2 Samuẹli 22 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

2 Samuẹli 22:1-51

Orin ìyìn Dafidi

1Dafidi sì kọ ọ̀rọ̀ orin yìí sí Olúwa ní ọjọ́ tí Olúwa gbà á kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ Saulu. 222.2-51: Sm 18.2-50.Ó sì wí pé:

Olúwa ni àpáta mi, àti Olùgbàlà mi;

3Ọlọ́run mi, àpáta mi, nínú ẹni tí èmi ní ààbò,

àti ìwo ìgbàlà mi, ibi ìsádi gíga mi.

Àti ibi ìlùmọ̀ mi, Olùgbàlà mi;

ìwọ ni ó ti gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìwà ipá.

4“Èmi ké pe Olúwa, tí ó yẹ láti máa yìn,

ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.

5Nígbà tí ìbìlù ìrora ikú yí mi káàkiri;

tí àwọn ìṣàn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.

6Ọ̀já isà òkú yí mi káàkiri;

ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí.

7“Nínú ìpọ́njú mi, èmi ké pé Olúwa,

èmi sì gbé ohùn mi sókè sí Ọlọ́run mi.

Ó sí gbóhùn mi láti tẹmpili rẹ̀

igbe mí wọ etí rẹ̀.

8Ilẹ̀ sì mì, ó sì wárìrì;

ìpìlẹ̀ ọ̀run wárìrì,

ó sì mì, nítorí tí ó bínú.

9Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá;

Iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá,

ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.

10Ó tẹ orí ọ̀run ba pẹ̀lú, ó sì sọ̀kalẹ̀;

òkùnkùn biribiri sì ń bẹ ní àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.

11Ó sì gun orí kérúbù, ó sì fò:

a sì rí i lórí ìyẹ́ afẹ́fẹ́.

12Ó sì fi òkùnkùn ṣe ibùjókòó yí ara rẹ̀, àti àgbájọ omi,

àní ìṣúdudu ìkùùkuu àwọ̀ sánmọ̀.

13Nípasẹ̀ ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀

ẹ̀yín iná ràn.

14Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá,

Ọ̀gá-ògo jùlọ sì fọhùn rẹ̀.

15Ó sì ta ọfà, ó sì tú wọn ká;

ó kọ mànàmànà, ó sì ṣẹ́ wọn.

16Ìṣàn ibú Òkun sì fi ara hàn,

ìpìlẹ̀ ayé fi ara hàn,

nípa ìbáwí Olúwa,

nípa fífún èémí ihò imú rẹ̀.

17“Ó ránṣẹ́ láti òkè wá, ó mú mi;

ó fà mí jáde láti inú omi ńlá wá.

18Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára,

lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi: nítorí pé wọ́n lágbára jù mí lọ.

19Wọ́n wá láti borí mi lọ́jọ́ ìpọ́njú mi:

ṣùgbọ́n Olúwa ni aláfẹ̀yìntì mi.

20Ó sì mú mi wá sí ààyè ńlá:

ó gbà mi, nítorí tí inú rẹ̀ dún sí mi.

21Olúwa sán án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;

ó sì san án fún mi gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi.

22Nítorí pé èmi pa ọ̀nà Olúwa mọ́,

èmi kò sì fi ìwà búburú yapa kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.

23Nítorí pé gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ ni ó wà níwájú mi;

àti ní ti òfin rẹ̀, èmi kò sì yapa kúrò nínú wọn.

24Èmi sì wà nínú ìwà títọ́ sí í,

èmi sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi.

25Olúwa sì san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi,

gẹ́gẹ́ bí ìwà mímọ́ mi níwájú rẹ̀.

26“Fún aláàánú ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ni aláàánú,

àti fún ẹni ìdúró ṣinṣin ní òdodo ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní ìdúró ṣinṣin ní òdodo.

27Fún onínú funfun ni ìwọ fi ara rẹ hàn ní funfun;

àti fún ẹni wíwọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní wíwọ́.

28Àwọn ènìyàn tí ó wà nínú ìyà ni ìwọ ó sì gbàlà;

ṣùgbọ́n ojú rẹ wà lára àwọn agbéraga, láti rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.

29Nítorí ìwọ ni ìmọ́lẹ̀ mi, Olúwa;

Olúwa yóò sì sọ òkùnkùn mi di ìmọ́lẹ̀.

