, vår Gud, ville ge oss.

Uppror mot Herren

(4 Mos 14:1-45)

26Men ni vägrade att gå in dit, ni gjorde uppror mot Herrens, er Guds, befallning. 27Ni muttrade och klagade i era tält och sa: ”Herren måste hata oss, eftersom han har lett oss hit från Egypten för att förgöras av dessa amoréer. 28Vad är det vi ger oss in i? Våra bröder som utforskade landet har skrämt oss med det de berättat, att folket i landet är stort och mäktigt och att städernas murar reser sig högt upp mot himlen. De har till och med sett Anaks ättlingar1:28 Se 4 Mos 13:33-34. där.”

29Jag sa då till er: ”Låt er inte skrämmas! Var inte rädda för dem! 30Herren, er Gud, går framför er och han kommer att strida för er, precis som ni såg honom göra i Egypten. 31Du såg ju också vilken omsorg han har haft om dig här i öknen, alldeles som en far som tar hand om sina barn, tills ni kommit ända hit.”

32Men ni vägrade trots detta att tro Herren, er Gud, 33som hade lett er hela vägen, valt ut lägerplatserna och gått före er i en eld om natten för att visa vägen och i ett moln om dagen.

34När Herren hörde hur ni klagade blev han arg. Han svor 35att inte en enda då levande vuxen från denna onda generation skulle få se det underbara land han hade lovat deras förfäder. 36Det enda undantaget var Kalev, Jefunnes son. Han hade helhjärtat följt Herren och därför skulle han och hans ättlingar få del av det land Kalev varit med om att utforska.

37Till och med på mig blev Herren arg för er skull. Han sa: ”Du ska inte få komma in dit! 38Istället ska din medhjälpare, Josua, Nuns son, komma dit. Uppmuntra honom, för han kommer att leda Israel och dela landet som arv åt dem. 39Era barn, de som ännu inte kan skilja på gott och ont, och som ni påstod skulle tillfångatas, de ska få komma dit, och till dem ska jag ge landet och de ska ta det i besittning. 40Men ni själva får vända om och gå tillbaka genom öknen mot Sävhavet.”

41Då svarade ni: ”Vi har syndat mot Herren. Vi vill gå och strida som Herren, vår Gud, har befallt oss.” Ni tog alltså era vapen och tänkte att det skulle bli en enkel sak att marschera upp i bergen.

42Men Herren sa till mig: ”Säg till dem att inte göra det, för jag tänker inte gå med dem. De kommer att besegras av fienden.”

43Jag sa detta till er, men ingen lyssnade. Istället handlade ni än en gång upproriskt mot Herrens befallning och gick i övermod upp i bergen. 44Men amoréerna som bodde där kom emot er som en bisvärm och dödade er hela vägen från Seir till Horma. 45Då återvände ni till Herren och grät inför honom, men han ville inte lyssna. 46Sedan blev ni kvar ganska länge i Kadesh.