1 Kronika 2 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Kronika 2:1-55

Àwọn ọmọ Israẹli

12.1-2: Gẹ 35.23-26.Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli. Reubeni, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Sebuluni, 2Dani, Josẹfu, Benjamini; Naftali, Gadi: àti Aṣeri.

Juda

Àwọn ọmọ Hesroni

32.3-4: Gẹ 38.3-7,29-30; Nu 26.19,20.Àwọn ọmọ Juda:

Eri, Onani àti Ṣela, àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí ni wọ́n bí fún un láti ọ̀dọ̀ arábìnrin Kenaani, ọmọbìnrin Ṣua.

Eri àkọ́bí Juda, ó sì burú ní ojú Olúwa; Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì pa á.

4Tamari, aya ọmọbìnrin Juda, ó sì bí Peresi àti Sera sì ní ọmọ márùn-ún ní àpapọ̀.

52.5: Gẹ 46.12; Gẹ 26.21.Àwọn ọmọ Peresi:

Hesroni àti Hamulu.

6Àwọn ọmọ Sera:

Simri, Etani, Hemani, Kalkoli àti Dara, gbogbo wọn jẹ́ márùn-ún.

7Àwọn ọmọ Karmi:

Akani, ẹni tí ó mú ìyọnu wá sórí Israẹli nípa ẹ̀ṣẹ̀ ìfibú lórí mímú ohun ìyàsọ́tọ̀.

8Àwọn ọmọ Etani:

Asariah.

9Àwọn ọmọ tí a bí fún Hesroni ni:

Jerahmeeli, Ramu àti Kalebu.

Láti ọ̀dọ̀ Ramu ọmọ Hesroni

10Ramu sì ni baba Amminadabu,

àti Amminadabu baba Nahiṣoni olórí àwọn ènìyàn Juda.

11Nahiṣoni sì ni baba Salmoni,

Salmoni ni baba Boasi,

12Boasi baba Obedi

àti Obedi baba Jese.

13Jese sì ni baba

Eliabu àkọ́bí rẹ̀; ọmọ ẹlẹ́kejì sì ni Abinadabu,

ẹlẹ́kẹta ni Ṣimea, 14Ẹlẹ́kẹrin Netaneli,

ẹlẹ́karùnún Raddai, 15ẹlẹ́kẹfà Osemu

àti ẹlẹ́keje Dafidi.

16Àwọn arábìnrin wọn ni Seruiah àti Abigaili.

Àwọn ọmọ mẹ́ta Seruiah ni Abiṣai, Joabu àti Asaheli.

17Abigaili ni ìyá Amasa, ẹni tí baba rẹ̀ sì jẹ́ Jeteri ará Iṣmaeli.

Kalebu ọmọ Hesroni

18Kalebu ọmọ Hesroni ní ọmọ láti ọ̀dọ̀ ìyàwó rẹ̀ Asuba (láti ọ̀dọ̀ Jerioti). Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ rẹ̀:

Jeṣeri, Ṣobabu àti Ardoni.

19Nígbà tí Asuba sì kú, Kalebu sì fẹ́ Efrata ní aya, ẹni tí ó bí Huri fún un.

20Huri ni baba Uri, Uri sì jẹ́ baba Besaleli.

21Nígbà tí ó yá, Hesroni sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ọmọbìnrin Makiri baba Gileadi (ó sì ti fẹ́ ní aya láti ìgbà tí ó ti wà ní ẹni ọgọ́ta ọdún) ó sì bí Segubu.

22Segubu sì jẹ́ baba Jairi, ẹni tí ó jẹ́ olùdarí ìlú mẹ́tàlélógún ní ilẹ̀ Gileadi.

23(Ṣùgbọ́n Geṣuri àti Aramu sì fi agbára gba Hafoti-Jairi, àti Kenati pẹ̀lú gbogbo agbègbè rẹ̀ tí wọn tẹ̀dó sí jẹ́ ọgọ́ta ìlú.)

Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Makiri Baba Gileadi.

24Lẹ́yìn tí Hesroni sì kú ni Kalebu Efrata, Abijah ìyàwó rẹ̀ ti Hesroni sì bí Aṣihuri baba Tekoa fún un.

Jerahmeeli ọmọ Hesroni

25Ọmọ Jerahmeeli àkọ́bí Hesroni:

Ramu ọmọ àkọ́bí rẹ̀ Buna, Oreni, Osemu àti Ahijah. 26Jerahmeeli ní ìyàwó mìíràn, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Atara; ó sì jẹ́ ìyá fún Onamu.

