Amosi 2 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Amosi 2:1-16

12.1-3: Isa 15–16; 25.10-12; Jr 48; El 25.8-11; Sf 2.8-11.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu,

àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,

Nítorí ó ti sun ún, di eérú,

egungun ọba Edomu

2Èmi yóò rán iná sí orí Moabu

èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run.

Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo

pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè

3Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò

Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,”

ni Olúwa wí.

4Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda,

àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà

Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀

wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́

Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà

òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé

5Èmi yóò rán iná sí orí Juda

èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”

Ìdájọ́ tí yóò wá sórí Israẹli

6Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli

àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.

Wọ́n ta olódodo fún fàdákà

àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.

7Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀

bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀

tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára

Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà

Láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́

8Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ

Lórí aṣọ tí wọ́n ti jẹ́ ẹ̀jẹ́

ní ilé òrìṣà wọn

wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.

9“Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn

gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari.

Òun sì le koko bí igi óákù

mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá

àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.

10Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá,

mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún

láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.

11“Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín

àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri

èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?”

ni Olúwa wí.

12“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu

e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.

13“Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀

bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.

14Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ

alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀

jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là

15Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀

bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin

kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là

16Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ

yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,”

ni Olúwa wí.

New International Version

Amos 2:1-16

1This is what the Lord says:

“For three sins of Moab,

even for four, I will not relent.

Because he burned to ashes

the bones of Edom’s king,

2I will send fire on Moab

that will consume the fortresses of Kerioth.2:2 Or of her cities

Moab will go down in great tumult

amid war cries and the blast of the trumpet.

3I will destroy her ruler

and kill all her officials with him,”

says the Lord.

4This is what the Lord says:

“For three sins of Judah,

even for four, I will not relent.

Because they have rejected the law of the Lord

and have not kept his decrees,

because they have been led astray by false gods,2:4 Or by lies

the gods2:4 Or lies their ancestors followed,

5I will send fire on Judah

that will consume the fortresses of Jerusalem.”

Judgment on Israel

6This is what the Lord says:

“For three sins of Israel,

even for four, I will not relent.

They sell the innocent for silver,

and the needy for a pair of sandals.

7They trample on the heads of the poor

as on the dust of the ground

and deny justice to the oppressed.

Father and son use the same girl

and so profane my holy name.

8They lie down beside every altar

on garments taken in pledge.

In the house of their god

they drink wine taken as fines.

9“Yet I destroyed the Amorites before them,

though they were tall as the cedars

and strong as the oaks.

I destroyed their fruit above

and their roots below.

10I brought you up out of Egypt

and led you forty years in the wilderness

to give you the land of the Amorites.

11“I also raised up prophets from among your children

and Nazirites from among your youths.

Is this not true, people of Israel?”

declares the Lord.

12“But you made the Nazirites drink wine

and commanded the prophets not to prophesy.

13“Now then, I will crush you

as a cart crushes when loaded with grain.

14The swift will not escape,

the strong will not muster their strength,

and the warrior will not save his life.

15The archer will not stand his ground,

the fleet-footed soldier will not get away,

and the horseman will not save his life.

16Even the bravest warriors

will flee naked on that day,”

declares the Lord.