30Bẹ́ẹ̀ ni nítorí nípa rẹ̀ ni èmi ti la àárín ogun kọjá;

nípa Ọlọ́run mi èmi ti fo odi kan.

31“Ọlọ́run yìí, pípé ni ọ̀nà rẹ̀;

ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ti dánwò.

Òun sì ni asà fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e.

32Nítorí ta ni Ọlọ́run, bí kò ṣe Olúwa?

Ta ni àpáta, bí kò ṣe Ọlọ́run wa.

33Ọlọ́run alágbára ni ó fún mi ní agbára,

ó sì sọ ọ̀nà mi di títọ́.

34Ó ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín;

ó sì mú mi dúró ní ibi gíga mi.

35Ó kọ́ ọwọ́ mi ní ogun jíjà;

tó bẹ́ẹ̀ tí apá mi fa ọrun idẹ.

36Ìwọ sì ti fún mi ní asà

ìgbàlà rẹ̀, ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ sì ti sọ mí di ńlá.

37Ìwọ sì sọ ìtẹ̀lẹ̀ di ńlá ní abẹ́ mi;

tó bẹ́ẹ̀ tí ẹsẹ̀ mi kò fi yọ̀.

38“Èmi ti lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì ti run wọ́n,

èmi kò pẹ̀yìndà títí èmi fi run wọ́n.

39Èmi ti pa wọ́n run, èmi sì ti fọ́ wọn,

wọn kò sì le dìde mọ́: wọ́n ṣubú lábẹ́ mi.

40Ìwọ sì ti fi agbára dì mí ní àmùrè fún ìjà;

àwọn tí ó ti dìde sí mi ni ìwọ sì ti tẹ̀ lórí ba fún mi.

41Ìwọ sì mú àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà fún mi,

èmi ó sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.

42Wọ́n wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti gbà wọ́n;

wọ́n wo Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá àwọn lóhùn.

43Nígbà náà ni èmi sì gún wọn wẹ́wẹ́ bí erùpẹ̀ ilẹ̀,

èmi sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ ìta, èmi sì tẹ́ wọn gbọrọ.

44“Ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìjà àwọn ènìyàn mi,

ìwọ pa mi mọ́ ki èmi lè ṣe olórí àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè.

Àwọn ènìyàn tí èmi kò tí mọ̀ yóò máa sìn mí.

45Àwọn àjèjì wá láti tẹríba fún mi;

bí wọ́n bá ti gbúròó mi, wọ́n á sì gbọ́ tèmi.

46Àyà yóò pá àwọn àlejò,

wọ́n ó sì fi ìbẹ̀rù sá kúrò níbi kọ́lọ́fín wọn.

47Olúwa ń bẹ́; olùbùkún sì ni àpáta mi!

Gbígbéga sì ni Ọlọ́run àpáta ìgbàlà mi.

48Ọlọ́run ni ẹni tí ń gbẹ̀san mi,

àti ẹni tí ń rẹ àwọn ènìyàn sílẹ̀ lábẹ́ mi.

49Àti ẹni tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.

Ìwọ sì gbé mi sókè ju àwọn tí ó kórìíra mi lọ;

ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin oníwà ipá.

5022.50: Ro 15.9.Nítorí náà èmi ó fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa,

láàrín àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè: èmi ó sì kọrin sí orúkọ rẹ.

51“Òun ni ilé ìṣọ́ ìgbàlà fún ọba rẹ̀;

ó sì fi àánú hàn fún ẹni ààmì òróró rẹ̀,

fún Dafidi, àti fún irú-ọmọ rẹ̀ títí láéláé.”

New International Version

2 Samuel 22:1-51

David’s Song of Praise

1David sang to the Lord the words of this song when the Lord delivered him from the hand of all his enemies and from the hand of Saul. 2He said:

“The Lord is my rock, my fortress and my deliverer;

3my God is my rock, in whom I take refuge,

my shield22:3 Or sovereign and the horn22:3 Horn here symbolizes strength. of my salvation.

He is my stronghold, my refuge and my savior—

from violent people you save me.

4“I called to the Lord, who is worthy of praise,

and have been saved from my enemies.

5The waves of death swirled about me;

the torrents of destruction overwhelmed me.

6The cords of the grave coiled around me;

the snares of death confronted me.

