2 Ọba 1 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

2 Ọba 1:1-18

Ìdájọ́ Olúwa lórí Ahasiah

1Lẹ́yìn ikú Ahabu, Moabu ṣọ̀tẹ̀ sí Israẹli. 2Nísinsin yìí Ahasiah ti ṣubú láàrín fèrèsé láti òkè yàrá rẹ̀ tí ó wà ní Samaria, ó sì fi ara pa. Ó sì rán oníṣẹ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni, bóyá èmi ó lè rí ìwòsàn ìfarapa yìí.”

3Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa wí fún Elijah ará Tiṣibi pé, “Lọ sókè kí o lọ bá ìránṣẹ́ ọba Samaria kí o sì béèrè lọ́wọ́ wọn, ‘Ṣé nítorí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni ẹ̀yìn fi jáde lọ ṣèwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu òrìṣà Ekroni?’ 4Nítorí náà ohun tí Olúwa sọ ní èyí: ‘Ìwọ kò ní kúrò lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé. Dájúdájú ìwọ yóò kú!’ ” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ.

5Nígbà tí ìránṣẹ́ náà padà sí ọ̀dọ̀ ọba, ó béèrè ní ọwọ́ wọn pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi tètè padà wá?”

6Wọ́n dáhùn pé, “Ọkùnrin kan wá láti pàdé wa, ó sì wí fún wa pé, ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ ọba tí ó rán an yín kí ẹ sì wí fún un pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni o fi ń rán àwọn ènìyàn láti lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni? Nítorí náà ìwọ kò ní fi orí ibùsùn tí ìwọ dùbúlẹ̀ lé sílẹ̀. Láìsí àní àní ìwọ yóò kùú!” ’ ”

7Ọba béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Irú ọkùnrin wo ni ó wá pàdé yín, tí ó sì sọ irú èyí fún un yín?”

8Wọ́n dáhùn pé, “Ó jẹ́ ọkùnrin tí ó wọ ẹ̀wù onírun lára pẹ̀lú ọ̀já àmùrè aláwọ tí ó gbà yíká ìbàdí rẹ̀.”

Ọba sì wí pé, “Elijah ará Tiṣibi ni.”

9Ó sì rán balógun pẹ̀lú àwọn ẹgbẹ́ ogun àádọ́ta rẹ̀. Balógun náà sì gòkè tọ Elijah lọ, ẹni tí ó jókòó ní orí òkè, wọ́n sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, ọba wí pé, ‘Sọ̀kalẹ̀ wá!’ ”

10Elijah sì dá balógun lóhùn pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ènìyàn Ọlọ́run ni mí, kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti òkè ọ̀run wá kí ó sì jó ìwọ àti àwọn àádọ́ta ọkùnrin rẹ!” Nígbà náà iná náà sì sọ̀kalẹ̀ wá láti òkè ọ̀run ó sì jó balógun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.

11Ọba sì tún rán balógun àádọ́ta pẹ̀lú àwọn ènìyàn àádọ́ta rẹ̀ sí Elijah. Balógun náà sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, èyí ni ohun tí ọba sọ, ‘Sọ̀kalẹ̀ kánkán!’ ”

12“Tí èmi bá jẹ́ ènìyàn Ọlọ́run,” Elijah sì dáhùn, “Ǹjẹ́ kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run kí ó sì jó ọ run àti àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ!” Nígbà náà iná Ọlọ́run sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó o run pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ̀.

13Bẹ́ẹ̀ ni ọba tún rán balógun kẹta pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ọkùnrin. Balógun ẹ̀ẹ̀kẹ́ta lọ sí òkè, ó sì kúnlẹ̀ lórí orókún rẹ̀ níwájú Elijah. “Ènìyàn Ọlọ́run,” Ó sì bẹ̀bẹ̀ pé, “Ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, jọ̀wọ́ jẹ́ kí ẹ̀mí mi àti ẹ̀mí àwọn àádọ́ta ìránṣẹ́ rẹ wọ̀nyí ṣọ̀wọ́n ní ojú rẹ! 14Wò ó, iná ti sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run láti jó àwọn balógun méjì àràádọ́ta àkọ́kọ́ pẹ̀lú àràádọ́ta wọn. Ṣùgbọ́n Nísinsin yìí ní ojúrere fún ẹ̀mí mi!”

15Angẹli Olúwa sọ fún Elijah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀; má ṣe bẹ̀rù rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀ sí ọ̀dọ̀ ọba.

16Ó sọ fún ọba pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli fún ọ láti pè ni ìwọ fi rán ìránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni láti lọ ṣe ìwádìí? Nítorí pé o ṣe èyí, ìwọ kò ní dìde lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé láìsí àní àní ìwọ yóò kú!” 17Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí Elijah ti sọ.

Nítorí Ahasiah kò ní ọmọ, Jehoramu jẹ ọba ní ọdún kejì tí Jehoramu ọmọ Jehoṣafati ọba Juda. 18Àti ní ti gbogbo àwọn ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìjọba Ahasiah, àti ohun tí ó ṣe, ṣe a kò ha kọ wọ́n sí inú ìwé ọdọọdún ti àwọn ọba Israẹli?

