1 Ọba 1 – YCB & CARS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Ọba 1:1-53

Adonijah fi ara rẹ̀ jẹ Ọba

1Nígbà tí Dafidi Ọba di arúgbó, ọjọ́ rẹ̀ sì pọ̀, ara rẹ̀ kò le è móoru bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n da ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ bò ó. 2Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí fún un pé, “Ẹ jẹ́ kí a wá ọ̀dọ́mọbìnrin wúńdíá kan kí ó dúró ti ọba, kì ó sì máa tọ́jú rẹ̀. Kí ó dùbúlẹ̀ ní àyà rẹ̀ kí ara ọba olúwa wa lè móoru.”

3Nígbà náà ni wọ́n lọ jákèjádò ilẹ̀ Israẹli láti wá ọ̀dọ́mọbìnrin arẹwà, wọ́n sì rí Abiṣagi, ará Ṣunemu, wọ́n sì mú un wá sí ọ̀dọ̀ ọba. 4Ọmọbìnrin náà rẹwà gidigidi; ó sì ń ṣe ìtọ́jú ọba, ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún un, ṣùgbọ́n ọba kò sì bá a lòpọ̀.

5Adonijah ẹni tí ìyá rẹ̀ ń ṣe Haggiti sì gbé ara rẹ̀ ga, ó sì wí pé, “Èmi yóò jẹ ọba.” Ó sì ṣètò kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin, pẹ̀lú àádọ́ta ọkùnrin láti máa sáré níwájú rẹ̀. 6(Baba rẹ̀ kò bà á nínú jẹ́ rí nípa bíbéèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí ìwọ fi hùwà báyìí?” Ó sì jẹ́ arẹwà ọkùnrin, òun ni a bí lé Absalomu.)

7Adonijah sì gbèrò pẹ̀lú Joabu, ọmọ Seruiah àti Abiatari àlùfáà, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún un. 8Ṣùgbọ́n Sadoku àlùfáà, Benaiah ọmọ Jehoiada, Natani wòlíì, Ṣimei àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ Rei àti olórí ogun Dafidi ni kò darapọ̀ mọ́ Adonijah.

9Nígbà náà ni Adonijah fi àgùntàn àti màlúù àti ẹran ọ̀sìn tí ó sanra rú ẹbọ níbi òkúta Soheleti tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ En-Rogeli. Ó sì pe gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ ọba, àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí wọ́n jẹ́ ìránṣẹ́ ọba. 10Ṣùgbọ́n kò pe Natani wòlíì tàbí Benaiah tàbí àwọn olórí tàbí Solomoni arákùnrin rẹ̀.

11Nígbà náà ni Natani béèrè lọ́wọ́ Batṣeba, ìyá Solomoni pé, “Ǹjẹ́ ìwọ kò gbọ́ pé Adonijah, ọmọ Haggiti ti jẹ ọba láìjẹ́ pé Dafidi olúwa wa mọ̀ sí i? 12Ǹjẹ́ nísinsin yìí, jẹ́ kí èmi gbà ọ́ ní ìmọ̀ràn bí ìwọ ṣe lè gba ẹ̀mí rẹ là àti ẹ̀mí ọmọ rẹ Solomoni. 13Lọ sọ́dọ̀ Dafidi ọba, kí o sì wí fún un pé, ‘Olúwa mi ọba, ǹjẹ́ ìwọ kò búra fún ìránṣẹ́ rẹ pé, “Dájúdájú Solomoni ọmọ rẹ ni yóò Jọba lẹ́yìn mi, yóò sì jókòó lórí ìtẹ́ mi?” Èéṣe nígbà náà tí Adonijah fi jẹ ọba?’ 14Níwọ́n ìgbà tí ìwọ sì wà níbẹ̀, tí o sì ń bá ọba sọ̀rọ̀ èmi yóò wá, láti wádìí ohun tí o ti sọ.”

15Bẹ́ẹ̀ ni Batṣeba lọ rí ọba ní inú yàrá rẹ̀, ọba sì gbó gidigidi níbi tí Abiṣagi ará Ṣunemu ti ń ṣe ìránṣẹ́ fún ọba. 16Batṣeba sì tẹríba, ó sì kúnlẹ̀ níwájú ọba.

Ọba sì béèrè pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?”

