2 Samuẹli 1 – YCB & ASCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

2 Samuẹli 1:1-27

1Lẹ́yìn ikú Saulu, Dafidi ti ibi tí ó ti ṣẹ́gun àwọn ará Amaleki bọ̀, ó sì dúró ní Siklagi ní ọjọ́ méjì. 2Ní ọjọ́ kẹta, ọkùnrin kan dé láti ibi ibùdó Saulu, pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ tí ó ti ya; àti erùpẹ̀ ní orí rẹ̀. Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ Dafidi, ó wólẹ̀ fún un láti bu ọlá fún un.

3Dafidi sì béèrè pé, “Ibo ni ìwọ ti wá?”

“Èmi sá láti ibùdó àwọn ọmọ Israẹli.”

4Dafidi béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” “Sọ fún mi.”

Ó wí pé, “Àwọn ọkùnrin náà sá láti ojú ogun. Ọ̀pọ̀ wọn ṣubú, wọ́n sì kú. Saulu àti ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Jonatani sì kú pẹ̀lú.”

5Nígbà náà, ní Dafidi sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Báwo ni o ṣe mọ̀ pé Saulu àti ọmọkùnrin rẹ̀ Jonatani ti kú.”

61.6-10: 1Sa 31.1-13; 1Ki 10.1-12.Ọ̀dọ́mọkùnrin náà sọ pé, “mo wà ní orí òkè Gilboa níbẹ̀ ni Saulu fi ara tí ọkọ̀ rẹ̀, àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin sì ń lépa rẹ̀. 7Nígbà tí ó wò yíká, tí ó rí mí, ó pè mi, mo sì wí pé, ‘Kí ni mo lè ṣe?’

8“Ó bi mí wí pé, ‘Ta ni ìwọ?’

“Mo dáhùn pé, ‘Ará a Amaleki.’

9“Nígbà náà ó wí fún mi pé, ‘Dúró lórí ì mi kí o sì pa mí! Èmi wà nínú ìrora ikú, ṣùgbọ́n mo wà láààyè.’

10“Nígbà náà, mo dúró lórí i rẹ̀, mo sì pa á nítorí mo mọ̀ wí pé, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣubú, kò le è yè mọ́. Mo sì mú adé tí ó wà lórí rẹ̀, idẹ tí ó wà ní apá a rẹ̀, mo sì kó wọn wá síbí fún olúwa mi.”

11Nígbà náà ni, Dafidi àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, di aṣọ wọn mú, wọ́n sì fà á ya. 12Wọ́n ṣọ̀fọ̀, wọ́n sì sọkún, wọ́n sì gbààwẹ̀ títí di ìrọ̀lẹ́ fún Saulu àti ọmọ rẹ̀ Jonatani àti fún àwọn ọmọ-ogun Olúwa, àti fún àwọn ilé Israẹli, nítorí wọ́n ti ṣubú nípa idà.

13Dafidi sọ fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Níbo ni ó ti wá?”

O dáhùn pé, “Ọmọ àlejò ni mo jẹ́, ará Amaleki.”

14Dafidi béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ kò fi bẹ̀rù láti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè láti fi pa ẹni ààmì òróró Olúwa?”

15Nígbà náà Dafidi pe ọ̀kan nínú ọkùnrin, ó sì wí pé, “Lọ, gbé e lulẹ̀!” Nígbà náà ó gbé e lulẹ̀, ó sì kú. 16Nítorí Dafidi wí fún un pé, “Ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò wà lórí ara rẹ, nítorí ẹnu ara rẹ ni o fi sọ pé ‘Mo pa ẹni ààmì òróró Olúwa.’ ”

17Dafidi sì fi orin ọ̀fọ̀ yìí ṣọ̀fọ̀ lórí Saulu àti lórí Jonatani ọmọ rẹ̀, 18Ó sì pàṣẹ pé kí a kọ́ àwọn ọkùnrin Juda ní orin arò yìí tí ó jẹ́ ti ọrun (a kọ ọ́ sí inú ìwé Jaṣari):

19“Ògo rẹ, Israẹli ni a pa ní òkè gíga rẹ.