27Àwọn ọmọ Ramu àkọ́bí Jerahmeeli:

Maasi, Jamini àti Ekeri.

28Àwọn ọmọ Onamu:

Ṣammai àti Jada.

Àwọn ọmọ Ṣammai:

Nadabu àti Abiṣuri. 29Orúkọ ìyàwó Abiṣuri ni Abihaili ẹni tí ó bí Ahbani àti Molidi.

30Àwọn ọmọ Nadabu

Ṣeledi àti Appaimu. Ṣeledi sì kú láìsí ọmọ.

31Àwọn ọmọ Appaimu:

Iṣi, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Ṣeṣani. Ṣeṣani sì jẹ́ baba fún Ahlai.

32Àwọn ọmọ Jada, arákùnrin Ṣammai:

Jeteri àti Jonatani. Jeteri sì kú láìní ọmọ.

33Àwọn ọmọ Jonatani:

Peleti àti Sasa.

Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Jerahmeeli.

34Ṣeṣani kò sì ní ọmọkùnrin àwọn ọmọbìnrin nìkan ni ó ní.

Ó sì ní ìránṣẹ́ ará Ejibiti tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jariha. 35Ṣeṣani sì fi ọmọ obìnrin rẹ̀ ní aya fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Jariha, ó sì bí ọmọ fún tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ Attai.

36Attai sì jẹ́ baba fún Natani,

Natani sì jẹ́ baba fún Sabadi,

37Sabadi ni baba Eflali,

Eflali jẹ́ baba Obedi,

38Obedi sì ni baba Jehu,

Jehu ni baba Asariah,

39Asariah sì ni baba Helesi,

Helesi ni baba Eleasa,

40Eleasa ni baba Sismai,

Sismai ni baba Ṣallumu,

41Ṣallumu sì ni baba Jekamiah,

Jekamiah sì ni baba Eliṣama.

Ìdílé Kalebu

42Àwọn ọmọ Kalebu arákùnrin Jerahmeeli:

Meṣa àkọ́bí rẹ̀, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Sifi,

àti àwọn ọmọ rẹ̀ Meraṣa, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Hebroni.

43Àwọn ọmọ Hebroni:

Kora, Tapua, Rekemu, àti Ṣema.

44Ṣema ni baba Rahamu,

Rahamu sì jẹ́ baba fún Jorkeamu.

Rekemu sì ni baba Ṣammai.

45Àwọn ọmọ Ṣammai ni Maoni,

Maoni sì ni baba Beti-Suri.

46Efani obìnrin Kalebu sì ni ìyá

Harani, Mosa àti Gasesi,

Harani sì ni baba Gasesi.

47Àwọn ọmọ Jahdai:

Regemu, Jotamu, Geṣani, Peleti, Efani àti Ṣaafa.

48Maaka obìnrin Kalebu sì ni ìyá

Seberi àti Tirhana.

49Ó sì bí Ṣaafa baba Madmana,

Ṣefa baba Makbena àti baba Gibeah.

ọmọbìnrin Kalebu sì ni Aksa.

50Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Kalebu.

Àwọn ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata:

Ṣobali baba Kiriati-Jearimu. 51Salma baba Bẹtilẹhẹmu àti Harefu baba Beti-Gaderi.

52Àwọn ọmọ Ṣobali baba Kiriati-Jearimu ni:

Haroe, ìdajì àwọn ará Manaheti. 53Àti ìdílé Kiriati-Jearimu: àti àwọn ara Itri, àti àwọn ará Puti, àti àwọn ará Ṣumati àti àwọn ará Miṣraiti: láti ọ̀dọ̀ wọn ni àwọn ọmọ ará Sorati àti àwọn ará Eṣtaoli ti wá.

54Àwọn ọmọ Salma:

Bẹtilẹhẹmu, àti àwọn ará Netofa, Atrotu Beti-Joabu, ìdajì àwọn ará Manahati, àti ará Sori, 55Àti àwọn ìdílé àwọn akọ̀wé, ẹni tí ń gbé ní Jabesi: àti àwọn ọmọ Tirati àti àwọn ará Ṣimeati àti àwọn ará Sukati. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ará Keni, ẹni tí ó wá láti ọ̀dọ̀ Hamati, baba ilé Rekabu.