17Ó sì wí fún ọba pé, “Olúwa mi; ìwọ fúnrarẹ̀ fi Olúwa Ọlọ́run rẹ búra fún ìránṣẹ́ rẹ pé: ‘Solomoni ọmọ rẹ yóò jẹ ọba lẹ́yìn mi, yóò sì jókòó lórí ìtẹ́ mi.’ 18Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, Adonijah ti di ọba, ìwọ, ọba olúwa mi kò sì mọ̀ nípa rẹ̀. 19Òun sì ti fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ màlúù, àti ẹran tí ó ní ọ̀rá, àti àgùntàn rú ẹbọ, ó sì pe gbogbo àwọn ọmọ ọba, àti Abiatari àlùfáà àti Joabu Balógun, ṣùgbọ́n kò sì pe Solomoni ìránṣẹ́ rẹ. 20Olúwa mi ọba, ojú gbogbo Israẹli ń bẹ lára rẹ, láti mọ ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ olúwa mi ọba lẹ́yìn rẹ. 21Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà tí olúwa mi ọba bá sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, wọn yóò sì ka èmi àti Solomoni sí ẹlẹ́ṣẹ̀.”

22Bí ó sì ti ń bá ọba sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, Natani wòlíì sì wọlé. 23Wọ́n sì sọ fún ọba pé, “Natani wòlíì wà níbí.” Ó sì lọ síwájú ọba, ó wólẹ̀, ó sì dojúbolẹ̀.

24Natani sì wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ, olúwa mi ọba, ti sọ pé Adonijah ni yóò jẹ ọba lẹ́yìn rẹ àti pé òun ni yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ? 25Ó sì ti sọ̀kalẹ̀ lọ ní òní, ó sì ti rú ẹbọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ màlúù, àti ẹran ọlọ́ràá àti àgùntàn. Ó sì ti pe gbogbo àwọn ọmọ ọba, Balógun àti Abiatari àlùfáà. Ní ṣinṣin yìí, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì wí pé, ‘Kí Adonijah ọba kí ó pẹ́!’ 26Ṣùgbọ́n èmi ìránṣẹ́ rẹ, àti Sadoku àlùfáà, àti Benaiah ọmọ Jehoiada, àti Solomoni ìránṣẹ́ rẹ ni kò pè. 27Ṣé nǹkan yìí ni olúwa mi ọba ti ṣe láìjẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ mọ ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ olúwa mi ọba lẹ́yìn rẹ?”

Dafidi fi Solomoni jẹ ọba

28Nígbà náà ni Dafidi ọba wí pé, “Pe Batṣeba wọlé wá.” Ó sì wá síwájú ọba, ó sì dúró níwájú rẹ̀.

29Ọba sì búra pé, “Dájúdájú bí Olúwa ti wà ẹni tí ó ti gbà mí kúrò nínú gbogbo wàhálà, 30Lónìí dandan ni èmi yóò gbé ohun tí mo ti fi Olúwa Ọlọ́run Israẹli búra fún yọ pé: Solomoni ọmọ rẹ ni yóò jẹ ọba lẹ́yìn mi, àti pé yóò jókòó lórí ìtẹ́ mi ní ipò mi.”

31Nígbà náà ni Batṣeba tẹríba, ó sì kúnlẹ̀ níwájú ọba pé, “Kí olúwa mi Dafidi ọba kí ó pẹ́!”

32Dafidi ọba sì wí pé, “Ẹ pe Sadoku àlùfáà wọlé fún mi àti Natani wòlíì àti Benaiah ọmọ Jehoiada.” Nígbà tí wọ́n wá síwájú ọba, 33Ọba sì wí fún wọn pé: “Ẹ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa yín pẹ̀lú yín kí ẹ sì mú kí Solomoni ọmọ mi kí ó gun ìbáaka mi, kí ẹ sì mú un sọ̀kalẹ̀ wá sí Gihoni. 34Níbẹ̀ ni Sadoku àlùfáà àti Natani wòlíì yóò ti fi òróró yàn án ní ọba lórí Israẹli. Ẹ fọn fèrè, kí ẹ sì ké pé, ‘Kí Solomoni ọba kí ó pẹ́!’ 35Nígbà náà ni kí ẹ sì gòkè pẹ̀lú rẹ̀, kí ó sì wá, kí ó sì jókòó sórí ìtẹ́ mi, kí ó sì jẹ ọba ní ipò mi. Èmi ti yàn án ní ọba lórí gbogbo Israẹli àti Juda.”

