Amosi 5 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Amosi 5:1-27

Wò mí kí o sì yè

1Gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ìwọ ilé Israẹli, ìpohùnréré ẹkún tí mo ṣe nípa rẹ:

2“Wúńdíá Israẹli ṣubú

láì kò sì le padà dìde

ó di ẹni ìkọ̀tì ní ilẹ̀ rẹ̀

kò sí ẹni tí yóò gbé e dìde.”

3Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí:

“Ìlú tí ẹgbẹ̀rún alágbára ti jáde,

yóò dín ku ọgọ́ọ̀rún ní Israẹli.

Ìlú tí ọgọ́ọ̀rún alàgbà ti jáde

yóò ṣẹ́kù ẹni mẹ́wàá.”

4Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ilé Israẹli:

“Wá mi kí o sì yè;

5Ẹ má ṣe wá Beteli,

Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali

Ẹ má ṣe rìnrìn àjò lọ sí Beerṣeba.

Nítorí dájúdájú a ó kó Gilgali ní ìgbèkùn

A ó sì sọ Beteli di asán.”

6Ẹ wá Olúwa, ẹ̀yin yóò sì yè,

kí ó má ba à gbilẹ̀ bí iná ní Josẹfu

a sì jó o run

Beteli kò sì ní rí ẹni tí yóò bu omi pa á.

7Ẹ̀yin tí ẹ̀ sọ òdodo di ìkorò

tí ẹ sì gbé olódodo ṣánlẹ̀.

8Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Pleiadesi àti Orioni

ẹni tí ó sọ òru dúdú di òwúrọ̀

tí ó sọ ọjọ́ dúdú di ìmọ́lẹ̀

ẹni tí ó wọ́ omi Òkun jọ pọ̀

tí ó sì rọ̀ wọ́n sí orí ilẹ̀

Olúwa ni orúkọ rẹ̀,

9Ó fọ́n ìparun sí ìlú olódi

tí ó sì sọ àwọn ibùgbé àwọn ọmọ-aládé di ahoro.

10Ìwọ kórìíra ẹni tí ń bá ni wí ní ẹnu ibodè

ó sì ń pẹ̀gàn ẹni tí ń sọ òtítọ́.

11Ìwọ ń tẹ tálákà mọ́lẹ̀

o ń fi ipá gba ọkà lọ́wọ́ wọn

Nítorí náà, ìwọ ti fi òkúta tí a gbẹ́ kọ́lé

ṣùgbọ́n ẹ kò sì ní gbé inú wọn

Nítòótọ́ ìwọ ti gbin ọgbà àjàrà tí ó lẹ́wà.

Ìwọ kò ní mu wáìnì inú wọn

12Nítorí mo mọ iye àìṣedéédéé rẹ

mo sì mọ bí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tí tóbi tó.

Ìwọ ni olódodo lára, ìwọ sì ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀

o sì ń fi òtítọ́ du tálákà ní ilé ẹjọ́

13Àwọn ọlọ́gbọ́n máa ń dákẹ́ jẹ́ẹ́ ní àkókò wọ̀nyí,

nítorí búburú ni gbogbo ọjọ́.

14Wá rere, má ṣe wá búburú

kí ìwọ ba à le yè

Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun yóò wà pẹ̀lú rẹ.

Òun yóò sì wà pẹ̀lú rẹ bí ìwọ ṣe wí

15Kórìíra búburú kí o sì fẹ́ rere

dúró ní orí òtítọ́ ní ilé ẹjọ́

bóyá Olúwa Ọlọ́run alágbára

yóò ṣíjú àánú wo ọmọ Josẹfu tó ṣẹ́kù.

16Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí:

“Ẹkún yóò wà ní àwọn òpópónà

igbe ìnira yóò sì wà ní àwọn gbàgede ìlú

A ó kó àwọn àgbẹ̀ jọ láti sọkún

àti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ láti pohùnréré ẹkún

17Ìpohùnréré ẹkún yóò wà ní gbogbo ọgbà àjàrà

Nítorí èmi yóò la àárín yín kọjá,”

ni Olúwa wí.

Ọjọ́ Olúwa

18Ègbé ni fún ìwọ tí ó pẹ́

nítorí ọjọ́ Olúwa

kí ni ìwọ fi pẹ́ fún ọjọ́ Olúwa?

Ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn ní ojú ọjọ́

19Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ó sá fún kìnnìún,

tí ó padà wá bọ́ sí ẹnu àmọ̀tẹ́kùn.

Yóò dàbí ẹni tí ó wọ ilé rẹ̀ lọ

tí ó sinmi lé ògiri ilé rẹ̀

tí ejò sì bù ú ṣán.

20Ǹjẹ́ ọjọ́ Olúwa kò ha ní ṣókùnkùn dípò kí ó ní ìmọ́lẹ̀?

Tí yóò sì ṣókùnkùn dúdú láìsí ìmọ́lẹ̀ kankan níbẹ̀.

21“Mo kórìíra, mo kẹ́gàn àwọn àsè ẹ̀sìn in yín

Èmi kò sì ní inú dídùn sí àpéjọ yín

22Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ mú ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà wá

Èmi kò ní tẹ́wọ́ gbà wọ́n

Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ mú àṣàyàn ọrẹ àlàáfíà wá.

Èmi kò ní náání wọn.

23Ẹ gbé ariwo orin yín sẹ́yìn

Èmi kò ní fetísí ohun èlò orin yín.

24Jẹ́ kí òtítọ́ sàn bí odò

àti òdodo bí ìsun tí kò lé è gbẹ!

255.25-27: Ap 7.42-43.“Àbí ẹ̀yin mú ẹbọ àti ọrẹ tọ̀ mí wá

ní ogójì ọdún ní aginjù ìwọ ilé Israẹli?

26Ẹ̀yin ti gbé ibi ìrúbọ àwọn ọba yín sókè

ibùgbé àwọn òrìṣà yín

àní, ti àwọn òrìṣà yín tí ó níyì jùlọ,

èyí tí ẹ̀yin fi ọwọ́ ara yín ṣe.

27Nítorí náà èmi yóò rán an yín lọ sí ìgbèkùn ní ìkọjá Damasku,”

ni Olúwa wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ọlọ́run alágbára.