1 Johanu 5 – YCB & CRO

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Johanu 5:1-21

Ìgbàgbọ́ nínú ọmọ Ọlọ́run

15.1: Jh 8.42.Olúkúlùkù ẹni tí ó bá gbàgbọ́ pé Jesu ni Kristi, a bí i nípa ti Ọlọ́run: àti olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ràn. Ẹni tí ó bi nì, ó fẹ́ràn ẹni tí a bí nípasẹ̀ rẹ̀ pẹ̀lú. 2Nípa èyí ni àwa mọ̀ pé àwa fẹ́ràn àwọn ọmọ Ọlọ́run, nígbà tí a bá fẹ́ràn Ọlọ́run, tí a sì ń pa òfin rẹ̀ mọ́. 35.3: Jh 14.15; 1Jh 2.5; 2Jh 6.Nítorí èyí ni ìfẹ́ Ọlọ́run, pé kí àwa pa òfin rẹ̀ mọ́: òfin rẹ̀ kò sì nira, 45.4: Jh 16.33.nítorí olúkúlùkù ẹni tí a bí nípa tí Ọlọ́run, ó ṣẹ́gun ayé. Èyí sì ni ìṣẹ́gun tí ó ṣẹ́gun ayé, àní ìgbàgbọ́ wa. 5Ta ni ẹni tí ó ṣẹ́gun ayé, bí kò ṣe ẹni tí ó gbàgbọ́ pé Ọmọ Ọlọ́run ni Jesu jẹ́?

65.6-8: Jh 19.34; 4.23; 15.26.Èyí ni ẹni tí ó wá nípa omi àti ẹ̀jẹ̀, Jesu Kristi, kì í ṣe nípa omi nìkan, bí kò ṣe nípa omi àti ẹ̀jẹ̀. Àti pé Ẹ̀mí ni ó sì ń jẹ́rìí, nítorí pé òtítọ́ ni Ẹ̀mí. 7Nítorí pé àwọn mẹ́ta ni ó ń jẹ́rìí. 8Ẹ̀mí, omi, àti ẹ̀jẹ̀: àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì wà ni ìṣọ̀kan. 95.9: Jh 5.32,36; 8.18.Bí àwa ba ń gba ẹ̀rí ènìyàn, ẹ̀rí Ọlọ́run tóbi jù: nítorí ẹ̀rí Ọlọ́run ni èyí pé, Ó tí jẹ́rìí ní ti Ọmọ rẹ̀. 105.10: 1Jh 1.10.Ẹni tí ó bá gba Ọmọ Ọlọ́run gbọ́, ó ni ẹ̀rí nínú ara rẹ̀; ẹni tí kò bá gba Ọlọ́run gbọ́, ó ti mú un ni èké; nítorí kò gba ẹ̀rí náà gbọ́ tí Ọlọ́run jẹ́ ní ti Ọmọ rẹ̀. 11Ẹ̀rí náà sì ni èyí pé Ọlọ́run fún wa ní ìyè àìnípẹ̀kun, ìyè yìí sì ń bẹ nínú Ọmọ rẹ̀. 125.12: Jh 3.36.Ẹni tí ó bá ni Ọmọ, ó ni ìyè; ẹni tí kò bá sì ni Ọmọ Ọlọ́run, kò ní ìyè.

Àwọn àfiyèsí ìparí

135.13: Jh 20.31.Nǹkan wọ̀nyí ni mo kọ̀wé rẹ̀ sí yín, àní sí ẹ̀yin tí ó gba orúkọ Ọmọ Ọlọ́run gbọ́; kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé ẹ̀yin ní ìyè àìnípẹ̀kun, àní fún ẹ̀yin tí ó gba orúkọ Ọmọ Ọlọ́run gbọ́. 145.14: Mt 7.7; 1Jh 3.21.Èyí sì ni ìgboyà tí àwa ní níwájú rẹ̀, pé bí àwa bá béèrè ohunkóhun gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, ó ń gbọ́ tí wa; 15Bí àwa bá sì mọ̀ pé ó ń gbọ́ tí wa, ohunkóhun tí àwa bá béèrè, àwa mọ̀ pé àwa rí ìbéèrè tí àwa ti béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ gbà.