36Benaiah ọmọ Jehoiada sì dá ọba lóhùn pé, “Àmín! Kí Olúwa Ọlọ́run olúwa mi ọba, kéde rẹ̀ bẹ́ẹ̀ 37Olúwa ti wà pẹ̀lú olúwa mi ọba, bẹ́ẹ̀ ni kí ó wà pẹ̀lú Solomoni kí ó lè mú kí ìjọba rẹ̀ pẹ́ ju ìtẹ́ olúwa mi Dafidi ọba lọ!”

38Nígbà náà ni Sadoku àlùfáà, Natani wòlíì, Benaiah ọmọ Jehoiada, àwọn ará Kereti àti Peleti sì sọ̀kalẹ̀ wá wọ́n sì gbé Solomoni gun ìbáaka Dafidi ọba wá sí Gihoni. 39Sadoku àlùfáà sì mú ìwo òróró láti inú àgọ́, ó sì dà á sí Solomoni lórí. Nígbà náà ni wọ́n sì fọn fèrè, gbogbo àwọn ènìyàn sì ké pé, “Kí Solomoni ọba kí ó pẹ́!” 40Gbogbo ènìyàn sì gòkè tọ̀ ọ́ lẹ́yìn wọ́n ń fọn ìpè, wọ́n sì ń yọ ayọ̀ ńlá, tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ mì fún ìró wọn.

41Adonijah àti gbogbo àwọn àlejò tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ gbọ́ ọ́ bí wọ́n ti ń jẹun tán, wọ́n ń gbọ́ ìpè, Joabu sì wí pé, “Kí ní ìtumọ̀ gbogbo ariwo nínú ìlú yìí?”

42Bí ó sì ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, Jonatani ọmọ Abiatari àlùfáà sì dé, Adonijah sì wí pé, “Wọlé wá, ọkùnrin yíyẹ ìwọ gbọdọ̀ mú ìròyìn rere wá.”

43Jonatani sì dáhùn, ó sì wí fún Adonijah pé, “Lóòótọ́ ni olúwa wa Dafidi ọba, fi Solomoni jẹ ọba. 44Ọba sì ti rán Sadoku àlùfáà, Natani wòlíì, Benaiah ọmọ Jehoiada àti àwọn ará Kereti àti Peleti pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì ti gbé e gun ìbáaka ọba, 45Sadoku àlùfáà àti Natani wòlíì ti fi òróró yàn án ní ọba ní Gihoni. Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gòkè wá pẹ̀lú ayọ̀, ìlú sì ń hó pẹ̀lú rẹ̀. Èyí ni ariwo tí ẹ̀yin ń gbọ́. 46Solomoni sì ti jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀. 47Àwọn ìránṣẹ́ ọba sì ti tún wá láti bá olúwa wa Dafidi ọba yọ̀, wí pé, ‘Kí Ọlọ́run rẹ̀ mú orúkọ Solomoni lókìkí ju tirẹ̀ lọ àti kí ìtẹ́ rẹ̀ kí ó pọ̀ ju tirẹ̀ lọ!’ Ọba sì tẹ ara rẹ̀ ba lórí ibùsùn rẹ̀, 48ọba sì wí pé, ‘Ògo ni fún Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti jẹ́ kí ojú mi rí ẹnìkan tí ó jókòó lórí ìtẹ́ mi lónìí.’ ”

49Nígbà náà ni gbogbo àwọn àlejò tí ó wà lọ́dọ̀ Adonijah dìde ní ìdágìrì, wọ́n sì túká. 50Ṣùgbọ́n Adonijah sì bẹ̀rù Solomoni, ó lọ, ó sì di ìwo pẹpẹ mú. 51Nígbà náà ni a sì sọ fún Solomoni pé, “Adonijah bẹ̀rù Solomoni ọba, ó sì di ìwo pẹpẹ mú, Ó wí pé, ‘Jẹ́ kí ọba Solomoni búra fún mi lónìí pé, òun kì yóò fi idà pa ìránṣẹ́ rẹ̀.’ ”

52Solomoni sì dáhùn pé, “Bí ó bá fi ara rẹ̀ hàn láti jẹ́ ẹni ọ̀wọ̀, irun orí rẹ̀ kan kì yóò sì bọ́ sílẹ̀; ṣùgbọ́n bí a bá rí búburú kan ní ọwọ́ rẹ̀ òun yóò kú.” 53Nígbà náà ni Solomoni ọba rán àwọn ènìyàn, wọ́n sì mú un sọ̀kalẹ̀ láti ibi pẹpẹ wá. Adonijah sì wá, ó sì foríbalẹ̀ fún Solomoni ọba, Solomoni sì wí pé, “Lọ ilé rẹ.”