7“In my distress I called to the Lord;

I called out to my God.

From his temple he heard my voice;

my cry came to his ears.

8The earth trembled and quaked,

the foundations of the heavens22:8 Hebrew; Vulgate and Syriac (see also Psalm 18:7) mountains shook;

they trembled because he was angry.

9Smoke rose from his nostrils;

consuming fire came from his mouth,

burning coals blazed out of it.

10He parted the heavens and came down;

dark clouds were under his feet.

11He mounted the cherubim and flew;

he soared22:11 Many Hebrew manuscripts (see also Psalm 18:10); most Hebrew manuscripts appeared on the wings of the wind.

12He made darkness his canopy around him—

the dark22:12 Septuagint (see also Psalm 18:11); Hebrew massed rain clouds of the sky.

13Out of the brightness of his presence

bolts of lightning blazed forth.

14The Lord thundered from heaven;

the voice of the Most High resounded.

15He shot his arrows and scattered the enemy,

with great bolts of lightning he routed them.

16The valleys of the sea were exposed

and the foundations of the earth laid bare

at the rebuke of the Lord,

at the blast of breath from his nostrils.

17“He reached down from on high and took hold of me;

he drew me out of deep waters.

18He rescued me from my powerful enemy,

from my foes, who were too strong for me.

19They confronted me in the day of my disaster,

but the Lord was my support.

20He brought me out into a spacious place;

he rescued me because he delighted in me.

21“The Lord has dealt with me according to my righteousness;

according to the cleanness of my hands he has rewarded me.

22For I have kept the ways of the Lord;

I am not guilty of turning from my God.

23All his laws are before me;

I have not turned away from his decrees.

24I have been blameless before him

and have kept myself from sin.

25The Lord has rewarded me according to my righteousness,

according to my cleanness22:25 Hebrew; Septuagint and Vulgate (see also Psalm 18:24) to the cleanness of my hands in his sight.

26“To the faithful you show yourself faithful,

to the blameless you show yourself blameless,

27to the pure you show yourself pure,

but to the devious you show yourself shrewd.

28You save the humble,

but your eyes are on the haughty to bring them low.

29You, Lord, are my lamp;

the Lord turns my darkness into light.

30With your help I can advance against a troop22:30 Or can run through a barricade;

with my God I can scale a wall.

31“As for God, his way is perfect:

The Lord’s word is flawless;

he shields all who take refuge in him.

32For who is God besides the Lord?

And who is the Rock except our God?

33It is God who arms me with strength22:33 Dead Sea Scrolls, some Septuagint manuscripts, Vulgate and Syriac (see also Psalm 18:32); Masoretic Text who is my strong refuge

and keeps my way secure.

34He makes my feet like the feet of a deer;

he causes me to stand on the heights.

35He trains my hands for battle;

my arms can bend a bow of bronze.

36You make your saving help my shield;

your help has made22:36 Dead Sea Scrolls; Masoretic Text shield; / you stoop down to make me great.

37You provide a broad path for my feet,

so that my ankles do not give way.

38“I pursued my enemies and crushed them;

I did not turn back till they were destroyed.

39I crushed them completely, and they could not rise;

they fell beneath my feet.

40You armed me with strength for battle;

you humbled my adversaries before me.

41You made my enemies turn their backs in flight,

and I destroyed my foes.

42They cried for help, but there was no one to save them—

to the Lord, but he did not answer.

43I beat them as fine as the dust of the earth;

I pounded and trampled them like mud in the streets.

44“You have delivered me from the attacks of the peoples;

you have preserved me as the head of nations.

People I did not know now serve me,

45foreigners cower before me;

as soon as they hear of me, they obey me.

46They all lose heart;

they come trembling22:46 Some Septuagint manuscripts and Vulgate (see also Psalm 18:45); Masoretic Text they arm themselves from their strongholds.

47“The Lord lives! Praise be to my Rock!

Exalted be my God, the Rock, my Savior!

48He is the God who avenges me,

who puts the nations under me,

49who sets me free from my enemies.

You exalted me above my foes;

from a violent man you rescued me.

50Therefore I will praise you, Lord, among the nations;

I will sing the praises of your name.

51“He gives his king great victories;

he shows unfailing kindness to his anointed,

to David and his descendants forever.”