Wò bí àwọn alágbára ṣe ń ṣubú!

20“Ẹ má ṣe sọ ọ́ ní Gati,

ẹ má ṣe kéde rẹ̀ ní òpópónà Aṣkeloni,

kí àwọn ọmọbìnrin Filistini má bá à yọ̀,

kí àwọn ọmọbìnrin aláìkọlà má ba à dunnú.

21“Ẹ̀yin òkè Gilboa,

kí ẹ̀yin kí ó má ṣe rí ìrì tàbí òjò,

tàbí oko tí ó mú èso ọrẹ wá.

Nítorí ibẹ̀ ni asà alágbára ti ṣègbé,

asà Saulu, bí ẹni pé a kò fi òróró yàn án.

22“Ọrun Jonatani kì í padà

bẹ́ẹ̀ ni idà Saulu kì í padà lásán,

láì kan ẹ̀jẹ̀ àwọn tí a pa,

àti ẹran àwọn alágbára.

23Saulu àti Jonatani—

ní ọjọ́ ayé, wọ́n fẹ́ràn ara, wọn sì dùn,

ní ikú, wọn kò sì yà ara wọ́n.

Wọ́n yára ju idì lọ,

wọ́n lágbára ju kìnnìún lọ.

24“Ẹ̀yin ọmọbìnrin Israẹli,

ẹ sọkún lórí Saulu,

ẹni tí ó fi aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára wọ̀ yín,

ẹni tí ó fi wúrà sí ara aṣọ yín.

25“Wò ó bí alágbára ti ṣubú ní ojú ogun!

Jonatani, ìwọ tí a pa ní òkè gíga.

26Ọkàn mi gbọgbẹ́ fún ọ Jonatani arákùnrin mi;

ìwọ ṣọ̀wọ́n fún mi.

Ìfẹ́ rẹ sí mi jẹ́ ìyanu,

ó jẹ́ ìyanu ju ti obìnrin lọ.

27“Wò ó bí alágbára ti ṣubú!

Ohun ìjà sì ti ṣègbé!”

Asante Twi Contemporary Bible

2 Samuel 1:1-27

Dawid Te Saulo Owuo

1Saulo owuo akyi no, Dawid sane firii nkonim a ɔdii Amalekfoɔ so no mu bɛtenaa Siklag nnanu. 2Ne nnansa so no, ɔbarima bi firi Saulo sraban mu a watete ne ntadeɛ mu, atu mfuturo agu ne tiri mu, de rekyerɛ sɛ ɔretwa adwo baeɛ. Ɔduruu Dawid nkyɛn no, ɔdanee ne ho hwee fam anidie mu.

3Dawid bisaa no sɛ, “Ɛhe na wofiri?”

Ɔbuaa sɛ, “Madwane afiri Israel sraban mu.”

4Dawid bisaa no sɛ, “Na ɛyɛɛ dɛn? Ɔko no kɔsii sɛn?”

Ɔkaa sɛ, “Mmarima no dwane firii akono. Bebree totɔeɛ. Na Saulo ne ne babarima Yonatan nso atotɔ.”

5Enti, Dawid bisaa aberanteɛ a ɔbɛbɔɔ no saa amaneɛ no sɛ, “Ɛyɛɛ dɛn na wohunuu sɛ Saulo ne ne babarima Yonatan awuwu?”

6Aberanteɛ no buaa sɛ, “Mekɔfirii Gilboa bepɔ so, na mekɔtoo sɛ Saulo sina ne pea so a atamfoɔ no nteaseɛnam ne nʼapɔnkɔsotefoɔ abɛn no ara. 7Ɔdanee ne ho a ɔhunuu me no, ɔteaam frɛɛ me sɛ memmra. Mebisaa no sɛ, ‘Menyɛ ɛdeɛn?’

8“Ɔbisaa me sɛ, ‘Wone hwan?’

“Mebuaa no sɛ, ‘Meyɛ Amalekni.’