16Bí ẹnikẹ́ni bá rí arákùnrin rẹ̀ tí ń dẹ́ṣẹ̀ tí kì í ṣe sí ikú, òun yóò béèrè, Ọlọ́run yóò sì fún un ni ìyè, àní, fún àwọn tí ń dẹ́ṣẹ̀ tí kì í ṣe sí ikú. Ẹ̀ṣẹ̀ kan ń bẹ sì ikú: èmi kò wí pé ki òun gbàdúrà fún èyí. 17Gbogbo àìṣòdodo ni ẹ̀ṣẹ̀: ẹ̀ṣẹ̀ kan ń bẹ tí kì í ṣe sí ikú.

185.18: Jh 17.15; 1Jh 3.9.Àwa mọ̀ pé ẹnikẹ́ni tí a bí nípa ti Ọlọ́run kì í dẹ́ṣẹ̀: ṣùgbọ́n ẹni tí a bí nípa tí Ọlọ́run a pa ara rẹ̀ mọ́, ẹni búburú kò ní lè fọwọ́ kàn án. 19Àwa mọ̀ pé tí Ọlọ́run ni wá, àti gbogbo ayé ni ó wà lábẹ́ agbára ẹni búburú náà. 205.20-21: Jh 17.3; If 3.7.Àwa sì mọ̀ pé Ọmọ Ọlọ́run dé, ó sì tí fi òye fún wa, kí àwa lè mọ ẹni tí í ṣe òtítọ́, àwa sì ń bẹ nínú ẹni tí í ṣe òtítọ́, àní, nínú Ọmọ rẹ̀, Jesu Kristi. Èyí ni Ọlọ́run òtítọ́, àti ìyè àìnípẹ̀kun.

21Ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ pa ara yín mọ́ kúrò nínú òrìṣà.

Knijga O Kristu

1 Ivanova 5:1-21

Vjera u Božjeg Sina

1Tko vjeruje da Isus jest Krist, rođen je od Boga. A tko voli Oca, voli i njegovu djecu. 2Volimo li Božju djecu, znat ćemo po tomu volimo li Boga i vršimo li njegove zapovijedi. 3Jer voljeti Boga znači držati njegove zapovijedi, a to zaista nije teško. 4Tko je rođen od Boga pobjeđuje ovaj zao svijet vjerom u Krista. 5Jer tko će pobijediti svijet ako ne oni koji vjeruju da je Isus Krist Božji Sin?

6On, Isus Krist, došao je kroz vodu i kroz krv; ne samo u vodi već i u vodi i u krvi. I Duh o tome svjedoči jer je Duh istina. 7Tako troje svjedoči: 8Duh, voda i krv, i to se troje slaže. 9Vjerujemo li ljudskom svjedočanstvu, kako ne bismo vjerovali Božjemu. A Bog svjedoči da je Isus njegov Sin. 10Tko vjeruje u Božjega Sina, ima to svjedočanstvo Božje u sebi. Tko ne vjeruje Bogu, naziva Boga lašcem jer ne vjeruje u Božje svjedočanstvo o njegovu Sinu.

11Evo tog svjedočanstva: Bog nam je dao vječni život i taj je život u njegovu Sinu. 12Tko ima Božjeg Sina, ima život; tko nema Božjeg Sina, nema ni života.

Zaključak

13Napisah ovo vama koji vjerujete u ime Sina Božjega da znate da imate vječni život. 14Pouzdajemo se u njega da uslišava što god ga zamolimo u skladu s njegovom voljom. 15A kad znamo da nas u svemu uslišava, znamo i da već imamo ono što smo ga molili.

16Vidi li tko brata da čini grijeh koji nije smrtonosan, neka moli i Bog će takvom bratu dati život. Postoji i smrtonosan grijeh; za nj ne kažem da molite. 17Svaka je nepravda grijeh, ali ima grijeha koji nisu smrtonosni.

18Znamo da nitko tko je rođen od Boga ne živi u grijehu jer Božji Sin takve sigurno čuva i Zli ih ne može dohvatiti. 19Znamo da smo mi Božja djeca, a da je sav svijet u vlasti Zloga. 20Znamo i to da je Krist, Božji Sin, došao i dao nam razum da bismo mogli spoznati Istinitoga. Mi smo u Istinitome, u njegovu Sinu Isusu Kristu. On je istiniti Bog i Život vječni.

21Čuvajte se, djeco moja, idola i svega drugoga što bi u vašim srcima moglo zauzeti Božje mjesto!