1Simoni Peteru, ìránṣẹ́ àti aposteli Jesu Kristi,
Sí àwọn tí ó gba irú iyebíye ìgbàgbọ́ kan náà pẹ̀lú wá nínú òdodo Ọlọ́run wa àti ti Jesu Kristi Olùgbàlà.
2Kí oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà máa bí sí i fún yín nínú ìmọ̀ Ọlọ́run àti ti Jesu Olúwa wa.
Mímú kí ìpè àti yíyàn ẹni dájú
3Bí agbára rẹ̀ bí Ọlọ́run ti fún wa ní ohun gbogbo tí a nílò fún ṣe ti ìyè àti ti ìwà-bí-Ọlọ́run, nípa ìmọ̀ ẹni tí ó pè wá nípa Ògo àti ìṣeun rẹ̀. 4Nípa èyí tí ó fi àwọn ìlérí rẹ̀ tí ó tóbi púpọ̀ tí ó ṣe iyebíye fún wa: pé nípa ìwọ̀nyí ni kí ẹ̀yin lè di alábápín nínú àbùdá ti Ọlọ́run, nígbà tí ẹ̀yin bá ti yọ kúrò nínú ìbàjẹ́ tí ó ń bẹ nínú ayé nípa ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.
5Àti nítorí ìdí èyí, ẹ máa ṣe àìsimi gbogbo, ẹ fi ìwà rere kún ìgbàgbọ́, àti ìmọ̀ kún ìwà rere; 6àti àìrékọjá kún ìmọ̀; àti sùúrù kún àìrékọjá; àti ìwà-bí-Ọlọ́run kún sùúrù. 7Àti ìfẹ́ ọmọnìkejì kún ìwà-bí-Ọlọ́run; àti ìfẹ́ni kún ìfẹ́ ọmọnìkejì. 8Nítorí bí ẹ̀yin bá ní nǹkan wọ̀nyí tí wọ́n bá sì pọ̀, wọn kì yóò jẹ́ kí ẹ ṣe ọ̀lẹ tàbí aláìléso nínú ìmọ̀ Olúwa wa Jesu Kristi. 9Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe aláìní nǹkan wọ̀nyí, kò lè ríran ní òkèèrè, ó fọjú, ó sì ti gbàgbé pé a ti wẹ òun nù kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ àtijọ́.
10Nítorí náà, ará ẹ túbọ̀ máa ṣe àìsimi láti sọ ìpè àti yíyàn yín di dájúdájú: nítorí bí ẹ̀yin bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí, ẹ̀yin kì yóò ṣubú. 11Nítorí báyìí ni a ó pèsè fún yín lọ́pọ̀lọpọ̀ láti wọ ìjọba àìnípẹ̀kun ti Olúwa àti Olùgbàlà wa Jesu Kristi.
Àsọtẹ́lẹ̀ ti ọrọ̀ Ọlọ́run
12Nítorí náà, èmi ó máa rán yin létí àwọn nǹkan wọ̀nyí nígbà gbogbo, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀yin ti mọ̀ wọ́n, tí ẹsẹ̀ yín sì múlẹ̀ nínú òtítọ́ tí ẹ ní báyìí. 13Èmi sì rò pé ó tọ́ láti máa mú wọn wá sí ìrántí yín, níwọ̀n ìgbà tí èmí ba ń bẹ nínú àgọ́ ara yìí. 14Bí èmi ti mọ̀ pé, bíbọ́ àgọ́ ara mi yìí sílẹ̀ kù sí dẹ̀dẹ̀, àní, bí Olúwa wa Jesu Kristi ti fihàn mí. 15Èmi ó sì máa ṣaápọn pẹ̀lú, kí ẹ̀yin lè máa rántí nǹkan wọ̀nyí nígbà gbogbo lẹ́yìn ikú mi.
16Nítorí kì í ṣe bí ẹni tí ó ń tọ ìtàn asán lẹ́yìn tí a fi ọgbọ́nkọ́gbọ́n là sílẹ̀, nígbà tí àwa sọ fún yín ní ti agbára àti wíwá Jesu Kristi Olúwa, ṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí ọláńlá rẹ̀ ni àwa jẹ́. 171.17-18: Mt 17.1-8; Mk 9.2-8; Lk 9.28-36.Nítorí tí Ó gba ọlá àti ògo láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba, nígbà tí irú ohùn yìí fọ̀ sí i láti inú ògo ńlá náà wá pé, “Èyí ni àyànfẹ́ ọmọ mi, ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.” 18Àwa pẹ̀lú sì gbọ́ ohun yìí tí ó ti ọ̀run wá nígbà tí àwa wà pẹ̀lú rẹ̀ ní orí òkè mímọ́ náà.
19Àwa sì ní ìfẹsẹ̀múlẹ̀ ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì dunjúdunjú sí i, èyí tí ó yẹ kí ẹ kíyèsi gẹ́gẹ́ bí fìtílà tó ń mọ́lẹ̀ níbi tí òkùnkùn gbé wà, títí ilẹ̀ yóò fi mọ́, tí ìràwọ̀ òwúrọ̀ yóò sì yọ lọ́kàn yín. 20Ju gbogbo rẹ̀ lọ, kí ẹ ní òye yìí pé kò sí àsọtẹ́lẹ̀ ìwé mímọ́ kankan tí ó wáyé nípa ìtumọ̀ wòlíì fún rara rẹ̀. 21Nítorí àsọtẹ́lẹ̀ kan kò ti ipá ìfẹ́ ènìyàn wá rí; ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ń sọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run bí a ti ń darí wọn láti ọwọ́ Ẹ̀mí Mímọ́ wá.