9“Na ɔsrɛɛ me sɛ, ‘Bɛgyina me so na kum me, na me ho yera me yie, na mepɛ sɛ mewu.’

10“Enti, megyinaa ne so kumm no, ɛfiri sɛ, na menim sɛ tebea a ɔwɔ mu no, ɔrennya nkwa. Na metuu nʼahenkyɛ a ɛhyɛ no no ne nʼabasa so kapo no sɛ mede rebrɛ wo, me wura.”

11Dawid ne ne mmarima no tee asɛm no, wɔde awerɛhoɔ sunsuanee wɔn ntadeɛ mu. 12Wɔtwaa ho agyaadwoɔ, suiɛ, bua daa da mu no nyinaa wɔ Saulo ne ne babarima Yonatan wuo ne Awurade akodɔm ne Israelman sɛ wɔn mu pii wuwuu saa da no.

13Na Dawid bisaa aberanteɛ a ɔbɛbɔɔ wɔn saa amaneɛ no sɛ, “Wofiri he?”

Na ɔbuaa sɛ, “Meyɛ ɔhɔhoɔ Amalekni a mete mo asase so.”

14Dawid bisaa no sɛ, “Na wonsuro sɛ wobɛkum obi a Awurade asra no no?”

15Dawid ka kyerɛɛ ne mmarima no mu baako sɛ, “Ku no!” Enti, ɔbarima no twee nʼakofena de wɔɔ Amalekni no, kumm no. 16Na Dawid kaa sɛ, “Wʼano ayi mmusuo ama wo ama woawu, ɛfiri sɛ, wo ara na wokaa sɛ woakum obi a Awurade asra no no.”

Dawid Dwom A Ɔhyehyɛ Maa Saulo Ne Yonatan

17Na Dawid too kwadwom maa Saulo ne Yonatan. 18Na ɔhyɛɛ sɛ wɔnkyerɛ nnipa a wɔwɔ Yuda nyinaa to. Wɔtoo no edin sɛ agyan dwom a wɔatwerɛ wɔ Yasar Nwoma mu.

19“Wʼanimuonyam ne wʼahosɛpɛ, Ao Israel, awu da mmepɔ so!

Akofoɔ akɛseɛ atotɔ!

20“Monnka asɛm yi wɔ Gat,1.20 Gat ne Askelon yɛ Filistia nkuro.

na Filistifoɔ abɔ ose!

Monnka wɔ Askelon mmɔntene so,

na abosonsomfoɔ ansere ahosɛpɛ mu.

21“Ao Gilboa mmepɔ,

mma bosuo anaa osuo ntɔ ngu wo so,

anaa wo nsianeɛ so.

Ɛfiri sɛ, ɛhɔ na wɔguu ɔkofoɔ kɛseɛ no akokyɛm ho fi;

wɔremfa ngo nsra Saulo akokyɛm ho bio.

22“Saulo ne Yonatan kunkumm wɔn atamfoɔ ahoɔdenfoɔ!

Wɔamfiri akono amma no nsapan.

23Ɔdɔ ne ahoɔfɛ bɛn

na na Saulo ne Yonatan nni,

wɔn mu antete da, nkwa ne owuo mu.

Na wɔn ho yɛ hare kyɛn akɔdeɛ;

na wɔn ho yɛ den kyɛn agyata.

24“Ao, Israel mmaa,

monsu Saulo,

ɛfiri sɛ, ɔfiraa mo ntoma pa,

hyehyɛɛ mo sikakɔkɔɔ agudeɛ.

25“Akofoɔ akɛseɛ atotɔ akono.

Yonatan awu da mmepɔ no so.

26Hwɛ sɛdeɛ mesu woɔ, me nua Yonatan;

Ao, hwɛ ɔdɔ a mede dɔɔ woɔ!

Na wo dɔ a wode dɔɔ me no mu dɔ;

emu dɔ sene mmaa dɔ!

27“Hwɛ sɛdeɛ akofoɔ akɛseɛ atotɔ!

Wɔayiyi wɔn akodeɛ afiri wɔn ho, na wɔawuwu deda hɔ.”