Amosi 1 – YCB & TCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Amosi 1:1-15

1Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.

21.2: Jl 3.16.Ó wí pé:

Olúwa yóò bú jáde láti Sioni

ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá;

Ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀,

orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”

Ìdájọ́ àwọn aládùúgbò Israẹli

31.3-5: Isa 17.1-3; Jr 49.23-27; Sk 9.1.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku,

àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà

Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi.

Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú

4Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli

Èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.

5Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku;

Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní Àfonífojì Afeni run

àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni.

Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,”

ni Olúwa wí.

61.6-8: Isa 14.29-31; Jr 47; El 25.15-17; Jl 3.4-8; Sf 2.4-7; Sk 9.5-7.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa,

àní nítorí mẹ́rin,

Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà

Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú,

ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn.

Ó sì tà wọ́n fún Edomu,

7Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa

tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run

8Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò,

ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú.

Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni

títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,”

ni Olúwa Olódùmarè wí.

91.9-10: Isa 23; El 26.1–28.19; Jl 3.4-8; Sk 9.3-4.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire

àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà.

Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu

Wọn kò sì nání májẹ̀mú ọbàkan,

10Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire

Tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”

111.11-12: Isa 34; 63.1-6; Jr 49.7-22; El 25.12-14; 35; Ọd; Ml 1.2-5.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu,

àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà

Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀,

Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù

ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí

ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́

12Èmi yóò rán iná sí orí Temani

Tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”

131.13-15: Jr 49.1-6; El 21.28-32; 25.1-7; Sf 2.8-11.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni

àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,

Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi

kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.

14Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba

èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run

pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun,

pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.

15Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn

Òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,”

ni Olúwa wí.

Tagalog Contemporary Bible

Amos 1:1-15

1Ito ang mensahe ni Amos na isang pastol ng mga tupa na taga-Tekoa. Ang mensaheng ito ay tungkol sa Israel. Ipinahayag ito sa kanya ng Dios dalawang taon bago lumindol, noong panahon na si Uzia ang hari ng Juda at si Jeroboam na anak ni Joash ang hari ng Israel.

2Sinabi ni Amos: “Umaatungal ang Panginoon mula sa Zion;1:2 Zion: Isa ito sa mga tawag sa Jerusalem. dumadagundong ang tinig niya mula sa Jerusalem. Dahil dito natutuyo ang mga pastulan ng mga pastol at nalalanta ang mga tanim sa tuktok ng Bundok ng Carmel.”

Ang Parusa sa Bansang Syria

3Ito ang sinasabi ng Panginoon tungkol sa Syria: “Dahil sa patuloy na pagkakasala ng mga taga-Damascus,1:3 Damascus: Ito ang kabisera ng Syria at kumakatawan sa buong bansa ng Syria. parurusahan ko sila. Sapagkat pinagmalupitan nila ang mga taga-Gilead na parang giniik ng tabla na may mga ngiping bakal sa ilalim. 4Kaya susunugin ko ang palasyo ni Haring Hazael at ang matitibay na bahagi ng Damascus na ipinagawa ng anak niyang si Haring Ben Hadad. 5Wawasakin ko ang pintuan ng Damascus at papatayin ko ang pinuno ng Lambak ng Aven at ng Bet Eden.1:5 Lambak ng Aven at ng Bet Eden: Itoʼy mga lugar na sakop ng Syria. Bibihagin at dadalhin sa Kir ang mga mamamayan ng Syria.1:5 Syria: sa Hebreo, Aram. Ako, ang Panginoon, ang nagsasabi nito.”

Ang Parusa sa Bansang Filistia

6Ito ang sinasabi ng Panginoon tungkol sa Filistia: “Dahil sa patuloy na pagkakasala ng mga taga-Gaza,1:6 Gaza: Ang Gaza ay isa sa mga pangunahing lungsod ng Filistia at kumakatawan sa buong bansa ng Filistia. parurusahan ko sila. Sapagkat binihag nila ang lahat ng naninirahan sa mga bayan at ipinagbili bilang mga alipin sa Edom. 7Kaya susunugin ko ang mga pader1:7 susunugin ko ang mga pader: Maaaring may mga bahagi ang pader na masusunog ng apoy, o ang apoy dito ay nangangahulugan ng pagkawasak. ng Gaza at ang matitibay na bahagi ng lungsod na ito. 8Lilipulin ko ang mga pinuno ng Ashdod at ng Ashkelon, at parurusahan ko ang mga taga-Ekron.1:8 Ashdod … Ashkelon … Ekron: Itoʼy mga lugar na sakop ng Filistia. At ang mga Filisteong makakatakas sa parusa ay mamamatay din. Ako, ang Panginoong Dios, ang nagsasabi nito.”

Ang Parusa sa Bansang Tyre

9Ito ang sinasabi ng Panginoon tungkol sa Tyre: “Dahil sa patuloy na pagkakasala ng mga taga-Tyre, parurusahan ko sila. Sapagkat ipinagbili nila ang lahat ng naninirahan sa mga bayan bilang mga alipin sa Edom. Hindi nila sinunod ang kanilang kasunduang pangkapatiran sa mga mamamayang ito. 10Kaya susunugin ko ang mga pader ng Tyre at ang matitibay na bahagi ng lungsod nito.”

Ang Parusa sa Bansang Edom

11Ito ang sinasabi ng Panginoon tungkol sa Edom: “Dahil sa patuloy na pagkakasala ng mga taga-Edom, parurusahan ko sila. Sapagkat tinugis nila ang kanilang mga kaanak na mga Israelita at walang awang pinatay. Hinding-hindi mawawala ang kanilang galit sa mga Israelita. 12Kaya susunugin ko ang Teman at ang matitibay na bahagi ng Bozra.”1:12 Teman … Bozra: Itoʼy mga lugar na sakop ng Edom.

Ang Parusa sa Bansang Ammon

13Ito ang sinasabi ng Panginoon tungkol sa Ammon: “Dahil sa patuloy na pagkakasala ng mga taga-Ammon, parurusahan ko sila. Sapagkat nilaslas nila ang tiyan ng mga buntis sa Gilead nang salakayin nila ito, upang mapalawak ang kanilang lupain. 14Kaya susunugin ko ang mga pader ng Rabba1:14 Rabba: Ito ang kabisera ng Ammon. at ang matitibay na bahagi ng lungsod na ito habang nagsisigawan ang mga kaaway na sumasalakay sa kanila, na parang umuugong na bagyo. 15At bibihagin ang hari ng Ammon gayon din ang kanyang mga opisyal. Ako, ang Panginoon, ang nagsasabi nito.”