Nouă Traducere În Limba Română

2 Regi 1:1-18

Judecata Domnului asupra lui Ahazia

1După moartea lui Ahab, Moab s‑a răsculat împotriva lui Israel. 2S‑a întâmplat că Ahazia a căzut prin grilajul odăii lui de sus, din palatul Samariei, și a zăcut la pat. Atunci a trimis niște mesageri, zicându‑le: „Duceți‑vă și întrebați‑l pe Baal-Zebub2 Baal-Zebub înseamnă Stăpânul (Baal) Muștelor, o parodiere a epitetului Baal-Zebul (Prințul Baal), Baal fiind zeul canaanit al fertilității [peste tot în capitol]., zeul Ekronului, dacă mă voi vindeca de boala aceasta.“

3Dar un înger3 Sau: Îngerul. Vezi Gen. 16:7-13. al Domnului i‑a zis lui Ilie3 Ilie (ebr.: Eliahu) înseamnă Domnul (YHWH) este Dumnezeul meu, nume sugestiv pentru misiunea sa [peste tot în carte]. tișbitul: „Ridică‑te, du‑te să‑i întâlnești pe mesagerii regelui Samariei și spune‑le: «Oare nu este Dumnezeu în Israel, de mergeți să‑l întrebați pe Baal-Zebub, zeul Ekronului? 4De aceea așa vorbește Domnul: ‘Nu vei coborî din patul în care te‑ai urcat, ci vei muri sigur!’»“ Apoi Ilie a plecat.

5Când mesagerii s‑au întors la rege, el i‑a întrebat:

– De ce v‑ați întors?

6Ei i‑au răspuns:

– Un om s‑a suit să ne întâlnească și ne‑a zis: „Duceți‑vă! Întoarceți‑vă la regele care v‑a trimis și spuneți‑i: «Așa vorbește Domnul: ‘Oare nu este Dumnezeu în Israel, de ai trimis să‑l întrebe pe Baal-Zebub, zeul Ekronului? De aceea nu vei coborî din patul în care te‑ai urcat, ci vei muri sigur!’»“

7El i‑a întrebat:

– Cum arăta bărbatul care s‑a suit să vă întâlnească și v‑a spus aceste cuvinte?

8Ei i‑au răspuns:

– Era un om îmbrăcat cu o manta de păr și încins la mijloc cu o curea de piele.

El a zis:

– Este Ilie tișbitul.

9Atunci a trimis la el o căpetenie peste cincizeci de oameni, împreună cu cei cincizeci de oameni ai acestuia.

Căpetenia s‑a suit la Ilie, care stătea pe vârful unui deal, și i‑a zis:

– Omule al lui Dumnezeu, regele spune: „Coboară!“

10Dar Ilie a răspuns și i‑a zis căpeteniei celor cincizeci:

– Dacă sunt un om al lui Dumnezeu, să coboare foc din ceruri și să te mistuie pe tine și pe cei cincizeci de oameni ai tăi.

Atunci a coborât foc din ceruri și i‑a mistuit pe el și pe cei cincizeci de oameni care erau cu el. 11Apoi regele a trimis o altă căpetenie peste cincizeci de oameni, împreună cu cei cincizeci de oameni ai acestuia.

Căpetenia i‑a zis:

– Omule al lui Dumnezeu, așa vorbește regele: „Coboară repede!“

12Dar Ilie a răspuns și le‑a zis:

– Dacă sunt un om al lui Dumnezeu, să coboare foc din ceruri și să te mistuie pe tine și pe cei cincizeci de oameni ai tăi.

Atunci a coborât focul lui Dumnezeu din ceruri și i‑a mistuit pe el și pe cei cincizeci de oameni care erau cu el. 13Regele a trimis o a treia căpetenie peste cincizeci de oameni, împreună cu cei cincizeci de oameni ai acestuia. Această a treia căpetenie s‑a suit, iar când a ajuns, s‑a plecat pe genunchi înaintea lui Ilie și a căutat bunăvoința lui, zicându‑i: „Omule al lui Dumnezeu, te rog, pune preț pe viața mea și pe viața acestor cincizeci de robi ai tăi! 14Iată că a coborât foc din ceruri și a mistuit primele două căpetenii peste cincizeci și cei cincizeci de oameni ai lor. Acum deci, pune preț pe viața mea!“

15Atunci îngerul Domnului i‑a zis lui Ilie: „Coboară cu el și nu te teme de el!“ Ilie s‑a ridicat și a coborât împreună cu el la rege. 16El i‑a zis regelui: „Așa vorbește Domnul: «Nu este în Israel Dumnezeu al Cărui cuvânt să‑L poți întreba, de trimiți mesageri să‑l întrebe pe Baal-Zebub, zeul Ekronului? Pentru că ai făcut aceasta, nu vei coborî din patul în care te‑ai urcat, ci vei muri cu siguranță!»“

17Ahazia a murit potrivit Cuvântului Domnului pe care l‑a rostit Ilie. Pentru că nu avea niciun fiu, în locul lui a devenit rege Ioram. Era al doilea an al lui Iehoram, fiul lui Iehoșafat, regele lui Iuda.

18Celelalte fapte pe care le‑a făcut Ahazia, nu sunt scrise oare în „Cartea cronicilor regilor lui Israel“?