Священное Писание

3 Царств 1:1-53

Давуд в старости

1Царь Давуд состарился и достиг преклонных лет. Его покрывали одеждами, но он всё равно не мог согреться. 2Тогда слуги сказали ему:

– Пусть господину нашему царю подыщут молодую девушку, чтобы она прислуживала царю и заботилась о нём. Она будет ложиться рядом с тобой, и господину нашему царю будет тепло.

3Они стали искать красивую девушку по всему Исраилу, нашли шунемитянку Авишаг и привели её к царю. 4Девушка была очень красива, она заботилась о царе и ухаживала за ним, но царь не имел с ней близости.

Адония претендует на престол

5Адония, сын Давуда от Хаггиты, кичливо говорил:

– Я буду царём.

Он завёл у себя колесницы и коней1:5 Или: «колесничих»; или: «всадников»., и пятьдесят слуг, которые бежали перед ним. 6(А его отец никогда не задавал ему вопроса: «Почему ты так поступаешь?» Адония родился после Авессалома и был очень красив.)

7Адония сговорился с Иоавом, сыном Церуи, и со священнослужителем Авиатаром, и они поддержали его. 8Но священнослужитель Цадок, Беная, сын Иодая, пророк Нафан, Шимей, Рей и личная стража Давуда не встали на сторону Адонии.

9Адония принёс в жертву овец, волов и откормленных телят у камня Зохелет, что рядом с Ен-Рогелом, и пригласил всех своих братьев, сыновей царя, и всех царских приближённых из Иудеи, 10но не пригласил ни пророка Нафана, ни Бенаю, ни личную стражу Давуда, ни своего брата Сулеймана.

Давуд передаёт престол Сулейману

11Тогда пророк Нафан спросил у Вирсавии, матери Сулеймана:

– Разве ты не слышала, что Адония, сын Хаггиты, стал царём, а наш господин Давуд о том и не знает? 12Так вот, позволь мне посоветовать тебе, как спасти свою жизнь и жизнь твоего сына Сулеймана. 13Сейчас же пойди к царю Давуду и скажи ему: «Господин мой царь, разве ты не клялся мне, твоей рабыне, говоря: „Твой сын Сулейман непременно будет царём после меня и сядет на моём престоле“? Так почему же царём стал Адония?» 14Когда ты ещё будешь говорить с царём, я войду вслед за тобой и подтвержу твои слова.

15И Вирсавия пошла к престарелому царю в его комнату, где ему прислуживала шунемитянка Авишаг. 16Вирсавия склонилась и поклонилась царю.

– Чего ты хочешь? – спросил царь.

17Она сказала ему:

– Мой господин, ты сам клялся мне, твоей рабыне, Вечным1:17 Вечный – на языке оригинала: «Яхве». Под этим именем Всевышний открылся Мусе и народу Исраила (см. Исх. 3:13-15). См. пояснительный словарь., твоим Богом: «Сулейман, твой сын, будет царём после меня и сядет на моём престоле». 18Но вот царём стал Адония, а ты, господин мой царь, и не знаешь об этом. 19Он принёс в жертву множество волов, откормленных телят и овец, пригласил всех царских сыновей, священнослужителя Авиатара и военачальника Иоава, но не пригласил твоего раба Сулеймана. 20Господин мой царь, взоры всего Исраила устремлены на тебя, чтобы ты объявил им, кто сядет на престоле господина моего царя после тебя. 21Ведь иначе, как только господин мой царь упокоится со своими предками, меня и моего сына Сулеймана сочтут изменниками.

22Когда она ещё говорила с царём, вошёл пророк Нафан. 23Царю доложили:

– Пришёл пророк Нафан.

Тогда Нафан предстал перед царём и поклонился ему лицом до земли.

24Он сказал:

– Говорил ли ты, господин мой царь, что Адония будет царём после тебя и сядет на твоём престоле? 25Сегодня он пошёл и принёс в жертву множество волов, откормленных телят и овец. Он пригласил всех царских сыновей, военачальников и священнослужителя Авиатара. Сейчас они едят и пьют с ним и говорят: «Да здравствует царь Адония!» 26Но меня, твоего раба, священнослужителя Цадока, Бенаю, сына Иодая, и твоего раба Сулеймана он не пригласил. 27Было ли это сделано по воле господина моего царя, который не известил своих рабов о том, кто сядет на престоле моего господина царя после него?

