Ọbadiah 1 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ọbadiah 1:1-21

1Ìran ti Ọbadiah.

1-21: Isa 34; 63.1-6; Jr 49.7-22; El 25.12-14; 35; Am 1.11-12; Ml 1.2-5.Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu.

Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá:

A sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé,

“Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”

2“Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí;

ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọpọ̀,

3Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ,

ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta,

tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga,

ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé,

‘ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’

4Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì,

bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀,

láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,”

ni Olúwa wí.

5“Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá,

bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru,

Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́:

wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́?

Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá,

wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?

6Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau,

tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.

7Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ

ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ:

Àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ;

àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́,

ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”

8Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà,

Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run,

àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?

9A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, Ìwọ Temani,

gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau

ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.

10Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ,

ìtìjú yóò bò ọ,

a ó sì pa ọ run títí láé.

11Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan,

ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ,

tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ

tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu,

ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.

12Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ,

ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀

ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda,

ní ọjọ́ ìparun wọn

ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀

ní ọjọ́ wàhálà wọn.

13Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ,

ní ọjọ́ àjálù wọn.

Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀

nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn.

Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó,

ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.

14Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà

láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò.

Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú

wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.

15“Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé

lórí gbogbo àwọn kèfèrí.

Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà;

ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.

16Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi

bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí

Wọn yóò mu wọn yóò sì mu àmutẹ́rùn

wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò wà rí

17Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni

Wọn yóò sì jẹ́ mímọ́

àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn

18Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná

àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná

ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko

wọn yóò fi iná sí i,

wọn yóò jo run.

Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.”

Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.

19Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau,

àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni

ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní.

Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria;

Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.

20Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani

yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati;

àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi

yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní

21Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá

láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau.

Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.

New International Reader’s Version

Obadiah 1:1-21

Obadiah’s Vision

1This is the vision about Edom that Obadiah had.

Here is what the Lord and King says about Edom.

We’ve heard a message from the Lord.

A messenger was sent to the nations.

The Lord told him to say,

“Get up! Let us go and make war against Edom.”

2The Lord says to Edom,

“I will make you weak among the nations.

They will look down on you.

3You live in the safety of the rocks.

You make your home high up in the mountains.

But your proud heart has tricked you.

So you say to yourself,

‘No one can bring me down to the ground.’

4You have built your home as high as an eagle does.

You have made your nest among the stars.

But I will bring you down from there,”

announces the Lord.

5“Edom, suppose robbers came to you at night.

They would steal only as much as they wanted.

Suppose grape pickers came to harvest your vines.

They would still leave a few grapes.

But you are facing horrible trouble!

6People of Esau, everything will be taken away from you.

Your hidden treasures will be stolen.

7All those who are helping you

will force you to leave your country.

Your friends will trick you and overpower you.

Those who eat bread with you

will set a trap for you.

But you will not see it.”

8Here is what the Lord announces. “At that time

I will destroy the wise men of Edom.

I will wipe out the men of understanding

in the mountains of Esau.

9People of Teman, your soldiers will be terrified.

Everyone in Esau’s mountains

will be cut down by swords.

10You did harmful things to the people of Jacob.

They are your relatives.

So you will be covered with shame.

You will be destroyed forever.

11Outsiders entered the gates of Jerusalem.

They cast lots to see what each one would get.

Strangers carried off its wealth.

When that happened, you just stood there and did nothing.

You were like one of them.

12That was a time of trouble for your relatives.

So you shouldn’t have been happy about what happened to them.

The people of Judah were destroyed.

So you should not have been happy about it.

You should not have laughed at them so much

when they were in trouble.

13You should not have marched

through the gates of my people’s city

when they were in trouble.

You shouldn’t have been happy about what happened to them.

You should not have stolen their wealth

when they were in trouble.

14You waited where the roads cross.

You wanted to cut down those who were running away.

You should not have done that.

You handed over to their enemies

those who were still left alive.

You should not have done that.

They were in trouble.

15“The day of the Lord is near

for all the nations.

Others will do to you

what you have done to them.

You will be paid back

for what you have done.

16You Edomites made my holy mountain of Zion impure

by drinking and celebrating there.

So all the nations will drink

from the cup of my anger.

And they will keep on drinking from it.

They will vanish.

It will be as if they had never existed.

17But on Mount Zion some of my people will be left alive.

I will save them.

Zion will be my holy mountain once again.

And the people of Jacob

will again receive the land as their own.

18They will be like a fire.

Joseph’s people will be like a flame.

The nation of Edom will be like straw.

Jacob’s people will set Edom on fire and burn it up.

No one will be left alive

among Esau’s people.”

The Lord has spoken.

19Israelites from the Negev Desert

will take over Esau’s mountains.

Israelites from the western hills

will possess the land of the Philistines.

They’ll take over the territories

of Ephraim and Samaria.

Israelites from the tribe of Benjamin

will possess the land of Gilead.

20Some Israelites were forced to leave their homes.

They’ll come back to Canaan and possess

it all the way to the town of Zarephath.

Some people from Jerusalem were taken

to the city of Sepharad.

They’ll return and possess

the towns of the Negev Desert.

21Leaders from Mount Zion will go

and rule over the mountains of Esau.

And the kingdom will belong to the Lord.