داستان سلام و درود از پطرس
1-2از طرف من، شمعون پطرس، خدمتگزار و رسول عيسی مسيح،
به همهٔ شما كه با ما ايمانی يكسان داريد.
دعا میكنم كه رحمت و آرامش در اثر شناخت خدا و خداوندمان عيسی، به فراوانی به شما عطا شود.
ايمانی كه به آن اشاره كردم، ايمانی است كه از جانب خدا و نجات دهندهٔ ما عيسی مسيح عطا میگردد و نعمتی گرانبهاست؛ و خدا به خاطر مهربانی و نيكويی مطلق خود، اين ايمان را به هر يک از ما عنايت میفرمايد.
زندگی برگزيدگان خدا
3او همچنين با قدرت عظيمش، هر چه كه برای يک زندگی خداپسندانه نياز داريم، عطا میكند و حتی ما را در جلال و نيكويی خود سهيم میسازد؛ اما برای اين منظور، لازم است كه او را بهتر و عمیقتر بشناسيم. 4با همين قدرت عظيم بود كه تمام بركات غنی و عالی را كه وعده داده بود، به ما بخشيد. يكی از اين وعدهها اين بود كه ما را از شهوت و فساد محيط اطرافمان رهايی دهد و از طبيعت و صفات الهی خود بهرهای به ما عطا فرمايد.
5اما برای دسترسی به اين بركات، علاوه بر ايمان، به خصلتهای ديگری نيز نياز داريد؛ بلی، بايد سخت بكوشيد كه نيک باشيد، خدا را بهتر بشناسيد و به ارادهٔ او پی ببريد. 6همچنين بايد حاضر باشيد تا خواستههای خود را كنار گذاشته، با صبر و دينداری خدا را با شادی خدمت نماييد. 7به اين ترتيب، راه را برای قدم بعدی هموار میكنيد، يعنی آماده میشويد تا انسانها را دوست بداريد. اين محبت رشد كرده، تبديل به محبتی عميق نسبت به انسانها خواهد گشت. 8اگر اجازه دهيد اين خصلتهای خوب در شما رشد كنند و فزونی يابند، از لحاظ روحانی نيرومند شده، برای خداوندمان عيسی مسيح مفيد و پرثمر خواهيد شد. 9اما كسی كه اجازه نمیدهد اين خصوصيات در او ريشه بدوانند، در حقيقت كور يا لااقل كوتهبين است و فراموش كرده است كه خدا او را از زندگی گناهآلود سابقش نجات داده تا بتواند برای خداوند زندگی كند.
10بنابراين، ای برادران عزيز، بكوشيد تا ثابت كنيد كه حقيقتاً جزو برگزيدگان و دعوتشدگان خدا هستيد؛ زيرا اگر چنين كنيد، هرگز لغزش نخواهيد خورد و از خدا دور نخواهيد شد؛ 11و خدا نيز دروازههای آسمان را به روی شما خواهد گشود تا وارد ملكوت جاودانی خداوند و نجاتدهندهٔمان عيسی مسيح گرديد.
يادآوری حقيقت
12اما من هيچگاه از يادآوری اين مطالب به شما، كوتاهی نخواهم كرد، گرچه آنها را میدانيد و در حقيقتی كه يافتهايد، ثابت و استوار میباشيد. 13تا زمانی كه در اين دنيای فانی به سر میبرم، وظيفهٔ خود میدانم كه اين نكات را به شما تذكر دهم تا آنها را فراموش نكنيد. 14زيرا میدانم كه بزودی دار فانی را وداع خواهم گفت؛ خداوندمان عيسی مسيح نيز مرا از اين موضوع آگاه ساخته است. 15بنابراين، سعی میكنم اين نكات را چنان در فكر و ذهن شما نقش نمايم كه حتی پس از رحلت من نيز بتوانيد آنها را به یاد آوريد.
16زمانی كه ما دربارهٔ قوت و بازگشت خداوندمان عيسی مسيح با شما سخن گفتيم، داستانهای ساختگی برايتان تعريف نكرديم، زيرا من با چشمان خود، عظمت و جلال او را ديدم. 17-18وقتی بر آن كوه مقدس، جلال و شكوه خدای پدر از او میدرخشيد، من آنجا بودم. من آن صدا را شنيدم كه از آسمان طنين افكند و گفت: «اين فرزند عزيز من است؛ از او بسيار خشنودم.»
19پس ملاحظه میكنيد كه ما آنچه را كه انبیا گفتهاند، به چشم ديده و ثابت كردهايم كه گفتار آنان حقيقت دارد. شما نيز اگر به نوشتههای ايشان با دقت بيشتری توجه نماييد، كار بسيار خوبی میكنيد. زيرا كلام ايشان همچون نور بر همهٔ زوايای تاريک میتابد و نكات مبهم و دشوار را برای ما روشن میسازد. با مطالعه و دقت در كلام ايشان، نور در وجودتان طلوع خواهد كرد و مسيح، اين «ستارهٔ صبح» در قلبتان خواهد درخشيد. 20-21اين را بدانيد كه هيچيک از پيشگويیهای كتاب آسمانی، از فكر خود انبیا تراوش نكرده، بلكه روحالقدس در وجود اين مردان خدا قرار میگرفت و حقيقت را به ايشان عطا میكرد تا بازگو نمايند.