28Тогда царь Давуд сказал:

– Позовите ко мне Вирсавию.

Она вошла к царю и предстала перед ним.

29И царь поклялся:

– Верно, как и то, что жив Вечный, Который избавил меня от всякой беды, – 30я непременно исполню сегодня то, о чём я клялся тебе Вечным, Богом Исраила: Сулейман, твой сын, станет царём после меня и сядет на моём престоле вместо меня.

31Вирсавия склонилась лицом до земли, поклонилась царю и сказала:

– Пусть господин мой царь Давуд живёт вечно!

32Давуд сказал:

– Позовите ко мне священнослужителя Цадока, пророка Нафана и Бенаю, сына Иодая.

Когда они вошли к царю, 33он сказал им:

– Возьмите с собой моих слуг, посадите моего сына Сулеймана на моего мула и доставьте его к источнику Гихон. 34Там пусть священнослужитель Цадок и пророк Нафан помажут1:34 Посредством обряда помазания человек посвящался на определённое служение. Такого помазания удостаивались пророки, цари и священнослужители. его в цари над Исраилом. Трубите в рог и восклицайте: «Да здравствует царь Сулейман!» 35Потом проводите его назад, и пусть он сядет на мой престол и правит вместо меня. Я поставил его правителем над Исраилом и Иудеей.

36Беная, сын Иодая, ответил царю:

– Аминь!1:36 Аминь – еврейское слово, которое переводится как «да, верно, воистину так» или «да будет так». Да скажет так Вечный, Бог господина моего царя! 37Как Вечный был с господином моим царём, так пусть он будет и с Сулейманом, чтобы возвеличить его престол больше, чем престол господина моего царя Давуда!

38И священнослужитель Цадок, пророк Нафан, Беная, сын Иодая, керетиты и пелетиты1:38 Керетиты и пелетиты – чужеземные наёмники, которые, возможно, были царскими телохранителями. пошли, усадили Сулеймана на мула царя Давуда и сопроводили его в Гихон. 39Священнослужитель Цадок взял из священного шатра рог с маслом и помазал Сулеймана. После этого затрубили в рога, и весь народ закричал:

– Да здравствует царь Сулейман!

40И весь народ пошёл вслед за ним, играя на свирелях и радуясь, да так, что земля сотрясалась от шума.

Сулейман щадит Адонию

41Адония и все гости, которые были с ним, услышали это в конце пира. Услышав звук рога, Иоав спросил:

– Что это за шум в городе?

42Он ещё не договорил, как пришёл Ионафан, сын священнослужителя Авиатара. Адония сказал:

– Подойди. Ты достойный человек и, конечно, несёшь добрые вести.

43– Нет, – ответил Ионафан Адонии. – Наш господин, царь Давуд, сделал царём Сулеймана. 44Царь отправил его со священнослужителем Цадоком, пророком Нафаном, Бенаей, сыном Иодая, и керетитами и пелетитами, и они усадили его на царского мула, 45а священнослужитель Цадок и пророк Нафан помазали его в цари в Гихоне. Они ушли оттуда в радости, и город пришёл в движение. Этот-то шум ты и слышишь. 46Больше того, Сулейман сел на царский престол, 47а царские приближённые пришли поздравлять господина нашего царя Давуда, говоря: «Пусть твой Бог прославит имя Сулеймана ещё больше, чем твоё, и возвеличит его престол больше твоего престола!» А царь поклонился на постели 48и сказал так: «Хвала Вечному, Богу Исраила, Который дал мне сегодня увидеть на престоле моего преемника!»

49Тут все гости Адонии, задрожав от страха, поднялись и разбежались. 50А Адония, боясь Сулеймана, пошёл и схватился за рога жертвенника в священном шатре1:50 Человек, которому грозит смерть, мог просить о пощаде, взявшись за рога жертвенника, которые возвышались с каждого из его четырёх углов (см. 3 Цар. 1:50-53).. 51Сулейману доложили:

– Адония боится царя Сулеймана и не отпускает рогов жертвенника. Он говорит: «Пусть царь Сулейман даст мне сегодня клятву, что он не предаст своего раба мечу».

52Сулейман ответил:

– Если он покажет себя достойным человеком, то ни один волос с его головы не упадёт на землю, но если в нём обнаружится зло, он умрёт.

53Царь Сулейман послал людей за Адонией, и они привели его от жертвенника. Адония вошёл и поклонился царю Сулейману, и Сулейман сказал:

– Ступай домой.